< Jérémie 27 >

1 Au commencement du règne de Joakim, fils de Josias, roi de Juda, cette parole fut adressée à Jérémie par le Seigneur, disant:
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 Voici ce que me dit le Seigneur: Fais-toi des liens, et des chaînes, et tu les mettras à ton cou.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 Et tu les enverras au roi d’Edom, et au roi de Moab, et au roi des enfants d’Ammon, et au roi de Tyr, et au roi de Sidon, par la main des ambassadeurs qui sont venus à Jérusalem vers Sédécias, roi de Juda.
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 Et tu leur ordonneras de parler ainsi à leurs maîtres: Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Vous direz ceci à vos maîtres:
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 C’est moi qui ai fait la terre, et les hommes et les hôtes qui sont sur la face de la terre, par ma grande puissance et par mon bras étendu; et j’ai donné la terre à celui qui a plu à mes yeux.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 Et c’est pourquoi moi j’ai maintenant mis toutes ces terres dans la maison de Nabuchodonosor, roi de Babylone, mon serviteur; de plus, je lui ai donné les bêtes de la campagne, afin qu’elles lui soient soumises.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 Et toutes les nations lui seront soumises, à lui et à son fils, et au fils de son fils, jusqu’à ce que vienne le temps de son royaume et son propre temps, et beaucoup de nations et de grands rois lui seront soumis.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 Mais la nation et le royaume qui ne se soumettra pas à Nabuchodonosor, roi de Babylone, et quiconque ne courbera pas son cou sous le joug du roi de Babylone, c’est par le glaive, par la faim, et par la peste, que je visiterai cette nation, jusqu’à ce que je les aie consumés par sa main.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Vous donc, n’écoutez pas vos prophètes, et vos devins et vos rêveurs, vos augures et vos magiciens, qui vous disent: Vous ne serez pas soumis au roi de Babylone.
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 Parce qu’ils vous prophétisent un mensonge, afin de vous envoyer loin de votre terre, et de vous en chasser, et de vous faire périr.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 Or la nation qui mettra son cou sous le joug du roi de Babylone, et se soumettra à lui, je la laisserai dans sa terre, dit le Seigneur; et elle la cultivera, et elle y habitera.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 Et à Sédécias, roi de Juda, dans les mêmes termes j’ai parlé, disant: Mettez vos cous sous le joug du roi de Babylone, et soumettez-vous à lui et à son peuple, et vous vivrez.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Pourquoi mourrez-vous, vous et votre peuple, par le glaive, et par la famine, et par la peste, comme l’a dit le Seigneur de la nation qui n’aura pas voulu se soumettre au roi de Babylone?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 N’écoutez pas les paroles des prophètes qui vous disent: Vous ne serez pas soumis au roi de Babylone; parce que c’est un mensonge qu’eux vous disent.
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 Parce que je ne les ai pas envoyés, dit le Seigneur, et ils prophétisent en mon nom faussement, afin de vous chasser de votre terre et de vous faire périr, vous et les prophètes qui vous prédisent l’avenir.
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 Et j’ai parlé aux prêtres et à ce peuple, disant: Voici ce que dit le Seigneur: N’écoutez pas les paroles de vos prophètes qui vous prophétisent, disant: Voilà que les vases du Seigneur seront bientôt rapportés de Babylone; car c’est un mensonge qu’ils vous prophétisent.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Ne les écoutez donc pas; mais soumettez-vous au roi de Babylone, afin que vous viviez; pourquoi cette cité sera-t-elle réduite en une solitude?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 Que s’ils sont prophètes et que la parole du Seigneur soit en eux, qu’ils s’opposent au Seigneur des armées, afin que les vases laissés dans la maison du Seigneur, et dans la maison du roi de Juda, et à Jérusalem, ne soient pas transférés à Babylone.
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 Parce que voici ce que dit le Seigneur des armées relativement aux colonnes, et à la mer, et aux bases, et aux restes des vases qui ont été laissés dans cette cité,
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 Que n’emporta pas Nabuchodonosor, roi de Babylone, lorsqu’il transféra Jéchonias, fils de Joakim, roi de Juda, de Jérusalem à Babylone, et tous les grands de Juda et de Jérusalem;
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 Parce que, dis-je, voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël, relativement aux vases qui ont été laissés dans la maison du roi de Juda et dans Jérusalem:
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 Ils seront transportés à Babylone, et ils y seront jusqu’au jour de leur visite, dit le Seigneur; et je les ferai rapporter et rétablir en ce lieu.
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jérémie 27 >