< Isaïe 17 >

1 Malheur accablant de Damas. Voilà que Damas cessera d’être une cité, et elle sera un monceau de pierres en ruines.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Damasku: “Kíyèsi i, Damasku kò ní jẹ́ ìlú mọ́ ṣùgbọ́n yóò padà di ààtàn.
2 Les cités d’Aroër seront abandonnées aux troupeaux, et ils s’y reposeront, et il n’y aura personne qui les effrayera.
Àwọn ìlú Aroeri ni a ó kọ̀sílẹ̀ fún àwọn agbo ẹran tí yóò máa sùn síbẹ̀, láìsí ẹni tí yóò dẹ́rùbà wọ́n.
3 Et le soutien manquera à Ephraïm et le règne à Damas; et les restes de la Syrie seront comme la gloire des fils d’Israël,
Ìlú olódi ni yóò pòórá kúrò ní Efraimu, àti agbára ọba kúrò ní Damasku; àwọn àṣẹ́kù Aramu yóò dá gẹ́gẹ́ bí ògo ti àwọn Israẹli,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
4 Et il arrivera en ce jour-là que la gloire de Jacob sera atténuée, et que la graisse de sa chair se desséchera.
“Ní ọjọ́ náà ni ògo Jakọbu yóò sá; ọ̀rá ara rẹ̀ yóò ṣòfò dànù.
5 Et il sera comme celui qui ramasse dans la moisson ce qui est resté, et son bras recueillera des épis; et il sera comme celui qui cherche des épis dans la vallée de Raphaïm.
Yóò sì dàbí ìgbà tí olùkórè kó àwọn irúgbìn tí ó dúró jọ tí ó sì ń kórè irúgbìn pẹ̀lú apá rẹ̀— àti gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí ènìyàn pa ọkà ní àfonífojì ti Refaimu.
6 Et il y sera laissé seulement comme une grappe de raisin, et comme, lorsqu’on secoue un olivier, son fruit restant sera de deux ou trois olives au sommet d’une branche, ou bien de quatre ou de cinq à ses cimes, dit le Seigneur Dieu d’Israël.
Síbẹ̀síbẹ̀ irúgbìn díẹ̀ yóò ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí a gbọn igi olifi, tí èso olifi méjì tàbí mẹ́ta ṣẹ́kù sórí ẹ̀ka tí ó ga jùlọ, mẹ́rin tàbí márùn-ún lórí ẹ̀ka tí ó so jù,” ni Olúwa wí, àní Ọlọ́run Israẹli.
7 En ce jour-là l’homme s’inclinera vers son Créateur, et ses yeux regarderont du côté du saint d’Israël.
Ní ọjọ́ náà, àwọn ènìyàn yóò gbójú sókè sí Ẹlẹ́dàá wọn, wọn yóò sì síjú wo Ẹni Mímọ́ Israẹli.
8 Et il ne s’inclinera pas du côté des autels qu’ont faits ses mains; et ce qu’ont façonné ses doigts, les bois sacrés et les temples, il ne les regardera pas.
Wọn kò ní wo àwọn pẹpẹ mọ́, èyí tí í ṣe iṣẹ́ ọwọ́ wọn, wọn kò sì ní kọbi ara sí ère Aṣerah mọ́ tàbí pẹpẹ tùràrí tí ìka ọwọ́ wọn ti ṣe.
9 En ce jour-là, ses cités les plus fortes seront abandonnées comme les charrues et les moissons qui furent abandonnées à la vue des fils d’Israël; et tu seras déserte.
Ní ọjọ́ náà àwọn ìlú alágbára rẹ̀, yóò dàbí ẹ̀ka ìkọ̀sílẹ̀, àti ẹ̀ka téńté òkè tí wọ́n fi sílẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli. Gbogbo wọn yóò sì di ahoro.
10 Parce que tu as oublié le Dieu ton sauveur, et que de ton puissant secours tu ne t’es pas souvenue; c’est pour cela que tu planteras du bon plant, et que tu sèmeras une semence étrangère.
Nítorí ìwọ ti gbàgbé Ọlọ́run ìgbàlà rẹ; tí ìwọ kò sì náání àpáta ìgbàlà rẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ti gbin ọ̀gbìn dáradára ìwọ sì tọ́ àjèjì ẹ̀ka sínú rẹ̀.
11 Au jour de ta plantation c’était une vigne sauvage, et dès le matin ta semence fleurira; la moisson a été enlevée au jour de l’héritage, et tu en éprouveras une douleur grave.
Nítorí náà, bí ẹ tilẹ̀ mú àṣàyàn igi tí ẹ sì gbin àjàrà tí ó ti òkèrè wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ọjọ́ tí ẹ kó wọn jáde ẹ mú wọn hù jáde, àti ní òwúrọ̀ tí ẹ gbìn wọ́n ẹ mú kí wọ́n rúdí, síbẹ̀síbẹ̀ ìkórè kò ní mú nǹkan wá ní ọjọ́ ààrùn àti ìrora tí kò gbóògùn.
12 Malheur à la multitude de peuples nombreux; elle est comme la multitude des flots d’une mer mugissante; et le tumulte des troupes, comme le bruit des grandes eaux.
Kíyèsi i, ìrunú àwọn orílẹ̀-èdè— wọ́n ń runú bí ìgbì Òkun! Kíyèsi i, rògbòdìyàn tí ogunlọ́gọ̀ ènìyàn wọ́n bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ariwo odò ńlá!
13 Des peuples feront un bruit, comme le bruit des eaux qui débordent, et il le menacera, et il fuira au loin; et il sera emporté comme la poussière des montagnes à la face du vent, et comme un tourbillon devant la tempête.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ènìyàn ń bú ramúramù gẹ́gẹ́ bí ìrúmi odò, nígbà tí ó bá wọn wí wọ́n sálọ jìnnà réré, a tì wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí ìyàngbò ní orí òkè, àti gẹ́gẹ́ bí ewéko níwájú ìjì líle.
14 Il sera au temps du soir, et voici le trouble, au temps du matin, et il n’existera plus, voilà la part de ceux qui nous ont dévastés, et le sort de ceux qui nous ont pillés.
Ní aginjù, ìpayà òjijì! Kí ó tó di òwúrọ̀, a ò rí wọn mọ́! Èyí ni ìpín àwọn tí ó jí wa lẹ́rù, àti ìpín àwọn tí ó fi ogun kó wa.

< Isaïe 17 >