< Ézéchiel 44 >

1 Et il me fit retourner vers la voie de la porte du sanctuaire extérieur, qui regardait vers l’orient; et elle était fermée.
Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
2 Et le Seigneur me dit: Cette porte sera fermée; elle ne sera pas ouverte, et aucun homme n’y passera, parce que le Seigneur Dieu d’Israël est entré par cette porte; et elle sera fermée
Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
3 Pour le prince. Le prince lui-même s’y assiéra, afin de manger le pain devant le Seigneur; par la voie de la porte du vestibule, il entrera, et par sa voie il sortira.
Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
4 Et il m’amena par la voie de la porte de l’aquilon, à la vue de la maison, et je vis, et voilà que la gloire du Seigneur remplit la maison du Seigneur, et je tombai sur ma face.
Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
5 Et le Seigneur me dit: Fils d’un homme, applique ton cœur, et vois de tes yeux, et de tes oreilles écoute toutes les choses que je te dis de toutes les cérémonies de la maison du Seigneur et de toutes ses lois: et tu appliqueras ton cœur à considérer les voies du temple avec toutes les sorties du sanctuaire.
Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
6 Et tu diras à la maison d’Israël qui m’exaspère: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Que tous vos crimes vous suffisent, maison d’Israël;
Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
7 Car vous engagez des fils de l’étranger, incirconcis de cœur et incirconcis de chair, à se tenir dans mon sanctuaire, et à souiller ma maison; et vous offrez mes pains, de la graisse et du sang, et vous rompez mon alliance par tous vos crimes.
Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
8 Et vous n’avez point observé les ordonnances de mon sanctuaire; et c’est pour vous-mêmes que vous avez établi des gardiens de mes prescriptions dans mon sanctuaire.
Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
9 Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Aucun étranger incirconcis de cœur et incirconcis de chair n’entrera dans mon sanctuaire, aucun fils de l’étranger qui est au milieu des enfants d’Israël.
Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
10 Mais les Lévites mêmes qui se sont retirés loin de moi dans l’erreur des enfants d’Israël, et se sont égarés à la suite de leurs idoles, et ont porté la peine de leur iniquité,
“‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Seront dans mon sanctuaire gardiens et portiers aux portes de la maison, et serviteurs de la maison; ce seront eux qui tueront les bêtes pour les holocaustes, et les victimes du peuple; et ce seront eux qui se tiendront en sa présence, afin de le servir.
Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
12 Parce qu’ils l’ont servi devant ses idoles et qu’ils sont devenus pour la maison d’Israël une pierre d’achoppement dans l’iniquité; c’est pour cela que J’ai levé ma main sur eux, dit le Seigneur, et ils porteront leur iniquité.
Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
13 Et ils ne s’approcheront pas de moi pour remplir les fonctions du sacerdoce en ma présence, et ils n’approcheront d’aucun de mes sanctuaires près des choses très saintes; mais ils porteront leur confusion et leurs crimes qu’ils ont commis.
Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
14 Et je les établirai portiers de la maison, dans toute sorte d’offices et dans tout ce qui s’y fait.
Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
15 Mais quant aux prêtres et aux Lévites, fils de Sadoc, qui ont gardé les cérémonies de mon sanctuaire, lorsque les enfants d’Israël erraient loin de moi, ce seront eux qui s’approcheront de moi pour me servir; et ils se tiendront en ma présence pour m’offrir la graisse et le sang des victimes, dit le Seigneur Dieu.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 Ce seront eux qui entreront dans mon sanctuaire, et eux qui s’approcheront de ma table pour me servir et pour garder mes cérémonies.
Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
17 Et lorsqu’ils entreront dans les portes du parvis intérieur, ils seront vêtus de robes de lin, et il n’y aura rien sur eux qui soit en laine, quand ils rempliront leur ministère aux portes du parvis intérieur, et au dedans.
“‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
18 Des bandeaux de lin seront à leur tête, et des caleçons de lin seront sur leurs reins, et ils ne se ceindront pas dans la sueur.
Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
19 Et lorsqu’ils sortiront dans le parvis extérieur pour aller parmi le peuple, ils quitteront les vêtements avec lesquels ils auront officié, et ils les déposeront dans la chambre du sanctuaire, ils se revêtiront d’autres vêtements, et ils ne sanctifieront pas le peuple avec leurs vêtements.
Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
20 Or ils ne raseront pas leur tête, et n’entretiendront pas leur chevelure; mais ils tondront soigneusement leurs têtes.
“‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
21 Aucun prêtre ne boira de vin, lorsqu’il devra entrer dans le parvis intérieur.
Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
22 Ils ne prendront pas pour épouses une veuve et une femme répudiée, mais des vierges de la race de la maison d’Israël; et ils pourront prendre aussi une veuve qui sera veuve d’un prêtre.
Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
23 Et ils enseigneront à mon peuple ce qu’il y a de différent entre ce qui est saint et ce qui est souillé; et ils lui montreront la différence entre ce qui est pur et ce qui est impur.
Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
24 Et lorsqu’il y aura une contestation, ils s’en tiendront à mes jugements, et ils jugeront; mes lois et mes ordonnances, ils les observeront dans toutes mes solennités, et mes sabbats, ils les sanctifieront.
“‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
25 Et ils n’entreront pas près d’un homme mort, afin qu’ils ne soient point souillés, à moins que ce ne soit près d’un père et d’une mère, et d’un fils, et d’une fille, et d’un frère, et d’une sœur qui n’a pas eu un second mari; ils en deviendraient impurs.
“‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
26 Et après que quelqu’un d’entre eux aura été purifié, on lui comptera encore sept jours.
Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
27 Et le jour de son entrée dans le sanctuaire au parvis intérieur, afin de me servir dans le sanctuaire, il fera une oblation pour son péché, dit le Seigneur Dieu.
Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
28 Mais il n’y aura point pour eux d’héritage; c’est moi qui suis leur héritage; et vous ne leur donnerez point de possession en Israël, car c’est moi qui suis leur possession.
“‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
29 La victime et pour le péché et pour le délit, ce sont eux qui la mangeront, et tout ce qui sera offert par vœu en Israël leur appartiendra.
Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
30 Et les prémices de tous les premiers-nés et tous les prélèvements sur toutes les choses qui sont offertes, appartiendront aux prêtres; les prémices même de toute votre nourriture, vous les donnerez au prêtre, afin qu’il répande la bénédiction sur votre maison.
Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
31 Les prêtres ne mangeront d’entre les oiseaux et d’entre les troupeaux aucun animal mort naturellement, ou pris par une bête.
Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.

< Ézéchiel 44 >