< Ézéchiel 4 >

1 Et toi, fils d’un homme, prends une brique, mets-la devant toi, et tu y traceras la cité de Jérusalem.
“Nísinsin yìí, ìwọ ọmọ ènìyàn, mú amọ̀ ṣíṣù kan, gbé e sí iwájú rẹ, kí o sì ya àwòrán ìlú Jerusalẹmu sí orí rẹ̀.
2 Et tu disposeras contre elle un siège, et tu bâtiras des fortifications, tu formeras un rempart, tu établiras contre elle des camps, et tu mettras des béliers autour.
Kí o sì dó tì í, kí o sì mọ ilé ìṣọ́ tì í, kí o sì mọ odi tì í, kí o sì gbé ogun sí i, kí o sì to òòlù yí i ká.
3 Et toi, prends pour toi une poêle de fer, et tu la placeras comme un mur de fer entre toi et entre la cité; tu dirigeras fixement ta face contre elle, et elle sera assiégée, et tu l’entoureras; c’est un signe pour la maison d’Israël.
Kí o sì fi àwo irin kan ṣe ògiri láàrín rẹ̀ àti ìlú yìí, kí o sì kọjú sí i, a ó sì dó tì í, ìwọ yóò sì dó tì í. Èyí yóò jẹ́ àmì fún ilé Israẹli.
4 Et toi, tu dormiras sur ton côté gauche, et tu mettras sur ce côté là les iniquités de la maison d’Israël, selon le nombre de jours que tu dormiras, et tu prendras sur toi leurs iniquités.
“Lẹ́yìn èyí, lọ fi ẹ̀gbẹ́ òsì dùbúlẹ̀, kí o sì gbé ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli lé orí ara rẹ. Iye ọjọ́ tí ìwọ bá fi sùn náà ni ìwọ yóò fi ru ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
5 Pour moi, je t’ai donné les années de leur iniquité, au nombre de trois cent quatre-vingt-dix jours; et tu porteras l’iniquité de la maison d’Israël.
Nítorí mo fi iye ọdún tí wọ́n fi ṣẹ̀ fún ọ gẹ́gẹ́ bí iye ọjọ́ tí ìwọ yóò lò. Nítorí náà, ìwọ yóò ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Israẹli fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
6 Et, quand tu auras accompli cela, tu dormiras une seconde fois sur ton côté droit, et tu prendras sur toi l’iniquité de la maison de Juda pendant quarante jours; c’est un jour pour une année; un jour, dis-je, pour une année, que je t’ai donné.
“Tí o bá parí èyí, tún fi ẹ̀gbẹ́ ọ̀tún dùbúlẹ̀ kí o sì ru ẹ̀ṣẹ̀ ilé Juda fún ogójì ọjọ́, nítorí pé ọjọ́ kan ló dúró fún ọdún kan.
7 Et vers le siège de Jérusalem tu tourneras ta face, et ton bras sera étendu, et tu prophétiseras contre elle.
Ìwọ dojúkọ ìgbógunti Jerusalẹmu, na ọwọ́ rẹ sí i, kí o sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ìlú náà.
8 Voilà que je t’ai environné de chaînes, et tu ne te retourneras pas d’un de tes côtés sur l’autre côté, jusqu’à ce que tu aies accompli les jours de ton siège.
Èmi yóò dè ọ́ ní okùn dé bi pé ìwọ kò ní í le yírapadà láti ìhà ọ̀tún sí ìhà òsì títí tí ọjọ́ ìgbóguntì rẹ yóò fi pé.
9 Et toi, prends pour toi du froment, de l’orge, des fèves, des lentilles, du millet et de la vesce, et tu les mettras dans un seul vase, et tu t’en feras des pains, selon le nombre de jours que tu dormiras sur ton côté; pendant trois cent quatre-vingt-dix jours, tu mangeras cela.
“Mú alikama, ọkà bàbà àti barle, erèé àti lẹntili, jéró àti ẹwẹ; fi àwọn nǹkan wọ̀nyí ṣe àkàrà tí ìwọ yóò máa jẹ nígbà tí ìwọ bá dùbúlẹ̀ fún irinwó ọjọ́ ó dín mẹ́wàá.
10 Or l’aliment dont tu te nourriras sera du poids de vingt statères par jour, et tu en mangeras d’un temps à un temps.
Wọn òsùwọ̀n ogún ṣékélì oúnjẹ tí ìwọ yóò máa jẹ lójoojúmọ́ kí o sì máa jẹ ẹ́ ní àkókò tí a ti yà sọ́tọ̀.
11 Et l’eau, tu en boiras par mesure, la sixième partie d’un hin; et tu la boiras d’un temps à un temps.
Bákan náà, wọn ìdámẹ́fà omi, kí ìwọ ó sì máa mú ní àkókò tí a yà sọ́tọ̀.
12 Et tu le mangeras comme un pain d’orge cuit sous la cendre; et de l’ordure qui sort de l’homme, tu le couvriras à leurs yeux.
Ìwọ yóò sì jẹ ẹ́ bí àkàrà barle; dín in ní ojú àwọn ènìyàn, ìgbẹ́ ènìyàn ni kí o fi dáná rẹ.”
13 Et dit le Seigneur: C’est ainsi que les enfants d’Israël mangeront leur pain souillé parmi les nations vers lesquelles je les chasserai.
Olúwa sọ pé, “Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli yóò jẹ oúnjẹ àìmọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí èmi yóò lé wọn lọ.”
14 Et je dis: Ah! ah! ah! Seigneur Dieu, voilà que mon âme n’a pas été souillée; et je n’ai pas mangé d’animal crevé, ni déchiré par des bêtes, depuis mon enfance jusqu’à maintenant, et il n’est entré dans ma bouche aucune chair immonde.
Nígbà náà ni mo wí pé, “Háà! Kò rí bẹ́ẹ̀ Olúwa Olódùmarè! Láti ìgbà èwe mi di ìsinsin yìí èmi kò tí ì sọ ara mi di aláìmọ́ rí. Èmi kò tí ì jẹ ohun tó kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí tí ẹranko búburú fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ. Bẹ́ẹ̀ ni ẹran àìmọ́ kan kò tí ì wọ ẹnu mi rí.”
15 Et il me dit: Voilà que je t’ai donné la fiente des bœufs au lieu des excréments humains; et tu feras ton pain avec cette fiente.
Nígbà náà ló wí fún mi pé, “Wò ó, Èmi ó fún ọ ní ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn. Èmi yóò mú ki ó dín àkàrà rẹ lórí ìgbẹ́ màlúù dípò ìgbẹ́ ènìyàn.”
16 Et il me dit: Fils d’un homme, voilà que moi je briserai le bâton du pain dans Jérusalem; et ils mangeront le pain au poids et dans l’inquiétude, et ils boiront l’eau par mesure et dans l’angoisse;
Ó sì tún sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, èmi yóò dáwọ́ ìpèsè oúnjẹ dúró ní Jerusalẹmu. Ní pípín ni àwọn ènìyàn yóò máa pín oúnjẹ jẹ pẹ̀lú ìfọkànsọ́nà bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wọn yóò máa mu omi pẹ̀lú ìdààmú,
17 Afin que, le pain et l’eau manquant, chacun tombe sur son frère et qu’ils se dessèchent dans leurs iniquités.
nítorí pé oúnjẹ àti omi yóò wọ́n. Wọn yóò máa wo ara wọn pẹ̀lú ìyanu, èmi yóò sì jẹ́ kí wọ́n ṣọ̀fọ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ wọn.

< Ézéchiel 4 >