< Isaïe 33 >

1 Malheur à toi qui pilles; est-ce que toi-même tu ne seras pas aussi pillé? et toi qui méprises, est-ce que toi-même tu ne seras pas méprisé? Lorsque tu auras consommé le pillage, tu seras pillé; lorsque fatigué, tu cesseras de mépriser, tu seras méprisé.
Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun, ìwọ tí a kò tí ì parun! Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀, ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́! Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run; a ó pa ìwọ náà run, nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani, a ó da ìwọ náà.
2 Seigneur, ayez pitié de nous, car c’est vous que nous avons attendu; soyez notre bras dès le matin, et noire salut au temps de la tribulation.
Olúwa ṣàánú fún wa àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ. Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀ ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
3 À la voix de l’ange, des peuples ont fui, et à cause de votre grandeur, des nations ont été dispersées.
Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá, nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
4 Et on amassera vos dépouilles, comme on amasse la sauterelle, comme lorsqu’on en remplit des fosses.
Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú; gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.
5 Le Seigneur a été magnifié, parce qu’il habite dans un lieu élevé; il a rempli Sion de jugement et de justice.
A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga, Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
6 Et la fidélité existera en tes jours; la sagesse et la science seront des richesses de salut; et la crainte du Seigneur est son trésor.
Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀; ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.
7 Voilà que voyant ils crieront au dehors; des anges de paix pleureront amèrement.
Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré ẹkún ní òpópónà; àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
8 Les voies ont été détruites, le passant a cessé d’aller par le sentier, l’alliance est devenue sans effet; il a rejeté des cités, il a compté pour rien les hommes.
Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì, kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà. A ti ba àdéhùn jẹ́, a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí, a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
9 La terre a pleuré, et elle a langui; le Liban a été couvert de confusion et avili; et le Saron est devenu comme un désert; et Basan a été ébranlé ainsi que le Carmel.
Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù, ojú ti Lebanoni ó sì sá Ṣaroni sì dàbí aginjù, àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.
10 Maintenant je me lèverai, dit le Seigneur; maintenant je serai exalté, maintenant je serai élevé.
“Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí. “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga, ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
11 Vous concevrez de la flamme, et vous enfanterez de la paille; votre esprit comme un feu vous dévorera.
Ìwọ lóyún ìyàngbò, o sì bí koríko; èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
12 Les peuples seront comme la cendre après un incendie; comme des épines rassemblées, ils seront brûlés par le feu.
A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú; bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
13 Ecoutez, vous qui êtes au loin, ce que j’ai fait, et connaissez, vous qui êtes proches, ma puissance.
Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun tí mo ti ṣe; ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
14 Les pécheurs ont été atterrés dans Sion; la terreur a saisi les hypocrites; qui de vous pourra habiter avec un feu dévorant? qui de vous habitera avec des flammes éternelles?
Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni; ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́: “Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun? Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
15 Celui qui marche dans la justice, et parle vérité; qui rejette un gain fruit de la calomnie, et secoue ses mains de tout présent; qui bouche ses oreilles, afin de ne pas entendre des paroles de sang, et ferme ses yeux afin de ne pas voir le mal;
Ẹni tí ó ń rìn lódodo tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́, tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi,
16 Celui-là habitera dans des hauts lieux; des roches fortifiées seront sa demeure élevée; le pain lui a été donné, et ses eaux sont fidèles.
Òun náà yóò gbé ní ibi gíga, ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi. A ó mú oúnjẹ fún un, omi rẹ̀ yóò sì dájú.
17 Ses yeux verront un roi dans son éclat; ils apercevront une terre de loin.
Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀ yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
18 Ton cœur méditera la crainte: Où est le savant? où est celui qui pèse les paroles de la loi? où est le maître des petits enfants?
Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá: “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà? Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
19 Tu ne verras pas un peuple impudent, un peuple au discours profond; de manière que tu ne puisses comprendre son langage disert; un peuple dans lequel il n’est aucune sagesse.
Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́, àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin, pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.
20 Regarde, Sion, la ville de nos solennités; tes yeux verront Jérusalem, habitation opulente, tabernacle qui en aucune manière ne pourra être transporté; et ses clous ne seront jamais enlevés, et aucun de ses cordages ne sera rompu;
Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa, ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu, ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà; àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
21 Parce que c’est là seulement que notre Seigneur est magnifique; le lieu occupé par les fleuves offrira des canaux très larges et très spacieux; il n’y passera pas de vaisseau à rames, et la grande trirème ne le traversera pas.
Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ alágbára kan fún wa. Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńlá ńlá àti odò kéékèèké. Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn, ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
22 Car le Seigneur est notre juge, le Seigneur est notre législateur; le Seigneur est notre roi; c’est lui qui nous sauvera.
Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa òun ni ọba wa; òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.
23 Tes cordages se sont relâchés, et ils n’auront plus de force; tel sera ton mât, que tu ne pourras pas étendre ton signal. Alors on partagera les dépouilles et le grand butin; des boiteux même enlèveront du butin.
Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀: Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀, wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn, lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
24 Et un voisin ne dira pas: Je suis las; quant au peuple qui y habitera, l’iniquité lui sera ôtée.
Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,” a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.

< Isaïe 33 >