< Osée 12 >

1 Ephraïm se repaît de vent et poursuit un air brûlant; tout le jour il multiplie le mensonge et la dévastation; il a fait alliance avec les Assyriens et il portait de l’huile en Egypte.
Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
2 Voici donc venir le jugement du Seigneur avec Juda, et sa visite sur Jacob; il lui rendra selon ses voies et ses inventions.
Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 Dans le sein maternel il supplanta son frère; par sa force il lutta avec l’ange.
Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 Et il prévalut contre l’ange et il fut fortifié; il pleura, et le pria: il le trouva à Béthel, et là le Seigneur nous parla.
Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 Et le Seigneur, le Dieu des armées, le Seigneur devint l’objet de son souvenir.
àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
6 Et toi, Israël, à ton Dieu tu te convertiras; garde la miséricorde et le jugement, et espère en ton Dieu, toujours.
Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
7 Quant à Chanaan, dans sa main est une balance trompeuse; il a aimé l’oppression.
Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
8 Et Ephraïm a dit: Cependant je suis devenu riche, j’ai trouvé une idole pour moi; aucun de mes travaux ne trouvera l’iniquité par laquelle j’ai péché.
Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
9 Et moi, je suis le Seigneur ton Dieu, depuis que je t’ai retiré de la terre d’Egypte; je te ferai encore demeurer dans des tabernacles comme aux jours de fête.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
10 Et j’ai parlé aux prophètes, et c’est moi qui ai multiplié les visions; et par le ministère des prophètes j’ai été assimilé aux hommes.
Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
11 Si Galaad était une idole, c’est donc en vain qu’ils sacrifiaient aux bœufs de Galgal; car leurs autels sont comme des monceaux de pierre sur les sillons des champs.
Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
12 Jacob a fui dans la contrée de Syrie, et Israël a servi pour une femme, et pour une autre femme il a servi.
Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
13 Par un prophète, le Seigneur a tiré Israël de l’Egypte, et par un prophète il a été conservé.
Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
14 Par ses plaintes amères, Ephraïm m’a provoqué au courroux; et son sang retombera sur lui, et son opprobre, le Seigneur le lui rendra.
Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.

< Osée 12 >