< Osée 5 >

1 Écoutez ceci, prêtres, et soyez attentive, maison d’Israël; et, maison du roi, prêtez l’oreille; parce que c’est contre vous que le jugement est préparé, parce que vous êtes devenus un lacs dans un lieu d’observation, et un rets tendu sur le Thabor.
“Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yìn àlùfáà! Ẹ fetísílẹ̀ ẹ̀yin ọmọ Israẹli! Ẹ gbọ́, ẹ̀yìn ilé ọba! Ìdájọ́ yìí kàn yín. Ẹ ti jẹ́ ẹ̀bìtì ní Mispa àwọ̀n ti a nà sílẹ̀ lórí Tabori.
2 Et vous avez détourné des victimes en les faisant tomber dans un endroit profond; et moi je les ai tous instruits.
Àwọn ọlọ̀tẹ̀ ti gbilẹ̀ nínú ìpànìyàn gbogbo wọn ni èmi ó bá wí,
3 Moi, je connais Ephraïm, et Israël ne m’est point caché; je sais que maintenant Ephraïm a forniqué, qu’Israël s’est souillé.
mo mọ ohun gbogbo nípa Efraimu Israẹli kò sì pamọ́ fún mi Efraimu, ní báyìí ó ti ṣe àgbèrè Israẹli sì ti díbàjẹ́.
4 Ils n’appliqueront pas leurs pensées à revenir à leur Dieu, parce que l’esprit de fornication est au milieu d’eux, et qu’ils n’ont pas connu le Seigneur.
“Ìṣe wọn kò gbà wọ́n láààyè láti padà sí ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wọn. Ẹ̀mí àgbèrè wà ni ọkàn wọn, wọn kò sì mọ Olúwa.
5 Et l’arrogance d’Israël lui répondra en face; et Israël et Ephraïm tomberont par leur iniquité, et Juda tombera avec eux.
Ìgbéraga Israẹli ń jẹ́rìí lé wọn; àwọn ọmọ Israẹli, àti Efraimu pàápàá kọsẹ̀ nínú ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Juda náà sì kọsẹ̀ pẹ̀lú wọn.
6 Avec leurs troupeaux de menu et de gros bétail, ils iront pour chercher le Seigneur et ils ne le trouveront pas; il s’est retiré d’eux.
Nígbà tí wọ́n bá lọ pẹ̀lú agbo ẹran àti ọ̀wọ́ ẹran wọn láti wá Olúwa, wọn kò ní rí i, ó ti yọ ara rẹ̀ kúrò láàrín wọn.
7 C’est contre le Seigneur qu’ils ont prévariqué, parce qu’ils ont engendré des enfants étrangers; maintenant un mois les dévorera avec leurs biens.
Wọ́n jẹ́ aláìṣòótọ́ sí Olúwa wọ́n sì bí àwọn àjèjì ọmọ. Nísinsin yìí, ọdún oṣù tuntun wọn, ni yóò pa wọn run pẹ̀lú ìpín wọn.
8 Sonnez du cor dans Gabaa, de la trompette à Rama; hurlez à Bethaven, et arrière, toi, ô Benjamin.
“Fọn fèrè ní Gibeah, kí ẹ sì fun ìpè ní Rama. Ẹ pariwo ogun ní Beti-Afeni; máa wárìrì, ìwọ Benjamini.
9 Ephraïm sera dans la désolation au jour du châtiment; dans les tribus d’Israël j’ai montré ma fidélité.
Efraimu yóò di ahoro ní ọjọ́ ìbáwí láàrín àwọn ẹ̀yà Israẹli, Mo sọ ohun tí ó dájú.
10 Les princes de Juda sont devenus comme ceux qui enlèvent une borne; sur eux je répandrai comme l’eau ma colère.
Àwọn olórí Juda dàbí àwọn tí í máa yí òkúta ààlà kúrò. Èmi ó tú ìbínú gbígbóná mi lé wọn lórí bí ìkún omi.
11 Ephraïm souffre l’oppression, brisé par le jugement, parce qu’il s’est mis à aller après les ordures.
A ni Efraimu lára, a sì tẹ̀ ẹ́ mọ́lẹ̀ ní ìdájọ́, nítorí pé, ó pinnu láti tẹ̀lé òrìṣà.
12 Et moi, je suis pour Ephraïm comme la teigne, et comme la gangrène pour la maison de Juda.
Mo dàbí kòkòrò aṣọ sí Efraimu, Mo sì dàbí ìdin ara Juda.
13 Et Ephraïm a vu sa langueur, et Juda ses liens; et Ephraïm est allé vers Assur, et il a envoyé vers un roi vengeur, et lui-même ne pourra vous guérir, et ne pourra rompre vos liens.
“Nígbà ti Efraimu ri àìsàn rẹ̀, tí Juda sì rí ojú egbò rẹ̀ ni Efraimu bá tọ ará Asiria lọ, ó sì ránṣẹ́ sí ọba ńlá náà fún ìrànlọ́wọ́. Ṣùgbọ́n kò le è wò ó sàn bẹ́ẹ̀ ni kò le wo ojú egbò rẹ̀ jinná.
14 Parce que moi, je suis comme une lionne à Ephraïm, et comme le petit d’un lion à la maison de Juda; moi, moi, je saisirai et je m’en irai; j’emporterai et il n’y a personne qui arrachera de mes mains.
Nítorí pé, èmi ó dàbí kìnnìún sí Efraimu, bí i kìnnìún ńlá sí ilé Juda. Èmi ó fà wọ́n ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ èmi ó sì lọ; Èmi ó gbé wọn lọ, láìsí ẹni tí yóò gbà wọ́n sílẹ̀.
15 Allant, je retournerai en mon lieu, jusqu’à ce que vous tombiez en défaillance et que vous cherchiez ma face.
Nígbà náà ni èmi ó padà lọ sí ààyè mi títí di ìgbà tí wọn ó fi gbà pé àwọn jẹ̀bi wọn yóò sì wá ojú mi nínú ìpọ́njú wọn, wọn ó fi ìtara wá mi.”

< Osée 5 >