< Jérémie 40 >
1 Paroles qui furent adressées à Jérémie par le Seigneur après qu’il fut mis en liberté à Rama par Nabuzardan, chef de la milice, quand il le prit lié de chaînes au milieu de ceux qui émigraient de Jérusalem et de Juda et étaient conduits à Babylone.
Ọ̀rọ̀ náà sì tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa lẹ́yìn tí Nebusaradani balógun àwọn ẹ̀ṣọ́ ti tú u sílẹ̀ ní Rama. Ó rí Jeremiah tí a fi ẹ̀wọ̀n dè láàrín gbogbo àwọn tí wọ́n mú ní Jerusalẹmu àti Juda. Wọ́n kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli.
2 Prenant donc Jérémie, le prince de la milice lui dit: Le Seigneur ton Dieu a prononcé ce mal sur ce lieu,
Nígbà tí balógun ẹ̀ṣọ́ rí Jeremiah, ó sọ fún un wí pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ni ó pàṣẹ ibí yìí fún mi.
3 Et il l’a amené; ainsi le Seigneur a fait comme il a dit, parce que vous avez péché contre le Seigneur, et que vous n’avez pas écouté sa voix; c’est ainsi que cela vous est arrivé.
Nísinsin yìí, Olúwa ti mú un jáde; ó ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ pé òun yóò ṣe. Gbogbo èyí ṣẹlẹ̀ nítorí wí pé ẹ̀yin ènìyàn ṣẹ̀ sí Olúwa, àti pé ẹ kò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀.
4 Maintenant donc, voilà que je t’ai délivré des chaînes que tu avais aux mains; s’il te plaît de venir avec moi à Babylone, viens, et je tiendrai mes yeux sur toi; mais s’il te déplaît de venir avec moi à Babylone, demeure ici; voilà toute cette terre en ta présence; ce que tu choisiras, tu l’auras, et où il te plaira d’aller, vas-y.
Ṣùgbọ́n, ní òní yìí mò ń tú ọ sílẹ̀ kúrò nínú ẹ̀wọ̀n tí ó wà ní ọwọ́ rẹ. Bí o bá fẹ́, tẹ̀lé mi ká lọ sí Babeli, èmi yóò sì bojútó ọ; ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá fẹ́, dúró síbí. Wò ó, gbogbo orílẹ̀-èdè wà níwájú rẹ, lọ sí ibikíbi tí ó bá tẹ́ ọ lọ́rùn.”
5 Et ne viens pas avec moi, tu le peux; mais habite chez Godolias, fils d’Ahicam, fils de Saphan, que le roi de Babylone a préposé sur les villes de Juda; habite donc avec lui au milieu du peuple; ou bien va partout où il te plaira d’aller. Le chef de la milice lui donna aussi des vivres et des présents, et le renvoya.
Ẹ̀wẹ̀, kí ó tó di pé Jeremiah pẹ̀yìndà láti máa lọ, Nebusaradani fi kún un wí pé, “Padà tọ Gedaliah ọmọ Ahikamu lọ, ọmọ Ṣafani, ẹni tí ọba Babeli ti fi jẹ baálẹ̀ lórí ìlú Juda, kí o sì máa gbé ní àárín àwọn ènìyàn wọ̀nyí tàbí kí o máa lọ ibikíbi tí ó bá tọ́ ní ojú rẹ.” Nígbà náà ni balógun náà fún un ní oúnjẹ àti ẹ̀bùn, ó sì jẹ́ kí ó lọ.
6 Or Jérémie vint vers Godolias, fils d’Ahicam, à Masphath, et il habita avec lui au milieu du peuple qui avait été laissé dans le pays.
Báyìí ni Jeremiah lọ sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ní Mispa, ó sì dúró tì í láàrín àwọn ènìyàn tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ náà.
7 Et lorsque tous les princes de l’armée des Juifs, qui avaient été dispersés en diverses contrées, eux et leurs compagnons, eurent appris que le roi de Babylone avait préposé Godolias, fils d’Ahicam, sur la terre de Juda, et qu’il lui avait recommandé les hommes, les femmes et les petits enfants, et ceux d’entre les pauvres de la terre qui n’avaient pas été transférés à Babylone,
Nígbà tí gbogbo àwọn olórí ogun àti àwọn ènìyàn tí wọ́n kù lórí orílẹ̀-èdè náà gbọ́ pé ọba Babeli ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu gẹ́gẹ́ bí baálẹ̀ ní ilẹ̀ náà; àti pé ó ti fi àwọn ọkùnrin, obìnrin àti ọmọdé tí wọ́n jẹ́ tálákà ní ilẹ̀ náà tí wọn kò kó lọ sí ilẹ̀ àjèjì sí ìkáwọ́ rẹ̀,
8 Ils vinrent vers Godolias à Masphath, savoir: Ismahel, fils de Nathanias, et Johanan, et Jonathan, fils de Carée, et Saréas, fils de Thanéhumeth, et les enfants d’Ophi, qui étaient de Nétophati, et Jézonias, fils de Maachati, eux et les leurs.
wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Gedaliah ní Mispa; Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, Johanani àti Jonatani ọmọkùnrin ti Karea, Seraiah ọmọkùnrin Tanhumeti tí í ṣe ọmọkùnrin Efai ará Netofa àti Jesaniah ọmọkùnrin Maakati àti àwọn ènìyàn wọn.
9 Et Godolias, fils d’Ahicam, fils de Saphan, jura à eux et à leurs compagnons, disant: Ne craignez point de servir les Chaldéens; demeurez dans cette terre, et servez le roi de Babylone, et bien vous sera.
Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu, ọmọkùnrin ti Ṣafani ṣe ìbúra láti tún fi dá àwọn ènìyàn lójú pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù láti sin àwọn Babeli.” Ó sọ wí pé, “Gbé ilẹ̀ náà kí ẹ sì máa sin ọba Babeli, yóò sì dára fún un yín.
10 Voilà que moi, j’habite à Masphath pour répondre à l’ordre des Chaldéens qui sont envoyés vers nous; mais vous, recueillez la vendange, et la moisson, et l’huile; et renfermez-les dans des vases; et demeurez dans vos villes que vous occupez.
Èmi fúnra mi yóò dúró ní Mispa láti ṣojú yín níwájú Babeli tí wọ́n tọ̀ wá wá. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin ni yóò máa kórè ọtí wáìnì, èso igi àti òróró; kí ẹ sì kó wọn sí inú àpò àpamọ́wọ́ yín; kí ẹ̀yin sì máa gbé ní ìlú tí ẹ ti gbà.”
11 Mais aussi tous les Juifs qui étaient en Moab, et parmi les enfants d’Ammon, et dans l’Idumée, et dans toutes les contrées, ayant appris que le roi de Babylone avait laissé des restes du peuple dans Juda, et qu’il avait préposé sur eux Godolias, fils d’Ahicam. fils de Saphan,
Nígbà tí gbogbo àwọn Juda ní Moabu, Ammoni, Edomu àti gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè gbọ́ pé ọba Babeli ti fi ohun tókù sílẹ̀ ní Juda, àti pé ó ti yan Gedaliah ọmọkùnrin Ahikamu ọmọkùnrin Ṣafani gẹ́gẹ́ bí gómìnà lórí wọn.
12 Tous ces Juifs, dis-je, retournèrent de tous les lieux où ils s’étaient enfuis, et vinrent dans la terre de Juda vers Godolias, à Masphath; et ils recueillirent du vin, et une moisson très abondante.
Gbogbo wọn padà wá sí ilẹ̀ Juda sọ́dọ̀ Gedaliah ní Mispa láti orílẹ̀-èdè gbogbo tí a ti lé wọn sí. Wọ́n sì kórè ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọtí wáìnì àti èso igi.
13 Mais Johanan, fils de Carée, et tous les princes de l’armée, qui étaient dispersés en diverses contrées, vinrent vers Godolias à Masphath,
Johanani ọmọkùnrin ti Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí ó kù ní orílẹ̀-èdè sì tọ Gedaliah wá ní Mispa.
14 Et lui dirent: Sachez que Baalis, roi des enfants d’Ammon, a envoyé Ismahel, fils de Nathanias, pour vous ôter la vie. Et Godolias, fils d’Ahicam, ne les crut pas.
Wọ́n sì sọ fún un wí pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ha mọ̀ pé Baalisi ọba àwọn Ammoni ti rán Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah láti lọ mú ẹ̀mí rẹ?” Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọkùnrin ti Ahikamu kò gbà wọ́n gbọ́.
15 Mais Johanan, fils de Carée, dit en particulier à Godolias, à Masphath, disant: J’irai et je frapperai Ismahel, fils de Nathanias, personne ne le sachant, de peur qu’il ne tue votre âme, et que ne soient dispersés tous les Juifs qui sont rassemblés auprès de vous; et les restes de Juda périront.
Nígbà náà ni Johanani ọmọkùnrin Karea sọ ní ìkọ̀kọ̀ fún Gedaliah ní Mispa pé, “Jẹ́ kí èmi lọ pa Iṣmaeli ọmọkùnrin Netaniah, ẹnikẹ́ni kò sì ní mọ èyí. Kí ni ìdí rẹ̀ tí yóò ṣe mú ẹ̀mí rẹ, tí o sì ṣe fẹ́ mú àwọn Júù tí ó yí ọ ká túká, kí ìyókù Juda sì parun?”
16 Et Godolias, fils d’Ahicam, dit à Johanan, fils de Carée: Ne fais pas cela; car tu parles faussement d’Ismahel.
Ṣùgbọ́n Gedaliah ọmọ Ahikamu sọ fún Johanani ọmọ Karea pé, “Má ṣe ṣe nǹkan yìí! Nítorí nǹkan tí ò ń sọ nípa Iṣmaeli kì í ṣe òtítọ́.”