< Osée 3 >

1 Et le Seigneur me dit: Vas encore, et aime une femme aimée par un ami, et adultère; comme le Seigneur aime les enfants d’Israël, et eux se tournent vers les dieux étrangers, et ils aiment le marc de raisins.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Tun lọ fẹ́ obìnrin kan tí í ṣe olùfẹ́ ọ̀rẹ́ rẹ̀, àti panṣágà, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ Olúwa sì àwọn ọmọ Israẹli tí ń wo àwọn ọlọ́run mìíràn, tí wọ́n sì ń fẹ́ àkàrà èso àjàrà.”
2 Et j’achetai cette femme quinze pièces d’argent, et un cor d’orge, et un demi-cor d’orge.
Nítorí náà, mo sì rà á padà ní ṣékélì fàdákà mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti homeri kan àti lẹ́tékì barle kan.
3 Et je lui dis: Tu m’attendras durant de longs jours; tu ne forniqueras pas, et tu ne seras à aucun homme; et moi aussi je t’attendrai.
Mo sì sọ fún un pé, “Ìwọ gbọdọ̀ máa gbé pẹ̀lú mi fún ọjọ́ pípẹ́, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe àgbèrè mọ́ tàbí kí o fẹ́ ọkùnrin mìíràn, èmi náà yóò sì gbé pẹ̀lú rẹ.”
4 Parce que durant de longs jours, les enfants d’Israël seront sans roi et sans prince, et sans sacrifice et sans autel, et sans éphod et sans théraphim.
Nítorí pé àwọn ọmọ Israẹli yóò wà fún ọjọ́ pípẹ́ láìní ọba tàbí olórí, láìsí ìrúbọ tàbí pẹpẹ mímọ́, láìsí àlùfáà tàbí òrìṣà kankan.
5 Et après cela, les enfants d’Israël reviendront, et ils chercheront le Seigneur leur Dieu et David leur roi; et ils craindront en approchant du Seigneur et de ses biens au dernier des jours.
Lẹ́yìn èyí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò padà láti wá Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi ọba wọn. Wọn yóò sì wá síwájú Olúwa pẹ̀lú ẹ̀rù, wọn ó sì jọ̀wọ́ ara wọn fún Olúwa àti ìbùkún rẹ̀ ní ọjọ́ ìkẹyìn.

< Osée 3 >