< Josué 13 >

1 Josué était vieux et d’un âge fort avancé, et le Seigneur lui dit: Tu es vieux, et même très avancé en âge, et une terre très étendue est restée, qui n’a pas été encore divisée par le sort:
Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
2 Savoir, toute la Galilée, la terre des Philistins et toute celle de Gessuri,
“Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
3 Depuis le fleuve fangeux qui arrose l’Egypte jusqu’aux confins d’Accaron, contre l’aquilon; la terre de Chanaan qui est partagée entre les cinq princes des Philistins, celui de Gaza, celui d’Azot, celui d’Ascalon, celui de Geth et celui d’Accaron.
láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
4 Mais au midi sont les Hévéens, toute la terre de Chanaan, Maara des Sidoniens, jusqu’à Aphéca et jusqu’aux frontières des Amorrhéens,
láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
5 Et jusqu’aux pays qui leur sont voisins; de plus, la contrée du Liban contre l’orient, depuis Baalgad, au-dessous de la montagne d’Hermon, jusqu’à ce qu’on entre à Emath;
àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
6 La contrée de tous ceux qui habitent sur la montagne, depuis le Liban jusqu’aux eaux de Maséréphoth, et tous les Sidoniens. Je suis celui qui les exterminerai de la face des enfants d’Israël. Que cela entre donc dans la part de l’héritage d’Israël, comme je t’ai ordonné.
“Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
7 Et maintenant partage la terre en possession aux neuf tribus, et à la demi-tribu de Manassé,
pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
8 Avec laquelle Ruben et Gad possédèrent déjà la terre que leur a livrée Moïse, serviteur du Seigneur, au-delà des courants du Jourdain, du côté oriental,
Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
9 Depuis Aroer, qui est située sur la rive du torrent d’Arnon, et au milieu de la vallée; de plus, toute la campagne de Médaba, jusqu’à Dibon;
Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
10 Et toutes les villes de Séhon, roi de l’Amorrhéen, lequel a régné à Hésébon, jusqu’aux frontières des enfants d’Ammon:
Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
11 Galaad, les confins de Gessuri et de Machati; toute la montagne d’Hermon, et tout le Basan, jusqu’à Salécha,
Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
12 Tout le royaume d’Og en Basan, lequel a régné à Astaroth et à Edraï, et qui était des restes des Raphaïm; et Moïse les battit et les détruisit.
ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
13 Cependant les enfants d’Israël ne voulurent pas exterminer ceux de Gessuri et de Machati; aussi ont-ils habité au milieu d’Israël jusqu’au présent jour.
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
14 Mais à la tribu de Lévi. Moïse ne donna point de possession, parce que les sacrifices et les victimes du Seigneur Dieu d’Israël sont son héritage, comme lui a dit le Seigneur.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
15 Moïse donna donc des possessions à la tribu des enfants de Ruben, selon sa parenté.
Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
16 Et sa limite fut depuis Aroer, qui est située sur la rive du torrent d’Arnon, et au milieu de la vallée du même torrent, toute la plaine qui conduit à Médaba,
láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
17 Hésébon, et tous leurs villages qui sont dans la campagne; Dibon aussi, Bamothbaal, la ville de Baalméon,
sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
18 Jassa, Cédimoth, Méphaath,
Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
19 Cariathaïm, Sabama, Sarathasar sur la montagne de la vallée,
Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
20 Bethphogor et Asédoth, Phasga et Bethiésimoth,
Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
21 Et toutes les villes de la plaine, tous les royaumes de Séhon, roi de l’Amorrhéen, qui régna à Hésébon, que Moïse battit avec les princes de Madian, Hévi, Résem, Sur, Hur et Rébé, chefs de Séhon, habitants de cette terre.
gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
22 Et les enfants d’Israël firent mourir par le glaive Balaam le devin, fils de Béor, avec tous les autres qui furent tués,
Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
23 Et le Jourdain devint la limite des enfants de Ruben. C’est là la possession des villes et des villages des Rubénites, selon leur parenté.
Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
24 Moïse donna aussi à la tribu de Gad et a ses enfants, selon leur parenté, une possession dont voici la division:
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
25 Sa limite fut Jaser, toutes les villes de Galaad, et la moitié de la terre des enfants d’Ammon, jusqu’à Aroer, qui est contre Rabba,
Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
26 Depuis Hésébon jusqu’à Ramoth, Masphé et Betonim, et depuis Manaïm jusqu’aux confins de Dabir;
àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
27 De plus, dans la vallée de Betharan, de Bethnemra, de Socoth et de Saphon, reste du royaume de Séhon, roi d’Hésébon; sa limite est aussi le Jourdain jusqu’à l’extrémité de la mer de Généreth, au-delà du Jourdain, du côté oriental.
àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
28 Voilà la possession des enfants de Gad, selon leurs familles, voilà les villes et les villages de ces familles.
Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
29 Moïse donna aussi à la demi-tribu de Manassé et à ses enfants, selon leur parenté, une possession,
Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
30 Dont voici le commencement: Depuis Manaïm, tout Basan, tous les royaumes d’Og, roi de Bazan, tous les bourgs de Jaïr qui sont en Basan, soixante villes;
Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
31 Et la moitié de Galaad, Astaroth et Edraï, villes du royaume d’Og, en Basan, aux enfants de Machir, fils de Manassé, c’est-à-dire à la moitié des enfants de Machir, selon leur parenté.
ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
32 Moïse partagea cette possession dans la plaine de Moab, au-delà du Jourdain, contre Jéricho, du côté oriental.
Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
33 Mais à la tribu de Lévi, il ne donna pas de possession, parce que le Seigneur Dieu d’Israël est lui-même sa possession, comme il lui a dit.
Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.

< Josué 13 >