< Isaïe 59 >

1 Voici que la main du Seigneur n’est point raccourcie pour ne pouvoir sauver, et son oreille n’est point appesantie pour ne pas écouter;
Lódodo ọwọ́ Olúwa kò kúrú láti gbàlà, tàbí kí etí rẹ̀ wúwo láti gbọ́.
2 Mais vos iniquités ont mis une séparation entre vous et votre Dieu, et vos péchés vous ont caché sa face, afin qu’il ne vous écoutât point.
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ yín ló ti yà yín kúrò lọ́dọ̀ Ọlọ́run yín; ẹ̀ṣẹ̀ yín ti fi ojú u rẹ̀ pamọ́ fún un yín tó bẹ́ẹ̀ tí òun kò fi le gbọ́.
3 Car vos mains se sont souillées de sang, et vos doigts d’iniquité; vos lèvres ont parlé le mensonge, votre langue profère l’iniquité.
Nítorí ọwọ́ yín di aláìmọ́ fún ẹ̀jẹ̀, àti ìka ọwọ́ yín fún ẹ̀bi. Ètè yín ń pa irọ́ púpọ̀, ahọ́n yín sì ń sọ̀rọ̀ nǹkan ibi.
4 Il n’est personne qui invoque la justice, et il n’est personne qui juge dans la vérité; mais ils se confient au néant, et ne font entendre que des paroles vaines; ils ont conçu la peine et ils ont enfanté l’iniquité.
Kò sí ẹni tí ó béèrè fún ìdájọ́ òdodo; kò sí ẹni tí ó ro ẹjọ́ rẹ̀ pẹ̀lú òtítọ́. Wọ́n gbẹ́kẹ̀lé àwíjàre asán àti ọ̀rọ̀ irọ́; wọ́n lóyún ìkà, wọn sì bí wàhálà.
5 Ils ont fait éclore des œufs d’aspic, et ils ont ourdi des toiles d’araignée; celui qui mangera de leurs œufs mourra; et de ce qui aura été couvé sortira un basilic.
Wọn ń pa ẹ̀yin paramọ́lẹ̀ wọn sì ń ta owú aláǹtakùn. Ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ ẹyin wọn yóò kú, àti nígbà tí a pa ọ̀kan, paramọ́lẹ̀ ni ó jáde.
6 Leurs toiles ne serviront pas de vêtement: ils ne se revêtiront pas de leurs œuvres; leurs œuvres sont inutiles, et une œuvre d’iniquité est dans leurs mains.
Òwú wọn kò wúlò fún aṣọ rírán; wọn kò lè fi aṣọ tí wọ́n hun bo ara wọn. Iṣẹ́ wọn jẹ́ ti ibi, ìwà jàǹdùkú sì kún ọwọ́ wọn.
7 Leurs pieds courent au mal, et ils se hâtent pour répandre un sang innocent; leurs pensées sont des pensées inutiles; le ravage et la destruction sont dans leurs voies.
Ẹsẹ̀ wọn yára bọ́ sínú ẹ̀ṣẹ̀; wọ́n yára láti ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀. Èrò wọn sì jẹ́ èrò ibi; ìparun àti ìdahoro ni ó wà ní ṣíṣe àmì ọ̀nà wọn.
8 Ils n’ont pas connu la voie de la paix, et il n’y a pas de jugement dans leurs démarches; leurs sentiers sont devenus tortus pour eux; quiconque y marche ignore la paix.
Ọ̀nà àlàáfíà èyí ni wọn kò mọ̀; kò sí òdodo ní ojú ọ̀nà wọn wọ́n ti sọ wọ́n dì ọ̀nà kọ́rọkọ̀rọ, kò sí ẹni tí ó tọ ọ̀nà yìí tí yóò rí àlàáfíà.
9 À cause de cela le jugement s’est éloigné de nous, et la justice ne nous atteindra pas; nous avons attendu la lumière, et voilà les ténèbres; la splendeur du jour, et c’est au milieu des ténèbres que nous avons marché.
Nítorí èyí ni ẹ̀tọ́ fi jìnnà sí wa, àti tí òdodo kò fi tẹ̀ wá lọ́wọ́. A ń wá ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n gbogbo rẹ̀ jẹ́ òkùnkùn; ìmọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n à ń rìn nínú òjìji.
10 Comme des aveugles nous nous sommes attachés à la muraille, et comme privés de nos yeux, nous avons marché à tâton: nous nous sommes heurtés en plein midi, de même qu’au milieu des ténèbres; nous sommes dans des lieux obscurs comme les morts.
Gẹ́gẹ́ bí afọ́jú à ń táràrà lọ lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri tí a ń wá ọ̀nà wa gẹ́gẹ́ bí ènìyàn tí kò ní ojú. Ní ọ̀sán gangan ni à ń kọsẹ̀ bí ẹni pé alẹ́ ni; láàrín alágbára àwa dàbí òkú.
11 Nous rugirons tous comme les ours, et comme les colombes, méditant, nous gémirons; nous avons attendu le jugement, et il n’est pas venu; le salut, et il s’est éloigné de nous.
Gbogbo wa là ń ké bí i beari; àwa pohùnréré ẹkún bí àdàbà. A ń wá ìdájọ́ òdodo ṣùgbọ́n kò sí; à ń wọ́nà fún ìtúsílẹ̀, ṣùgbọ́n ó jìnnà réré.
12 Car nos iniquités se sont multipliées devant vous, et nos péchés nous ont répondu; parce que nos crimes sont avec nous, et nous avons connu nos iniquités:
Nítorí àwọn àṣìṣe wa pọ̀ níwájú rẹ, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa sì ń jẹ́rìí takò wá. Àwọn àìṣedéédéé wa sì wà pẹ̀lú wa, àwa pẹ̀lú sì mọ àìṣedéédéé wa,
13 Pécher et mentir contre le Seigneur; et nous nous sommes détournés pour ne pas suivre notre Dieu, pour proférer la calomnie et la révolte; nous avons conçu et proféré de notre cœur des paroles de mensonge.
ọ̀tẹ̀ àti àrékérekè wa sí Olúwa, kíkọ ẹ̀yìn wa sí Ọlọ́run, dídá yánpọnyánrin àti ìnilára sílẹ̀, pípààrọ̀ tí ọkàn wa ti gbèrò síta.
14 Et le jugement est retourné en arrière; et la justice s’est tenue au loin; parce que la vérité est tombée sur la place publique, et l’équité n’a pu y entrer.
Nítorí èyí ni a ṣe lé ìdájọ́ òdodo sẹ́yìn, àti ti òdodo dúró lókèèrè; òtítọ́ ti ṣubú ní òpópó ọ̀nà, òdodo kò sì le è wọlé.
15 Et la vérité est devenue en oubli; et celui qui s’est retiré du mal a été exposé en proie; le Seigneur l’a vu; et mal a paru à ses yeux qu’il n’y eût point de justice.
A kò rí òtítọ́ mọ́, àti ẹni tí ó bá sá fun ibi tì di ìjẹ. Olúwa wò ó ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ pé kò sí ìdájọ́ òdodo.
16 Et il a vu qu’il n’y avait point d’homme, et il s’est étonné que personne ne s’opposât à ces maux, et son propre bras l’a sauvé, et sa justice elle même l’a soutenu.
Òun rí i pé kò sí ẹnìkan, àyà fò ó pé kò sí ẹnìkan láti ṣèrànwọ́; nítorí apá òun tìkára rẹ̀ ló ṣiṣẹ́ ìgbàlà fún ara rẹ̀, àti òdodo òun tìkára rẹ̀ ló gbé e ró.
17 Il s’est revêtu de la justice comme d’une cuirasse, et le casque de salut a été sur sa tête; il s’est revêtu des vêtements de vengeance, il s’est couvert comme d’un manteau de zèle.
Ó gbé òdodo wọ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbàyà rẹ̀, àti àṣíborí ìgbàlà ní orí rẹ̀; ó gbé ẹ̀wù ẹ̀san wọ̀ ó sì yí ara rẹ̀ ní ìtara bí ẹ̀wù.
18 Comme pour exercer sa vengeance, comme pour imposer le salaire de son indignation à ses ennemis et payer de retour ses adversaires: aux îles il rendra la pareille.
Gẹ́gẹ́ bí ohun tí wọ́n ti ṣe, bẹ́ẹ̀ ni yóò san án ìbínú fún àwọn ọ̀tá rẹ̀ àti ẹ̀san fún àwọn ọ̀tá rẹ̀; òun yóò san án fún àwọn erékùṣù ẹ̀tọ́ wọn.
19 Et ils craindront, ceux qui sont de l’occident, le nom du Seigneur, et ceux qui sont du levant, sa gloire; lorsqu’il viendra comme un fleuve impétueux, que le souffle du Seigneur agite;
Láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn ènìyàn yóò bẹ̀rù orúkọ Olúwa, àti láti ìlà-oòrùn, wọn yóò bọ̀wọ̀ fún ògo rẹ̀. Nítorí òun yóò wá gẹ́gẹ́ bí i rírú omi èyí tí èémí Olúwa ń tì lọ.
20 Et que viendra un rédempteur pour Sion, et pour ceux qui dans Jacob reviennent de l’iniquité, dit le Seigneur.
“Olùdáǹdè yóò wá sí Sioni, sí àwọn tí ó wà ní Jakọbu tí ó ronúpìwàdà ẹ̀ṣẹ̀ wọn,” ni Olúwa wí.
21 Voici mon alliance avec eux, dit le Seigneur: Mon esprit, qui est en toi, et mes paroles que j’ai mises en ta bouche ne s’éloigneront pas de ta bouche, ni de la bouche de ta postérité, ni de la bouche de la postérité de ta postérité, depuis ce moment jusque dans l’éternité, dit le Seigneur.
“Àti fún èmi, májẹ̀mú mi pẹ̀lú wọn nìyìí,” ni Olúwa wí, “Ẹ̀mí mi, tí ó wà nínú yín, àti ọ̀rọ̀ mi tí mo ti fi sí ẹnu yín, kì yóò kúrò lẹ́nu yín, tàbí lẹ́nu àwọn ọmọ yín, tàbí láti ẹnu àwọn ìrandíran wọn láti àkókò yìí lọ àti títí láéláé,” ni Olúwa wí.

< Isaïe 59 >