< Isaïe 46 >

1 Bel a été rompu; Nabo a été brisé; leurs simulacres ont été mis sur des bêtes et sur des animaux de service; ces fardeaux que vous portiez allaient par leur grand poids jusqu’à vous lasser.
Beli tẹrí i rẹ̀ ba, Nebo bẹ̀rẹ̀ mọ́lẹ̀; àwọn ère wọn ni àwọn ẹranko rù. Àwọn ère tí wọ́n ń rù káàkiri ti di àjàgà sí wọn lọ́rùn, ẹrù fún àwọn tí àárẹ̀ mú.
2 Ils ont péri et ont été brisés tous ensemble; ils n’ont pu sauver celui qui les portait, et ils iront eux-mêmes en captivité.
Wọ́n bẹ̀rẹ̀ wọ́n sì foríbalẹ̀ papọ̀; wọn kò lè gba ẹrù náà, àwọn pẹ̀lú ni a kó lọ ní ìgbèkùn.
3 Ecoutez-moi, maison de Jacob, et vous tous, restes de la maison d’Israël, qui êtes portés dans mon sein, qui êtes renfermés dans mes entrailles.
“Tẹ́tí sí mi, ìwọ ilé Jakọbu, gbogbo ẹ̀yin tí ó ṣẹ́kù nínú ilé Israẹli, ìwọ tí mo ti gbéró láti ìgbà tí o ti wà nínú oyún, tí mo sì ti ń pọ̀n láti ìgbà tí a ti bí ọ.
4 Moi-même je vous porterai jusqu’à la vieillesse, jusqu’aux cheveux blancs; c’est moi qui vous ai faits, et c’est moi qui vous soutiendrai; c’est moi qui vous porterai, et vous sauverai.
Pẹ̀lúpẹ̀lú sí àwọn arúgbó àti ewú orí yín, Èmi ni ẹni náà, Èmi ni ẹni tí yóò gbé ọ ró. Èmi ti mọ ọ́, èmi yóò sì gbé ọ; Èmi yóò dì ọ́ mú èmi ó sì gbà ọ́ sílẹ̀.
5 À qui m’avez-vous assimilé, égalé, comparé et rendu semblable?
“Ta ni ìwọ yóò fi mí wé tàbí ta ni èmi yóò bá dọ́gba? Ta ni ìwọ yóò fi ṣe àkàwé mi tí àwa yóò jọ fi ara wé ara?
6 Vous qui tirez de l’or de la bourse, et pesez de l’argent dans la balance; louant un orfèvre afin qu’il fasse un Dieu; et on se prosterne et on adore.
Ọ̀pọ̀ da wúrà sílẹ̀ nínú àpò wọn wọ́n sì wọn fàdákà lórí òsùwọ̀n; wọ́n bẹ alágbẹ̀dẹ lọ́wẹ̀ láti fi wọ́n ṣe òrìṣà, wọn sì tẹríba láti sìn ín.
7 Ils le chargent sur les épaules pour le porter, et pour le placer en son lieu; il y demeurera et ne sera pas ôté de son lieu; mais lorsqu’on criera vers lui, il n’entendra pas; de la tribulation il ne les sauvera pas.
Wọ́n gbé e lé èjìká wọn, wọ́n rù wọ́n, wọ́n sì gbé e sí ààyè rẹ̀ níbẹ̀ ni ó sì dúró sí. Láti ibẹ̀ náà kò le è paradà. Bí ènìyàn tilẹ̀ pariwo lé e lórí, òun kò le è dáhùn; òun kò lè gbà á nínú ìyọnu rẹ̀.
8 Souvenez-vous de cela et soyez confondus; rentrez dans votre cœur, prévaricateurs.
“Rántí èyí, fi í sí ọkàn rẹ, fi sí ọkàn rẹ, ẹ̀yin ọlọ̀tẹ̀.
9 Rappelez-vous le siècle passé; parce que moi je suis Dieu, et qu’il n’y a plus d’autre Dieu, et qu’il n’y a pas semblable à moi;
Rántí àwọn nǹkan àtẹ̀yìnwá, àwọn ti àtijọ́-tijọ́; Èmi ni Ọlọ́run, kò sì sí ẹlòmíràn; Èmi ni Ọlọ́run, kò sí ẹlòmíràn bí ì mi.
10 Annonçant dès l’origine la fin des temps, et dès le commencement les choses qui ne sont pas encore faites, disant: Ma résolution sera inébranlable, et toute ma volonté s’exécutera;
Mo fi òpin hàn láti ìbẹ̀rẹ̀ wá, láti àtètèkọ́ṣe, ohun tí ó sì ń bọ̀ wá. Mo wí pé, Ète mi yóò dúró, àti pé èmi yóò ṣe ohun tí ó wù mí.
11 J’appelle de l’orient un oiseau, et d’une terre lointaine l’homme de ma volonté; et je l’ai dit, et je l’accomplirai; j’ai formé ce dessein et je l’exécuterai.
Láti ìlà-oòrùn wá ni mo ti pe ẹyẹ ajẹran wá; láti ọ̀nà jíjìn réré, ọkùnrin kan tí yóò mú ète mi ṣẹ. Ohun tí mo ti sọ, òun ni èmi yóò mú ṣẹ; èyí tí mo ti gbèrò, òun ni èmi yóò ṣe.
12 Ecoutez-moi, vous au cœur dur, qui êtes éloignés de la justice.
Gbọ́ tèmi, ẹ̀yin alágídí ọkàn, ìwọ tí ó jìnnà sí òdodo.
13 J’ai rapproché le temps de ma justice, il ne sera pas différé, et mon salut ne tardera pas. J’établirai dans Sion le salut, et dans Israël ma gloire.
Èmi ń mú òdodo mi bọ̀ nítòsí, kò tilẹ̀ jìnnà rárá; àti ìgbàlà mi ni a kì yóò dádúró. Èmi yóò fún Sioni ní ìgbàlà ògo mi fún Israẹli.

< Isaïe 46 >