< Isaïe 9 >

1 Dans le premier temps a été allégée la terre de Zabulon, ainsi que la terre de Nephthali; et dans le dernier, a été aggravée la voie de la mer, au-delà du Jourdain, la voie de la Galilée des nations.
Síbẹ̀síbẹ̀, kò ní sí ìpòrúru kankan mọ́ fún àwọn tí ó wà nínú ìbànújẹ́. Nígbà kan rí ó rẹ ilẹ̀ Sebuluni sílẹ̀ àti ilẹ̀ Naftali pẹ̀lú, ṣùgbọ́n ní ọjọ́ iwájú, yóò bu ọ̀wọ̀ fún Galili ti àwọn aláìkọlà, ní ọ̀nà Òkun, ní ẹ̀gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ Jordani.
2 Le peuple qui marchait dans les ténèbres a vu une grande lumière; pour ceux qui habitaient dans la région de l’ombre de la mort, une lumière s’est levée.
Àwọn ènìyàn tí ń rìn nínú òkùnkùn ti rí ìmọ́lẹ̀ ńlá; lórí àwọn tí ń gbé nínú ilẹ̀ òjìji ikú, ní ara wọn ni ìmọ́lẹ̀ mọ́ sí.
3 Vous avez augmenté la nation et vous n’avez pas agrandi sa joie. Ils se réjouiront devant vous, comme ceux qui se réjouissent dans la moisson; et comme exultent les vainqueurs après le butin pris, quand ils partagent les dépouilles.
Ìwọ ti sọ orílẹ̀-èdè di ńlá; wọ́n sì yọ̀ níwájú rẹ gẹ́gẹ́ bí àwọn ènìyàn ti í yọ ayọ̀ ìkórè, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ti í yọ̀ nígbà tí à ń pín ìkógun.
4 Car le joug de son fardeau, la verge de son épaule, et le sceptre de son exacteur, vous en avez triomphé, comme à la journée de Madian.
Nítorí gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí a ṣẹ́gun Midiani, ìwọ ti fọ́ ọ túútúú àjàgà ti ń pa wọ́n lẹ́rù, ọ̀pá tí ó dábùú èjìká wọn, ọ̀gọ aninilára wọn.
5 Parce que tout pillage fait dans le tumulte, et tout vêtement souillé de sang sera en combustion et la pâture du feu.
Gbogbo bàtà jagunjagun tí a ti lò lójú ogun àti gbogbo ẹ̀wù tí a yí nínú ẹ̀jẹ̀, ni yóò wà fún ìjóná, àti ohun èlò iná dídá.
6 Car UN ENFANT NOUS EST NÉ, et un fils nous a été donné; et sa principauté est sur son épaule, et son nom sera appelé Admirable, Conseiller, Dieu, Fort, Père du siècle à venir. Prince de la paix.
Nítorí a bí ọmọ kan fún wa, a fi ọmọkùnrin kan fún wa, ìjọba yóò sì wà ní èjìká rẹ̀. A ó sì máa pè é ní Ìyanu Olùdámọ̀ràn, Ọlọ́run Alágbára, Baba ayérayé, Ọmọ ọba aládé Àlàáfíà.
7 Son empire s’accroîtra et la paix n’aura pas de fin; sur le trône de David et sur son royaume il s’assiéra pour raffermir et le fortifier dans le jugement et la justice, dès maintenant à tout jamais. Le zèle du Seigneur des armées fera cela.
Ní ti gbígbòòrò Ìjọba rẹ̀ àti àlàáfíà rẹ̀ ni kì yóò ní ìpẹ̀kun. Yóò jẹ ọba lórí ìtẹ́ Dafidi àti lórí ẹ̀kún un rẹ̀ gbogbo, nípa ìfìdímúlẹ̀ àti ìgbéró rẹ̀, pẹ̀lú òtítọ́ àti òdodo láti ìgbà náà lọ àti títí láéláé. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
8 Le Seigneur a envoyé une parole dans Jacob, et elle est tombée dans Israël.
Olúwa ti dojú iṣẹ́ kan kọ Jakọbu; yóò sì wá sórí Israẹli.
9 Et tout le peuple d’Ephraïm le saura de même que ceux qui habitent Samarie, qui disent dans l’orgueil et l’enflure du cœur:
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì mọ̀ ọ́n— Efraimu àti gbogbo olùgbé Samaria— tí ó sọ pẹ̀lú ìgbéraga àti gààrù àyà pé.
10 Les briques sont tombées; mais nous bâtirons avec des pierres de taille; on a coupé nos sycomores, nous y substituerons des cèdres.
Àwọn bíríkì ti wó lulẹ̀ ṣùgbọ́n a ó tún un kọ́ pẹ̀lú òkúta dídán, a ti gé àwọn igi sikamore lulẹ̀ ṣùgbọ́n igi kedari ní a ó fi dípò wọn.
11 Et le Seigneur élèvera les ennemis de Rasin sur lui, et il fera venir tous ses ennemis en foule:
Ṣùgbọ́n Olúwa fún àwọn ọ̀tá Resini ní agbára láti dojúkọ wọ́n ó sì ti rú àwọn ọ̀tá wọn sókè.
12 La Syrie de l’Orient, les Philistins de l’Occident; et ils dévoreront Israël de toute leur bouche. Avec toutes ces choses sa fureur n’a pas été détournée, mais sa main est encore étendue;
Àwọn ará Aramu láti ìlà-oòrùn àti Filistini láti ìwọ̀-oòrùn. Wọ́n sì fi gbogbo ẹnu jẹ Israẹli run. Ní gbogbo èyí ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ṣùgbọ́n ọwọ́ rẹ̀ nà jáde síbẹ̀.
13 Et le peuple n’est pas revenu vers celui qui le frappait, et ils n’ont pas recherché le Seigneur des armées.
Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn náà kò tí ì yípadà sí ẹni náà tí ó lù wọ́n bẹ́ẹ̀ ni wọ́n kò wá Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
14 Et le Seigneur retranchera d’Israël, dans un même jour, la tête et la queue, celui qui plie et celui qui réfrène.
Nítorí náà ni Olúwa yóò ṣe ké àti orí àti ìrù kúrò ní Israẹli, àti ọ̀wá ọ̀pẹ àti koríko odò ní ọjọ́ kan ṣoṣo,
15 Le vieillard et l’homme en dignité, c’est la tête; et le prophète qui enseigne le mensonge, c’est la queue.
àwọn àgbàgbà, àti àwọn gbajúmọ̀ ní orí, àwọn wòlíì tí ń kọ́ni ní irọ́ ni ìrù.
16 Et ceux qui appellent ce peuple heureux seront des séducteurs; et ceux qui sont appelés heureux seront précipités.
Àwọn tí ó ń tọ́ àwọn ènìyàn wọ̀nyí ṣì wọ́n lọ́nà, àwọn tí a sì tọ́ ni a ń sin sí ìparun.
17 À cause de cela le Seigneur ne mettera pas sa joie dans ses jeunes hommes; et de ses orphelins, et de ses veuves, il n’aura pas pitié; parce que tous sont hypocrites et méchants, et que toute bouche a parlé folie. Avec toutes ces choses sa fureur n’a pas été détournée, mais sa main est encore étendue.
Nítorí náà, Olúwa kì yóò dunnú sí àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin tàbí kí ó káàánú àwọn aláìní baba àti opó, nítorí pé gbogbo wọn jẹ́ ìkà àti aláìmọ Ọlọ́run, ibi ni ó ti ẹnu wọn jáde. Síbẹ̀, fún gbogbo èyí, ìbínú rẹ̀ kò yí kúrò ọwọ́ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.
18 Car comme un feu, l’impiété s’est allumée, et elle dévorera la ronce et l’épine; et elle s’embrasera comme dans l’épaisseur d’une forêt; et une fumée formera des tourbillons en s’élevant.
Nítòótọ́ ìwà búburú ń jóni bí iná, yóò jó ẹ̀wọ̀n àti ẹ̀gún run, yóò sì rán nínú pàǹtí igbó, tó bẹ́ẹ̀ tí yóò fi gòkè lọ bí ọ̀wọ́n èéfín ti í gòkè.
19 Par la colère du Seigneur des armées, la terre a été bouleversée, et le peuple sera comme la pâture du feu; l’homme n’épargnera pas son frère.
Nípasẹ̀ ìbínú Olúwa àwọn ọmọ-ogun ilẹ̀ náà yóò di gbígbẹ àwọn ènìyàn yóò sì di ohun ìdáná, ẹnìkan kì yóò sì dá arákùnrin rẹ̀ sí.
20 Et il se tournera à droite et il aura faim; et il mangera en allant à gauche, et il ne sera pas rassasié; chacun dévorera la chair de son bras: Manassé dévorera Ephraïm, et Ephraïm Manassé; et eux ensemble seront contre Juda.
Ní apá ọ̀tún wọn yóò jẹrun, síbẹ̀ ebi yóò sì máa pa wọ́n, ní apá òsì, wọn yóò jẹ, ṣùgbọ́n, kò ní tẹ́ wọn lọ́rùn. Ẹnìkọ̀ọ̀kan yóò sì máa jẹ ẹran-ara apá rẹ̀.
21 Avec toutes ces choses sa fureur n’a pas été détournée, mais sa main est encore étendue.
Manase yóò máa jẹ Efraimu, nígbà tí Efraimu yóò jẹ Manase wọn yóò parapọ̀ dojúkọ Juda. Síbẹ̀síbẹ̀, ìbínú un rẹ̀ kò yí kúrò Ọwọ́ọ rẹ̀ sì wà ní gbígbéró.

< Isaïe 9 >