< Osée 2 >
1 Dites à vos frères: Mon peuple; et à votre sœur: Tu as reçu miséricorde.
“Sọ fún àwọn arákùnrin rẹ, ‘Ènìyàn mi,’ kí o sì wí fún àwọn arábìnrin rẹ ‘Àyànfẹ́ mi.’
2 Jugez votre mère, jugez-la; elle n’est pas mon épouse, et moi je ne suis pas son époux; qu’elle ôte ses fornications de sa face, et ses adultères du milieu de son sein.
“Ẹ bá ìyá yín wí, ẹ bá a wí, nítorí pé kì í ṣe ìyàwó mi, Èmi náà kì í sì í ṣe ọkọ rẹ̀. Jẹ́ kí ó yọ àgbèrè rẹ̀ kúrò lójú rẹ̀ àti àìṣòótọ́ kúrò ní àyà rẹ̀.
3 De peur que je ne la dépouille à nu, et que je ne la mette comme au jour de sa naissance; et que je ne la réduise en solitude, et que je ne la rende comme une terre inaccessible, et que je ne la fasse mourir de soif.
Àìṣe bẹ́ẹ̀ èmi yóò tú u sí ìhòhò, Èmi yóò sì gbé e kalẹ̀ bí ọjọ́ tí a bí i. Èmi yóò ṣe ọ́ bí i aṣálẹ̀ ilẹ̀, Èmi yóò sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀ Èmi yóò sì fi òǹgbẹ gbẹ ẹ́.
4 Je n’aurai pas pitié de ses enfants, parce que ce sont des enfants de fornications:
Èmi kò ní fi àánú mi hàn sí àwọn ọmọ rẹ̀ nítorí ọmọ àgbèrè ni wọ́n jẹ́.
5 Parce que leur mère a forniqué, que celle qui les a conçus s’est couverte de confusion; parce qu’elle a dit: J’irai après mes amants, qui me donnent mon pain et mon eau, ma laine et mon lin, mon huile et mon breuvage.
Nítorí ìyá wọn ti hùwà àgbèrè, ó sì lóyún wọn nínú ìtìjú. Ó wí pé, ‘Èmi ó tún tọ́ àwọn àyànfẹ́ mi lẹ́yìn, tó ń fún mi ní oúnjẹ àti omi, ní irun àgùntàn mi àti ọ̀gbọ̀ mi, òróró mi àti ohun mímu mi.’
6 À cause de cela, voici que moi, j’entourerai ton chemin d’une haie d’épines, je l’entourerai d’une muraille, et elle ne retrouvera pas ses sentiers.
Nítorí náà, èmi ó fi ẹ̀gún dì í lọ́nà, Èmi ó mọ odi yí i ká kí ó má ba à rọ́nà lọ.
7 Et elle poursuivra ses amants, et elle ne les atteindra pas; et elle les cherchera, et elle ne les trouvera pas; et elle dira: J’irai, et je retournerai à mon premier mari, parce que j’étais alors mieux que maintenant.
Yóò sáré lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ ṣùgbọ́n kò ní bá wọn; yóò wá wọn ṣùgbọ́n kò ní rí wọn. Nígbà náà ni yóò sọ pé, ‘Èmi ó padà sí ọ̀dọ̀ ọkọ mi àkọ́kọ́ nítorí pé ó dára fún mi nígbà náà ju ìsinsin yìí lọ.’
8 Elle n’a pas su que moi, je lui ai donné le blé, le vin et l’huile; j’ai multiplié pour elle l’argent et l’or qui ont fait Baal.
Nítorí pé kò tí ì mọ̀ pé èmi ni àti ẹni tó fún un ní ọkà, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ẹni tí ó fún un ní fàdákà àti wúrà lọ́pọ̀lọ́pọ̀, èyí tí wọ́n lò fún Baali.
9 C’est pour cela que je changerai, et que je reprendrai mon blé en son temps et mon vin en son temps; et que j’enlèverai mon lin et ma laine qui couvraient son ignominie.
“Nítorí náà, èmi yóò mú ọkà mi kúrò nígbà tó bá pọ́n, èmi yóò sì mú wáìnì mi kúrò ní àsìkò rẹ̀. Èmi yóò sì gba irun àgùntàn àti ọ̀gbọ̀ mi padà ti mo ti fi fún un láti bo ìhòhò rẹ̀.
10 Et maintenant je révélerai sa folie aux yeux de ses amants, et pas un homme ne l’arrachera de ma main.
Èmi yóò sì fi ìwà ìtìjú rẹ̀ hàn lójú àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ kò sí ẹni tí yóò gbà á sílẹ̀ lọ́wọ́ mi,
11 Et je ferai cesser sa joie, ses solennités, ses néoménies, son sabbat et tous ses temps de fêtes.
Èmi yóò mú gbogbo ayọ̀ rẹ̀ wá sí òpin: àjọ̀dún ọdọọdún rẹ̀, oṣù tuntun rẹ̀, ọjọ́ ìsinmi, àti gbogbo àwọn àjọ̀dún tí a yàn.
12 Je gâterai sa vigne et son figuier dont elle disait: Ce sont mes récompenses que m’ont données mes amants; et j’en ferai une forêt, et la bête de la campagne la mangera.
Èmi yóò pa àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ̀ run, èyí tí ó pè ní èrè rẹ̀ láti ọ̀dọ̀ àwọn olólùfẹ́ rẹ̀, Èmi yóò sọ wọ́n di igbó, àwọn ẹranko búburú yóò sì jẹ́ wọn run.
13 Et je visiterai sur elle les jours de Baalim, pendant lesquels elle brûlait de l’encens, et se parait de ses pendants d’oreilles et de son collier, et allait après ses amants, et m’oubliait, dit le Seigneur.
Èmi yóò bẹ̀ ọjọ́ Baalimu wò ní ara rẹ̀ nínú èyí tó ń fi tùràrí jóná fún Baali; tí ó fi òrùka etí àti ohun ọ̀ṣọ́ rẹ̀, ṣe ara rẹ̀ lọ́ṣọ̀ọ́, tó sì tẹ̀lé àwọn olólùfẹ́ rẹ̀ lọ. Ṣùgbọ́n èmi ni òun gbàgbé,” ni Olúwa wí.
14 À cause de cela, voici que moi, je l’attirerai doucement et l’amènerai dans la solitude, et je parlerai à son cœur.
“Nítorí náà, èmi yóò tàn án, Èmi ó sì mú u lọ sí ilẹ̀ aṣálẹ̀, Èmi ó fi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́ bá a sọ̀rọ̀
15 Et je lui donnerai des vignerons du même lieu, et la vallée d’Achor pour lui ouvrir une espérance; et elle chantera là comme aux jours de sa jeunesse, et comme au jour où elle remonta de la terre d’Egypte.
Níbẹ̀ ni èmi yóò ti dá ọgbà àjàrà rẹ̀ padà fún un, Èmi yóò fi àfonífojì Akori ṣe ìlẹ̀kùn ìrètí fún un. Yóò sì kọrin níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìgbà tó kúrò ní Ejibiti.
16 Et il arrivera qu’en ce jour-là, dit le Seigneur, elle m’appellera: Mon époux, et elle ne m’appellera plus Baali.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà, ìwọ yóò pè mí ní ‘ọkọ mi’; ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ ni Olúwa wí.
17 J’ôterai de sa bouche les noms de Baalim, et elle ne se souviendra plus de leur nom.
Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Baali kúrò lẹ́nu rẹ̀; ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Baali pè mọ́.
18 Et je contracterai en ce jour-là une alliance avec eux, avec la bête de la campagne, et avec l’oiseau du ciel, et avec le reptile de la terre; et je briserai l’arc, et le glaive, et la guerre, en les faisant disparaître de la terre, et je les ferai dormir dans la confiance.
Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀mú fún wọn àti àwọn ẹranko igbó àti ẹyẹ ojú ọ̀run àti àwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀. Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́. Ọfà, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náà kí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
19 Et je te prendrai pour mon épouse à jamais: et je te prendrai pour mon épouse par la justice, et par le jugement, et par la miséricorde, et par les bontés.
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé; Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àti òtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
20 Et je te prendrai pour mon épouse par la foi, et tu sauras que je suis le Seigneur.
Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní òtítọ́ ìwọ yóò sì mọ Olúwa.
21 Et il arrivera qu’en ce jour-là, j’exaucerai, dit le Seigneur, j’exaucerai les cieux, et eux exauceront la terre.
“Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí; “Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùn àwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;
22 Et la terre exaucera le blé, et le vin, et l’huile, et ces choses exauceront Jezrahel.
ilẹ̀ náà yóò sì dá ọkà, wáìnì tuntun àti òróró lóhùn Gbogbo wọn ó sì dá Jesreeli lóhùn.
23 Je la sèmerai sur la terre, et j’aurai pitié de celle qui fut nommée Sans miséricorde. Et je dirai à celui qui n’était pas mon peuple: Tu es mon peuple; et lui dira: Vous êtes mon Dieu, vous.
Èmi ó sì gbìn ín fún ara mi lórí ilẹ̀ náà, Èmi yóò ṣàánú fún ẹni tí kò tì í ri ‘Àánú gbà.’ Èmi yóò sọ fún àwọn tí ‘Kì í ṣe ènìyàn mi pé,’ ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi’; àwọn náà yóò sì wí pé, ‘Ìwọ ni Ọlọ́run mi.’”