< Jérémie 31 >

1 En ce temps-là, dit le Seigneur, je serai le Dieu de toutes les familles d’Israël, et elles seront mon peuple.
“Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
2 Voici ce que dit le Seigneur: Il a trouvé grâce dans le désert, un peuple qui avait échappé au glaive: Israël ira à son repos.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
3 De loin le Seigneur m’a apparu. Et je t’ai aimée d’un amour éternel: c’est pour cela que je t’ai attirée ayant pitié de toi.
Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
4 Et de nouveau je t’édifierai, et tu seras édifiée, vierge d’Israël; tu paraîtras encore ornée au milieu des tambours, et tu sortiras dans un chœur de joueurs d’instruments.
Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
5 Tu planteras encore des vignes sur les montagnes de Samarie; des planteurs les planteront, et jusqu’à ce que le temps arrive, ils ne vendangeront pas.
Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
6 Car viendra un jour auquel les gardes crieront sur la montagne d’Ephraïm: Levez-vous, et montons en Sion vers le Seigneur notre Dieu.
Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
7 Parce que voici ce que dit le Seigneur: Exultez d’allégresse, Jacob, et poussez des cris éclatants à la tête des nations, faites retentir vos voix, chantez, et dites: Seigneur, sauvez votre peuple, les restes d’Israël.
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
8 Voilà que moi je les amènerai de la terre de l’aquilon, et que je les rassemblerai des extrémités de la terre; parmi eux seront l’aveugle et le boiteux, la femme enceinte et celle qui a enfanté, mêlés ensemble, grande assemblée d’hommes revenant ici.
Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
9 C’est dans le pleur qu’ils viendront, et c’est dans la miséricorde que je les ramènerai, et je les ramènerai à travers des torrents d’eau dans une voie droite, et ils n’y heurteront point, parce que je suis devenu pour Israël un père, et qu’Éphraïm est mon premier-né.
Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
10 Ecoutez, nations, la parole du Seigneur, et annoncez-la aux îles qui sont au loin, et dites: Celui qui a dispersé Israël le rassemblera, et il le gardera comme un pasteur son troupeau.
“Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
11 Car le Seigneur a racheté Jacob, et l’a délivré de la main d’un plus puissant que lui.
Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
12 Et ils viendront, et ils chanteront des louanges sur la montagne de Sion; et ils accourront en foule vers les biens du Seigneur, vers le blé, et le vin, et l’huile, et le fruit des troupeaux de menu et de gros bétail; et leur âme sera comme un jardin arrosé; et ils n’auront plus faim.
Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
13 Alors se réjouira la vierge au milieu d’un chœur, ainsi que les jeunes hommes et les vieillards ensemble; et je changerai leur deuil en joie, et je les consolerai, et je les remplirai d’allégresse après leur douleur.
Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
14 Et j’enivrerai l’âme des prêtres de graisse, et mon peuple sera rempli de mes biens, dit le Seigneur.
Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
15 Voici ce que dit le Seigneur: Une voix a été entendue sur une hauteur, voix de lamentation, de deuil et de pleur, la voix de Rachel déplorant la perte de ses enfants, et ne voulant pas en être consolée, parce qu’ils ne sont plus,
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
16 Voici ce que dit le Seigneur: Que ta voix cesse ses gémissements, et tes yeux leurs larmes; parce qu’il est une récompense à tes œuvres, dit le Seigneur, et ils reviendront de la terre de l’ennemi.
Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
17 Et il est un espoir pour tes derniers moments, dit le Seigneur, et tes fils reviendront dans tes confins.
Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
18 Entendant, j’ai entendu Ephraïm dans sa transmigration: Vous m’avez châtié et j’ai été instruit, comme un jeune taureau indompté; convertissez-moi et je serai converti, parce que vous êtes le Seigneur mon Dieu.
“Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
19 Car, après que vous m’avez converti, j’ai fait pénitence, et après que vous m’avez montré mon état, j’ai frappé ma cuisse, l’ai été confondu, et j’ai rougi, parce que j’ai supporté l’opprobre de ma jeunesse.
Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
20 Est-ce qu’il n’est pas un fils honorable pour moi, Ephraïm, n’est-il pas un enfant de délices? parce que, depuis que j’ai parlé de lui, je me souviendrai encore de lui. C’est pour cela que mes entrailles sont émues sur lui; ayant pitié, j’aurai pitié de lui, dit le Seigneur.
Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
21 Etablis-toi un lieu d’observation, abandonne-toi à l’amertume, dirige ton cœur vers la voie droite, dans laquelle tu as marché: retourne, vierge d’Israël, retourne vers ces cités tiennes.
“Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
22 Jusques à quand seras-tu énervée par les délices, fille vagabonde? parce que le Seigneur a créé un nouveau prodige sur la terre: UNE FEMME ENVIRONNERÀ UN HOMME.
Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
23 Voici ce que dit le Seigneur, Dieu d’Israël: Ils diront encore cette parole dans la terre de Juda et dans ses villes, lorsque j’aurai ramené leurs captifs: Que le Seigneur te bénisse, beauté de justice, montagne sainte;
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
24 Et y habiteront Juda et toutes ses cités ensemble, les laboureurs et ceux qui conduisent les troupeaux.
Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
25 Parce que j’ai enivré l’âme fatiguée, et j’ai rassasié toute âme qui avait faim.
Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
26 C’est pour cela que je me suis comme éveillé de mon sommeil; et j’ai vu, et mon sommeil m’a été doux.
Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
27 Voilà que des jours viennent, dit le Seigneur, et je sèmerai la maison d’Israël et la maison de Juda d’une semence d’hommes et d’une semence de bêtes,
“Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
28 Et comme j’ai veillé sur eux, afin de les arracher, et de les détruire, et de les dissiper, et de les perdre, et de les affliger, ainsi je veillerai sur eux, afin de les édifier et de les planter, dit le Seigneur.
Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
29 En ces jours-là, on ne dira plus: Les pères ont mangé des raisins verts, et les dents des fils ont été agacées.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
30 Mais chacun mourra dans son iniquité; tout homme qui aura mangé le raisin vert, ses dents seront agacées.
Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
31 Voilà que des jours viendront, dit le Seigneur, et je ferai une nouvelle alliance avec la maison d’Israël et avec la maison de Juda,
“Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
32 Non pas selon l’alliance que j’ai formée avec leurs pères, au jour auquel je pris leur main, afin de les faire sortir de la terre d’Egypte; alliance qu’ils ont rendue vaine, et moi je les ai maîtrisés, dit le Seigneur.
Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
33 Mais voici l’alliance que je ferai avec la maison d’Israël après ces jours-là, dit le Seigneur: Je mettrai ma loi dans leurs entrailles, et je l’écrirai dans leur cœur; et je serai leur Dieu, et eux seront mon peuple.
“Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
34 Et un homme n’instruira plus son prochain, et un homme son frère, disant: Connais le Seigneur; car tous me connaîtront, depuis le plus petit d’entre eux jusqu’au plus grand, dit le Seigneur; parce que je pardonnerai leur iniquité, et que de leur péché je ne me souviendrai plus.
Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
35 Voici ce que dit le Seigneur, qui donne le soleil pour éclairer dans le jour, et le cours réglé de la lune et des étoiles pour éclairer pendant la nuit; qui agite la mer, et ses flots mugissent; le Seigneur des armées est son nom.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
36 Si ces lois défaillent devant moi, dit le Seigneur, alors aussi la race d’Israël défaudra pour n’être plus à jamais un peuple devant moi.
“Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
37 Voici ce que dit le Seigneur: Si les cieux peuvent être mesurés dans leur hauteur, et les fondements de la terre sondés dans leur profondeur; moi aussi je rejetterai toute la race d’Israël, à cause de tout ce qu’ils ont fait, dit le Seigneur.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
38 Voilà que des jours viennent, dit le Seigneur, et la cité sera édifiée pour le Seigneur, depuis la tour d’Hananéel, jusqu’à la porte de l’angle.
“Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
39 Et le cordeau sortira encore au-delà à sa vue sur la colline de Gareb; et fera le tour de Goatha,
Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
40 Et de toute la vallée des cadavres et de la cendre, et de toute la région de la mort, jusqu’au torrent de Cédron, et jusqu’à l’angle de la porte orientale des chevaux; le lieu saint du Seigneur ne sera pas renversé, et il ne sera jamais plus détruit.
Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”

< Jérémie 31 >