< Ézéchiel 34 >

1 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ́ mi wá:
2 Fils d’un homme, prophétise sur les pasteurs d’Israël: prophétise, et tu diras aux pasteurs: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Malheur aux pasteurs d’Israël qui se paissaient eux-mêmes; n’est-ce pas les troupeaux que les pasteurs font paître?
“Ọmọ ènìyàn, fi àsọtẹ́lẹ̀ tako Olùṣọ́-àgùntàn Israẹli; sọtẹ́lẹ̀ fún wọn pé: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn Israẹli tí ó ń tọ́jú ara wọn nìkan! Ṣé ó dára kí olùṣọ́-àgùntàn ṣaláì tọ́jú agbo ẹran?
3 Vous mangiez le lait, et vous vous couvriez des laines, et ce qui était gras, vous l’égorgiez: mais mon troupeau, vous ne le paissiez pas.
Ìwọ jẹ wàrà. O sì wọ aṣọ olówùú sí ara rẹ, o sì ń pa ẹran tí ó wù ọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kò tọ́jú agbo ẹran.
4 Ce qui était faible, vous ne l’avez pas fortifié; et ce qui était malade, vous ne l’avez pas guéri; et ce qui a été brisé, vous ne l’avez pas lié; et ce qui était égaré, vous ne l’avez pas ramené; et ce qui était perdu, vous ne l’avez pas cherché; mais vous leur commandiez avec rigueur et avec empire.
Ìwọ kò ì tí ì mú aláìlágbára lára le tàbí wo aláìsàn sàn tàbí di ọgbẹ́ fún ẹni tí o fi ara pa. Ìwọ kò í tí ì mú aṣáko padà tàbí wá ẹni tí ó nù. Ìwọ ṣe àkóso wọn ní ọ̀nà lílé pẹ̀lú ìwà òǹrorò.
5 Et mes brebis ont été dispersées, parce qu’il n’y avait point de pasteur; et elles sont devenues la pâture de toutes les bêtes des champs, et elles ont été dispersées.
Nítorí náà wọn fọ́n káàkiri nítorí àìsí olùṣọ́-àgùntàn, nígbà tí wọ́n fọ́nká tán wọn di ìjẹ fún gbogbo ẹranko búburú.
6 Mes troupeaux ont erré sur toutes les montagnes et sur toute colline élevée; et sur toute la face de la terre mes troupeaux ont été dispersés, et il n’y avait personne qui les recherchât, il n’y avait personne, dis-je, qui les recherchât.
Àgùntàn mi n rin ìrìn àrè kiri ní gbogbo àwọn òkè gíga àti òkè kékeré. A fọ́n wọn ká gbogbo orí ilẹ̀ ẹni kankan kò sì wá wọn.
7 À cause de cela, pasteurs, écoutez la parole du Seigneur.
“‘Nítorí náà, ìwọ olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
8 Je vis, moi, dit le Seigneur Dieu: parce que mes troupeaux sont devenus une proie, et mes brebis la pâture de toutes les bêtes des champs, parce qu’il n’y avait pas de pasteur, car mes pasteurs n’ont pas cherché mon troupeau; mais les pasteurs se paissaient eux-mêmes, et mes troupeaux, ils ne les paissaient pas;
Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ní Olúwa Olódùmarè wí, nítorí pé agbo ẹran mi kò ní olùṣọ́-àgùntàn nítorí tí a kọ̀ wọ́n, tì wọ́n sì di ìjẹ fún ẹranko búburú gbogbo àti pé, nítorí tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn mi kò ṣe àwárí agbo ẹran mi, ṣùgbọ́n wọn ń ṣe ìtọ́jú ara wọn dípò ìtọ́jú agbo ẹran mi,
9 À cause de cela, pasteurs, écoutez la parole du Seigneur.
nítorí náà, ẹ̀yin olùṣọ́-àgùntàn, gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
10 Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que je viens moi-même vers ces pasteurs; je redemanderai mon troupeau à leur main, et j’empêcherai qu’ils ne paissent à l’avenir un troupeau, et que ces pasteurs ne se paissent eux-mêmes; et j’arracherai mon troupeau à leur bouche, et il ne sera plus leur nourriture.
Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi ṣe ìlòdì sí àwọn Olùṣọ́-àgùntàn, èmi yóò sì béèrè agbo ẹran mi lọ́wọ́ wọn. Èmi yóò sì mú wọn dẹ́kun àti máa darí agbo ẹran mi, tí àwọn olùṣọ́-àgùntàn náà kò sì ní lè bọ́ ara wọn mọ́. Èmi yóò gba agbo ẹran mi kúrò ni ẹnu wọn, kì yóò sì jẹ́ oúnjẹ fún wọn mọ́.
11 Parce que voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi-même je rechercherai mes brebis, et que je les visiterai.
“‘Nítorí èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi fúnra mi yóò wá àgùntàn mi kiri, èmi yóò sì ṣe àwárí wọn.
12 Comme un berger visite son troupeau au jour où il est au milieu de ses brebis disséminées; ainsi je visiterai mes brebis; et je les délivrerai de tous les lieux où elles avaient été dispersées dans un jour de nuage et d’obscurité;
Gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe fojú tó agbo ẹran rẹ̀ tí ó fọ́nká nígbà tí ó wà pẹ̀lú wọn, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣe fojú tó àgùntàn mi. Èmi yóò gbá wọn kúrò ni gbogbo ibi tí wọ́n fọ́nká sí ni ọjọ́ ìkùùkuu àti òkùnkùn.
13 Et je les retirerai d’entre les peuples, et je les rassemblerai de divers pays, et je les amènerai dans leur propre terre, et je les ferai paître sur les montagnes d’Israël, le long des ruisseaux, et dans tous les lieux habités du pays.
Èmi yóò mú wọn jáde kúrò ní àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò sì kó wọn jọ láti inú àwọn ìlú, èmi yóò sì mú wọn wá sí ilẹ̀ ara wọn. Èmi yóò mú wọn jẹ ni orí àwọn òkè gíga Israẹli, ni àárín àwọn òkè àti ní gbogbo ibùdó ilẹ̀ náà.
14 C’est dans les pâturages les plus abondants que je les ferai paître, et sur les hautes montagnes d’Israël que seront leurs pâturages: là, elles se reposeront sur des herbes verdoyantes, et elles paîtront dans des pâturages gras, sur les montagnes d’Israël.
Èmi yóò ṣe ìtọ́jú wọn ní pápá oko tútù dáradára, àní orí àwọn òkè gíga ti Israẹli ni yóò jẹ́ ilẹ̀ ìjẹ koríko wọ́n. Níbẹ̀ wọn yóò dùbúlẹ̀ ní ilẹ̀ ìjẹ koríko dídára, níbẹ̀ wọn yóò jẹun ní pápá oko tútù tí ó dara ní orí òkè ti Israẹli.
15 C’est moi qui paîtrai mes brebis, moi qui les ferai reposer, dit le Seigneur Dieu.
Èmi fúnra mi yóò darí àgùntàn mi, èmi yóò mú wọn dùbúlẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 Ce qui était perdu, je le rechercherai; et ce qui était égaré, je le ramènerai; et ce qui était brisé, je le lierai; et ce qui était faible, je le fortifierai; et ce qui était fort et gras, je le conserverai, et je les ferai paître avec discernement.
Èmi yóò ṣe àwárí àwọn tí ó nú, èmi yóò mú àwọn tí ó ń rin ìrìn àrè kiri padà. Èmi yóò di ọgbẹ́ àwọn tí ó fi ara pa, èmi yóò sì fún àwọn aláìlágbára ni okun, ṣùgbọ́n àwọn tí ó sanra tí ó sì ni agbára ní èmi yóò parun. Èmi yóò ṣe olùṣọ́ àwọn agbo ẹran náà pẹ̀lú òdodo.
17 Mais vous, mes troupeaux, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi je juge entre troupeau et troupeau de béliers et de boucs.
“‘Ní tìrẹ, agbo ẹran mi, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn, àti láàrín àgbò àti ewúrẹ́.
18 N’était-ce pas assez pour vous de paître en de bons pâturages? mais vous avez de plus foulé aux pieds les restes de vos pâturages, et lorsque vous buviez une eau très pure, vous troubliez le reste avec vos pieds.
Ṣé oúnjẹ jíjẹ ní pápá oko tútù dídára kò tó yín! Ṣé ó jẹ́ dandan fún ọ láti fi ẹsẹ̀ tẹ pápá oko tútù rẹ tí ó kù? Ṣé omi tí ó tòrò kò tó fún yín ní mímu? Ṣe dandan ni kí ó fi ẹrẹ̀ yí ẹsẹ̀ yín?
19 Et mes brebis paissaient ce qui avait été foulé par vos pieds, et ce que vos pieds avaient troublé, elles le buvaient.
Ṣé dandan ni kí agbo ẹran mi jẹ́ koríko tí ẹ ti tẹ̀ mọ́lẹ̀, kí wọn sì mú omi tí wọ́n ti fi ẹsẹ̀ wọn sọ di ẹrẹ̀?
20 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voilà que moi-même je juge entre une brebis grasse et une maigre;
“‘Nítorí náà, èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí fún wọn: Wò ó, èmi fúnra mi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn tí ó sanra àti èyí tí ó rù.
21 Parce que vous heurtiez des côtés et de l’épaule, et que vous choquiez de vos cornes toutes les brebis faibles, jusqu’à ce qu’elles fussent dispersées dehors;
Nítorí ti ìwọ sún síwájú pẹ̀lú ìhà àti èjìká, tí ìwọ sì kan aláìlágbára àgùntàn pẹ̀lú ìwo rẹ títí ìwọ fi lé wọn lọ,
22 Je sauverai mon troupeau, il ne sera plus en proie, et je jugerai entre brebis et brebis.
Èmi yóò gba agbo ẹran mi là, a kì yóò sì kò wọ́n tì mọ́. Èmi yóò ṣe ìdájọ́ láàrín àgùntàn kan àti òmíràn.
23 Et JE SUSCITERAI SUR ELLES UN PASTEUR UNIQUE qui les paisse, mon serviteur David; lui-même me les paîtra, et il sera pour elles un pasteur.
Èmi yóò fi Olùṣọ́-àgùntàn kan ṣe olórí wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi, òun yóò sì tọ́jú wọn; òun yóò bọ́ wọn yóò sì jẹ́ Olùṣọ́-àgùntàn wọn.
24 Mais moi, le Seigneur, je serai leur Dieu, et mon serviteur David sera prince au milieu d’eux; c’est moi, le Seigneur, qui ai parlé.
Èmi Olúwa yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, ìránṣẹ́ mi Dafidi yóò jẹ́ ọmọ-aládé láàrín wọn. Èmi Olúwa ní o sọ̀rọ̀.
25 Et je ferai avec eux une alliance de paix, et j’exterminerai de la terre les bêtes très mauvaises; et ceux qui habitent dans le désert dormiront avec sécurité dans les forêts.
“‘Èmi yóò dá májẹ̀mú àlàáfíà pẹ̀lú wọn, èmi yóò sì gba ilẹ̀ náà kúrò lọ́wọ́ ẹranko búburú, kí wọn kí o lè gbé ní aṣálẹ̀, kí àgùntàn sì gbé ní inú igbó ní àìléwu.
26 Et je les rendrai autour de ma colline une bénédiction; et j’amènerai la pluie en son temps; ce seront des pluies de bénédiction.
Èmi yóò bùkún wọn àti ibi agbègbè ti ó yí òkè mi ká. Èmi yóò rán ọ̀wààrà òjò ni àkókò; òjò ìbùkún yóò sì wà.
27 Et l’arbre des champs donnera son fruit, et la terre donnera son germe; et ils seront dans leur terre sans crainte; et ils sauront que je suis le Seigneur, lorsque j’aurai brisé les chaînes de leur joug, et que je les aurai arrachés de la main de ceux qui les tenaient sous leur empire.
Àwọn igi igbó yóò mú èso wọn jáde, ilẹ̀ yóò sì mu irúgbìn jáde; A yóò sì dá ààbò bo àwọn ènìyàn ní ilẹ̀ náà. Wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá já àwọn ohun tí ó ṣe okùnfà àjàgà, tí mo sì gbà wọ́n kúrò lọ́wọ́ àwọn tí ó fi wọ́n ṣe ẹrú.
28 Et ils ne seront plus en proie aux nations, et les bêtes de la terre ne les dévoreront pas; mais ils habiteront avec confiance sans aucune crainte.
Àwọn orílẹ̀-èdè kì yóò lè kó wọn ní ẹrú mọ́, àwọn ẹranko búburú kì yóò lè pa wọn mọ́. Wọn yóò gbé ni àìléwu, kò sì ṣí ẹni kankan tí yóò le dẹ́rùbà wọ́n.
29 Et je leur susciterai un germe renommé, ils ne seront plus détruits par la famine sur la terre, et ils ne porteront plus l’opprobre des nations.
Èmi yóò pèsè ilẹ̀ ti o ní oríyìn fún èso rẹ̀ fún wọn, wọn kì yóò sì jìyà nípasẹ̀ ìyàn mọ́ ni ilẹ̀ náà tàbí ru ẹ̀gàn àwọn orílẹ̀-èdè.
30 Et ils sauront que moi le Seigneur leur Dieu, je suis avec eux, et qu’eux-mêmes sont mon peuple, la maison d’Israël, dit le Seigneur Dieu.
Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, èmi ni Olúwa Ọlọ́run wọn, èmi wà pẹ̀lú wọn àti pé, àwọn ilé Israẹli jẹ́ ènìyàn mi, ni Olúwa Olódùmarè wí.
31 Mais vous, mes troupeaux, les troupeaux de mon pâturage, vous êtes des hommes, et moi je suis le Seigneur votre Dieu, dit le Seigneur Dieu.
Ìwọ àgùntàn mi, àgùntàn pápá mi; ni ènìyàn, èmi sì ni Ọlọ́run rẹ; ni Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ézéchiel 34 >