< Jérémie 22 >

1 Voici ce que dit le Seigneur: Descends dans la maison du roi de Juda, et tu prononceras là cette parole,
Báyìí ni Olúwa wí, “Sọ̀kalẹ̀ lọ sí ààfin ọba Juda, kí o sì sọ ọ̀rọ̀ yìí níbẹ̀:
2 Et tu diras: Ecoute la parole du Seigneur, roi de Juda, toi qui es assis sur le trône de David; toi, et tes serviteurs, et ton peuple, qui entrez par ces portes.
‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ìwọ ọba Juda, tí ó jókòó ní ìtẹ́ Dafidi, ìwọ, àwọn ènìyàn rẹ àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ, tí ó wọlé láti ẹnu ibodè wọ̀nyí.
3 Voici ce que dit le Seigneur: Rendez le jugement et la justice; délivrez celui qui est opprimé par la violence de la main de l’oppresseur; ne contristez pas l’étranger, l’orphelin, et la veuve, et ne les opprimez pas injustement, et le sang innocent, ne le répandez pas dans ce lieu.
Báyìí ni Olúwa wí: Ṣé ohun tí ó jẹ́ òtítọ́ tí ó sì yẹ, kí o sì gba ẹni tí a fi ẹ̀tọ́ rẹ̀ dù ú kúrò lọ́wọ́ aninilára. Kí ó má ṣe fi agbára àti ìkà lé àlejò, aláìní baba, tàbí opó, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ níbí yìí.
4 Si observant vous observez ces paroles, des rois de la race de David entreront par les portes de cette maison; ils seront assis sur son trône, et montés sur des chars et sur des chevaux, leurs serviteurs et leur peuple.
Nítorí bí ẹ̀yin bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, nígbà náà ni àwọn ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi yóò gba inú ààfin láti ẹnu-ọ̀nà, wọn yóò gun kẹ̀kẹ́ àti ẹṣin, àwọn àti ìránṣẹ́ wọn àti àwọn ènìyàn wọn.
5 Que si vous n’écoutez point ces paroles, j’ai juré par moi-même, dit le Seigneur, que cette maison deviendra une solitude.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin kò bá tẹ̀lé àṣẹ wọ̀nyí, mo búra fúnra mi pé ààfin yìí yóò di ìparun ni Olúwa wí.’”
6 Parce que voici ce que dit le Seigneur sur la maison du roi de Juda: Tu es pour moi, Galaad, la tête du Liban; néanmoins je te rendrai toi, une solitude, et tes villes inhabitables.
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa ààfin ọba Juda, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé ìwọ dàbí Gileadi sí mi, gẹ́gẹ́ bí góńgó òkè Lebanoni, dájúdájú Èmi yóò sọ ọ́ di aṣálẹ̀, àní gẹ́gẹ́ bí ìlú tí a kò gbé inú wọn.
7 Et je consacrerai contre toi un homme qui tuera, et ses armes; et ils abattront tes cèdres choisis, et ils les jetteront dans le feu.
Èmi ó ya àwọn apanirun sọ́tọ̀ fún ọ, olúkúlùkù ọkùnrin pẹ̀lú ohun ìjà rẹ̀, wọn yóò sì gé àṣàyàn igi kedari rẹ lulẹ̀, wọn ó sì kó wọn jù sínú iná.
8 Et des nations nombreuses passeront par cette cité, et chacun dira à son voisin: Pourquoi le Seigneur a-t-il fait ainsi à cette cité considérable?
“Àwọn ènìyàn láti ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè yóò rékọjá lẹ́bàá ìlú yìí wọn yóò sì máa bi ara wọn léèrè pé, ‘Èéṣe tí Olúwa ṣe irú èyí sí ìlú ńlá yìí?’
9 Et on répondra: Parce qu’ils ont abandonné l’alliance du Seigneur leur Dieu, et qu’ils ont adoré des dieux étrangers, et qu’ils les ont servis.
Ìdáhùn wọn yóò sì jẹ́: ‘Nítorí tí wọ́n ti kọ májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọn ti ń fi orí balẹ̀ fún ọlọ́run mìíràn, wọ́n sì sìn wọ́n.’”
10 Ne pleurez pas un mort, ne faites pas de deuil pour lui par votre pleur; désolez-vous au sujet de celui qui sort, parce qu’il ne reviendra plus, et qu’il ne verra plus la terre de sa naissance.
Nítorí náà má ṣe sọkún nítorí ọba tí ó ti kú tàbí ṣọ̀fọ̀ fún àdánù rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ sọkún kíkorò fún ẹni tí a lé kúrò nílùú nítorí kì yóò padà wá mọ́ tàbí fi ojú rí ilẹ̀ tí a ti bí i.
11 Parce que voici ce que dit le Seigneur, contre Sellum, fils de Josias, et roi de Juda, qui a régné pour Josias, son père, et qui est sorti de ce lieu: Il ne reviendra plus ici;
Nítorí báyìí ni Olúwa wí, nípa Ṣallumu ọmọ Josiah ọba Juda tí ó jẹ ọba lẹ́yìn baba rẹ̀, ṣùgbọ́n tí ó jáde kúrò níhìn-ín: “Òun kì yóò padà wá mọ́.
12 Mais dans le lieu où je l’ai transporté, là il mourra, et il ne verra plus cette terre.
Yóò kú ni ibi tí a mú u ní ìgbèkùn lọ, kì yóò sì rí ilẹ̀ yìí mọ́.”
13 Malheur à celui qui bâtit sa maison dans l’injustice, et ses cénacles dans l’iniquité; il opprimera son ami sans sujet, et il ne lui payera pas son salaire;
“Ègbé ni fún ẹni tí a kọ́ ààfin rẹ̀ lọ́nà àìṣòdodo, àti àwọn yàrá òkè rẹ̀ lọ́nà àìtọ́ tí ó mú kí àwọn ará ìlú rẹ ṣiṣẹ́ lásán láìsan owó iṣẹ́ wọn fún wọn.
14 Qui dit: Je me bâtirai une maison vaste et des cénacles spacieux; qui s’ouvre des fenêtres, fait des lambris de cèdre, et il les peint avec de la terre de Sinope.
Ó wí pé, ‘Èmi ó kọ́ ààfin ńlá fún ara mi àwọn yàrá òkè tí ó fẹ̀, ojú fèrèsé rẹ̀ yóò tóbi.’ A ó sì fi igi kedari bò ó, a ó fi ohun aláwọ̀ pupa ṣe é ní ọ̀ṣọ́.
15 Est-ce que tu régneras, parce que tu te compares au cèdre? ton père n’a-t-il pas mangé et bu, et rendu le jugement et la justice, alors que tout allait bien pour lui?
“Ìwọ ó ha jẹ ọba kí ìwọ kí ó lè ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ igi kedari? Baba rẹ kò ha ní ohun jíjẹ àti mímu? Ó ṣe ohun tí ó tọ́ àti òdodo, nítorí náà ó dára fún un.
16 Et il a jugé la cause du pauvre et de l’indigent pour son propre bonheur; n’est-ce pas parce qu’il m’a connu, dit le Seigneur?
Ó gbèjà òtòṣì àti aláìní, ohun gbogbo sì dára fún un. Bí a ti mọ̀ mí kọ́ ni èyí?” ni Olúwa wí.
17 Mais tes yeux et ton cœur sont portés seulement à l’avarice, à répandre le sang innocent, à la calomnie, et à courir après les mauvaises œuvres.
“Ṣùgbọ́n ojú rẹ àti ọkàn rẹ wà lára èrè àìṣòótọ́ láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀ ìnilára àti ìlọ́nilọ́wọ́gbà.”
18 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur à Joakim, fils de Josias et roi de Juda: On ne se désolera pas à son sujet, en disant: Malheur, frère! Malheur, sœur! on ne fera pas retentir pour lui: Malheur, maître! Malheur, illustre!
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí, nípa Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda: “Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, arákùnrin mi! Ó ṣe, arábìnrin mi!’ Wọn kì yóò ṣọ̀fọ̀ fún un: wí pé, ‘Ó ṣe, olúwa tàbí ó ṣe ọlọ́lá!’
19 De la sépulture d’un âne il sera enseveli; pourri, il sera jeté hors des portes de Jérusalem.
A ó sin òkú rẹ̀ bí i kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí a wọ́ sọnù láti ẹnu ibodè Jerusalẹmu.”
20 Monte sur le Liban, et crie; et en Basan élève ta voix, et crie aux passants qu’ils ont été brisés, tous ceux qui t’aimaient.
“Gòkè lọ sí Lebanoni, kígbe síta, kí a sì gbọ́ ohùn rẹ ní Baṣani, kí o kígbe sókè láti Abarimu, nítorí a ti ṣẹ́ gbogbo olùfẹ́ rẹ túútúú.
21 Je t’ai parlé dans le temps de ton abondance, et tu as dit: Je n’écouterai pas; ça a été ta voie dès ta jeunesse, que de ne pas écouter ma parole.
Èmi ti kìlọ̀ fún ọ nígbà tí o rò pé kò séwu, ṣùgbọ́n o sọ pé, ‘Èmi kì yóò fetísílẹ̀!’ Èyí ni iṣẹ́ rẹ láti ìgbà èwe rẹ, ìwọ kò fìgbà kan gba ohùn mi gbọ́.
22 Le vent paîtra tous tes pasteurs, et tes amants iront en captivité; et alors tu seras confondue, et tu rougiras de toute ta malice.
Ẹ̀fúùfù yóò lé gbogbo àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ̀ lọ, gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ yóò lọ sí ìgbèkùn, nígbà náà ni a ó kẹ́gàn rẹ, ojú yóò tì ọ́ nítorí gbogbo ìwà búburú rẹ.
23 Toi qui es assise sur le Liban, et qui as fait ton nid dans les cèdres, comment as-tu gémi profondément, lorsque te sont venues des douleurs, comme celles d’une femme en travail?
Ìwọ tí ń gbé ‘Lebanoni,’ tí ó tẹ́ ìtẹ́ sí orí igi kedari, ìwọ yóò ti kérora pẹ́ tó, nígbà tí ìrora bá dé bá ọ, ìrora bí i ti obìnrin tí ń rọbí!
24 Je vis, moi, dit le Seigneur; quand Jéchonias, fils de Joakim, roi de Juda, serait un anneau à ma main droite, je l’en arracherai.
“Dájúdájú bí èmi ti wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Bí Koniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda tilẹ̀ jẹ́ òrùka èdìdì lọ́wọ́ ọ̀tún mi, síbẹ̀ èmi ó fà ọ́ tu kúrò níbẹ̀.
25 Et je te livrerai à la main de ceux qui cherchent ton âme, et à la main de ceux dont tu redoutes la face, et à la main de Nabuchodonosor, roi de Babylone, et à la main des Chaldéens.
Èmi ó sì fà ọ́ lé ọwọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí rẹ, àwọn tí ìwọ bẹ̀rù, àní lé ọwọ́ Nebukadnessari, ọba Babeli àti ọwọ́ àwọn ará Babeli.
26 Je t’enverrai, toi et ta mère qui t’a enfantée, dans une terre étrangère dans laquelle vous n’êtes pas nés, et vous y mourrez.
Èmi ó fi ìwọ àti ìyá tí ó bí ọ sọ̀kò sí ilẹ̀ mìíràn, níbi tí a kò bí ẹnikẹ́ni nínú yín sí. Níbẹ̀ ni ẹ̀yin méjèèjì yóò kú sí.
27 Et quant à la terre vers laquelle eux-mêmes élèvent leur âme pour y retourner, ils n’y retourneront pas.
Ẹ̀yin kì yóò padà sí ilẹ̀ tí ẹ̀yin fẹ́ mọ́ láéláé.”
28 N’est-ce pas un vase d’argile, et un vase brisé, que cet homme, Jéchonias? n’est-ce pas un vase sans aucun agrément? pourquoi ont-ils été rejetés, lui et sa race, et jetés dans une terre qu’ils ne connaissaient pas?
Ǹjẹ́ Jehoiakini ẹni ẹ̀gàn yàtọ̀ sí ìkòkò òfìfo, ohun èlò tí ẹnìkan kò fẹ́? Èéṣe tí a fi òun àti àwọn ọmọ rẹ̀ sókè sí ilẹ̀ tí wọn kò mọ̀.
29 Terre, terre, terre, écoute la parole du Seigneur.
Ìwọ ilẹ̀, ilẹ̀, ilẹ̀, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
30 Voici ce que dit le Seigneur: Inscris cet homme comme stérile, comme un homme qui durant ses jours ne prospérera pas, car il n’y aura pas d’homme de sa race qui s’assiéra sur le trône de David, et qui aura à; l’avenir le pouvoir dans Juda.
Báyìí ni Olúwa wí: “Kọ àkọsílẹ̀ ọkùnrin yìí sínú ìwé gẹ́gẹ́ bí aláìlọ́mọ, ẹni tí kì yóò ṣe rere ní ọjọ́ ayé rẹ̀; nítorí ọ̀kan nínú irú-ọmọ rẹ̀ kì yóò ṣe rere, èyíkéyìí wọn kì yóò jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi tàbí jẹ ọba ní Juda mọ́.”

< Jérémie 22 >