< Ézéchiel 31 >

1 Et il arriva en la onzième année, au troisième mois, au premier jour du mois, que la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kẹta ọdún kọkànlá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Fils d’un homme, dis à Pharaon, roi d’Egypte, et à son peuple: À qui es-tu devenu semblable dans ta grandeur?
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún Farao ọba Ejibiti àti sí ìjọ rẹ̀: “‘Ta ní a le fiwé ọ ní ọláńlá?
3 Voilà qu’Assur était comme un cèdre sur le Liban, beau en ses branches, abondant en feuillage, et d’une hauteur très élevée, et entre des rameaux touffus montait sa cime.
Kíyèsi Asiria, tí ó jẹ́ igi kedari ni Lebanoni ní ìgbà kan rí, pẹ̀lú àwọn ẹ̀ka dáradára tí ó ṣẹ́ ìji bo igbó náà; tí ó ga sókè, òkè rẹ̀ lókè ni ewé tí ó nípọn wà.
4 Des eaux l’ont nourri; l’abîme l’a fait pousser en haut; ses fleuves coulaient autour de ses racines, et il a envoyé ses ruisseaux vers tous les arbres de la campagne.
Omi mú un dàgbàsókè: orísun omi tí ó jinlẹ̀ mú kí o dàgbàsókè; àwọn odo rẹ̀ ń sàn yí ìdí rẹ̀ ká, ó sì rán ìṣàn omi rẹ̀ sí gbogbo igi orí pápá.
5 À cause de cela, sa hauteur s’est élevée au-dessus de tous les arbres de la contrée, et ses branches se sont multipliées; et ses rameaux se sont élevés, arrosés par les grandes eaux.
Nítorí náà ó ga sí òkè fíofío ju gbogbo igi orí pápá lọ; ẹ̀ka rẹ̀ pọ̀ sí i àwọn ẹ̀ka rẹ̀ sì gùn, wọn tẹ́ rẹrẹ nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi.
6 Et, lorsqu’il eut étendu son ombre, tous les volatiles du ciel firent leur nid sur ses rameaux, et sous son feuillage toutes les bêtes des forêts déposèrent leurs petits, et sous son ombrage habitait une troupe de nations très nombreuses.
Ẹyẹ ojú ọ̀run kọ ilé sí ẹ̀ka rẹ̀ gbogbo ẹranko igbó ń bímọ ní abẹ́ ẹ̀ka rẹ̀; gbogbo orílẹ̀-èdè ńlá ń gbé abẹ́ ìji rẹ̀.
7 Et il était très beau dans sa grandeur et dans l’étendue de ses branches, car sa racine était près des grandes eaux.
Ọláńlá ní ẹwà rẹ̀ jẹ́, pẹ̀lú títẹ́ rẹrẹ ẹ̀ka rẹ̀, nítorí gbòǹgbò rẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ sí ibi tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi wà.
8 Les cèdres n’étaient pas plus élevés dans le paradis de Dieu, les sapins n’égalaient pas sa cime, et les platanes ne lui étaient pas égaux en feuillage; aucun arbre du paradis de Dieu ne fut comparable à lui et à sa beauté.
Àwọn igi kedari nínú ọgbà Ọlọ́run kò lè è bò ó mọ́lẹ̀; tàbí kí àwọn igi junifa ṣe déédé pẹ̀lú ẹ̀ka rẹ̀, tàbí kí a fi igi títẹ́ rẹrẹ wé ẹ̀ka rẹ̀, kò sí igi nínú ọgbà Ọlọ́run tí ó dà bí rẹ̀ ní ẹwà rẹ̀.
9 Parce que je le fis si beau, et avec des feuilles si nombreuses et si épaisses, tous les arbres de délices, qui étaient dans le paradis de Dieu, lui ont porté envie.
Mo mú kí ó ní ẹwà pẹ̀lú ẹ̀ka lọ́pọ̀lọ́pọ̀ tó fi jẹ́ ìlara àwọn igi gbogbo ní Edeni tí í ṣe ọgbà Ọlọ́run.
10 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Parce qu’il s’est élevé en hauteur, et qu’il a poussé sa cime verdoyante et touffue, et que son cœur s’est enorgueilli dans sa grandeur,
“‘Nítorí náà, èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ó ga lọ sókè fíofío, tí ó sì gbé òkè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ, àti nítorí pé gíga rẹ mú kí ó gbéraga,
11 Je l’ai livré à la main de l’homme le plus fort des nations, qui agira comme il voudra; selon son impiété je l’ai rejeté.
mo fi lé alákòóso àwọn orílẹ̀-èdè náà lọ́wọ́, fún un láti fi ṣe ẹ̀tọ́ fún un gẹ́gẹ́ bí ìwà búburú rẹ̀. Mo pa á tì sí ẹ̀gbẹ́ kan,
12 Et des étrangers, et les hommes les plus cruels des nations le couperont par le pied, et le jetteront sur les montagnes; et dans toutes les vallées tomberont ses rameaux, et ses branches seront brisées sur tous les rochers de la terre; et tous les peuples de la terre se retireront de son ombrage et l’abandonneront.
àwọn orílẹ̀-èdè àjèjì aláìláàánú jùlọ ké e lulẹ̀, wọn sì fi kalẹ̀. Àwọn ẹ̀ka rẹ̀ ṣubú sórí òkè àti sí gbogbo àárín àwọn òkè; àwọn ẹ̀ka rẹ̀ tí ó ṣẹ nà sílẹ̀ ní gbogbo àlàfo jíjìn ilẹ̀. Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè ilẹ̀ ayé jáde kúrò ní abẹ́ ìji rẹ̀ wọn sì fi sílẹ̀.
13 Dans ses ruines ont habité tous les volatiles du ciel, et dans ses rameaux ont demeuré toutes les bêtes de la contrée.
Gbogbo àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run ṣe àtìpó ni orí igi tí ó ṣubú lulẹ̀ náà, gbogbo àwọn ẹranko igbó wà ní àárín ẹ̀ka rẹ̀.
14 C’est pour cette raison qu’aucun arbre planté sur les eaux ne s’élèvera dans sa hauteur, et il ne portera pas son sommet au milieu de rameaux touffus et feuillus, et aucun de ceux qui sont arrosés par les eaux ne se soutiendra dans son élévation, parce que tous ont été livrés à la mort, précipités au fond de la terre, au milieu des fils des hommes, avec ceux qui descendent dans la fosse.
Nítorí náà kò sí igi mìíràn lẹ́gbẹ̀ẹ́ omi tí ó lè fi ìgbéraga ga sókè fíofío, tí yóò sì gbé sókè rẹ̀ ga ju ewé tí ó nípọn lọ. Kò sí igi mìíràn tí ó ní omi tó bẹ́ẹ̀ tí ó lè ga tó bẹ́ẹ̀; gbogbo wọn ni a kádàrá ikú fún, fún ìsàlẹ̀ ilẹ̀, ní àárín àwọn alààyè ènìyàn, pẹ̀lú àwọn tí o lọ sí ọ̀gbun ní ìsàlẹ̀.
15 Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Au jour qu’il est descendu aux enfers, j’ai fait faire un deuil, je l’ai couvert de l’abîme; et j’ai arrêté ses fleuves, et retenu les grandes eaux: le Liban a été attristé sur lui, et tous les arbres des champs ont été ébranlés. (Sheol h7585)
“‘Èyí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ní ọjọ́ ti a mú u wá sí isà òkú mo fi ọ̀fọ̀ ṣíṣe bo orísun omi jíjìn náà, mo dá àwọn ìṣàn omi rẹ̀ dúró, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi rẹ̀ ní a dí lọ́nà. Nítorí rẹ̀ mo fi ìwúwo ọkàn wọ Lebanoni ní aṣọ, gbogbo igi igbó gbẹ dànù. (Sheol h7585)
16 Par le bruit de sa ruine, j’ai agité des nations, lorsque je le conduisais dans l’enfer avec ceux qui descendent dans la fosse; et ils se sont consolés au fond de la terre, tous les arbres de délices, beaux et magnifiques du Liban, tous ceux qui étaient arrosés par les eaux. (Sheol h7585)
Mo mú kí orílẹ̀-èdè wárìrì sì ìró ìṣubú rẹ̀ nígbà tí mo mú un wá sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun ìsàlẹ̀. Nígbà náà gbogbo igi Edeni, àṣàyàn àti èyí tí ó dára jùlọ nínú Lebanoni, gbogbo igi tí ó ní omi dáradára ni a tù nínú ni ayé ìsàlẹ̀. (Sheol h7585)
17 Car eux-mêmes aussi descendront avec lui dans l’enfer parmi les tués par le glaive; et le bras de chacun d’eux restera immobile sous son ombrage au milieu des nations. (Sheol h7585)
Àwọn tí ó ń gbé ní abẹ́ òjìji rẹ̀, àwọn àjèjì rẹ ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè náà, ti lọ sí ìsàlẹ̀ isà òkú pẹ̀lú rẹ̀, ní dídárapọ̀ mọ́ àwọn tí a fi idà pa. (Sheol h7585)
18 À qui as-tu été assimilé, ô illustre et sublime entre les arbres de délices? Voilà que tu as été précipité au plus profond de la terre avec les arbres de délices, tu dormiras au milieu des incirconcis, avec ceux qui ont été tués par le glaive; c’est là Pharaon lui-même et toute sa multitude, dit le Seigneur Dieu.
“‘Èwo lára igi Edeni ní a lè fiwé ọ ní dídán àti ọláńlá? Síbẹ̀ ìwọ, gan an wá sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn igi Edeni lọ sí ìsàlẹ̀ ilẹ̀; ìwọ yóò sùn ni àárín àwọn aláìkọlà, pẹ̀lú àwọn tí a fi idà pa. “‘Èyí yìí ní Farao àti ìjọ rẹ̀, ní Olúwa Olódùmarè wí.’”

< Ézéchiel 31 >