< Job 41 >

1 Pourras-tu enlever Léviathan à l’hameçon, et avec une corde lier sa langue?
“Ǹjẹ́ ìwọ le è fi ìwọ̀ fa Lefitani jáde? Tàbí ìwọ lè fi okùn so ahọ́n rẹ̀ mọ́lẹ̀?
2 Est-ce que tu mettras un cercle dans ses narines, ou avec un anneau perceras-tu sa mâchoire?
Ìwọ lè fi okùn bọ̀ ọ́ ní í mú, tàbí fi ìwọ̀ ẹ̀gún gun ní ẹ̀rẹ̀kẹ́?
3 Est-ce qu’il t’adressera de nombreuses prières, ou te dira-t-il de douces paroles?
Òun ha jẹ́ bẹ ẹ̀bẹ̀ fún àánú lọ́dọ̀ rẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ bí òun ha bá ọ sọ̀rọ̀ pẹ̀lẹ́?
4 Est-ce qu’il fera avec toi un pacte, et le recevras-tu comme un esclave éternel?
Òun ha bá ọ dá májẹ̀mú bí? Ìwọ ó ha máa mú ṣe ẹrú láéláé bí?
5 Est-ce que tu te joueras de lui comme d’un oiseau, ou le lieras-tu pour tes servantes?
Ìwọ ha lè ba sáré bí ẹni pé ẹyẹ ni, tàbí ìwọ ó dè é fún àwọn ọmọbìnrin ìránṣẹ́ rẹ̀?
6 Des amis le découperont-ils, ou des marchands le partageront-ils?
Ẹgbẹ́ àwọn apẹja yóò ha máa tà á bí? Wọn ó ha pín láàrín àwọn oníṣòwò?
7 Est-ce que tu rempliras de sa peau des filets, et un réservoir de poissons de sa tête?
Ìwọ ha lè fi ọ̀kọ̀-irin gun awọ rẹ̀, tàbí orí rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ ìpẹja.
8 Mets sur lui ta main: souviens-toi de la guerre, et ne continue pas à parler.
Fi ọwọ́ rẹ lé e lára, ìwọ ó rántí ìjà náà, ìwọ kì yóò sì ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
9 Voilà que son espoir le trompera, et à la vue de tous il se précipitera
Kíyèsi, ìgbìyànjú láti mú un ní asán; ní kìkì ìrí rẹ̀ ara kì yóò ha rọ̀ ọ́ wẹ̀sì?
10 Je ne suis pas assez cruel pour le susciter: car qui peut résister à mon visage;
Kò sí ẹni aláyà lílé tí ó lè ru sókè. Ǹjẹ́ ta ni ó lè dúró níwájú mi.
11 Qui m’a donné le premier, afin que je lui rende? Tout ce qui est sous le ciel est à moi.
Ta ni ó kọ́kọ́ ṣe fún mi, tí èmi ìbá fi san án fún un? Ohunkóhun ti ń bẹ lábẹ́ ọ̀run gbogbo, tèmi ni.
12 Je ne l’épargnerai pas, malgré ses discours arrogants et ses paroles suppliantes.
“Èmi kì yóò fi ẹ̀yà ara Lefitani, tàbí ipá rẹ, tàbí ìhámọ́ra rẹ tí ó ní ẹwà pamọ́.
13 Qui découvrira la face de son vêtement? Et qui entrera dans le milieu de sa gueule?
Ta ni yóò lè rídìí aṣọ àpáta rẹ̀? Tàbí ta ni ó lè súnmọ́ ọ̀nà méjì eyín rẹ̀?
14 Les portes de son visage, qui les ouvrira? autour de ses dents habite la terreur.
Ta ni ó lè ṣí ìlẹ̀kùn iwájú rẹ̀? Àyíká ẹ̀yin rẹ ni ìbẹ̀rù ńlá.
15 Son corps est comme des boucliers jetés en fonte et couvert d’écaillés épaisses et serrées.
Ìpẹ́ lílé ní ìgbéraga rẹ̀; ó pàdé pọ̀ tímọ́tímọ́ bí àmì èdìdì.
16 L’une est jointe à l’autre, et pas même l’air ne passe entre elles.
Èkínní fi ara mọ́ èkejì tó bẹ́ẹ̀ tí afẹ́fẹ́ kò lè wọ àárín wọn.
17 L’une s’attache à l’autre, et se tenant, jamais elles ne se sépareront.
Èkínní fi ara mọ́ èkejì rẹ̀; wọ́n lè wọ́n pọ̀ tí a kò lè mọ̀ wọ́n.
18 Son éternument, c’est l’éclat du feu, et ses yeux sont comme les paupières de l’aurore.
Nípa sí sin rẹ̀ ìmọ́lẹ̀ á mọ́, ojú rẹ̀ a sì dàbí ìpéǹpéjú òwúrọ̀.
19 De sa gueule sortent des lampes, comme des torches allumées.
Láti ẹnu rẹ ni ọ̀wọ́-iná ti jáde wá, ìpẹ́pẹ́ iná a sì ta jáde.
20 De ses narines sort une fumée comme celle d’un pot mis au feu et bouillant.
Láti ihò imú rẹ ni èéfín ti jáde wá, bí ẹni pé láti inú ìkòkò tí a fẹ́ iná ìfèéfèé lábẹ́ rẹ̀.
21 Son souffle fait brûler des charbons, et une flamme sort de sa bouche.
Èémí rẹ̀ tiná bọ ẹ̀yin iná, ọ̀wọ́-iná sì ti ẹnu rẹ̀ jáde.
22 Dans son cou résidera sa force, et devant sa face marche la famine.
Ní ọrùn rẹ̀ ní agbára kù sí, àti ìbànújẹ́ àyà sì padà di ayọ̀ níwájú rẹ̀.
23 Les parties de ses chairs adhèrent entre elles: Dieu lancera des foudres contre lui, et elles ne se porteront vers aucun autre lieu.
Jabajaba ẹran rẹ̀ dìjọ pọ̀, wọ́n múra gírí fún ara wọn, a kò lè sí wọn ní ipò.
24 Son cœur se durcira comme une pierre, et il se resserrera comme une enclume de marteleur.
Àyà rẹ̀ dúró gbagidi bí òkúta, àní, ó le bi ìyá ọlọ.
25 Lorsqu’il s’élèvera, des anges craindront, et, épouvantés, ils se purifieront.
Nígbà tí ó bá gbé ara rẹ̀ sókè, àwọn alágbára bẹ̀rù; nítorí ìbẹ̀rù ńlá, wọ́n dààmú.
26 Lorsque le glaive l’atteindra, ni lance, ni cuirasse ne pourra subsister.
Ọ̀kọ̀ tàbí idà, tàbí ọfà, ẹni tí ó ṣá a kò lè rán an.
27 Car il regardera le fer comme de la paille, et l’airain comme un bois pourri.
Ó ká irin sí ibi koríko gbígbẹ àti idẹ si bi igi híhù.
28 L’archer ne le mettra pas en fuite, les pierres de la fronde sont devenues pour lui une paille légère.
Ọfà kò lè mú un sá; òkúta kànnakánná lọ́dọ̀ rẹ̀ dàbí àgékù koríko.
29 Il estimera le marteau comme une paille légère, et il se rira de celui qui brandira la lance.
Ó ka ẹṣin sí bí àgékù ìdì koríko; ó rẹ́rìn-ín sí mímì ọ̀kọ̀.
30 Sous lui seront les rayons du soleil, et il fera son lit sur l’or comme sur la boue.
Òkúta mímú ń bẹ nísàlẹ̀ abẹ́ rẹ̀, ó sì tẹ́ ohun mímú ṣóńṣó sórí ẹrẹ̀.
31 Il fera bouillir comme un pot la profonde mer, et il la rendra comme des essences lorsqu’elles sont en ébullition.
Ó mú ibú omi hó bí ìkòkò; ó sọ̀ agbami òkun dàbí kólòbó ìkunra.
32 Derrière lui un sentier répandra la lumière, et l’abîme paraîtra comme un vieillard aux blancs cheveux.
Ó mú ipa ọ̀nà tan lẹ́yìn rẹ̀; ènìyàn a máa ka ibú sí ewú arúgbó.
33 Il n’est pas sur la terre de puissance qui puisse être comparée à lui, qui a été fait pour ne craindre personne.
Lórí ilẹ̀ ayé kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ̀, tí a dá láìní ìbẹ̀rù.
34 Il voit tout ce qu’il y a d’élevé au-dessous de lui; c’est lui qui est le roi de tous les fils de l’orgueil.
Ó bojú wo ohun gíga gbogbo, ó sì nìkan jásí ọba lórí gbogbo àwọn ọmọ ìgbéraga.”

< Job 41 >