< Jérémie 32 >

1 Parole qui fut adressée à Jérémie par le Seigneur en la dixième année de Sédécias, roi de Juda; c’est la dix-huitième année de Nabuchodonosor.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọdún kẹwàá Sedekiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kejìdínlógún ti Nebukadnessari.
2 Alors l’armée du roi de Babylone assiégeait Jérusalem; et Jérémie le prophète était enfermé dans le vestibule de la prison qui était dans la maison du roi de Juda.
Àwọn ogun ọba Babeli ìgbà náà há Jerusalẹmu mọ́. A sì sé wòlíì Jeremiah mọ́ inú túbú tí wọ́n ń ṣọ́ ní àgbàlá ilé ọba Juda.
3 Car Sédécias, roi de Juda, l’avait enfermé, disant: Pourquoi prophétises-tu, disant: Voici ce que dit le Seigneur: Voilà que moi je livrerai cette ville entre les mains du roi de Babylone, et il la prendra?
Nítorí Sedekiah ọba Juda ti há a mọ́lé síbẹ̀; pé, “Kí ló dé tí ìwọ fi ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ bẹ́ẹ̀? Tí o sì wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa wí: Èmi ń bọ̀ wá fi ìlú yìí fún ọba Babeli, tí yóò sì gbà á.
4 Et Sédécias, roi de Juda, n’échappera pas à la main des Chaldéens; mais il sera livré entre les mains du roi de Babylone; et sa bouche parlera à sa bouche, et ses yeux verront ses yeux.
Sedekiah ọba Juda kò lè bọ́ lọ́wọ́ àwọn Kaldea, ṣùgbọ́n à ó mú fún ọba Babeli, yóò sì bá sọ̀rọ̀ ní ojúkojú; yóò sì rí pẹ̀lú ojú rẹ̀.
5 Et il mènera Sédécias à Babylone; et il y sera jusqu’à ce que je le visite, dit le Seigneur; mais, si vous combattez contre les Chaldéens, vous n’aurez aucun succès.
Yóò mú Sedekiah lọ sí Babeli tí yóò wà títí èmi yóò fi bẹ̀ ọ́ wò ni Olúwa wí. Tí ẹ̀yin bá bá àwọn ará Kaldea jà, ẹ̀yin kì yóò borí wọn.’”
6 Et Jérémie dit: La parole du Seigneur m’a été adressée, disant:
Jeremiah wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
7 Voilà qu’Hanaméel, fils de Sellum, ton cousin germain, viendra vers toi, disant: Achète-toi mon champ qui est à Anathoth, parce que c’est à toi qu’il appartient de l’acheter, à cause de ta parenté.
Hanameli ọmọkùnrin Ṣallumu ẹ̀gbọ́n rẹ̀ yóò tọ̀ ọ́ wá pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti; nítorí gẹ́gẹ́ bí ẹni tó súnmọ́ wọn, ẹ̀tọ́ àti ìṣe rẹ ní láti rà á.’
8 Et Hanaméel, fils de mon oncle, vint à moi, selon la parole du Seigneur, dans le vestibule de la prison, et il me dit: Prends possession de mon champ qui est à Anathoth, en la terre de Benjamin; parce que c’est à toi qu’il appartient de prendre possession de cet héritage, car tu es le proche parent. Or je compris que c’était la parole du Seigneur.
“Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti sọ, Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi tọ̀ mí wá ní àgbàlá túbú wí pé, ‘Ra pápá mi tí ó wà ní Anatoti tí ó wà ní ilẹ̀ Benjamini, èyí tí ó jẹ́ pé ẹ̀tọ́ rẹ ni láti gbà á àti láti ni, rà á fún ara rẹ.’ “Nígbà náà ni èmi mọ̀ wí pé ọ̀rọ̀ Olúwa ni èyí.
9 Et j’achetai d’Hanaméel, fils de mon oncle, le champ qui est à Anathoth; et je lui pesai l’argent, sept statères et dix pièces d’argent.
Bẹ́ẹ̀ ni; èmi ra pápá náà ní Anatoti láti ọwọ́ Hanameli ọmọ ẹ̀gbọ́n mi. Mo sì wọn ìwọ̀n ṣékélì àti fàdákà mẹ́tàdínlógún fún un.
10 Et j’écrivis sur la feuille et je la scellai et, je pris des témoins; et je pesai l’argent dans une balance.
Mo fọwọ́ sínú ìwé, mo sì dì í pa. Mo pe ẹlẹ́rìí sí i, mo sì wọn fàdákà náà lórí òsùwọ̀n.
11 Et je pris la feuille d’acquisition scellée, et les stipulations, et ce qui était convenu, et les sceaux mis en dehors.
Mo mú ìwé tí mo fi rà á, èyí tí a di pa nípa àṣẹ àti òfin wa, àti èyí tí a kò lẹ̀.
12 Et je donnai la feuille d’acquisition à Baruch, fils de Néri, fils de Maasias, sous les yeux d’Hanaméel, mon cousin germain, sous les yeux des témoins qui étaient inscrits sur la feuille d’achat., sous les yeux et en présence de tous les Juifs qui étaient assis dans le vestibule de la prison.
Èmi sì fi èyí fún Baruku, ọmọ Neriah, ọmọ Maseiah, ní ojú Hanameli, ọmọ ẹ̀gbọ́n mi àti níwájú àwọn ẹlẹ́rìí tí ó ti fi ọwọ́ sí ìwé àti ní ojú àwọn Júù gbogbo tí wọ́n jókòó ní àgbàlá ilé túbú.
13 Et j’ordonnai à Baruch devant eux, disant:
“Ní ojú wọn ni èmi ti pàṣẹ fún Baruku pé,
14 Voici ce que dit le Seigneur des armées. Dieu d’Israël: Prends ces feuilles, cette feuille d’achat scellée, et cette feuille qui est ouverte; et mets-les dans un vase de terre, afin qu’elles puissent se conserver durant de longs jours.
èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; mú àwọn ìwé tí a fi rà á wọ̀nyí, àti èyí tí a lẹ̀ àti èyí tí a kò lẹ̀, kí o wá gbé wọn sínú ìkòkò amọ̀, kí wọn ó lè wà ní ọjọ́ púpọ̀.
15 Car voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: On acquerra encore des maisons, des champs et des vignes en cette terre.
Nítorí èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí; àwọn ilẹ̀, pápá àti ọgbà àjàrà ni à ó tún rà padà nílẹ̀ yìí.
16 Et je priai le Seigneur, après que j’eus donné le feuillet d’acquisition à Baruch, fils de Néri, disant:
“Lẹ́yìn tí mo ti fi ìwé rírà náà fún Baruku ọmọkùnrin Neriah, mo gbàdúrà sí Olúwa wí pé:
17 Hélas! hélas! hélas! Seigneur mon Dieu, voilà que vous avez fait le ciel et la terre par votre grande puissance et par votre bras étendu; aucune chose ne vous sera difficile;
“Háà! Olúwa Olódùmarè, ìwọ tí o dá ọ̀run àti ayé pẹ̀lú títóbi agbára rẹ àti gbogbo ọ̀rọ̀ apá rẹ. Kò sí ohun tí ó ṣòro fún ọ láti ṣe.
18 Vous qui faites miséricorde à des milliers de créatures, et qui rendez l’iniquité des pères dans le sein de leurs fils après eux, ô le très fort, le grand, et le puissant, le Seigneur des armées est votre nom.
O fi ìfẹ́ hàn sí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n o gbé ìyà ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba lé àwọn ọmọ lẹ́yìn wọn. Ọlọ́run títóbi àti alágbára, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ.
19 Vous êtes grand dans vos conseils, et incompréhensible dans vos pensées; vous dont les yeux sont ouverts sur toutes les voies des fils d’Adam, afin de rendre à chacun selon ses voies et selon le fruit de ses inventions.
Títóbi ni ìgbìmọ̀, àti alágbára ní í ṣe, ojú rẹ̀ ṣì sí gbogbo ọ̀nà àwọn ọmọ ènìyàn; láti fi fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ ọ̀nà rẹ̀ àti gẹ́gẹ́ bí èso iṣẹ́ rẹ̀.
20 C’est vous qui avez fait jusqu’à ce jour des signes et des prodiges dans la terre d’Egypte, en Israël et parmi les hommes, et vous avez rendu votre nom célèbre comme il est en ce jour.
O ṣe iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu ńlá ní Ejibiti. O sì ń ṣe é títí di òní ní Israẹli àti lára ọmọ ènìyàn tí ó sì ti gba òkìkí tí ó jẹ́ tìrẹ.
21 Et vous avez tiré Israël votre peuple de la terre d’Egypte, par des signes, et par des prodiges, et par une main forte, et par un bras étendu, et par une grande terreur.
O kó àwọn Israẹli ènìyàn rẹ jáde láti Ejibiti pẹ̀lú iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu nínú ọwọ́ agbára àti nína apá rẹ pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá.
22 Et vous leur avez donné cette terre que vous aviez juré à leurs pères de leur donner, une terre où couleraient du lait et du miel.
Ìwọ fún wọn nílẹ̀ yìí, èyí tí o ti ṣèlérí fún àwọn baba ńlá wọn; ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin.
23 Et ils sont entrés, et ils l’ont possédée; et ils n’ont point obéi à votre voix, et ils n’ont pas marché dans votre loi; et ils n’ont rien fait de tout ce que vous leur avez ordonné; et tous ces maux sont venus sur eux.
Wọ́n wá, wọ́n sì gba ilẹ̀ náà ṣùgbọ́n wọn kò gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ tàbí tẹ̀lé òfin rẹ. Wọn kò ṣe ohun tí o pàṣẹ fún wọn, nítorí náà ìwọ mú àwọn ibi yìí wá sórí wọn.
24 Voilà que des fortifications ont été construites contre la cité, afin de la prendre; et la ville a été livrée aux mains des Chaldéens qui combattent contre elle, au glaive, et à la famine, et à la peste, et tout ce que vous avez dit est arrivé, comme vous-même le voyez.
“Wò ó, bí àwọn ìdọ̀tí ṣe kórajọ láti gba ìlú. Nítorí idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, sì fi ìlú lé ọwọ́ àwọn ará Kaldea tí ń gbóguntì wọ́n. Ohun tí ìwọ sọ ṣẹ gẹ́gẹ́ bí o ṣe rí i.
25 Et vous, Seigneur mon Dieu, vous me dites: Achète le champ avec de l’argent, et prends des témoins, quoique la ville ait été livrée aux mains des Chaldéens.
Síbẹ̀ a ó fi ìlú náà fún àwọn ará Babeli, ìwọ Olúwa Olódùmarè sọ fún mi pé, ‘Ra pápá náà pẹ̀lú owó fàdákà, kí o sì pe ẹlẹ́rìí.’”
26 Et la parole du Seigneur fut adressée à Jérémie, disant:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá pé:
27 Voici que moi je suis le Seigneur, le Dieu de toute chair; est-ce qu’une chose me sera difficile?
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run gbogbo ẹran-ara. Ǹjẹ́ ohun kan ha a ṣòro fún mi bí?
28 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur: Voilà que moi je livrerai cette cité aux mains des Chaldéens, et aux mains du roi de Babylone, et ils la prendront.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa wí, Èmi ṣetán láti fi ìlú yìí fún àwọn ará Kaldea àti fún Nebukadnessari ọba Babeli ẹni tí yóò kó o.
29 Elles Chaldéens viendront combattant contre cette ville, et ils y mettront le feu, et ils la brûleront, ainsi que les maisons sur les toits desquelles ils sacrifiaient à Baal et faisaient à des dieux étrangers de nombreuses libations pour m’irriter.
Àwọn ará Kaldea tí ó ń gbógun tí ìlú yóò wọ ìlú. Wọn ó sì fi iná sí ìlú; wọn ó jó o palẹ̀ pẹ̀lú ilé tí àwọn ènìyàn ti ń mú mi bínú, tí wọ́n ń rú ẹbọ tùràrí lórí pẹpẹ fún Baali tiwọn sì ń da ẹbọ ohun mímu fún àwọn ọlọ́run mìíràn.
30 Car les fils d’Israël et les fils de Juda faisaient continuellement le mal sous mes yeux dès leur jeunesse; les fils d’Israël qui jusqu’à ce jour me révoltaient par les œuvres de leurs mains, dit le Seigneur.
“Àwọn ènìyàn Israẹli àti Juda kò ṣe ohun kankan bí kò ṣe ibi lójú mi láti ìgbà èwe wọn. Nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti fi kìkì iṣẹ́ ọwọ́ wọ́n mú mi bínú ni Olúwa wí.
31 Parce que cette cité est devenue pour moi un objet de fureur et d’indignation, depuis le jour qu’on l’a bâtie, jusqu’au jour où elle disparaîtra de ma présence,
Láti ọjọ́ tí wọ́n ti kọ́ ọ, títí di àkókò yìí ni ìlú yìí ti jẹ́ ohun ìbínú àti ìyọnu fún mi tó bẹ́ẹ̀ tí èmi yóò fà á tu kúrò níwájú mi.
32 À cause du mal que les enfants d’Israël et les enfants de Juda ont fait, en me provoquant au courroux, eux et leurs rois, leurs princes, et leurs prêtres, et leurs prophètes, les hommes de Juda et les habitants de Jérusalem.
Àwọn ènìyàn Israẹli àti àwọn ènìyàn Juda ti mú mi bínú pẹ̀lú gbogbo ìbàjẹ́ tí wọ́n ṣe. Àwọn Israẹli, ọba wọn àti gbogbo ìjòyè, àlùfáà àti wòlíì, àwọn ọkùnrin Juda àti àwọn ènìyàn Jerusalẹmu.
33 Et ils ont tourné vers moi le dos et non la face, lorsque je les enseignais au point du jour, et que je les instruisais, et qu’ils ne voulaient pas écouter et recevoir l’instruction.
Wọ́n kọ ẹ̀yìn sí mi, wọ́n sì yí ojú wọn padà. Èmi kọ wọ́n, síbẹ̀ wọn kò fetísílẹ̀ láti gbọ́ ẹ̀kọ́ tàbí kọbi ara sí ìwà ìbàjẹ́.
34 Et ils ont mis leurs idoles dans la maison dans laquelle a été invoqué mon nom. afin de la souiller.
Wọ́n kó òrìṣà ìríra wọn jọ sí inú ilé tí wọ́n fi orúkọ mi pè, wọ́n sì ṣọ́ di àìmọ́.
35 Et ils ont bâti les hauts lieux de Baal qui sont dans la vallée du fils d’Ennom, afin de consacrer leurs fils et leurs filles à Moloch; ce que je ne leur ai pas commandé; et il n’est pas monté jusqu’à mon cœur qu’ils feraient cette abomination, et qu’ils entraîneraient Juda dans le péché.
Wọ́n kọ́ ibi gíga fún Baali ní àfonífojì Hinnomu láti fi ọmọ wọn ọkùnrin àti obìnrin rú ẹbọ sí Moleki. Èmi kò pàṣẹ, fún wọn, bẹ́ẹ̀ ni kò wá sí ọkàn mi pé kí wọ́n ṣe ohun ìríra wọ̀nyí tí ó sì mú Juda dẹ́ṣẹ̀.
36 Et maintenant, à cause de cela, voici ce que dit le Seigneur, Dieu d’Israël, à cette cité dont vous dites, vous, qu’elle sera livrée aux mains du roi de Babylone, par le glaive, par la famine et par la peste:
“Ìwọ ń sọ̀rọ̀ nípa ti ìlú yìí pé, ‘Pẹ̀lú idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn ni à ó fi wọ́n fún ọba Babeli,’ ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ nìyìí,
37 Voilà que moi, je les rassemblerai de toutes les terres dans lesquelles je les ai jetés dans ma fureur, et dans ma colère et dans ma grande indignation, et je les ramènerai en ce lieu, et je les y ferai habiter en assurance.
Èmi ó kó wọn jọ láti gbogbo ilẹ̀ tí mo ti lé wọn kúrò ní ìgbà ìbínú àti ìkáàánú ńlá mi. Èmi yóò mú wọn padà wá sí ilẹ̀ yìí; èmi ó sì jẹ́ kí wọn ó máa gbé láìléwu.
38 Et ils seront mon peuple, et moi je serai leur Dieu.
Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
39 Et je leur donnerai un seul cœur et une seule voie, afin qu’ils me craignent tous les jours de leur vie, et que bien leur soit à eux et à leurs fils après eux.
Èmi ó fún wọn ní ọkàn kan àti ìṣe kí wọn kí ó lè máa bẹ̀rù mi fún rere wọn àti fún rere àwọn ọmọ wọn tí ó tẹ̀lé wọn.
40 Et je ferai avec eux une alliance éternelle, et je ne cesserai point de leur faire du bien; et je mettrai ma crainte dans leur cœur, afin qu’ils ne se retirent pas de moi.
Èmi ò bá wọn dá májẹ̀mú ayérayé, èmi kò ní dúró láti ṣe rere fún wọn, Èmi ó sì jẹ́ kí wọ́n bẹ̀rù mi, wọn kì yóò sì padà lẹ́yìn mi.
41 Et je me réjouirai en eux, lorsque je leur aurai fait du bien; et je les rétablirai en cette terre dans la vérité, de tout mon cœur, et de toute mon âme.
Lóòtítọ́, èmi ó yọ̀ nípa ṣíṣe wọ́n ní rere, èmi ó sì fi dá wọn lójú nípa gbígbìn wọ́n sí ilẹ̀ yìí tọkàntọkàn mi.
42 Car voici ce que dit le Seigneur: Comme j’ai amené sur ce peuple tous ces grands maux, ainsi j’amènerai sur eux tous les biens que je leur promets.
“Nítorí báyìí ni Olúwa wí, gẹ́gẹ́ bí èmi ti mú gbogbo ibi ńlá yìí wá sórí àwọn ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni èmi ó mú gbogbo rere tí èmi ti sọ nípa tiwọn wá sórí wọn.
43 Elles champs auront encore des possesseurs dans cette terre de laquelle vous dites, vous, qu’elle est déserte, parce qu’il n’y est pas demeure d’homme ni de bête, et qu’elle a été livrée aux mains des Chaldéens.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, pápá yóò di rírà ní ilẹ̀ yìí tí ìwọ ti sọ pé, ‘Ohun òfò ni tí kò bá sí ọkùnrin tàbí àwọn ẹran, nítorí tí a ti fi fún àwọn ará Babeli.’
44 Les champs seront achetés avec de l’argent, et ils seront inscrits sur la feuille, et un sceau y sera gravé, des témoins seront invoqués, dans la terre de Benjamin et aux environs de Jérusalem; dans les cités de Juda, dans les cités des montagnes, dans les cités de la plaine, et dans les cités qui sont au midi; parce que je ramènerai leurs captifs, dit le Seigneur.
Wọn ó fi owó fàdákà ra oko, wọn yóò fi ọwọ́ sí ìwé, wọn ó dí pa pẹ̀lú ẹlẹ́rìí láti ilẹ̀ Benjamini àti ní ìlú kéékèèké tí ó yí Jerusalẹmu ká, àti ní ìlú Juda àti ní ìlú àwọn ìlú orí òkè, àti ni àwọn ẹsẹ̀ òkè, àti ní gúúsù, èmi ó mú ìgbèkùn wọn padà wá, ni Olúwa wí.”

< Jérémie 32 >