< Jérémie 41 >

1 Et il arriva dans le septième mois qu’Ismahel, fils de Nathanias, fils d’Elisama, de la race royale, et les grands du roi, et dix hommes avec lui vinrent vers Godolias, fils d’Ahicam, à Masphath; et ils mangèrent là des pains ensemble à Masphath.
Ní oṣù keje Iṣmaeli, ọmọ Netaniah ọmọ Eliṣama, nínú irú-ọmọ ọba, àti àwọn ìjòyè ọba, àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu wá ní Mispa; níbẹ̀ ni wọ́n jùmọ̀ jẹun ní Mispa.
2 Or Ismahel, fils de Nathanias, se leva, et les dix hommes qui étaient avec lui, et ils frappèrent Godolias, fils d’Ahicam, fils de Saphan, par le glaive, et tuèrent celui qu’avait préposé le roi de Babylone sur la terre.
Iṣmaeli ọmọ Netaniah àti àwọn ọkùnrin mẹ́wàá tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀, sì dìde wọ́n kọlu Gedaliah ọmọ Ahikamu, ọmọ Ṣafani pẹ̀lú idà. Wọ́n sì pa á, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ilẹ̀ náà.
3 Tous les Juifs aussi qui étaient avec Godolias, à Masphath, et les Chaldéens qui se trouvèrent là, et les hommes de guerre, Ismahel les frappa.
Iṣmaeli sì tún pa gbogbo àwọn Júù tí wọ́n wà pẹ̀lú Gedaliah ní Mispa, àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun Babeli tí wọ́n wà níbẹ̀ bákan náà.
4 Mais le second jour après qu’il eut tué Godolias, personne encore ne le sachant,
Ní ọjọ́ kejì tí wọ́n pa Gedaliah kí ó tó di wí pé ẹnikẹ́ni mọ̀,
5 Quatre-vingts hommes vinrent de Sichem, de Silo et de Samarie, la barbe rasée, et les habits déchirés, et le visage défiguré; ils portaient de l’encens et des présents, afin de les offrir dans la maison du Seigneur.
àwọn ọgọ́rin ọkùnrin wá láti Ṣekemu, Ṣilo àti Samaria, wọ́n fa irùngbọ̀n wọn, wọ́n ya aṣọ wọn, wọ́n ṣá ara wọn lọ́gbẹ́, wọ́n mú ẹbọ ọpẹ́ àti tùràrí wá sí ilé Olúwa.
6 Ismahel, fils de Nathanias, étant donc sorti de Masphath à leur rencontre, allait marchant en pleurant; or, lorsqu’il les eut rencontrés, il leur dit: Venez vers Godolias, fils d’Ahicam,
Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah jáde kúrò láti Mispa láti lọ pàdé wọn. Ó sì ń sọkún bí ó ti ṣe ń lọ, nígbà tí ó pàdé wọn, ó wí pé, “Ẹ wá sọ́dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu.”
7 Et lorsqu’ils furent arrivés au milieu de la cité, Ismahel, fils de Nathanias, les tua et les jeta vers le milieu de la fosse, et les hommes qui étaient avec lui.
Nígbà tí wọ́n dé ìlú náà; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pa wọ́n, wọ́n sì sọ òkú wọn sínú ihò kan.
8 Mais dix hommes se trouvèrent parmi eux qui dirent à Ismahel: Ne nous faites pas mourir, parce que nous avons des trésors cachés dans le champ, du blé, de l’orge, de l’huile et du miel. Et il s’arrêta et ne les tua pas avec leurs frères.
Ṣùgbọ́n mẹ́wàá nínú wọn sọ fún Iṣmaeli pé, “Má ṣe pa wá! Àwa ní ọkà àti barle, òróró àti oyin ní ìpamọ́ nínú oko.” Nítorí náà, ó fi wọ́n sílẹ̀: kò sì pa wọ́n pẹ̀lú àwọn yòókù.
9 Or la fosse dans laquelle Ismahel avait jeté tous les cadavres des hommes qu’il tua à cause de Godolias, est celle-là même qu’avait faite le roi Asa à cause de Baasa, roi d’Israël; Ismahel, fils de Nathanias, la remplit de morts.
Nísinsin yìí, ihò náà tí ó kó gbogbo ara àwọn ọkùnrin tí ó ti pa pẹ̀lú Gedaliah sí ni ọba Asa ń lò gẹ́gẹ́ bí i ààbò nítorí ọba Baaṣa ti Israẹli. Iṣmaeli ọmọ Netaniah sì ti kó òkú kún inú rẹ̀.
10 Et Ismahel fit prisonniers tous les restes du peuple qui étaient à Masphath, les filles du roi et tout le peuple qui était demeuré à Masphath, que Nabuzardan, prince de la milice, avait recommandés à Godolias, fils d’Ahicam. Et Ismahel, fils de Nathanias, les prit, et s’en alla afin de passer vers les enfants d’Ammon.
Iṣmaeli sì kó gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní Mispa nígbèkùn, ọmọbìnrin ọba àti gbogbo àwọn ènìyàn tókù síbẹ̀ lórí àwọn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti fi yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ṣe olórí. Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah kó wọn ní ìgbèkùn, ó sì jáde rékọjá sí ọ̀dọ̀ àwọn Ammoni.
11 Mais Johanan, fils de Carée, et tous les princes des hommes de guerre qui étaient avec lui, apprirent tout le mal qu’avait fait Ismahel, fils de Nathanias.
Nígbà tí Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ gbọ́ nípa gbogbo ìpànìyàn náà tí Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti ṣe.
12 Et ayant pris tous les hommes de guerre, ils partirent afin de combattre Ismahel, fils de Nathanias, et ils le trouvèrent près des grandes eaux qui sont à Gabaon.
Wọ́n kó gbogbo àwọn ọkùnrin wọn, wọ́n sì, lọ bá Iṣmaeli ọmọ Netaniah jà. Wọ́n pàdé rẹ̀ ní odò kan lẹ́bàá Gibeoni.
13 Et lorsque tout le peuple qui était avec Ismahel eut vu Johanan, fils de Carée, et tous les princes des hommes de guerre qui étaient avec lui, ils se réjouirent.
Nígbà tí gbogbo àwọn ènìyàn Iṣmaeli tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀ rí Johanani ọmọkùnrin Karea àti àwọn olórí ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì yọ̀.
14 Et tout le peuple qu’Ismahel avait pris à Masphath retourna; et, étant retourné, il vint vers Johanan, fils de Carée.
Gbogbo àwọn ènìyàn tí Iṣmaeli ti kó ní ìgbèkùn ní Mispa yípadà, wọ́n sì lọ sọ́dọ̀ Johanani ọmọ Karea.
15 Mais Ismahel, fils de Nathanias, s’enfuit avec huit hommes de devant la face de Johanan, et s’en alla vers les enfants d’Ammon.
Ṣùgbọ́n Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah àti àwọn mẹ́jọ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀ bọ́ lọ́wọ́ Johanani, wọ́n sì sálọ sí Ammoni.
16 Johanan, fils de Carée, et tous les princes des hommes de guerre qui étaient avec lui, prirent donc tous les restes du peuple qu’il avait retirés des mains d’Ismahel, fils de Nathanias, et ramenés de Masphath, après qu’il eut tué Godolias, fils d’Ahicam; tous les hommes vaillants au combat et les femmes, les enfants et les eunuques qu’il avait ramenés de Gabaon.
Lẹ́yìn náà Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí wọn wà pẹ̀lú rẹ̀ sì kó gbogbo àwọn tí ó kù ní Mispa; àwọn tí ó ti rí gbà lọ́wọ́ Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah; lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu. Àwọn ọmọ-ogun, àwọn obìnrin, àwọn ọmọdé àti àwọn olórí ilé ẹjọ́ tí ó ti kó wa láti Gibeoni.
17 Et ils s’en allèrent, et ils s’arrêtèrent en passant à Chamaam, près de Bethléhem, afin de se rendre et d’entrer en Egypte,
Wọ́n sì kúrò níbẹ̀, wọ́n dúró ní Geruti Kimhamu ní ẹ̀bá Bẹtilẹhẹmu ní ọ́nà ìrìnàjò wọn sí Ejibiti.
18 À cause des Chaldéens; car ils les craignaient, parce qu’Ismahel, fils de Nathanias, avait tué Godolias, fils d’Ahicam, qu’avait préposé le roi de Babylone sur la terre de Juda.
Láti gba àwọn Babeli sílẹ̀. Wọ́n bẹ̀rù wọn nítorí wí pé, “Iṣmaeli ọmọ Netaniah ti pa Gedaliah ọmọ Ahikamu èyí tí ọba Babeli ti yàn gẹ́gẹ́ bí i gómìnà lórí ilẹ̀ náà.”

< Jérémie 41 >