< Isaïe 2 >
1 Parole qu’a vue Isaïe, fils d’Amos, touchant Juda et Jérusalem.
Èyí ni ohun tí Isaiah ọmọ Amosi rí nípa Juda àti Jerusalẹmu.
2 Et il arrivera dans les derniers jours que la montagne préparée pour la demeure du Seigneur sera établie sur le sommet des montagnes, et elle sera élevée au-dessus des collines, et tous les peuples y afflueront.
Ní ìgbẹ̀yìn ọjọ́ òkè tẹmpili Olúwa ni a ó fi ìdí rẹ̀ kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olú nínú àwọn òkè, a ó sì gbé e ga ju àwọn òkè kéékèèké lọ, gbogbo orílẹ̀-èdè yóò sì máa sàn sínú un rẹ̀.
3 Et beaucoup de peuples iront et diront: Venez, et montons à la montagne du Seigneur, et à la maison du Dieu de Jacob, et il nous enseignera ses voies, et nous marcherons dans ses sentiers; parce que de Sion sortira la loi, et la parole du Seigneur de Jérusalem.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn ni yóò wá, wọn yóò sì wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí á gòkè ńlá Olúwa, àti sí ilé Ọlọ́run Jakọbu. Òun yóò kọ́ wa ní ọ̀nà rẹ̀, kí àwa kí ó lè rìn ní ọ̀nà rẹ̀.” Òfin yóò jáde láti Sioni wá, àti ọ̀rọ̀ Olúwa láti Jerusalẹmu.
4 Et il jugera les nations, et il convaincra beaucoup de peuples; et de leurs glaives ils forgeront des socs de charrue, et de leurs lances des faux; une nation ne lèvera pas le glaive contre une autre nation, elles ne s’exerceront plus au combat.
Òun ó ṣe ìdájọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì parí aáwọ̀ fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn. Wọn yóò fi idà wọn rọ ọkọ́ ìtulẹ̀, wọn yóò sì fi ọ̀kọ̀ wọn rọ dòjé. Orílẹ̀-èdè kì yóò sì gbé idà sí orílẹ̀-èdè mọ́, bẹ́ẹ̀ ní wọn kì yóò kọ́ ogun jíjà mọ́.
5 Maison de Jacob, venez, et marchons à la lumière du Seigneur.
Wá, ẹ̀yìn ará ilé e Jakọbu, ẹ jẹ́ kí a rìn nínú ìmọ́lẹ̀ Olúwa.
6 Car vous avez rejeté votre peuple, la maison de Jacob; parce qu’ils ont été remplis comme autrefois, qu’ils ont eu des augures comme les Philistins, et qu’ils se sont attachés à des enfants étrangers.
Ìwọ ti kọ àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, ìwọ ilé Jakọbu. Wọ́n kún fún ìgbàgbọ́ tí kò lẹ́sẹ̀ nílẹ̀ tí ó ti ìlà-oòrùn wá, wọ́n ń wo iṣẹ́ gẹ́gẹ́ bí àwọn Filistini, wọ́n ń pa ọwọ́ pọ̀ pẹ̀lú àwọn abọ̀rìṣà.
7 Sa terre est remplie d’argent et d’or; et il n’y a pas de bornes à ses trésors;
Ilẹ̀ wọn kún fún fàdákà àti wúrà, ìṣúra wọn kò sì ní òpin. Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ẹṣin, kẹ̀kẹ́ ogun wọn kò sì lópin.
8 Et sa terre est remplie de chevaux, et ses quadriges sont innombrables. Et sa terre est remplie d’idoles; ils ont adoré l’ouvrage de leurs mains, l’ouvrage qu’ont fait leurs doigts.
Ilẹ̀ ẹ wọn kún fún ère, wọ́n sì ń foríbalẹ̀ fún iṣẹ́ ọwọ́ ara wọn, èyí tí ìka ọwọ́ àwọn tìkára wọn ti ṣe.
9 Et l’homme du peuple s’est courbé, et l’homme de condition est humilié; ne leur pardonnez donc point.
Nítorí náà ni a ó ṣe rẹ ènìyàn sílẹ̀ ìran ọmọ ènìyàn ni yóò sì di onírẹ̀lẹ̀, má ṣe dáríjì wọ́n.
10 Entre dans la pierre, et cache-toi dans les creux de la terre, par la crainte du Seigneur et de la gloire de sa majesté.
Wọ inú àpáta lọ, fi ara pamọ́ nínú erùpẹ̀ kúrò nínú ìpayà Olúwa, àti ògo ọláńlá rẹ̀!
11 Les yeux altiers de l’homme du peuple ont été humiliés, et la fierté des hommes de condition sera abaissée; mais le Seigneur seul sera exalté en ce jour-là.
Ojú agbéraga ènìyàn ni a ó rẹ̀ sílẹ̀ a ó sì tẹrí ìgbéraga ènìyàn ba, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà.
12 Parce que le jour du Seigneur des armées éclatera sur tout esprit superbe et hautain et sur tout arrogant; et ils seront humiliés;
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ọjọ́ kan ní ìpamọ́ fún gbogbo agbéraga àti ọlọ́kàn gíga nítorí gbogbo àwọn tí a gbéga (ni a ó rẹ̀ sílẹ̀),
13 Et sur tous les cèdres du Liban, grands et élevés, et sur tous les chênes de Basan;
nítorí gbogbo igi kedari Lebanoni, tó ga tó rìpó àti gbogbo óákù Baṣani,
14 Et sur toutes les montagnes les plus hautes, et sur toutes les collines les plus élevées;
nítorí gbogbo òkè gíga ńlá ńlá àti àwọn òkè kéékèèké,
15 Et sur toute tour la plus élevée et sur toute muraille fortifiée;
fún ilé ìṣọ́ gíga gíga àti àwọn odi ìdáàbòbò,
16 Et sur tous les vaisseaux de Tharsis, et sur tout ce qui est beau à voir.
fún gbogbo ọkọ̀ àwọn oníṣòwò àwọn ọkọ̀ tí a ṣe lọ́ṣọ̀ọ́.
17 Et l’orgueil des hommes du peuple sera abaissé, et la hauteur des hommes de condition sera humiliée, et le Seigneur seul sera élevé en ce jour-là;
Ìgbéraga ènìyàn ni a ó tẹ̀ lórí ba a ó sì rẹ ìgbéraga ènìyàn sílẹ̀, Olúwa nìkan ṣoṣo ni a ó gbéga ní ọjọ́ náà,
18 Et les idoles seront entièrement brisées;
gbogbo ère òrìṣà yóò pòórá.
19 Et ils entreront dans les creux des rochers, dans les antres de la terre, par la frayeur du Seigneur, et à cause de la gloire de sa majesté, lorsqu’il se lèvera pour frapper la terre.
Àwọn ènìyàn yóò sálọ sínú ihò àpáta àti sínú ihò ilẹ̀ kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
20 En ce jour-là l’homme rejettera ses idoles d’argent et ses simulacres d’or, qu’il s’était faits pour les adorer, les taupes et les chauves-souris.
Ní ọjọ́ náà ni àwọn ènìyàn yóò máa sọ àwọn ère fàdákà àti ère wúrà tí wọ́n ti yá fún bíbọ sí èkúté àti àwọn àdán.
21 Et il entrera dans les fentes des pierres, et dans les cavernes des roches par la frayeur du Seigneur, et à cause de la gloire de sa majesté, lorsqu’il se lèvera pour frapper la terre.
Wọn yóò sálọ sínú ihò ìsàlẹ̀ àpáta àti sínú ihò pàlàpálá àpáta kúrò lọ́wọ́ ìpayà Olúwa àti ògo ọláńlá rẹ̀, nígbà tí ó bá dìde láti mi ayé tìtì.
22 Laissez donc l’homme dont le souffle est dans ses narines, parce qu’il a été réputé pour le Très-Haut.
Dẹ́kun à ń gba ènìyàn gbọ́, èémí ẹni tó wà ní ihò imú rẹ̀. Nítorí nínú kín ni a lè kà á sí?