< Jérémie 7 >

1 Parole qui a été adressée à Jérémie par le Seigneur, disant:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.
2 Tiens-toi à la porte de la maison du Seigneur, et publie là cette parole, et dis: Ecoutez la parole du Seigneur, vous tous, habitants de Juda, qui entrez par ces portes afin d’adorer le Seigneur.
“Dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa kí o sì kéde ọ̀rọ̀ yí: “‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa gbogbo ẹ̀yin ará Juda tí ń gba ọ̀nà yí wọlé láti wá sin Olúwa.
3 Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Rendez bonnes vos voies et vos œuvres; et j’habiterai avec vous dans ce lieu.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: Tún àwọn ọ̀nà yín ṣe, èmi yóò sì jẹ́ kí ẹ gbé ilẹ̀ yìí.
4 Ne vous confiez pas en des paroles de mensonge, disant: Le temple du Seigneur, le temple du Seigneur, c’est le temple du Seigneur.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn gbọ́ kí ẹ sì wí pé, “Èyí ni tẹmpili Olúwa ilé tẹmpili Olúwa, ilé tẹmpili Olúwa!”
5 Parce que si vous dirigez bien vos voies et vos œuvres; si vous faites la Justice entre un homme et son prochain;
Bí ẹ̀yin bá tún ọ̀nà yín àti iṣẹ́ yín ṣe nítòótọ́, tí ẹ sì ń bá ara yín lò ní ọ̀nà tó tọ́.
6 Si vous ne faites point de violence à l’étranger, au pupille et à la veuve; si vous ne répandez pas un sang innocent en ce lieu, et si vous ne marchez pas à la suite des dieux étrangers pour votre propre malheur:
Bí ẹ kò bá fi ara ni àwọn àlejò, àwọn ọmọ aláìní baba àti àwọn opó tí ẹ kò sì ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ní ibí yìí, bí ẹ kò bá sì tọ ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn sí ìpalára ara yín.
7 J’habiterai avec vous d’un siècle à un autre siècle dans ce lieu, dans cette terre que j’ai donnée à vos pères.
Nígbà náà ni èmi yóò jẹ́ kí ẹ gbé ìbí yìí, nílẹ̀ tí mo fún àwọn baba ńlá yín títí láé.
8 Mais voilà que vous vous confiez en des paroles de mensonge, qui ne vous seront pas utiles:
Ẹ wò ó, ẹ ń gba ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn tí kò níláárí gbọ́.
9 Dérober, tuer, commettre l’adultère, jurer en mentant, faire des libations aux Baalim, aller à la suite de dieux étrangers que vous ne connaissez pas.
“‘Ẹ̀yin yóò ha jalè, kí ẹ pànìyàn, kí ẹ ṣe panṣágà, kí ẹ búra èké, kí ẹ sun tùràrí sí Baali, kí ẹ sì tọ ọlọ́run mìíràn tí ẹ̀yin kò mọ̀ lọ?
10 Et vous êtes venus vous présenter devant moi dans cette maison, dans laquelle a été invoqué mon nom, et vous avez dit. Nous sommes délivrés, parce que nous avons fait toutes ces abominations.
Nígbà náà ni kí ó wá dúró ní iwájú nínú ilé yìí tí a fi orúkọ mi pè, “Kí ẹ wá wí pé àwa yè,” àwa yè láti ṣe gbogbo àwọn nǹkan ìríra wọ̀nyí bí?
11 Est-ce donc qu’elle est devenue une caverne de voleurs, cette maison dans laquelle a été invoqué mon nom devant vos yeux? C’est moi, moi qui suis; moi qui ai vu, dit le Seigneur.
Ṣé ilé yìí, tí a fi orúkọ mi pè ti di ihò àwọn ọlọ́ṣà lọ́dọ̀ yín ni? Èmi ti ń wò ó! ni Olúwa wí.
12 Allez à mon lieu, à Silo, où a habité mon nom dès le commencement, et voyez ce que je lui ai fait, à cause de la méchanceté d’Israël, mon peuple;
“‘Ẹ lọ nísinsin yìí sí Ṣilo níbi ti mo kọ́ fi ṣe ibùgbé fún orúkọ mi, kí ẹ sì rí ohun tí mo ṣe sí i nítorí ìwà búburú Israẹli tí í ṣe ènìyàn mi.
13 Et maintenant, parce que vous avez fait toutes ces choses, dit le Seigneur, et que je vous ai parlé, me levant dès le matin, et parlant, que vous n’avez pas entendu; que je vous ai appelés et que vous n’avez pas répondu:
Nígbà tí ẹ̀yin ń ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí ni èmi bá a yín sọ̀rọ̀ léraléra ni Olúwa wí ẹ̀yin kò gbọ́, èmi pè yín, ẹ̀yin kò dáhùn.
14 Je ferai à cette maison, dans laquelle a été invoqué mon nom, et en laquelle vous avez confiance, et à ce lieu que je vous ai donné à vous et à vos pères, comme j’ai fait à Silo.
Nítorí náà, èmi yóò ṣe ohun tí mo ṣe sí Ṣilo sí ilé náà tí a fi orúkọ mi pè, ilé tẹmpili nínú èyí tí ẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ààyè tí mo fún ẹ̀yin àti àwọn baba yín.
15 Et je vous rejetterai de ma face, comme j’ai rejeté tous vos frères, toute la race d’Ephraïm.
Èmi yóò tú kúrò ní iwájú mi gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe sí àwọn arákùnrin yín, àwọn ará Efraimu.’
16 Toi donc, ne prie pas pour ce peuple, ne m’adresse pour eux ni louange ni prière, et ne t’oppose pas à moi, parce que je ne t’exaucerai point.
“Nítorí náà má ṣe gbàdúrà fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o bẹ̀bẹ̀ fún wọn; ma ṣe bẹ̀ mí, nítorí èmi kì yóò tẹ́tí sí ọ.
17 Ne vois-tu pas ce que font ceux-ci dans les villes de Juda, et dans les places publiques de Jérusalem?
Ṣé ìwọ kò rí ohun tí wọ́n ń ṣe ní àwọn ìlú Juda àti ní òpópó Jerusalẹmu?
18 Les fils amassent le bois, les pères allument le feu, et les femmes arrosent de farine la graisse, afin de faire des gâteaux à la reine du ciel, des libations à des dieux étrangers, et me provoquer au courroux.
Àwọn ọmọ ṣa igi jọ, àwọn baba fi iná sí i, àwọn ìyá sì po ìyẹ̀fun láti ṣe àkàrà fún ayaba ọ̀run, wọ́n tú ẹbọ ọrẹ mímu sí àwọn ọlọ́run àjèjì láti ru bínú mi sókè.
19 Est-ce moi qu’ils provoquent au courroux, dit le Seigneur? N’est-ce pas eux-mêmes qu’il provoquent à la confusion de leur visage?
Ṣùgbọ́n ṣe èmi ni wọ́n fẹ́ mú bínú? ni Olúwa wí. Ǹjẹ́ kì í ṣe pé wọ́n kúkú ń pa ara wọn lára sí ìtìjú ara wọn?
20 C’est pourquoi voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que ma fureur et mon indignation se sont embrasées sur ce lieu, sur les hommes et sur les animaux; sur les arbres de la contrée, et sur les fruits de la terre; et un feu brûlera, et il ne s’éteindra pas.
“‘Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò tú ìbínú àti ìrunú mi sí orílẹ̀ yìí ènìyàn àti ẹranko, igi, pápá àti èso orí ilẹ̀, yóò sì jó tí kò ní ṣe é pa.”
21 Voici ce que dit le Seigneur des armées. Dieu d’Israël: Ajoutez vos holocaustes à vos victimes, et mangez-en les chairs;
“‘Èyí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: Tẹ̀síwájú kí ẹ kó ẹbọ sísun yín àti àwọn ẹbọ yòókù papọ̀ kí ẹ̀yin kí ó sì jẹ ẹran wọ́n fúnra yín.
22 Parce que je n’ai point parlé à vos pères, je ne leur ai rien commandé au jour que je les ai tirés de la terre d’Egypte, au sujet des holocaustes et des victimes.
Ní tòsí nígbà tí mo mú àwọn baba ńlá yín jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti tí mo sì bá wọn sọ̀rọ̀. N kò pàṣẹ fún wọn lórí ẹbọ sísun lásán.
23 Mais voici la chose que je leur ai commandée: Ecoutez ma voix, et je serai votre Dieu, et vous serez mon peuple; et marchez dans toute la voie que je vous ai prescrite, afin que bien vous soit.
Mo pàṣẹ fún wọn báyìí pé; gbọ́ tèmi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín ẹ̀yin yóò sì jẹ́ ènìyàn mi. Máa rìn ní ojú ọ̀nà tí mo pàṣẹ fún yín, kí ó lè dára fún yín.
24 Et ils n’ont pas écouté, et ils n’ont pas incliné leur oreille; mais ils se sont abandonnés à leurs volontés et à la dépravation de leur cœur mauvais; ils sont allés en arrière, et non en avant,
Ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́, wọn kò sì fetísílẹ̀ dípò èyí wọ́n ń tẹ̀ sí ọ̀nà agídí ọkàn wọn. Dípò kí wọn tẹ̀síwájú wọ́n ń rẹ̀yìn.
25 Depuis le jour que leurs pères sont sortis de l’Egypte jusqu’à ce jour. Et je vous ai envoyé tous mes serviteurs les prophètes, me levant au point du jour, et les envoyant.
Láti ìgbà tí àwọn baba ńlá yín ti jáde ní Ejibiti títí di òní, ni èmi ti ń rán àwọn ìránṣẹ́ mi, àwọn wòlíì sí yín.
26 Et ils ne m’ont pas écouté, et ils n’ont pas incliné leur oreille; mais ils ont rendu leur cou inflexible, et ils ont fait pis que leurs pères.
Wọn kò gbọ́ wọn kò sì fetísílẹ̀. Wọ́n wa ọrùn le, wọn wa ọrùn kì, wọ́n sì hu ìwà ìbàjẹ́ ju àwọn baba ńlá wọn.’
27 Et tu leur diras toutes ces choses, et ils ne t’écouteront point; tu les appelleras, et ils ne te répondront point.
“Nígbà tí ìwọ bá sọ gbogbo èyí fún wọn, wọn kì yóò gbọ́ tirẹ̀, nígbà tí ìwọ bá sì pè wọ́n, wọn kì yóò dáhùn.
28 Et tu leur diras: Voici la nation qui n’a pas écouté la voix du Seigneur son Dieu, et qui n’a pas reçu sa correction; la bonne foi a péri, et elle a été enlevée de leur bouche.
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni orílẹ̀-èdè tí kò gbọ́ ti Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ tàbí kí ó ṣe ìgbọ́ràn sí ìbáwí. Ọ̀rọ̀ òtítọ́ kò sí ní ètè wọn.
29 Tonds ta chevelure, et jette-la; pousse en haut des plaintes, parce que le Seigneur a rejeté et abandonné la génération de sa fureur.
“‘Gé irun yín kí ẹ sì dàánù, pohùnréré ẹkún lórí òkè, nítorí Olúwa ti kọ ìran yìí tí ó wà lábẹ́ ìbínú rẹ̀ sílẹ̀.
30 Parce que les fils de Juda ont fait le mal devant mes yeux, dit le Seigneur. Ils ont mis leurs pierres d’achoppement dans la maison dans laquelle a été invoqué mon nom, afin de la souiller;
“‘Àwọn ènìyàn Juda ti ṣe búburú lójú mi, ni Olúwa wí. Wọ́n ti to àwọn ère ìríra wọn jọ sí ilé tí a fi orúkọ mi pè wọ́n sì ti sọ ọ́ di àìmọ́.
31 Et ils ont bâti des hauts lieux à Topheth, qui est dans la Vallée du fils d’Ennom, afin d’y brûler leurs fils et leurs filles au feu; choses que je n’ai pas ordonnées, ni pensées dans mon cœur.
Wọ́n ti kọ́ àwọn ibi gíga ti Tofeti ní àfonífojì Beni-Hinnomu láti sun àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin wọn nínú iná èyí tí èmi kò pàṣẹ tí kò sì wá sí ọkàn mi.
32 C’est pourquoi voilà que des jours viendront, dit le Seigneur, et l’on ne dira plus Topheth, et la Vallée du fils d’Ennom; mais la Vallée du carnage; et l’on ensevelira à Topheth, parce qu’il n’y aura pas d’autre lieu pour ensevelir.
Nítorí náà kíyèsára ọjọ́ ń bọ̀, ni Olúwa wí, nígbà tí àwọn ènìyàn kò ní pè é ní Tafeti tàbí àfonífojì ti Beni-Hinnomu; ṣùgbọ́n yóò ma jẹ àfonífojì ìparun, nítorí wọn yóò sin òkú sí Tofeti títí kò fi ní sí ààyè mọ́.
33 Et les cadavres de ce peuple seront en pâture aux oiseaux du ciel et aux bêtes de la terre, et il n’y aura personne qui les chasse.
Nígbà náà ni òkú àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò di oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀, kò sì ní sí ẹnìkan tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
34 Et je ferai cesser, dans les villes de Juda et dans les places publiques de Jérusalem, la voix de la joie et la voix de l’allégresse, la voix de l’époux et la voix de l’épouse; car la terre sera désolée.
Èmi yóò mú òpin bá ìró ayọ̀ àti ìdùnnú àti ohùn àwọn tọkọtaya ní àwọn ìlú Juda àti ní ìgboro Jerusalẹmu, nítorí tí ilẹ̀ náà yóò di ahoro.

< Jérémie 7 >