< Josué 11 >

1 Lorsque Jabin, roi d’Asor, eut appris ces choses, il envoya vers Jobab, roi de Madon, vers le roi de Séméron, vers le roi d’Achsaph,
Nígbà tí Jabini ọba Hasori gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó ránṣẹ́ sí Jobabu ọba Madoni, sí ọba Ṣimroni àti Akṣafu,
2 Et aussi vers les rois de l’aquilon, qui habitaient dans les montagnes et dans la plaine, contre le midi de Cénéroth, dans les campagnes mêmes et dans les contrées de Dor, près de la mer;
àti sí àwọn ọba ìhà àríwá tí wọ́n wà ní orí òkè ní aginjù, gúúsù ti Kinnereti, ní ẹsẹ̀ òkè ìwọ̀-oòrùn àti ní Nafoti Dori ní ìwọ̀-oòrùn;
3 De plus, vers le Chananéen à l’orient et à l’occident, vers l’Amorrhéen, l’Héthéen, le Phérézéen, le Jébuséen dans les montagnes; vers l’Hévéen aussi qui habitait au pied de l’Hermon, dans la terre de Maspha.
sí àwọn ará Kenaani ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Amori, Hiti, Peresi àti Jebusi ní orí òkè; àti sí àwọn Hifi ní ìsàlẹ̀ Hermoni ní agbègbè Mispa.
4 Ils sortirent tous avec leurs troupes, peuple très nombreux, comme le sable qui est sur le rivage de la mer, et avec une grande multitude de chevaux et de chars.
Wọ́n sì jáde pẹ̀lú gbogbo ogun wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun ńlá, wọ́n sì pọ̀, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun.
5 Et tous ces rois vinrent ensemble auprès des eaux de Mérom, pour combattre contre Israël.
Gbogbo àwọn ọba yìí pa ọmọ-ogun wọn pọ̀, wọ́n sì pa ibùdó sí ibi omi Meromu láti bá Israẹli jà.
6 Alors le Seigneur dit à Josué: Ne les crains point; car demain, à cette même heure, moi-même je les livrerai tous pour être battus en présence d’Israël: tu couperas les nerfs des jambes de leurs chevaux, et tu brûleras leurs chars au feu.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí ní àkókò yìí ní ọ̀la, gbogbo wọn ni èmi yóò fi lé Israẹli lọ́wọ́ ní pípa. Ìwọ yóò já iṣan ẹ̀yìn ẹṣin wọn, ìwọ yóò sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.”
7 Et Josué vint soudainement et toute son armé avec lui, contre eux auprès des eaux de Mérom, et ils fondirent sur eux,
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ yọ sí wọn ní òjijì ní ibi omi Meromu, wọ́n sì kọlù wọ́n,
8 Et le Seigneur les livra aux mains d’Israël. Ils les battirent et les poursuivirent jusqu’à la grande Sidon, jusqu’aux eaux de Maséréphoth et jusqu’à la campagne de Masphé, laquelle est à sa partie orientale. Il les battit tous de telle sorte qu’il n’en laissa aucun reste;
Olúwa sì fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́. Wọ́n ṣẹ́gun wọn, wọ́n sì lépa wọn ní gbogbo ọ̀nà títí dé Sidoni ńlá, sí Misrefoti-Maimu, àti sí àfonífojì Mispa ní ìlà-oòrùn, títí tí kò fi ku ẹnìkankan sílẹ̀.
9 Et il fit comme lui avait ordonné le Seigneur, il coupa les nerfs des jambes de leurs chevaux, et brûla les chars au feu.
Joṣua sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ: Ó sì já iṣan ẹ̀yìn ẹsẹ̀ ẹṣin wọn ó sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.
10 Et étant retourné aussitôt il prit Asor, et frappa de son glaive le roi de cette ville; car Asor anciennement tenait le premier rang entre tous ces royaumes.
Ní àkókò náà Joṣua sì padà sẹ́yìn, ó sì ṣẹ́gun Hasori, ó sì fi idà pa ọba rẹ̀. (Hasori tí jẹ́ olú fún gbogbo àwọn ìlú wọ̀nyí kó tó di àkókò yí.)
11 Il frappa toutes les âmes qui s’y trouvaient, et il n’y laissa aucun reste; mais il ravagea tout jusqu’à une dernière extermination; et la ville elle-même, il la détruisit par un incendie.
Wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀. Wọ́n sì pa wọ́n run pátápátá, wọn kò sì fi ohun alààyè kan sílẹ̀; ó sì fi iná sun Hasori fúnra rẹ̀.
12 Quant à toutes les cités d’alentour et à leurs rois, il les prit, les battit et les détruisit, comme lui avait ordonné Moïse, serviteur du Seigneur.
Joṣua sì kó gbogbo àwọn ìlú ọba àti ọba wọn, ó sì fi idà pa wọ́n. Ó sì run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ.
13 Israël mit le feu à toutes les autres villes, excepté à celles qui étaient situées sur les collines et sur les hauteurs; il ne consuma entièrement par les flammes que la seule Asor, qui était très fortifiée.
Síbẹ̀ Israẹli kò sun ọ̀kankan nínú àwọn ìlú tó wà lórí òkè kéékèèké, àyàfi Hasori nìkan tí Joṣua sun.
14 Mais tout le butin de ces villes et les bestiaux, les enfants d’Israël se les partagèrent, tous les hommes ayant été tués.
Àwọn ará Israẹli sì kó gbogbo ìkógun àti ohun ọ̀sìn ti ìlú náà fún ara wọn. Wọ́n sì fi idà pa gbogbo ènìyàn títí wọ́n fi run wọ́n pátápátá, kò sí ẹni tí ó wà láààyè.
15 Comme le Seigneur avait ordonné à Moïse, son serviteur, ainsi ordonna Moïse à Josué, et celui-ci accomplit tout; il n’omit aucun des commandements, ni même une seule parole de ce que le Seigneur avait commandé à Moïse.
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní Mose pàṣẹ fún Joṣua, Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀. Kò fi ọ̀kankan sílẹ̀ láìṣe nínú gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
16 C’est pourquoi Josué prit toute la terre montagneuse et méridionale, la terre de Gosen, la plaine, la région occidentale, la montagne d’Israël et ses campagnes.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gba gbogbo ilẹ̀ náà: ilẹ̀ òkè, gbogbo gúúsù, gbogbo agbègbè Goṣeni, ẹsẹ̀ òkè ti ìwọ̀-oòrùn, aginjù àti àwọn òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ Israẹli,
17 Et la partie de la montagne qui monte vers Séir jusqu’à Baalgad par la plaine du Liban, au-dessous de la montagne d’Hermon: il prit tous leurs rois, les battit et les tua.
láti òkè Halaki títí dé òkè Seiri, sí Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni. Ó sì mú gbogbo ọba wọn, ó sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n.
18 Pendant longtemps Josué combattit contre ses rois.
Joṣua sì bá gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí jagun ní ọjọ́ pípẹ́.
19 Il n’y eut pas de ville qui se rendît aux enfants d’Israël, excepté l’Hévéen qui habitait à Gabaon; car il les prit toutes en combattant.
Kò sí ìlú kan tí ó bá àwọn ará Israẹli ṣe àdéhùn àlàáfíà, àyàfi àwọn ará Hifi tí wọ́n ń gbé ní Gibeoni, gbogbo wọn ló bá a jagun.
20 L’arrêt du Seigneur, en effet, avait été que leurs cœurs seraient endurcis, qu’ils combattraient contre Israël et qu’ils succomberaient, qu’ils ne mériteraient aucune clémence, et qu’ils périraient, comme avait ordonné le Seigneur à Moïse.
Nítorí Olúwa fúnra rẹ̀ ní ó sé ọkàn wọn le, kí wọn kí ó lè bá Israẹli jagun, kí òun lè pa wọ́n run pátápátá, kí wọn má sì ṣe rí ojúrere, ṣùgbọ́n kí ó lè pa wọ́n, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
21 En ce temps-là Josué vint, et il tua les Enacim des montagnes d’Hébron, de Dabir, d’Anab, et de toute la montagne de Juda et d’Israël, et il détruisit leurs villes.
Ní àkókò náà ni Joṣua lọ tí ó sì run àwọn ará Anaki kúrò ní ilẹ̀ òkè, láti Hebroni, Debiri, àti ní Anabu, àti gbogbo ilẹ̀ Juda, àti kúrò ní gbogbo ilẹ̀ òkè Israẹli. Joṣua sì run gbogbo wọn pátápátá àti ìlú wọn.
22 Il ne laissa aucun de la race des Enacim, dans la terre des enfants d’Israël, excepté dans les villes de Gaza, de Geth et d’Azot, dans lesquelles seules il en fut laissé.
Kò sí ará Anaki kankan tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ Israẹli: bí kò ṣe ní Gasa, Gati àti Aṣdodu.
23 Josué donc prit tout le pays, comme avait dit le Seigneur à Moïse, et il le livra en possession aux enfants d’Israël, selon leurs parts et leurs tribus; et le pays se reposa des combats.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gba gbogbo ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, ó sì fi fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn nípa ẹ̀yà wọn. Ilẹ̀ náà sì sinmi ogun.

< Josué 11 >