< Isaïe 11 >
1 Et il sortira un rejeton de la racine de Jessé, et une fleur s’élèvera de sa racine,
Èèkàn kan yóò sọ láti ibi kùkùté Jese, láti ara gbòǹgbò rẹ̀ ni ẹ̀ka kan yóò ti so èso.
2 Et l’esprit du Seigneur reposera sur lui; l’esprit de sagesse et d’intelligence, l’esprit de conseil et de force, l’esprit de science et de piété.
Ẹ̀mí Olúwa yóò sì bà lé e, ẹ̀mí ọgbọ́n àti ti òye, ẹ̀mí ìmọ̀ràn àti ti agbára, ẹ̀mí ìmọ̀ àti ti ìbẹ̀rù Olúwa.
3 L’esprit de crainte du Seigneur le remplira. Il ne jugera pas d’après ce qu’auront vu les yeux, et il ne condamnera pas d’après ce qu’auront ouï les oreilles.
Òun yóò sì ní inú dídùn nínú ìbẹ̀rù Olúwa. Òun kì yóò ṣe ìdájọ́ pẹ̀lú ohun tí ó fi ojú u rẹ̀ rí, tàbí pẹ̀lú ohun tí ó fi etí i rẹ̀ gbọ́,
4 Mais il jugera les pauvres dans la justice, et il se prononcera avec équité pour les hommes paisibles de la terre; et il frappera la terre de la verge de sa bouche, et du souffle de ses lèvres il tuera l’impie.
ṣùgbọ́n pẹ̀lú òdodo ni yóò ṣe ìdájọ́ àwọn aláìní, pẹ̀lú òtítọ́ ni yóò ṣe ìpinnu fún àwọn aláìní ayé. Òun yóò lu ayé pẹ̀lú ọ̀pá tí ó wà ní ẹnu rẹ̀, pẹ̀lú èémí ẹnu rẹ̀ ni yóò pa àwọn ìkà.
5 Et la justice sera la ceinture de ses reins, et la fidélité le ceinturon de ses flancs
Òdodo ni yóò jẹ́ ìgbànú rẹ̀ àti òtítọ́ ni yóò ṣe ọ̀já yí ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ká.
6 Le loup habitera avec l’agneau, et le léopard se couchera près du chevreau; le jeune taureau, et le Mon, et la brebis demeureront ensemble, et un petit enfant les conduira.
Ìkookò yóò sì máa bá ọmọ àgùntàn gbé, ẹkùn yóò sì sùn ti ewúrẹ́ ọmọ màlúù òun ọmọ kìnnìún àti ọmọ ẹran ó wà papọ̀ ọ̀dọ́mọdé yóò sì máa dà wọ́n.
7 Le veau et l’ours iront aux mêmes pâturages; leurs petits se reposeront ensemble; le lion comme le bœuf mangera la paille.
Màlúù àti beari yóò máa jẹun pọ̀, àwọn ọmọ wọn yóò dùbúlẹ̀ pọ̀, kìnnìún yóò sì máa jẹ koríko gẹ́gẹ́ bí akọ màlúù.
8 Et l’enfant à la mamelle se jouera sur le trou de l’aspic; et celui qui viendra d’être sevré portera sa main dans la caverne du basilic.
Ọ̀dọ́mọdé yóò ṣeré lẹ́bàá ihò ọká, ọmọdé yóò ki ọwọ́ rẹ̀ bọ ìtẹ́ paramọ́lẹ̀.
9 Ils ne nuiront pas, et ils ne tueront pas sur toute ma montagne sainte; parce que la terre est remplie de la connaissance du Seigneur, comme les eaux qui couvrent la mer.
Wọn kò ní ṣe ni léṣe tàbí pa ni run ní gbogbo òkè mímọ́ mi, nítorí gbogbo ayé yóò kún fún ìmọ̀ Olúwa gẹ́gẹ́ bí omi ti bo Òkun.
10 En ce jour-là viendra la racine de Jessé qui est comme l’étendard des peuples; c’est à lui que les nations adresseront leurs prières, et son sépulcre sera glorieux.
Ní ọjọ́ náà, gbòǹgbò Jese yóò dúró gẹ́gẹ́ bí àsíá fún gbogbo ènìyàn, àwọn orílẹ̀-èdè yóò pagbo yí i ká, ibùdó ìsinmi rẹ̀ yóò jẹ́ èyí tí ó lógo.
11 Et il arrivera en ce jour-là que le Seigneur étendra une seconde fois sa main pour posséder le reste de son peuple, qui aura échappé aux Assyriens, et à l’Egypte, et à Phétros, et à l’Ethiopie, et à Elam et à Sennaar, et à Emath, et aux îles de la mer.
Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò na ọwọ́ rẹ̀ jáde nígbà kejì láti tún gba àwọn tí ó ṣẹ́kù àní àwọn tí a ṣẹ́kù nínú àwọn ènìyàn an rẹ̀ láti Asiria wá, láti ìsàlẹ̀ Ejibiti àti òkè Ejibiti, láti Kuṣi, láti Elamu láti Babiloni, láti Hamati àti láti àwọn erékùṣù inú Òkun.
12 Et il élèvera son étendard parmi les nations, il réunira les fugitifs d’Israël, et les dispersés de Juda, il les rassemblera des quatre coins de la terre.
Òun yóò gbé àsíá sókè fún àwọn orílẹ̀-èdè, yóò sì kó àwọn ìgbèkùn Israẹli jọ, yóò kó gbogbo àwọn ènìyàn Juda tí a ti fọ́n káàkiri jọ, láti igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ilẹ̀ ayé.
13 Et la jalousie d’Ephraïm sera détruite, et les ennemis de Juda périront; Ephraïm n’enviera pas Juda, et Juda ne combattra pas contre Ephraïm.
Owú jíjẹ Efraimu yóò pòórá, àwọn ọ̀tá Juda ni a ó ké kúrò, Efraimu kò ní jowú Juda, tàbí Juda kó dojúkọ Efraimu.
14 Et ils voleront sur les épaules des Philistins par la mer; ils pilleront ensemble les fils de l’Orient. L’Idumée et Moab seront la première capture de leur main, et les fils d’Ammon leur obéiront.
Wọn yóò fò mọ́ èjìká Filistini sí apá ìwọ̀-oòrùn, wọn yóò pawọ́pọ̀ kọlu àwọn ènìyàn apá ìlà-oòrùn. Wọn yóò gbé ọwọ́ wọn lé Edomu àti Moabu, àwọn ará Ammoni yóò sì di ìwẹ̀fà wọn.
15 Et le Seigneur mettra à sec la langue de la mer d’Égypte, et il lèvera sa main sur le fleuve, il l’agitera par la force de son souffle, et il le frappera dans ses sept ruisseaux, en sorte qu’on le passera tout chaussé.
Olúwa yóò sọ di gbígbé àyasí Òkun Ejibiti, pẹ̀lú atẹ́gùn gbígbóná ni yóò na ọwọ́ rẹ̀, kọjá lórí odò Eufurate. Òun yóò sì sọ ọ́ di ọmọdò méje tó fi jẹ́ pé àwọn ènìyàn yóò máa là á kọjá pẹ̀lú bàtà.
16 Et il y aura une voie pour le reste de mon peuple qui aura échappé aux Assyriens, comme il y en eut une pour Israël, au jour auquel il monta de la terre d’Egypte.
Ọ̀nà gidi yóò wà fún àwọn ènìyàn an rẹ̀ tí ó ṣẹ́kù tí ó kù sílẹ̀ ní Asiria, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà fún Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè láti Ejibiti wá.