< Isaïe 14 >
1 Près de venir est son temps, et ses jours ne seront pas différés. Car le Seigneur aura pitié de Jacob, il fera encore choix d’Israël, et il les fera reposer dans leur terre; l’étranger se joindra à eux, et il s’attachera à la maison de Jacob.
Olúwa yóò fi àánú hàn fún Jakọbu, yóò tún Israẹli yàn lẹ́ẹ̀kan sí i yóò sì fi ìdí wọn kalẹ̀ ní ilẹ̀ àwọn tìkára wọn. Àwọn àjèjì yóò darapọ̀ mọ́ wọn, wọn yóò sì fọwọ́sowọ́pọ̀ pẹ̀lú ilé e Jakọbu.
2 Et les peuples les prendront et les ramèneront en leur lieu; et la maison d’Israël les possédera dans la terre du Seigneur comme serviteurs et comme servantes; et ils prendront ainsi ceux qui les avaient pris; et ils soumettront leurs exacteurs.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbà wọ́n wọn yóò sì mú wọn wá sí ààyè e wọn. Ilé Israẹli yóò gba àwọn orílẹ̀-èdè gẹ́gẹ́ bí àwọn ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin ní ilẹ̀ Olúwa. Wọn yóò kó àwọn akónilẹ́rú wọn ní ìgbèkùn wọn yóò sì jẹ ọba lórí àwọn amúnisìn wọn.
3 Et il arrivera en ce jour-là, que lorsque le Seigneur t’aura donné du repos après ton travail, et après ton oppression, et après la dure servitude à laquelle tu as été auparavant assujetti;
Ní ọjọ́ tí Olúwa yóò fi ìtura fún un yín kúrò nínú ìpọ́njú àti ìyà àti ìdè ìkà,
4 Tu emploieras cette parabole contre le roi de Babylone, et tu diras: Comment a cessé l’exacteur, et a discontinué le tribut?
ẹ ó sì fi ọ̀rọ̀ àbùkù yìí kan ọba Babeli pé, báwo ni amúnisìn ṣe wá sí òpin! Báwo ni ìbínú rẹ̀ ṣe parí!
5 Le Seigneur a brisé le bâton des impies, la verge des dominateurs,
Olúwa ti dá ọ̀pá ìkà náà, ọ̀pá àwọn aláṣẹ,
6 Qui, dans son indignation, frappait des peuples d’une plaie incurable, qui, dans sa fureur, assujettissait des nations, qui les persécutait cruellement.
èyí tí ó ti lu àwọn ènìyàn bolẹ̀ pẹ̀lú ti kò dáwọ́ dúró, nínú ìrunú ni ó ṣẹ́gun àwọn orílẹ̀-èdè pẹ̀lú ìgbónára tí kò lópin.
7 Toute la terre se repose et est en silence, elle est dans la joie et dans l’exultation;
Gbogbo ilẹ̀ ni ó wà ní ìsinmi àti àlàáfíà, wọ́n bú sí orin.
8 Les sapins même et les cèdres du Liban se sont réjouis à ton sujet, disant: Depuis que tu dors, il ne monte personne qui nous abatte.
Pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn igi junifa àti àwọn igi kedari ti Lebanoni ń yọ̀ lórí rẹ wí pé, “Níwọ́n bí a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ báyìí, kò sí agégi tí yóò wá láti gé wa lulẹ̀.”
9 L’enfer au-dessous a été tout troublé au moment de ton arrivée, il t’a suscité les géants. Tous les princes de la terre se sont levés de leurs trônes, ainsi que tous les princes des nations. (Sheol )
Ibojì tí ó wà ní ìsàlẹ̀ ni a ru sókè láti pàdé rẹ ní ìpadàbọ̀ rẹ̀ ó ru ẹ̀mí àwọn tí ó ti lọ sókè láti wá kí ọ gbogbo àwọn tí ó jẹ́ olórí ní ayé ó mú kí wọn dìde lórí ìtẹ́ wọn gbogbo àwọn tí ó jẹ ọba lórí àwọn orílẹ̀-èdè. (Sheol )
10 Tous élèveront la voix, et te diront: Toi aussi tu as reçu des blessures comme nous, tu es devenu semblable à nous.
Gbogbo wọn yóò dáhùn, wọn yóò wí fún ọ wí pé, “Ìwọ pẹ̀lú ti di aláìlera, gẹ́gẹ́ bí àwa pẹ̀lú ìwọ náà ti dàbí wa.”
11 Ton orgueil a été précipité dans les enfers, ton cadavre est tombé par terre; au-dessous de toi la teigne formera ta couche, et ta couverture seront les vers. (Sheol )
Gbogbo rẹ̀ ni ó di ìrẹ̀sílẹ̀ lọ sí ibojì, pẹ̀lú ariwo àwọn dùùrù rẹ, àwọn ìdin ni wọ́n fọ́nkálẹ̀ lábẹ́ rẹ àwọn ekòló sì ti bò ọ́ mọ́lẹ̀. (Sheol )
12 Comment es-tu tombé du ciel, lucifer qui dès le matin te levais? Comment as-tu été renversé sur la terre, toi qui faisais des blessures aux nations?
Báwo ni ìwọ ṣe ṣubú lulẹ̀ láti ọ̀run wá, ìwọ ìràwọ̀ òwúrọ̀, ọmọ òwúrọ̀ náà! A ti sọ ọ́ sílẹ̀ sínú ayé, ìwọ tí o ti tẹ orí àwọn orílẹ̀-èdè ba rí!
13 Qui disais dans ton cœur: Je monterai au ciel, sur les astres de Dieu j’élèverai mon trône; je m’assiérai sur la montagne du Testament, aux côtés de l’aquilon.
Ìwọ sọ nínú ọkàn rẹ pé, “Èmi yóò gòkè lọ sí ọ̀run; èmi yóò gbé ìtẹ́ mi sókè ga ju àwọn ìràwọ̀ Ọlọ́run, Èmi yóò gúnwà ní orí òkè àpéjọ ní ṣóńṣó orí òkè mímọ́.
14 Je monterai sur la hauteur des nues, je serai semblable au Très-Haut.
Èmi yóò gòkè lọ rékọjá àwọn àwọsánmọ̀; èmi yóò ṣe ara mi gẹ́gẹ́ bí Ọ̀gá-ògo.”
15 Mais cependant tu seras traîné dans l’enfer, au profond de la fosse; (Sheol )
Ṣùgbọ́n a ti rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ wọ inú ibojì lọ lọ sí ìsàlẹ̀ ọ̀gbun. (Sheol )
16 Ceux qui te verront se pencheront vers toi, et ils te considéreront et te diront: Est-ce là cet homme qui a troublé la terre, qui a ébranlé les royaumes;
Àwọn tí ó rí ọ yóò tẹjúmọ́ ọ, wọ́n ronú nípa àtubọ̀tán rẹ: “Ǹjẹ́ èyí ni ẹni tí ó mi ayé tìtì tí ó sì jẹ́ kí àwọn ilẹ̀ ọba wárìrì.
17 Qui a fait de l’univers un désert, et a détruit ses villes, et à ses captifs n’a pas ouvert la prison?
Ẹni tí ó sọ ayé di aginjù, tí ó sì pa ìlú ńlá ńlá rẹ̀ run tí kò dá àwọn òǹdè rẹ̀ sílẹ̀ láti padà sílé?”
18 Tous les rois des nations, tous se seront endormis dans la gloire, chacun dans sa maison.
Gbogbo àwọn ọba orílẹ̀-èdè ni a tẹ́ sílẹ̀ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú ibojì tirẹ̀.
19 Mais toi, tu as été jeté loin de ton sépulcre, comme un tronc inutile, et souillé, et enveloppé avec ceux qui ont été tués par le glaive et qui sont descendus au fond de la fosse comme un cadavre putréfié.
Ṣùgbọ́n a jù ọ́ síta kúrò nínú ibojì gẹ́gẹ́ bí ẹ̀ka igi tí a kọ̀sílẹ̀, àwọn tí a pa ni ó bò ọ́ mọ́lẹ̀, àwọn tí idà ti gún, àwọn tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ sínú òkúta inú ọ̀gbun. Gẹ́gẹ́ bí òkú ó di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ ní abẹ́ àtẹ́lẹsẹ̀,
20 Tu n’auras pas même part avec eux à la sépulture, parce que c’est toi qui as détruit entièrement ta terre, toi qui as tué ton peuple; la race des méchants n’existera pas éternellement.
a kò ní sin ọ́ pẹ̀lú wọn, nítorí pé o ti ba ilẹ̀ rẹ jẹ́ o sì ti pa àwọn ènìyàn rẹ. Ìran àwọn ìkà ni a kì yóò dárúkọ wọn mọ́.
21 Préparez ses enfants au massacre, à cause de l’iniquité de leurs pères ils ne s’élèveront pas, ils n’hériteront pas de la terre, et ils ne rempliront pas la face du globe de cités.
Tọ́jú ibìkan tí a ó ti pa àwọn ọmọkùnrin rẹ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn baba ńlá wọn, wọn kò gbọdọ̀ dìde láti jogún ilẹ̀ kí wọ́n sì bo orí ilẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìlú u wọn.
22 Et je m’élèverai contre eux, dit le Seigneur des armées, et je perdrai le nom de Babylone, et les restes, et le germe, et la race, dit le Seigneur.
“Èmi yóò dìde sókè sí wọn,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Èmi yóò ké orúkọ rẹ̀ kúrò ní Babeli àti àwọn tí ó sálà, àwọn ọmọ àti ìran rẹ̀,” ni Olúwa wí.
23 Et j’en ferai la possession du hérisson; j’en ferai des marais d’eaux, et je la balayerai avec un balai en la raclant, dit le Seigneur des armées.
Èmi yóò yí i padà sí ibùgbé àwọn òwìwí àti sí irà; Èmi yóò fi ọwọ́ ìparun gbá a, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
24 Le Seigneur des armées a juré, disant: Certainement, comme j’ai pensé, de même il en sera, et comme j’ai arrêté dans mon esprit,
Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti búra, “Gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣètò, bẹ́ẹ̀ ni yóò rí, àti bí mo ti pinnu, bẹ́ẹ̀ ni yóò sì dúró.
25 Ainsi il arrivera; afin que je brise l’Assyrien dans ma terre, et que sur mes montagnes je le foule aux pieds, que son joug soit emporté loin d’eux, et que son fardeau soit enlevé de leur épaule.
Èmi yóò run Asiria ní ilẹ̀ mi, ní àwọn orí òkè mi ni èmi yóò ti rún un mọ́lẹ̀. Àjàgà rẹ̀ ni a ó mú kúrò lọ́rùn àwọn ènìyàn mi, ẹrù u rẹ̀ ni ó mú kúrò ní èjìká wọn.”
26 C’est là le dessein que j’ai formé sur toute la terre, et c’est là la main étendue sur toutes les nations.
Èyí ni ètò tí a pinnu rẹ̀ fún gbogbo ayé, èyí ni ọwọ́ tí a nà jáde káàkiri gbogbo orílẹ̀-èdè.
27 Car le Seigneur des armées l’a décrété; qui pourra infirmer son décret? et sa main est étendue, qui la détournera?
Nítorí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pète, ta ni yóò sì ká a lọ́wọ́ kò? Ọwọ́ọ rẹ ti nà jáde, ta ni ó sì le è fà á padà?
28 En l’année, à laquelle est mort le roi Achaz, a été faite cette prophétie accablante:
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ yí wá ní ọdún tí ọba Ahasi kú.
29 Ne te réjouis pas, toi terre entière de Palestine, de ce qu’a été brisée la verge de celui qui te frappait; car de la race du serpent sortira un basilic, et ce qui en naîtra dévorera l’oiseau.
Má ṣe yọ̀, gbogbo ẹ̀yin Filistia, pé ọ̀pá tí ó lù ọ́ ti dá; láti ibi gbòǹgbò ejò náà ni paramọ́lẹ̀ yóò ti hù jáde, èso rẹ̀ yóò sì jẹ́ oró ejò tí í jóni.
30 Et les plus indigents seront nourris, et les pauvres reposeront avec confiance; et je ferai mourir ta racine, et tes restes, je les tuerai.
Ẹni tí ó kúṣẹ̀ẹ́ jù yóò ní pápá oko, àwọn aláìní yóò sì dùbúlẹ̀ láìléwu. Ṣùgbọ́n gbòǹgbò o rẹ̀ ni èmi ó fi ìyàn parun, yóò sì ké àwọn ẹni rẹ tí ó sálà kúrò.
31 Pousse des hurlements, porte; crie, cité; toute la Palestine a été renversée; car c’est de l’aquilon que la fumée viendra; et il n’est personne qui fuira son armée.
Hu, ìwọ ẹnu-ọ̀nà! Kígbe, ìwọ ìlú! Yọ́ kúrò, gbogbo ẹ̀yin Filistia! Èéfín kurukuru kan ti àríwá wá, kò sì ṣí amóríbọ́ kan nínú ẹgbẹ́ wọn.
32 Et que répondra-t-on aux messagers de la nation? Que c’est le Seigneur qui a fondé Sion, et qu’en lui espéreront les pauvres de son peuple.
Kí ni ìdáhùn tí a ó fún agbẹnusọ orílẹ̀-èdè náà? “Olúwa ti fi ìdí Sioni kalẹ̀, àti nínú rẹ̀ ni àwọn ènìyàn rẹ̀ tí a ti pọ́n ọn lójú yóò ti rí ààbò o wọn.”