< Jérémie 25 >
1 Parole qui fut adressée à Jérémie touchant tout le peuple de Juda, en la quatrième année de Joakim, fils de Josias, roi de Juda, qui est la première année de Nabuchodonosor, roi de Babylone;
Ọ̀rọ̀ sì tọ Jeremiah wá nípa àwọn ènìyàn Juda ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda, èyí tí ó jẹ́ ọdún kìn-ín-ní Nebukadnessari ọba Babeli.
2 Et que Jérémie, le prophète, annonça à tout le peuple de Juda, et à tous les habitants de Jérusalem, disant:
Nítorí náà, Jeremiah wòlíì sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn Juda àti sí àwọn olùgbé Jerusalẹmu.
3 Depuis la treizième année de Josias, fils d’Ammon, roi de Juda, jusqu’à ce jour, c’est la vingt-troisième année; la parole du Seigneur m’a été adressée, et je vous ai parlé, me levant durant la nuit et parlant, et vous ne m’avez pas écouté.
Fún odidi ọdún mẹ́tàlélógún, bẹ̀rẹ̀ láti ọdún kẹtàlá Josiah, ọmọ Amoni ọba Juda, títí di ọjọ́ yìí, ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, mo sì ti sọ ọ́ fún un yín láti ìgbà dé ìgbà, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
4 Et le Seigneur a envoyé vers vous tous ses serviteurs les prophètes, se levant au point du jour, et les envoyant; et vous n’avez pas écouté, et vous n’avez pas incliné vos oreilles afin d’écouter,
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn wòlíì sí i yín láti ìgbà dé ìgbà, ẹ̀yin kò fetísílẹ̀.
5 Lorsqu’il disait: Revenez chacun de votre voie mauvaise, et de vos très mauvaises pensées; et vous habiterez dans la terre que le Seigneur vous a donnée, à vous et à vos pères, de siècle en siècle.
Wọ́n sì wí pé, “Ẹ yípadà olúkúlùkù yín kúrò ní inú ibi rẹ̀ àti ní ọ̀nà ibi rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì lè dúró ní ilẹ̀ tí Olúwa fún un yín àti àwọn baba yín títí láéláé.
6 Et n’allez pas à la suite de dieux étrangers, afin de les servir et de les adorer; ne me provoquez pas au courroux par les œuvres de vos mains, et je ne vous affligerai point.
Má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn láti sìn wọ́n tàbí bọ wọ́n; ẹ má ṣe mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ ti fi ọwọ́ yín ṣe. Nígbà náà ni Èmi kò ní ṣe yín ní ibi.”
7 Et vous ne m’avez pas écouté, dit le Seigneur, en sorte que vous m’avez provoqué au courroux par les œuvres de vos mains, pour votre malheur.
“Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni ẹ sì ti mú inú bí mi pẹ̀lú ohun tí ẹ fi ọwọ́ yín ṣe, ẹ sì ti mú ibi wá sórí ara yín.”
8 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur des armées: À cause de ce que vous n’avez pas écouté mes paroles,
Nítorí náà, Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ èyí: “Nítorí wí pé ẹ̀yin kò fetí sí ọ̀rọ̀ mi,
9 Voilà que moi j’enverrai et que je prendrai toutes les familles de l’aquilon, dit le Seigneur, et Nabuchodonosor, roi de Babylone, mon serviteur; et je les amènerai sur cette terre et sur ses habitants, et sur toutes les nations qui sont autour d’elle; et je les perdrai, et j’en ferai un objet de stupeur et de sifflement, et je les réduirai à des solitudes éternelles.
Èmi yóò pe gbogbo àwọn ènìyàn àríwá, àti ìránṣẹ́ mi Nebukadnessari ọba Babeli,” ni Olúwa wí. “Èmi yóò sì mú wọn dìde lòdì sí ilẹ̀ náà àti àwọn olùgbé rẹ̀ àti sí gbogbo orílẹ̀-èdè àyíká rẹ̀. Èmi yóò pa wọ́n run pátápátá, Èmi yóò sọ wọ́n di nǹkan ẹ̀rù àti yẹ̀yẹ́ àti ìparun ayérayé.
10 Et je ferai cesser parmi eux la voix de la joie et la voix de l’allégresse, la voix de l’époux et la voix de l’épouse, la voix de la meule et la lumière de la lampe.
Èmi yóò sì mú ìró ayọ̀ àti inú dídùn kúrò lọ́dọ̀ wọn; ohùn ìyàwó àti ọkọ ìyàwó, ìró ọlọ òkúta àti ìmọ́lẹ̀ fìtílà.
11 Et toute cette terre sera une solitude et un objet de stupeur; et toutes ces nations serviront le roi de Babylone durant soixante et dix ans.
Gbogbo orílẹ̀-èdè yìí yóò sì di ahoro, orílẹ̀-èdè yìí yóò sì sìn ọba Babeli ní àádọ́rin ọdún.
12 Et lorsque les soixante et dix années seront accomplies, je visiterai le roi de Babylone, et cette nation, dit le Seigneur, et leur iniquité, et la terre des Chaldéens; et j’en ferai des solitudes éternelles.
“Ṣùgbọ́n, nígbà tí àádọ́rin ọdún náà bá pé, Èmi yóò fi ìyà jẹ ọba Babeli àti orílẹ̀-èdè rẹ, ilẹ̀ àwọn ará Babeli nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí; “bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò sọ ọ́ di ahoro títí láé.
13 Et j’amènerai sur cette terre toutes mes paroles que j’ai dites contre elle, tout ce qui a été écrit dans ce livre, toutes les choses qu’a prophétisées Jérémie contre toutes les nations;
Èmi yóò sì mú gbogbo ohun tí mo ti sọ wọ̀nyí wá sórí ilẹ̀ náà, gbogbo ohun tí a ti sọ àní gbogbo èyí tí a ti kọ sínú ìwé yìí, èyí tí Jeremiah ti sọtẹ́lẹ̀ sí gbogbo orílẹ̀-èdè.
14 Parce qu’elles les ont servis, quoique ce fussent des nations nombreuses et de grands rois; et je leur rendrai selon leurs œuvres, et selon les ouvrages de leurs mains.
Àwọn fúnra wọn yóò sì sin orílẹ̀-èdè púpọ̀ àti àwọn ọba ńlá. Èmi yóò sì sán fún oníkálùkù gẹ́gẹ́ bí ìṣe àti iṣẹ́ ọwọ́ wọn.”
15 Parce qu’ainsi dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Prends ce calice de vin de fureur de ma main, et tu en feras boire à toutes les nations vers lesquelles moi je t’enverrai.
Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí fún mi: “Gba ago yìí ní ọwọ́ mí tí ó kún fún ọtí wáìnì ìbínú mi, kí o sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè ti mo rán ọ sí mu ún.
16 Et elles boiront, et elles seront troublées, et elles perdront le sens à la face du glaive que moi j’enverrai parmi elles.
Nígbà tí wọ́n bá mu ún, wọn yóò ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n: bẹ́ẹ̀ ni kí wọ́n di aṣiwèrè nítorí idà tí yóò ránṣẹ́ sí àárín wọn.”
17 Et je reçus le calice de la main du Seigneur, et j’en fis boire à toutes les nations vers lesquelles m’a envoyé le Seigneur:
Mo sì gba ago náà lọ́wọ́ Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni mo sì mú gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó rán mi sí mu ún.
18 À Jérusalem et aux cités de Juda, et à ses rois, et à ses princes; afin d’en faire un désert, et un objet de stupeur et de sifflement, et de malédiction, comme c’est en ce jour;
Jerusalẹmu àti àwọn ìlú Juda, àwọn ọba wọn pẹ̀lú àwọn aláṣẹ wọn, láti sọ wọ́n di ohun ìparun, ohun ẹ̀rù, ẹ̀sìn àti ègún, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti rí lónìí yìí.
19 À Pharaon, roi d’Egypte, et à ses serviteurs, et à ses princes, et à tout son peuple;
Farao ọba Ejibiti, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àwọn aláṣẹ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn rẹ̀.
20 Et à tous généralement: à tous les rois de la terre d’Ausite, et à tous les rois de la terre des Philistins, et à Ascalon, et à Gaza, et à Accaron, et aux restes d’Azot;
Àti gbogbo àwọn ènìyàn àjèjì tí ó wà níbẹ̀; gbogbo àwọn ọba Usi, gbogbo àwọn ọba Filistini, gbogbo àwọn ti Aṣkeloni, Gasa, Ekroni àti gbogbo àwọn ènìyàn tí ó kù sí Aṣdodu.
21 Et à l’Idumée, et à Moab, et aux enfants d’Ammon;
Edomu, Moabu àti Ammoni;
22 Et à tous les rois de Tyr, et à tous les rois de Sidon, et aux rois de la terre des îles qui sont au-delà de la mer;
gbogbo àwọn ọba Tire àti Sidoni; gbogbo àwọn ọba erékùṣù wọ̀n-ọn-nì tí ń bẹ ní ìkọjá Òkun.
23 Et à Dédan, et à Théma, et à Buz, et à tous ceux dont la chevelure est coupée;
Dedani, Tema, Busi àti gbogbo àwọn tí ń gbé lọ́nà jíjìn réré.
24 Et à tous les rois d’Arabie, et à tous les rois d’Occident qui habitent dans le désert;
Gbogbo àwọn ọba Arabia àti àwọn ọba àwọn àjèjì ènìyàn tí ń gbé inú aginjù.
25 Et à tous les rois de Zambri, et à tous les rois d’Elam, et à tous les rois des Mèdes;
Gbogbo àwọn ọba Simri, Elamu àti Media.
26 Et aussi à tous les rois de l’aquilon, proches et éloignés, à chacun contre son frère et à tous les royaumes de la terre, qui sont sur sa face; et le roi de Sésach boira après eux.
Àti gbogbo àwọn ọba àríwá ní tòsí àti lọ́nà jíjìn, ẹnìkínní lẹ́yìn ẹnìkejì; gbogbo àwọn ìjọba lórí orílẹ̀ ayé. Àti gbogbo wọn, ọba Ṣeṣaki náà yóò sì mu.
27 Et tu leur diras: Voici ce que dit le Seigneur des armées, Dieu d’Israël: Buvez et enivrez-vous, et vomissez; et tombez et ne vous relevez pas à la face du glaive que moi j’enverrai parmi vous.
“Nígbà náà, sọ fún wọn, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí. Mu, kí o sì mú àmuyó kí o sì bì, bẹ́ẹ̀ ni kí o sì ṣubú láì dìde mọ́ nítorí idà tí n ó rán sí àárín yín.
28 Que s’ils ne veulent pas recevoir de ta main le calice pour boire, tu leur diras: Voici ce que dit le Seigneur des armées: Buvant, vous boirez;
Ṣùgbọ́n bí wọ́n ba kọ̀ láti gba ago náà ní ọwọ́ rẹ kí wọ́n sì mu ún, sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: Ẹyin gbọdọ̀ mu ún!
29 Parce que voilà que dans la cité dans laquelle mon nom a été invoqué, moi je commencerai à affliger, et vous, vous serez comme des innocents et exempts de châtiment? Vous n’en serez pas exempts; car moi j’appelle le glaive sur tous les habitants de la terre, dit le Seigneur des armées.
Wò ó, èmi ń mú ibi bọ̀ sí orí orílẹ̀-èdè tí ó ń jẹ́ orúkọ mi; ǹjẹ́ yóò ha a lè lọ láìjìyà? Ẹ̀yin ń pe idà sọ̀kalẹ̀ sórí gbogbo àwọn olùgbé ayé, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ.’
30 Et toi, tu leur prophétiseras toutes ces choses et tu leur diras: Le Seigneur d’en haut rugira, et de son habitacle saint il fera entendre sa voix; rugissant il rugira contre le lieu même de sa gloire, et un cri, comme les cris de ceux qui foulent le pressoir, retentira contre tous les habitants de la terre.
“Nísinsin yìí, sọ àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí nípa wọn: “‘Kí o sì sọ pé, Olúwa yóò bú láti òkè wá, yóò sì bú kíkankíkan sí ilẹ̀ náà. Yóò parí gbogbo olùgbé ayé, bí àwọn tí ń tẹ ìfúntí.
31 Le bruit en est parvenu jusqu’aux extrémités de la terre, parce que le Seigneur entre en jugement avec toutes les nations; il est lui-même en contestation avec toute chair: j’ai livré les impies au glaive, dit le Seigneur.
Ìrọ́kẹ̀kẹ̀ yóò wà títí dé òpin ilẹ̀ ayé, nítorí pé Olúwa yóò mú ìdààmú wá sí orí àwọn orílẹ̀-èdè náà, yóò mú ìdájọ́ wá sórí gbogbo ènìyàn, yóò sì fi àwọn olùṣe búburú fún idà,’” ni Olúwa wí.
32 Voici ce que dit le Seigneur des armées: Voilà que l’affliction passera d’une nation sur une nation, et une grande tempête sortira des extrémités de la terre.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “Wò ó! Ibi ń tànkálẹ̀ láti orílẹ̀-èdè kan sí òmíràn; ìjì ńlá yóò sì ru sókè láti òpin ayé.”
33 Et les tués par le Seigneur seront en ce jour-là d’un bout de la terre à son autre bout; ils ne seront pas pleures, et ils ne seront pas recueillis, ni ensevelis, mais comme un fumier sur la face de la terre, ils seront étendus.
Nígbà náà, àwọn tí Olúwa ti pa yóò wà ní ibi gbogbo, láti ìpẹ̀kun kan sí òmíràn. A kì yóò ṣọ̀fọ̀ wọn, a kì yóò kó wọn jọ tàbí sin wọ́n; ṣùgbọ́n wọn yóò dàbí ààtàn lórí ilẹ̀.
34 Hurlez, pasteurs, et criez; couvrez-vous de cendres, vous les chefs du troupeau, parce que sont remplis les jours après lesquels vous devez être tués; vous serez dispersés, et vous tomberez comme des vases précieux.
Ké, kí ẹ sì pohùnréré ẹkún ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, ẹ yí nínú eruku, ẹ̀yin olùdarí agbo ẹran. Nítorí pé ọjọ́ àti pa yín ti dé, ẹ̀yin ó sì ṣubú bí ohun èlò iyebíye.
35 Et la fuite sera enlevée aux pasteurs, et le salut aux chefs du troupeau.
Àwọn olùṣọ́-àgùntàn kì yóò rí ibi sálọ kì yóò sì ṣí àsálà fún olórí agbo ẹran.
36 La voix de la clameur des pasteurs, et les hurlements des chefs du troupeau se feront entendre, parce que le Seigneur a dévasté leurs pâturages.
Gbọ́ igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn, àti ìpohùnréré ẹkún àwọn olórí agbo ẹran; nítorí pé Olúwa ń pa pápá oko tútù wọn run.
37 Et les champs de la paix sont dans le silence, à la face de la colère de la fureur du Seigneur.
Ibùgbé àlàáfíà yóò di ahoro, nítorí ìbínú ńlá Olúwa.
38 Il a abandonné, comme le lion, sa retraite, et leur terre a été désolée à la face de la colère de la colombe, et à la face de la colère de la fureur du Seigneur.
Gẹ́gẹ́ bí kìnnìún yóò fi ibùba rẹ̀ sílẹ̀, ilẹ̀ wọn yóò sì di ahoro, nítorí idà àwọn aninilára, àti nítorí ìbínú ńlá Olúwa.