< Ézéchiel 32 >

1 Et il arriva, en la douzième année, au douzième mois, au premier jour du mois, que la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kejìlá, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Fils d’un homme, fais entendre des lamentations sur Pharaon, roi d’Egypte, et tu lui diras: Tu as été assimilé à un lion de nations et au dragon qui est dans la mer, et tu agitais ta corne dans tes fleuves, et tu troublais les eaux avec tes pieds, et tu foulais leurs fleuves.
“Ọmọ ènìyàn, ṣe ìpohùnréré ẹkún nítorí Farao ọba Ejibiti kí o sì wí fún un: “‘Ìwọ dàbí kìnnìún láàrín àwọn orílẹ̀-èdè náà; ìwọ dàbí ohun ẹ̀mí búburú inú àwọn omi okun to ń lọ káàkiri inú àwọn odò rẹ, ìwọ fi ẹsẹ̀ rẹ tẹ omi láti mú kí àwọn odò ní ẹrẹ̀.
3 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur: J’étendrai sur toi mon filet par une multitude de peuples nombreux, et je t’entraînerai dans mon filet.
“‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ìpéjọ ènìyàn èmi yóò da àwọ̀n mi bò ọ́ wọn yóò sì fà ọ́ sókè nínú àwọ̀n mi.
4 Je te jetterai sur la terre, et je t’étendrai sur la face d’un champ; et je ferai habiter sur toi tous les volatiles du ciel, et je rassasierai de toi toutes les bêtes de la terre.
Èmi yóò jù ọ́ sí orí ilẹ̀ èmi yóò sì fà ọ́ sókè sí orí pápá gbangba. Èmi yóò jẹ́ kí gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ní orí rẹ. Gbogbo àwọn ẹranko ayé yóò fi ìwọra gbé ara wọn lórí rẹ.
5 J’exposerai ta chair sur les montagnes, et je remplirai les collines de ta sanie.
Èmi yóò tan ẹran-ara rẹ ká sórí àwọn òkè gíga ìyókù ara rẹ ní wọn yóò fi kún àwọn àárín àwọn òkè gíga.
6 J’arroserai la terre sur les montagnes de ton sang infect; et les vallées seront remplies de toi.
Ẹ̀jẹ̀ rẹ ti ń sàn ní èmi yóò sì fi rin ilẹ̀ náà gbogbo ọ̀nà sí orí àwọn òkè gíga, àwọn àlàfo jíjìn ní wọn yóò kún fún ẹran-ara rẹ.
7 Et lorsque tu t’éteindras, je couvrirai le ciel, et je ferai noircir ses étoiles; je couvrirai le soleil d’un nuage, et la lune ne donnera pas sa lumière.
Nígbà tí mo bá fọ́n ọ jáde, èmi yóò pa ọ̀run dé àwọn ìràwọ̀ wọn yóò sì ṣókùnkùn; èmi yóò sì fi ìkùùkuu bo oòrùn òṣùpá kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀ rẹ̀.
8 Tous les flambeaux du ciel, je les ferai s’affliger sur toi; et je répandrai des ténèbres sur ta terre, dit le Seigneur Dieu; lorsque tomberont tes blessés sur la terre, dit le Seigneur Dieu.
Gbogbo ìmọ́lẹ̀ títàn ní ojú ọ̀run ni èmi yóò mú ṣókùnkùn lórí rẹ; èmi yóò mú òkùnkùn wá sórí ilẹ̀ rẹ, ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Et j’irriterai le cœur de peuples nombreux, lorsque j’apprendrai ta destruction parmi les nations, à des pays que tu ne connais pas.
Èmi yóò da ọkàn ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn rú nígbà tí mo bá mú ìparun rẹ wá ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè tí ìwọ kò í tí ì mọ̀.
10 Et je frapperai de stupeur à ton sujet des peuples nombreux; et leurs rois seront saisis d’effroi et d’une horreur extrême à cause de toi, lorsque mon glaive commencera à voler sur leurs faces, et chacun sera soudainement frappé de stupeur pour son âme au jour de ta ruine.
Èmi yóò mú kí ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn dẹ́rùbà ọ́, àwọn ọba wọn yóò sì wárìrì fún ìbẹ̀rù pẹ̀lú ìpayà nítorí rẹ, nígbà tí mo bá ju idà mi ní iwájú wọn. Ní ọjọ́ ìṣubú rẹ ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú wọn yóò wárìrì ní gbogbo ìgbà fún ẹ̀mí rẹ.
11 Parce que voici ce que dit le Seigneur Dieu: Le glaive du roi de Babylone viendra à toi;
“‘Nítorí èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: “‘Idà ọba Babeli yóò wá sí orí rẹ,
12 Par les glaives des forts j’abattrai ta multitude; toutes ces nations sont invincibles, et elles détruiront l’orgueil de l’Egypte, et sa multitude sera dissipée.
Èmi yóò mú kí ìjọ ènìyàn rẹ kí ó tí ipa idà àwọn alágbára ènìyàn ṣubú àwọn orílẹ̀-èdè aláìláàánú jùlọ. Wọn yóò tú ìgbéraga Ejibiti ká, gbogbo ìjọ rẹ ní a yóò dá ojú wọn bolẹ̀.
13 Et je ferai périr toutes ses bêtes qui étaient le long des grandes eaux; et le pied de l’homme ne les agitera plus, et le sabot des bêtes ne les troublera pas.
Gbogbo ẹran ọ̀sìn rẹ ni èmi yóò parun ní ẹ̀gbẹ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kì i ṣe ẹsẹ̀ ènìyàn ní yóò tẹ ibẹ̀ ẹsẹ̀ ẹran ọ̀sìn kì yóò sì mú kí ibẹ̀ ni ẹrọ̀fọ̀.
14 Alors je rendrai leurs eaux très pures, et je ferai couler leurs fleuves comme l’huile, dit le Seigneur Dieu,
Lẹ́yìn náà èmi yóò mú kí omi rẹ̀ tòrò kí àwọn odò rẹ̀ kí o sàn bí epo, ni Olúwa Olódùmarè wí.
15 Lorsque j’aurai livré la terre d’Egypte à la désolation; mais la terre sera dénuée de ce qui la remplissait, quand j’aurai frappé tous ses habitants; et ils sauront que je suis le Seigneur.
Nígbà tí mo bá sọ Ejibiti di ahoro, tí mo sì kó gbogbo ohun tí ó wà ní orí ilẹ̀ náà kúrò. Nígbà tí mo bá gé àwọn olùgbé ibẹ̀ lulẹ̀, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’
16 Voici un cantique de deuil, et on le chantera; les filles des nations le chanteront; c’est sur l’Egypte et sur sa multitude qu’elles le chanteront, dit le Seigneur Dieu.
“Èyí yìí ni ẹkún tí a yóò sun fún un. Àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè yóò sun ún; nítorí Ejibiti àti gbogbo ìjọ rẹ, wọn yóò sun ún, ní Olúwa Olódùmarè wí.”
17 Et il arriva, en la douzième année, au quinzième jour du mois, que la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù, ọdún kejìlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ mí wá:
18 Fils d’un homme, chante un cantique lugubre sur la multitude de l’Egypte; et précipite-la, elle-même et les filles des nations puissantes, au fond de la terre, avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Ọmọ ènìyàn, pohùnréré ẹkún lórí Ejibiti kí o sì ránṣẹ́ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀ àti òun àti àwọn ọmọbìnrin orílẹ̀-èdè alágbára, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ìsàlẹ̀, kòtò.
19 Que qui es-tu plus belle? descends, et dors avec les incirconcis.
Sọ fún wọn, ‘Ǹjẹ́ ìwọ ní ojúrere jù àwọn tí o kù lọ? Lọ sí ìsàlẹ̀ kí a sì tẹ́ ọ sí àárín àwọn aláìkọlà náà.’
20 C’est au milieu des tués par le glaive qu’ils tomberont, le glaive a été livré, ils l’ont attirée ainsi que tous ses peuples.
Wọn yóò ṣubú láàrín àwọn tí a fi idà pa. A fa idà yọ; jẹ́ kí a wọ́ Ejibiti kúrò pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀.
21 Ils lui parleront du milieu de l’enfer, les plus puissants d’entre les forts qui sont descendus avec ses auxiliaires, et qui dorment incirconcis, tués par le glaive. (Sheol h7585)
Láti inú isà òkú alágbára tí í ṣe aṣáájú yóò sọ nípa Ejibiti àti àwọn àlejò rẹ̀, ‘Wọn ti wá sí ìsàlẹ̀, wọn sì sùn pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.’ (Sheol h7585)
22 Là est Assur et toute sa multitude; autour de lui sont ses sépulcres, tous les tués, et ceux qui sont tombés sous le glaive;
“Asiria wà níbẹ̀ pẹ̀lú gbogbo jagunjagun rẹ̀; àwọn isà òkú àwọn tí a ti pa sì yí i ká, gbogbo àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú.
23 Dont les sépulcres ont été placés au plus profond d’une fosse; et sa multitude se trouve autour de son tombeau; tous tués et tombés sous le glaive, qui autrefois avaient répandu la frayeur dans la terre des vivants.
Isà òkú wọn wà ní ibi tí ó jinlẹ̀ gan an nínú kòtò. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè ní a pa, tí ó ti ipa idà ṣubú.
24 Là est Elam, et toute sa multitude autour de son sépulcre; tous ceux-ci tués et tombés sous le glaive; qui sont descendus incirconcis au fond de la terre, qui ont jeté la terreur dans la terre des vivants, et ont porté leur ignominie avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Elamu wà níbẹ̀, o yí isà òkú rẹ̀ ká pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀. Gbogbo wọn ni a pa, àwọn tí ó ti ipa idà ṣubú. Gbogbo àwọn tí ó ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè lọ sí ìsàlẹ̀ láìkọlà sí abẹ́ ilẹ̀. Wọ́n gba ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
25 Au milieu des tués on a placé son lit parmi tous ses peuples; autour de lui est son sépulcre; tous ceux-ci sont des incirconcis et des tués par le glaive; car ils jetèrent la terreur dans la terre des vivants, et ils ont porté leur ignominie avec ceux qui descendent dans la fosse; c’est au milieu des tués qu’ils ont été placés.
A ṣe ibùsùn fún un láàrín àwọn tí a pa, pẹ̀lú gbogbo ìjọ rẹ̀ tí ó yí isà òkú ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, tí a fi idà pa. Nítorí pé a tan ẹ̀rù wọn ká ilẹ̀ alààyè, wọn ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò; a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a pa.
26 Là est Mosoch, et Thubal, et toute sa multitude; autour de lui sont ses sépulcres; tous ceux-ci sont des incirconcis, et des tués, et des tombés sous le glaive, parce qu’ils jetèrent la frayeur dans la terre des vivants.
“Meṣeki àti Tubali wà níbẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ogun wọn yí isà òkú wọn ká. Gbogbo wọn jẹ́ aláìkọlà, wọ́n fi idà pa wọ́n nítorí ẹ̀rù tiwọn tàn ká ilẹ̀ alààyè.
27 Et ils ne dormiront pas avec les forts, et ceux qui sont tombés, et les incirconcis descendus dans l’enfer avec leurs armes, et qui ont mis leurs glaives sous leurs têtes; et leurs iniquités ont pénétré dans leurs os, parce qu’ils sont devenus la terreur des forts dans la terre des vivants. (Sheol h7585)
Wọn kì yóò sì dùbúlẹ̀ ti àwọn tí ó ṣubú nínú àwọn aláìkọlà, tí wọn sọ̀kalẹ̀ lọ sí ipò òkú pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun wọn, wọ́n tí fi idà wọn rọ orí wọn. Ṣùgbọ́n àìṣedéédéé wọn yóò wà ní orí egungun wọn—bí wọ́n tilẹ̀ jẹ́ ẹ̀rù àwọn alágbára ní ilẹ̀ alààyè. (Sheol h7585)
28 Et toi donc, au milieu des incirconcis tu seras brisé, et tu dormiras avec les tués par le glaive.
“Ìwọ náà, Farao, ní yóò ṣẹ, ti yóò dùbúlẹ̀ láàrín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa.
29 Là est l’Idumée, et ses rois et tous ses chefs, qui ont été mis avec leur armée parmi les tués par le glaive, et qui ont dormi avec les incirconcis et avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Edomu wà níbẹ̀, àwọn ọba rẹ̀ àti gbogbo ọmọbìnrin ọba; bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó ní agbára, a tẹ́ wọn pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. Wọn dùbúlẹ̀ pẹ̀lú aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn ti o lọ sínú kòtò.
30 Là sont tous les princes de l’aquilon et tous les chasseurs qui ont été amenés avec les tués, tremblants et confondus dans leur force; qui ont dormi incirconcis avec les tués par le glaive, et ont porté leur confusion avec ceux qui descendent dans la fosse.
“Gbogbo àwọn ọmọ-aládé ilẹ̀ àríwá àti gbogbo àwọn ará Sidoni wà níbẹ̀; wọn lọ sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àwọn tí a pa ní ìtìjú, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn ṣe okùnfà ẹ̀rù pẹ̀lú agbára wọn. Wọn sùn ní àìkọlà pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa, wọn sì ru ìtìjú wọn pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ìsàlẹ̀ kòtò.
31 Pharaon les a vus, et il s’est consolé de toute sa multitude qui a été tuée par le glaive; Pharaon et toute son armée, dit le Seigneur Dieu,
“Farao, òun àti gbogbo jagunjagun rẹ̀ yóò rí wọn, a yóò sì tù ú nínú nítorí gbogbo ogun rẹ̀ tí a fi idà pa, ní Olúwa Olódùmarè wí.
32 Parce que j’ai répandu ma terreur dans la terre des vivants, et il a dormi au milieu des incirconcis avec les tués par le glaive; Pharaon et toute sa multitude, dit le Seigneur Dieu.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti tan ẹ̀rù ká ilẹ̀ alààyè, Farao àti gbogbo ogun rẹ̀ ni a yóò tẹ́ sí àárín aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 32 >