< Isaïe 27 >
1 En ce jour-là Dieu visitera avec son glaive dur et grand et fort, Léviathan, serpent levier, Léviathan, serpent tortueux, et il tuera le grand poisson qui est dans la mer.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò fi idà rẹ̀ jẹ ni ní yà idà rẹ̀ a mú bí iná tí ó tóbi tí ó sì lágbára Lefitani ejò tí ń yọ̀ tẹ̀ẹ̀rẹ̀ n nì, Lefitani ejò tí ń lọ́ bìrìkìtì; Òun yóò sì pa ẹ̀mí búburú inú Òkun náà.
2 En ce jour-là la vigne du vin pur le chantera.
Ní ọjọ́ náà, “Kọrin nípa ọgbà àjàrà eléso kan.
3 Moi, le Seigneur qui la garde, je l’arroserai soudain; de peur qu’elle ne soit endommagée, nuit et jour je la garde.
Èmi Olúwa ń bojútó o, Èmi ó bomirin ín láti ìgbàdégbà. Èmi ó ṣọ́ ọ tọ̀sán tòru kí ẹnikẹ́ni má ba à pa á lára.
4 Je n’ai pas d’indignation; qui me donnera une épine ou une ronce dans le combat? je marcherai dessus, et j’y mettrai aussi le feu?
Inú kò bí mi. Bí ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n bá dojú ìjà kọ mí! Èmi yóò dìde sí wọn ní ogun, Èmi yóò sì dáná sun gbogbo wọn.
5 Ou plutôt retiendra-t-il ma puissance, fera-t-il la paix avec moi, fera-t-il la paix avec moi?
Bí bẹ́ẹ̀ kọ́, jẹ́ kí wọn wá sọ́dọ̀ mi fún ààbò; jẹ́ kí wọ́n wá àlàáfíà pẹ̀lú mi, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí wọn wá àlàáfíà pẹ̀lú mi.”
6 Ceux qui entrent impétueusement dans Jacob, Israël fleurira et germera pour eux, et ils rempliront la face du globe de semence.
Ní ọjọ́ iwájú Jakọbu yóò ta gbòǹgbò, Israẹli yóò tanná yóò sì rudi èso rẹ̀ yóò sì kún gbogbo ayé.
7 Est-ce que le Seigneur a frappé Israël d’une plaie semblable à celle dont l’a frappé l’ennemi? ou Israël a-t-il été tué, comme le Seigneur a tué ceux qu’il a tués à l’ennemi?
Ǹjẹ́ Olúwa ti lù ú gẹ́gẹ́ bí ó ti lu àwọn tí ó lù ú bolẹ̀? Ǹjẹ́ a ti pa á gẹ́gẹ́ bí a ti pa àwọn tí ó pa á?
8 C’est avec mesure contre mesure que lorsqu’elle sera rejetée, vous la jugerez; le Seigneur a médité en son esprit sévère pour le jour d’une chaleur extrême.
Nípa ogun jíjà àti ìjìyà ti o le ni ó fi dojúkọ ọ́ pẹ̀lú ìjì gbígbóná ni ó lé e jáde, gẹ́gẹ́ bí ọjọ́ tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn fẹ́.
9 C’est pourquoi de cette manière sera remise son iniquité à la maison de Jacob; et tout le fruit de ce châtiment, c’est que son péché soit expié, lorsqu’Israël aura brisé toutes les pierres de l’autel comme des pierres de chaux, et que ne seront plus debout les bois sacrés et les temples.
Nítorí èyí báyìí ni ètùtù yóò ṣe wà fún ẹ̀ṣẹ̀ Jakọbu, èyí ni yóò sì jẹ́ èso kíkún ti ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀ rẹ. Nígbà tí ó bá mú kí àwọn òkúta pẹpẹ dàbí òkúta ẹfun tí a fọ́ sí wẹ́wẹ́, kì yóò sí ère Aṣerah tàbí pẹpẹ tùràrí tí yóò wà ní ìdúró.
10 Car la cité fortifiée sera désolée, la belle ville sera délaissée et abandonnée comme un désert; là paîtra le veau, et là il se reposera, et mangera les sommités de ses rameaux.
Ìlú olódi náà ti dahoro, ibùdó ìkọ̀sílẹ̀, tí a kọ̀ tì gẹ́gẹ́ bí aginjù; níbẹ̀ ni àwọn ọmọ màlúù ti ń jẹ oko níbẹ̀ ni wọn ń sùn sílẹ̀; wọn sì jẹ gbogbo ẹ̀ka rẹ̀ tán.
11 Ses moissons, desséchées, seront broyées; des femmes viendront et l’instruiront; car ce n’est pas un peuple sage; à cause de cela, il n’aura pas pitié de lui, celui qui l’a fait; et celui qui l’a formé ne l’épargnera pas.
Nígbà tí àwọn ẹ̀ka rẹ̀ bá rọ, a ó ya wọn dànù àwọn obìnrin dé, wọ́n sì fi wọ́n dáná nítorí aláìlóye ènìyàn ni wọn jẹ́, nítorí náà ni ẹni tí ó dá wọn kì yóò ṣàánú fún wọn; bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó mọ wọn kì yóò sì fi ojúrere wò wọ́n.
12 Et il arrivera en ce jour-là que le Seigneur frappera depuis le lit du fleuve jusqu’au torrent de l’Egypte; et vous, vous serez rassemblés un à un, fils d’Israël.
Ní ọjọ́ náà Olúwa yóò sì kó oore láti ìṣàn omi odo Eufurate wá títí dé Wadi ti Ejibiti, àti ìwọ, ìwọ ọmọ Israẹli, ni a ó kójọ ní ọ̀kọ̀ọ̀kan.
13 Et il arrivera en ce jour-là qu’on sonnera d’une grande trompette, et ils viendront de la terre des Assyriens, ceux qui y étaient perdus, et ceux qui avaient été jetés sur la terre d’Egypte, et ils adoreront le Seigneur sur la montagne sainte, à Jérusalem.
Àti ní ọjọ́ náà, a ó fun fèrè ńlá kan. Gbogbo àwọn tí ń ṣègbé lọ ní Asiria àti àwọn tí ń ṣe àtìpó ní Ejibiti yóò wá sin Olúwa ní òkè mímọ́ ní Jerusalẹmu.