< Esdras 2 >
1 Voici les fils de la province qui montèrent dentre les captifs qu’avait transportés à Babylone, Nabuchodonosor, roi de Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem et en Juda, chacun dans sa ville.
Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
2 Ceux qui vinrent avec Zorobabel et Josué sont: Néhémias, Saraïa, Rahélaïa, Mardochaï, Belsan, Mesphar, Béguaï, Réhum et Baana. Nombres des hommes du peuple d’Israël;
Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
3 Les fils de Pharos, deux mille cent soixante-douze;
Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
4 Les fils de Séphatia, trois cent soixante-douze;
Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
5 Les fils d’Aréa, sept cent soixante-quinze;
Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
6 Les fils de Phahath-Moab, des fils de Josué: Joab, deux mille huit cent douze;
Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
7 Les fils d’Elam, mille deux cent cinquante-quatre;
Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
8 Les fils de Zéthua, neuf cent quarante-cinq;
Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
9 Les fils de Zachaï, sept cent soixante;
Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
10 Les fils de Bani, six cent quarante-deux;
Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
11 Les fils de Bébaï, six cent vingt-trois:
Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
12 Les fils d’Azgad, mille deux cent vingt-deux;
Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
13 Les fils d’Adonicam, six cent soixante-six;
Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
14 Les fils de Béguaï, deux mille cinquante-six;
Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
15 Les fils d’Adin, quatre cent cinquante-quatre;
Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
16 Les fils d’Ather, qui étaient d’Ezéchias, quatre-vingt-dix-huit;
Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
17 Les fils de Bésaï, trois cent vingt-trois;
Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
18 Les fils de Jora, cent douze;
Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
19 Les fils d’Hasum, deux cent vingt-trois;
Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
20 Les fils de Gebbar, quatre vingt-quinze;
Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
21 Les fils de Bethléhem, cent vingt-trois;
Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
22 Les hommes de Nétupha, cinquante-six;
Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
23 Les hommes d’Anathoth, cent vingt-huit;
Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
24 Les fils d’Azmaveth, quarante-deux;
Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
25 Les fils de Cariathiarim, de Céphira et de Béroth, sept cent quarante-trois;
Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
26 Les fils de Rama et de Gabaa, six cent vingt et un;
Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
27 Les hommes de Machmas, cent vingt-deux;
Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
28 Les hommes de Béthel et de Haï, deux cent vingt-trois;
Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
29 Les fils de Nébo, cinquante-deux;
Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
30 Les fils de Megbis, cent cinquante-six;
Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
31 Les fils d’un autre Elam, mille deux cent cinquante-quatre;
Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
32 Les fils de Harim, trois cent vingt;
Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
33 Les fils de Lod, de Hadid et d’Ono, sept cent vingt-cinq;
Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
34 Les fils de Jéricho, trois cent quarante-cinq;
Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
35 Les fils de Sénaa, trois mille six cent trente.
Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
36 Les prêtres: Les fils de Jadaïa, dans la maison de Josué, neuf cent soixante-treize;
Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
37 Les fils d’Emmer, mille cinquante-deux;
Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
38 Les fils de Pheshur, mille deux cent quarante-sept;
Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
39 Les fils de Harim, mille dix-sept.
Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
40 Les Lévites: Les fils de Josué et de Cedmihel, fils d’Odovia, soixante-quatorze.
Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
41 Les chantres: Les fils d’Asaph, cent vingt-huit.
Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
42 Les fils des portiers: Les fils de Sellum, les fils d’Ater, les fils de Telmon, les fils d’Accub, les fils de Hatitha, les fils de Sobaï, tous ensemble, cent trente-neuf.
Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
43 Les Nathinéens: Les fils de Siha, les fils de Hasupha, les fils de Tabbaoth,
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
44 Les fils de Céros, les fils de Siaa, les fils de Phadon,
Kerosi, Siaha, Padoni,
45 Les fils de Lébana, les fils de Hagaba, les fils d’Accub,
Lebana, Hagaba, Akkubu,
46 Les fils de Hagab, les fils de Semlaï, les fils de Hanan,
Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
47 Les fils de Gaddel, les fils de Gaher, les fils de Raaïa,
Giddeli, Gahari, Reaiah,
48 Les fils de Rasin, les fils de Nécoda, les fils de Gazam,
Resini, Nekoda, Gassamu,
49 Les fils d’Aza, les fils de Phaséa, les fils de Bésée,
Ussa, Pasea, Besai,
50 Les fils d’Aséna, les fils de Munim, les fils de Néphusim,
Asna, Mehuni, Nefisimu,
51 Les fils de Bacbuc, les fils de Hacupha, les fils de Harhur,
Bakbu, Hakufa, Harhuri.
52 Les fils de Besluth, les fils de Mahida, les fils de Harsa,
Basluti, Mehida, Harṣa,
53 Les fils de Bercos, les fils de Sisara, les fils de Théma,
Barkosi, Sisera, Tema,
54 Les fils de Nasia, les fils de Hatipha,
Nesia àti Hatifa.
55 Les fils des serviteurs de Salomon, les fils de Sotaï, les fils de Sophéret, les fils de Pharuda,
Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
56 Les fils de Jala, les fils de Dercon, les fils de Geddel,
Jaala, Darkoni, Giddeli,
57 Les fils de Saphatia, les fils de Hatil, les fils de Phochéreth, qui étaient d’Asebaïm, les fils d’Ami;
Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
58 Tous les Nathinéens et les fils des serviteurs de Salomon, trois cent quatre-vingt-douze.
Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
59 Et ceux qui montèrent de Thelmala, Thelharsa, Chérub, Adon et Emer, et qui ne purent faire connaître la maison de leurs pères et leur race, s’ils étaient d’Israël, sont:
Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
60 Les fils de Dalaïa, les fils de Tobie, les fils de Nécoda, six cent cinquante-deux.
Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
61 Et d’entre les fils des prêtres: les fils de Hobia, les fils d’Accos, les fils de Berzellaï, qui prit parmi les filles de Berzellaï, le Galaadite, une femme, et fut appelé de leur nom;
Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
62 Ceux-ci cherchèrent l’écrit de leur généalogie et ne le trouvèrent pas, et ils furent rejetés du sacerdoce.
Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
63 Et Athersatha leur dit qu’ils ne mangeraient point de ce qui est très saint, jusqu’à ce qu’il s’élevât un prêtre instruit et parfait.
Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
64 Toute la multitude, comme un seul homme, était du nombre de quarante-deux mille trois cent soixante,
Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
65 Outre leurs serviteurs et servantes, qui étaient sept mille trois cent trente-sept; et parmi eux les chantres et les chanteuses étaient deux cents;
Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
66 Leurs chevaux sept cent trente-six; leurs mulets, deux cent quarante-cinq;
Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
67 Leurs chameaux, quatre cent tente-cinq; leurs ânes, six mille sept cent vingt.
ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
68 Et des princes des pères, étant entrés dans le temple du Seigneur, qui est à Jérusalem, firent spontanément les dons dans la maison de Dieu, pour la construire en son lieu.
Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
69 Ils donnèrent, selon leurs facultés, pour les dépenses de cet ouvrage, soixante et un mille solides d’or, et cinq mille mines d’argent, et cent vêtements sacerdotaux.
Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
70 Les prêtres donc, les Lévites, ceux du peuple, les chantres, les portiers et les Nathinéens, habitèrent dans leurs villes, et tout Israël dans ses cités.
Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.