< Jérémie 35 >

1 Parole qui fut adressée à Jérémie par le Seigneur, dans les jours de Joakim, fils de Josias, roi de Juda, disant:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
2 Vas à la maison des Réchabites, et parle-leur; et tu les introduiras dans la maison du Seigneur, dans une des salles des trésors; et tu leur donneras à boire du vin.
“Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
3 Et je pris Jézonias, fils de Jérémie, fils d’Habsanias, et ses frères, et tous ses fils, et toute la maison des Réchabites;
Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
4 Et je les introduisis dans la maison du Seigneur, dans la chambre du trésor des fils d’Hanan, fils de Jégédélias, homme de Dieu, laquelle chambre était près de la chambre du trésor des princes, au-dessus du trésor de Maasias, fils de Sellum, qui était garde du vestibule.
Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
5 Et je mis devant les enfants de la maison des Réchabites des tasses pleines de vin et des coupes; et je leur dis: Buvez du vin.
Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
6 Et ils répondirent: Nous ne boirons pas de vin, parce que Jonadab, notre père, fils de Réchab, nous a ordonné, disant: Vous ne boirez jamais de vin, ni vous, ni vos enfants;
Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
7 Et vous ne bâtirez pas de maison, et vous ne sèmerez point de grains, et vous ne planterez pas de vignes, et vous n’en aurez point à vous, mais vous habiterez sous des tabernacles tous vos jours, afin que vous viviez de longs jours sur la terre dans laquelle vous êtes étrangers.
Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
8 Nous avons donc obéi à la voix de Jonadab, notre père, fils de Réchab, dans toutes les choses qu’il nous a ordonnées, en sorte que nous n’avons pas bu de vin durant tous nos jours, ni nous, ni nos femmes, ni nos fils, ni nos filles.
Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
9 Et que nous n’avons pas bâti de maisons pour y habiter; et nous n’avons eu ni vigne, ni champ, ni grain.
Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
10 Mais nous avons habité dans des tabernacles, et nous avons obéi à toutes les choses que nous a ordonnées Jonadab notre père.
Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
11 Mais lorsque Nabuchodonosor, roi de Babylone, est monté dans notre terre, nous avons dit: Venez, et entrons dans Jérusalem, à cause de l’armée des Chaldéens et à cause de l’armée de Syrie; et nous sommes demeurés dans Jérusalem.
Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
12 Et la parole du Seigneur a été adressée à Jérémie, disant:
Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
13 Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Va, et dis aux hommes de Juda et aux habitants de Jérusalem: Est-ce que vous ne recevrez jamais la correction, afin d’obéir à mes paroles, dit le Seigneur?
“Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
14 Elles ont prévalu, les paroles de Jonadab, fils de Réchab, par lesquelles il ordonna à ses enfants de ne point boire de vin, et ils n’en ont pas bu jusqu’à ce jour, parce qu’ils ont obéi au précepte de leur père; mais moi je vous ai parlé, me levant dès le matin, et parlant, et vous ne m’avez pas obéi.
‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
15 Et j’ai envoyé vers vous mes serviteurs, les prophètes, me levant au point du jour, envoyant, et disant: Détournez-vous chacun de vos voies très mauvaises, et rendez bonnes vos œuvres; ne suivez pas des dieux étrangers, et ne les adorez pas; et vous habiterez dans la terre que je vous ai donnée à vous et à vos pères; et vous n’avez pas incliné votre oreille, et vous ne m’avez pas écouté.
Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
16 Ainsi les enfants de Jonadab, fils de Réchab, ont gardé fermement l’ordre que leur père leur avait donné; mais ce peuple ne m’a pas obéi.
Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
17 C’est pourquoi voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Voilà que moi j’amènerai sur Juda et sur tous les habitants de Jérusalem toute l’affliction que j’ai prononcée contre eux; parce que je leur ai parlé, et ils n’ont pas écouté; je les ai appelés, et ils ne m’ont pas répondu.
“Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
18 Or Jérémie dit à la maison des Réchabites: Voici ce que dit le Seigneur des armées. Dieu d’Israël: Parce que vous avez obéi au précepte de Jonadab votre père, que vous avez gardé tous ses commandements, et que vous avez fait toutes les choses qu’il vous a ordonnées;
Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
19 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur des armées. Dieu d’Israël: Il ne manquera pas dans la race de Jonadab, fils de Réchab, d’homme se tenant tous les jours en ma présence.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”

< Jérémie 35 >