< Aggée 1 >
1 En la seconde année du roi Darius, au sixième mois, au premier jour du mois, la parole du Seigneur fut adressée, par l’entremise d’Aggée, le prophète, à Zorobabel, chef de Juda, fils de Salathiel, et à Jésus, le grand-prêtre, fils de Josédec, disant:
Ní ọdún kejì ọba Dariusi ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kẹfà, ọ̀rọ̀ Olúwa wá nípasẹ̀ wòlíì Hagai sí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, baálẹ̀ Juda, àti sọ́dọ̀ Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà.
2 Voici ce que dit le Seigneur des armées: Ce peuple dit: Il n’est pas encore venu, le temps de bâtir la maison du Seigneur.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Àwọn ènìyàn wọ̀nyí wí pé, ‘Kò tí ì tó àkókò láti kọ́ ilé Olúwa.’”
3 Et la parole du Seigneur fut adressée par l’entremise d’Aggée, le prophète, disant:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa wá láti ọ̀dọ̀ wòlíì Hagai wí pé,
4 Est-ce qu’il est temps pour vous d’habiter dans des maisons lambrissées, quand cette maison est déserte?
“Ǹjẹ́ àkókò ni fún ẹ̀yin fúnra yín láti máa gbé ní ilé tí a ṣe ní ọ̀ṣọ́ nígbà tí ilé yìí wà ni ahoro?”
5 Et maintenant, voici ce que dit le Seigneur des armées: Appliquez vos cœurs à vos voies.
Nísìnsinyìí, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
6 Vous avez semé beaucoup, et vous avez peu recueilli; vous avez mangé, et vous n’avez pas été rassasiés; vous avez bu, et vous n’avez pas été désaltérés; vous vous êtes couverts, et vous ne vous êtes pas réchauffés; et celui qui a accumulé des profits les a mis dans un sac percé.
Ẹ̀yin ti gbìn ohun ti ó pọ̀. Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kórè díẹ̀ níbẹ̀. Ẹ̀yin jẹun, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò yó. Ẹ̀yin mu ṣùgbọ́n kò tẹ́ ẹ yín lọ́run; ẹ̀yin wọ aṣọ, ṣùgbọ́n kò mú òtútù yin lọ; ẹyin gba owó iṣẹ́ ṣùgbọ́n ẹ ń gbà á sínú ajádìí àpò.”
7 Voici ce que dit le Seigneur des armées: Appliquez vos cœurs à vos voies.
Báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ kíyèsi ọ̀nà yín.
8 Montez sur la montagne, portez des bois, et bâtissez la maison, et elle me sera agréable, et je serai glorifié, dit le Seigneur.
Ẹ gun orí àwọn òkè ńlá lọ, kí ẹ sì mú igi wá pẹ̀lú yín. Kí ẹ sì kọ́ ilé náà, kí inú mi bà le è dùn sí i, kí a sì yín mí lógo,” ni Olúwa wí.
9 Vous avez espéré plus, et il arrive moins; ce peu, vous l’ avez apporté dans votre maison, et j’ai soufflé dessus; pour quel motif, dit le Seigneur des armées? parce que ma maison est déserte, et que chacun de vous se hâte pour la sienne.
“Ẹyin ti ń retí ọ̀pọ̀, ṣùgbọ́n kíyèsi i, o yípadà sí díẹ̀. Ohun tí ẹ̀yin mú wa ilé, èmi sì fẹ́ ẹ dànù. Nítorí kí ni?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nítorí ilé mi tí ó dahoro; tí olúkúlùkù yín sì ń sáré fún ilé ara rẹ̀.
10 C’est pour cela qu’au-dessus de vous il a été défendu aux cieux de donner de la rosée, et qu’à la terre il a été défendu de donner ses productions.
Nítorí yín ni àwọn ọ̀run ṣe dá ìrì dúró tí ilẹ̀ sì kọ̀ láti mu èso jáde.
11 Et j’ai appelé la sécheresse sur la terre, et sur les montagnes, et sur le blé, et sur le vin, et sur l’huile, et sur tout ce que produit la terre, et sur les hommes, et sur les bêtes, et sur tous les travaux de vos mains.
Mo sì ti pe ọ̀dá sórí ilẹ̀ àti sórí àwọn òkè ńlá, sórí ọkà àti sórí wáìnì tuntun, sórí òróró àti sórí ohun ti ilẹ̀ ń mú jáde, sórí ènìyàn, sórí ẹran àti sórí gbogbo iṣẹ́ ọwọ́ yín.”
12 Et Zorobabel, fils de Salathiel, et Jésus, fus de Josédec, le grand-prêtre, et tous ceux qui étaient restés du peuple, entendirent la voix du Seigneur leur Dieu, et les paroles d’Aggée, le prophète, qu’envoya vers eux le Seigneur leur Dieu; et le peuple fut saisi de crainte devant la face du Seigneur.
Nígbà náà ni Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli, Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà pẹ̀lú gbogbo ènìyàn ìyókù, gba ohùn Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́ àti ọ̀rọ̀ wòlíì Hagai, nítorí Olúwa Ọlọ́run ni ó rán an. Àwọn ènìyàn sì bẹ̀rù Olúwa.
13 Et Aggée, envoyé du Seigneur dans les messages du Seigneur, parla, disant au peuple: Moi, je suis avec vous, dit le Seigneur.
Nígbà náà ni Hagai ìránṣẹ́ Olúwa ń jíṣẹ́ Olúwa fún àwọn ènìyàn pé, “Èmí wà pẹ̀lú yín,” ni Olúwa wí.
14 Et le Seigneur suscita l’esprit de Zorobabel, fils de Salathiel, chef de Juda, et l’esprit de Jésus, fils de Josédec, le grand prêtre, et l’esprit de tous ceux qui étaient restés du peuple, et ils entrèrent dans le temple, et ils travaillaient dans la maison du Seigneur des armées leur Dieu.
Nítorí náà, Olúwa ru ẹ̀mí Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli sókè, baálẹ̀ Juda àti ẹ̀mí Joṣua ọmọ Josadaki, olórí àlùfáà àti ẹ̀mí gbogbo ènìyàn ìyókù. Wọ́n sì wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí ní ṣiṣẹ́ lórí ilé Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run wọn,
15 Au vingt-quatrième jour, au sixième mois, en la seconde année du roi Darius;
ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kẹfà ní ọdún kejì ọba Dariusi.