< Isaïe 3 >

1 Car voici que le dominateur, Seigneur des armées, enlèvera de Jérusalem le robuste et le fort, tout soutien de pain, et tout soutien d’eau;
Kíyèsi i, Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, fẹ́ mú ìpèsè àti ìrànlọ́wọ́ kúrò ní Jerusalẹmu àti Juda gbogbo ìpèsè oúnjẹ àti ìpèsè omi.
2 Le fort et l’homme de guerre, le juge et le prophète, le devin et le vieillard;
Àwọn akíkanjú àti jagunjagun, adájọ́ àti wòlíì, aláfọ̀ṣẹ àti alàgbà,
3 Le chef de cinquante et le vénérable de visage, et le conseiller, et l’habile d’entre les architectes, et celui qui a l’intelligence du langage mystique.
balógun àádọ́ta àti àwọn ènìyàn, onípò gíga; olùdámọ̀ràn, oníṣọ̀nà tí ó dáńtọ́ àti ògbójú oníṣègùn.
4 Et je leur donnerai des enfants pour princes, et des efféminés les domineront.
“Èmi ó sọ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin di aláṣẹ wọn, ọ̀dọ́mọdé lásán làsàn ni yóò sì máa jẹ ọba lórí i wọn.”
5 Et le peuple se précipitera, l’homme sur l’homme, et chacun sur son prochain; l’enfant se soulèvera contre le vieillard, et le plébéien contre le noble.
Àwọn ènìyàn yóò sì máa pọ́n ọmọnìkejì, wọn lójú ẹnìkan sí ẹnìkejì rẹ̀, aládùúgbò sí aládùúgbò rẹ̀. Àwọn ọ̀dọ́ yóò gbógun ti àwọn àgbàgbà, àwọn mẹ̀kúnnù yóò dìde sí ọlọ́lá.
6 L’homme prendra son frère né dans la maison de son père, disant: Tu as un vêtement, sois notre prince; et que cette ruine soit sous ta main.
Ọkùnrin kan yóò di ọ̀kan nínú àwọn arákùnrin rẹ̀ mú, nínú ilé baba rẹ̀, yóò sì wí pé, “Ìwọ́ ní aṣọ, ìwọ máa ṣe olórí wa, sì mójútó àwọn ahoro wọ̀nyí!”
7 Il répondra en ce jour-là, disant: Je ne suis pas médecin, et dans ma maison il n’y a ni pain, ni vêtement; ne m’établissez pas prince du peuple.
Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ náà ni yóò figbe bọnu pé, “Èmi kò ní àtúnṣe kan. Èmi kò ní oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni n ó ní aṣọ nílé, ẹ má fi mí ṣe olórí àwọn ènìyàn náà.”
8 Car Jérusalem s’est écroulée et Juda est renversé; parce que leur langue et leurs inventions sont contre le Seigneur, afin d’irriter les yeux de sa majesté.
Jerusalẹmu ń ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n Juda ń ṣubú lọ, ọ̀rọ̀ àti ìṣe wọn lòdì sí Olúwa, láti mú ojú ògo rẹ̀ bínú.
9 La vue de leur visage leur a répondu, et comme Sodome, ils ont publié leur péché et ne l’ont pas caché; malheur à leur âme, parce que les maux qu’ils avaient faits leur ont été rendus.
Ìwò ojú wọn ń jẹ́rìí lòdì sí wọn, wọ́n ń polongo ẹ̀ṣẹ̀ wọn bí i Sodomu; wọn ò fi pamọ́! Ègbé ni fún wọn! Wọ́n ti mú ìparun wá sórí ara wọn.
10 Dites au juste qu’il est heureux, parce qu’il goûtera le fruit de ses inventions.
Ẹ sọ fún olódodo pé yóò dára fún wọn, nítorí ní àjẹgbádùn ni wọn yóò jẹ èso iṣẹ́ ẹ wọn.
11 Malheur à l’impie livré au mal; car il recevra le salaire des œuvres de ses mains.
Ègbé ni fún ènìyàn búburú! Ìparun wà lórí i wọn, a ó sì san èrè iṣẹ́ tí ọwọ́ wọn ti ṣe fún wọn.
12 Mon peuple a été dépouillé par ses exacteurs, et des femmes les ont dominés. Mon peuple, ceux qui te disent heureux, ceux-là même te trompent; ils détruisent la voie de tes pas.
Àwọn ọ̀dọ́mọdé ni o ń pọ́n àwọn ènìyàn mi lójú àwọn obìnrin ń jẹ ọba lé wọn lórí. Háà! Ènìyàn mi àwọn afinimọ̀nà yín ti ṣì yín lọ́nà, wọn sì mú yín kúrò ní ipa ọ̀nà yín.
13 Le Seigneur est debout pour juger, et il est debout pour juger les peuples.
Olúwa bọ sí ipò rẹ̀ ní ìtẹ́ ìdájọ́ Ó dìde láti dá àwọn ènìyàn lẹ́jọ́.
14 Le Seigneur entrera en jugement avec les anciens et princes de son peuple; car c’est vous qui avez ravagé ma vigne; et la dépouille du pauvre est dans votre maison.
Olúwa dojú ẹjọ́ kọ àwọn àgbàgbà àti àwọn olórí àwọn ènìyàn rẹ̀. “Ẹ̀yin ni ẹ ti run ọgbà àjàrà mi, ogún àwọn tálákà ń bẹ̀ nínú ilé yín.
15 Pourquoi foulez-vous aux pieds mon peuple, et meurtrissez-vous la face des pauvres, dit le Seigneur Dieu des armées?
Kín ni èrò yín láti máa run àwọn ènìyàn mi túútúú tí ẹ sì fojú àwọn tálákà ni gbolẹ̀?” ni Olúwa wí, Olúwa àwọn ọmọ-ogun.
16 Et le Seigneur dit: Parce que les filles de Sion se sont élevées, et qu’elles ont marché le cou tendu, et qu’elles allaient en faisant des signes des yeux, et qu’elles faisaient du bruit avec leurs pieds, en marchant, et quelles s’avançaient d’un pas mesuré:
Olúwa wí pé, “Àwọn obìnrin Sioni jẹ́ agbéraga, wọn ń rìn lọ pẹ̀lú ọrùn tí ó nà tàntàn, tí wọn ń fojú pe ọkùnrin, tí wọn ń sọ̀dí bí wọ́n ti ń yan lọ pẹ̀lú ohun ọ̀ṣọ́ tí ń mì wọnjanwọnjan lọ́rùn ẹsẹ̀ wọn.
17 Le Seigneur rendra chauve la tête des filles de Sion, et le Seigneur les dépouillera de leur chevelure.
Nítorí náà Olúwa yóò mú egbò wá sórí àwọn obìnrin Sioni, Olúwa yóò sì pá wọn ní agbárí.”
18 En ce jour-là, le Seigneur leur ôtera l’ornement des chaussures, et les croissants,
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò já ọ̀ṣọ́ wọn gbà kúrò ti ọwọ́ àti gèlè àti ẹ̀gbà ọrùn tí ó dàbí òṣùpá
19 Et les colliers, et les carcans, et les bracelets, et les mitres,
gbogbo yẹtí, ẹ̀gbà ọwọ́ àti ìbòjú,
20 Les aiguilles de tête, et les périscélides, et les petits colliers, et les boîtes de parfum, et les pendants d’oreilles,
gbogbo gèlè, ẹ̀gbà ọrùn, ẹsẹ̀ àti àyà, àwọn ìgò tùràrí àti òògùn,
21 Et les bagues, et les pierres précieuses, qui pendent sur leur front,
òrùka ọwọ́ àti ti imú,
22 Et les vêtements de rechange, et les écharpes, et les linges précieux, et les aiguilles,
àwọn àtàtà aṣọ, àwọ̀lékè, agbádá àti àpamọ́wọ́,
23 Et les miroirs, et les fins tissus, et les bandeaux, et les vêtements d’été.
dígí wọn, aṣọ funfun nigínnigín ìbòrí àti ìbòjú.
24 Et ce sera, au lieu d’une suave odeur, la puanteur, et au lieu d’une ceinture, une corde, et au lieu d’une chevelure frisée, la calvitie, et au lieu de la bandelette qui soutient leur gorge, un cilice.
Dípò òórùn dídùn, òórùn búburú ni yóò wá, okùn ni yóò wà dípò àmùrè, orí pípá ni yóò dípò irun ti a ṣe ní ọ̀ṣọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ ni yóò dípò aṣọ ẹ̀yẹ ìjóná dípò ẹwà.
25 Tes hommes aussi les plus beaux tomberont sous le glaive, et tes forts dans le combat.
Àwọn ọkùnrin rẹ yóò ti ipa idà ṣubú, àti àwọn jagunjagun rẹ̀ lójú ogun.
26 Et tes portes seront dans la tristesse et dans les larmes, et désolée, elle s’assiéra sur la terre.
Àwọn bodè Sioni yóò sọkún kíkorò, wọn ó ṣọ̀fọ̀, nítorí ó dahoro, yóò jókòó ní orí ilẹ̀.

< Isaïe 3 >