< Ézéchiel 22 >

1 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 Et toi, fils d’un homme, est-ce que tu ne juges pas la cité du sang?
“Ọmọ ènìyàn ǹjẹ́ ìwọ yóò ha ṣe ìdájọ́ rẹ̀? Ǹjẹ́ ìwọ ha ṣe ìdájọ́ ìlú atàjẹ̀sílẹ̀? Tó bá rí bẹ́ẹ̀ dojúkọ wọn pẹ̀lú gbogbo ìwà ìríra wọn.
3 Et tu lui montreras toutes ses abominations, et tu diras: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Une cité répandant le sang au milieu d’elle, afin que vienne son temps, et qui a fait des idoles contre elle-même, afin de se souiller,
Kí ó sì wí pé, ‘Èyí yìí ní ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwọ ìlú ńlá tí ó mú ìparun wá sórí ara rẹ nípa títàjẹ̀sílẹ̀ ní àárín rẹ, tí ó sì ba ara rẹ̀ jẹ́ nípa ṣíṣe àwọn ère.
4 Par le sang qui par toi a été répandu, tu t’es rendue coupable, et par les idoles que tu as faites tu t’es souillée, et tu as avancé tes jours et amené le temps de tes années; à cause de cela, je t’ai rendue l’opprobre des nations et la dérision de tous les pays.
Ìwọ ti jẹ̀bi nítorí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀, àti pé àwọn ère tí ó ṣe tí bà ọ́ jẹ́. Ìwọ tí mú ọjọ́ rẹ súnmọ́ tòsí, ìparí àwọn ọdún rẹ sì ti dé. Nítorí náà èmi yóò fi ọ ṣe ohun ẹ̀gàn lójú àwọn orílẹ̀-èdè àti ohun ẹ̀sín lójú gbogbo ìlú.
5 Ceux qui sont près et ceux qui sont loin de toi triompheront de toi, souillée, noble, grande par ta ruine.
Àwọn tí ó wà ní tòsí àti àwọn tí ó jìnnà sí ọ, yóò fi ọ ṣe ẹlẹ́yà, ìwọ ìlú ẹlẹ́gàn, tí ó kún fún làálàá.
6 Voilà que les princes d’Israël ont usé chacun de leur bras chez toi, pour répandre le sang.
“‘Wo bí ọ̀kọ̀ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin ọba Israẹli tí ó wà nínú yín ti ń lo agbára rẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀.
7 Ils ont accablé d’outrages père et mère au milieu de toi; ils ont calomnié l’étranger au milieu de toi, et ils ont contristé la veuve et l’orphelin chez toi.
Nínú rẹ wọn ti hùwà sí baba àti ìyá pẹ̀lú ìfojú tínrín; nínú rẹ wọn ti ni àwọn àlejò lára, wọn sì hùwàkiwà sí aláìní baba àti opó.
8 Tu as méprisé mes sanctuaires, et souillé mes sabbats.
Ìwọ tí kọ àwọn ohun mímọ́ mi sílẹ̀, ìwọ sì ti lo ọjọ́ ìsinmi mi ní ìlòkulò.
9 Des hommes détracteurs ont été chez toi pour répandre le sang; et sur les montagnes ils ont mangé chez toi, ils ont opéré le crime au milieu de toi.
Nínú rẹ ni àwọn ayannijẹ ènìyàn pinnu láti tàjẹ̀ sílẹ̀; nínú rẹ ní àwọn tí ó ń jẹun ní orí òkè ojúbọ òrìṣà, wọn sì hùwà ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́.
10 Ils ont découvert la nudité du père chez toi, ils ont humilié l’impureté de la femme qui était dans ses mois chez toi;
Nínú rẹ ní àwọn ti kò bu ọlá fún àwọn àkéte baba wọn; nínú rẹ ni àwọn tí o ń bá àwọn obìnrin lò nígbà tí wọ́n ń ṣe àkókò lọ́wọ́, ní àsìkò tí a ka wọn sì aláìmọ́.
11 Et chacun d’eux a commis une abomination sur la femme de son prochain, et le beau-père a souillé sa belle-fille par un crime horrible; le frère a fait violence à sa propre sœur, à la fille de son père chez toi.
Nínú rẹ ọkùnrin kan ti dá ẹ̀ṣẹ̀ ìríra pẹ̀lú aya aládùúgbò rẹ̀, òmíràn bá ìyàwó ọmọ rẹ̀ jẹ́, òmíràn sì bá arábìnrin rẹ̀ lòpọ̀ èyí tí í ṣe ọbàkan rẹ̀.
12 Ils ont reçu des présents chez toi, pour répandre le sang; tu as reçu un intérêt et un profit de surplus; et par avarice, tu calomniais tes’proches, et tu m’as oublié, dit le Seigneur Dieu.
Nínú rẹ àwọn ènìyàn gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ láti tàjẹ̀ sílẹ̀; ìwọ gba èlé ìlọ́po láti mú aláìṣòótọ́ jèrè láti ara aládùúgbò rẹ nípa ìrẹ́jẹ. Ìwọ sì ti gbàgbé èmi; ni Olúwa Olódùmarè wí.
13 Voici que moi j’ai frappé des mains contre ton avarice, et contre le sang qui a été répandu au milieu de toi.
“‘Èmi yóò kúkú pàtẹ́wọ́ lórí èrè àìmọ̀ tí ìwọ ti jẹ, àti lórí ẹ̀jẹ̀ tí ìwọ ti ta sílẹ̀ ní àárín yín.
14 Est-ce que ton cœur se soutiendra, ou tes mains prévaudront-elles, aux jours malheureux que je ferai pour toi? c’est moi le Seigneur qui ai parlé, et j’exécuterai.
Ọkàn rẹ le gbà á, tàbí ọwọ́ rẹ lè le, ní ọjọ́ tí èmi yóò bá ọ ṣé? Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀, Èmi yóò sì ṣe é.
15 Et Je te disperserai parmi les nations, et je te jetterai au vent dans divers pays, et je ferai disparaître ton impureté du milieu de toi.
Èmi yóò tú yin ká ní àárín àwọn orílẹ̀-èdè, èmi yóò fọ́n ọ ká sí àwọn ìlú; èmi yóò sì fi òpin sí àìmọ́ rẹ.
16 Et je te posséderai en présence des nations, et tu sauras que je suis le Seigneur.
Nígbà tí a ó bà ọ́ jẹ́ lójú àwọn orílẹ̀-èdè, ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”
17 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Nígbà náà ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
18 Fils d’un homme, la maison d’Israël s’est changée pour moi en scorie; tous sont de l’airain, et de l’étain, et du fer et du plomb, au milieu d’un fourneau; ils sont devenus une scorie d’argent.
“Ọmọ ènìyàn, ilé Israẹli ti di ìdàrọ́ sí mi; gbogbo wọn jẹ́ bàbà, idẹ, irin àti òjé ti a fi sínú iná ìléru. Wọn jẹ́ ìdàrọ́ ti fàdákà.
19 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Parce que vous avez été tous changés en scorie, à cause de cela, voilà que moi, je vous assemblerai au milieu de Jérusalem,
Nítorí náà èyí yìí ni ohun ti Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí tí ìwọ ti di ìdàrọ́, èmi yóò kó yín jọ sí Jerusalẹmu.
20 Comme on met ensemble l’argent, et l’airain, et le plomb, et le fer, au milieu d’un fourneau; comme j’y allumerai un feu pour les fondre, ainsi je vous rassemblerai dans ma fureur et dans ma colère; et je me reposerai, et je vous fondrai;
Gẹ́gẹ́ bí ènìyàn ṣe ń kó fàdákà, bàbà, irin, òjé àti idẹ jọ sínú iná ìléru láti fi iná yọ́ ọ, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò kó ọ jọ ní ìbínú àti ìrunú mi, èmi yóò sì fi ọ sì àárín ìlú, èmi yóò sì yọ́ ọ. Níbẹ̀ ní ìwọ yóò sì ti yọ́.
21 Et je vous rassemblerai, et je vous embraserai par le feu de ma fureur, et vous serez fondus au milieu de Jérusalem.
Èmi yóò kó yín jọ, èmi o sì fín iná ìbínú mi si yin lára, ẹ o si di yíyọ́ láàrín rẹ̀.
22 Comme l’argent fond au milieu d’un fourneau, ainsi vous serez au milieu d’elle; et vous saurez que je suis le Seigneur, lorsque j’aurai répandu mon indignation sur vous.
Bí a ti ń yọ́ fàdákà nínú iná ìléru bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ní ìwọ yóò ṣe yọ́ nínú rẹ̀, ìwọ yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi Olúwa ti tú ìbínú mi sórí rẹ.’”
23 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Lẹ́ẹ̀kan sí i ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé,
24 Fils d’un homme, dis-lui: Tu es une terre impure, et qui n’a point été arrosée de pluie au jour de la fureur.
“Ọmọ ènìyàn, sọ fún ilẹ̀ náà, ‘Ìwọ ní ilẹ̀ tí kò gbá mọ́, ti kò sì rọ òjò tàbí ìrì ní àkókò ìbínú.’
25 La conjuration de ses prophètes est au milieu d’elle; comme un lion rugissant et ravissant une proie, ils ont dévoré les âmes, ils ont reçu des richesses et des récompenses, ils ont multiplié ses veuves au milieu d’elle.
Ìdìtẹ̀ sì wà láàrín àwọn ọmọ-aládé inú rẹ̀, tó dàbí bíbú kìnnìún tó ń fà ẹran ya, wọ́n ń ba àwọn ènìyàn jẹ́, wọ́n ń kó ìṣúra àti àwọn ohun iyebíye wọ́n sì ń sọ púpọ̀ di opó nínú rẹ̀.
26 Ses prêtres ont méprisé ma loi, ils ont souillé mes sanctuaires; entre le saint et le profane ils n’ont pas mis de différence; et entre l’impur et le pur ils n’ont pas distingué; et de mes sabbats, ils ont détourné leurs yeux, et j’étais souillé au milieu d’eux.
Àwọn àlùfáà rẹ̀ ti rú òfin mi, wọn si ti sọ ohun mímọ́ mi di àìlọ́wọ̀: wọn kò fi ìyàtọ̀ sáàrín ohun mímọ́ àti àìlọ́wọ̀, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò fi ìyàtọ̀ hàn láàrín ohun àìmọ́, àti mímọ́, wọn sì ti fi ojú wọn pamọ́ kúrò ní ọjọ́ ìsinmi mi, mó sì dí ẹni àìlọ́wọ̀ láàrín wọn.
27 Ses princes sont au milieu d’elle comme des loups ravissant une proie pour répandre le sang, perdre les âmes, et par avarice courir après le gain.
Àwọn ọmọ-aládé àárín rẹ̀ dàbí ìkookò ti ń ṣọdẹ, láti tàjẹ̀ sílẹ̀, láti pa ọkàn run, láti jèrè àìṣòótọ́.
28 Mais ses prophètes les enduisaient sans mélange, voyant des choses vaines, et leur prédisant le mensonge, disant: Voici ce que dit le Seigneur Dieu, quoique le Seigneur n’ait point parlé.
Àti àwọn wòlíì rẹ́ ti ṣẹ̀tàn sí wọn, wọn ń rì ìran asán, wọn sì ń fọ àfọ̀ṣẹ èké sí wọn, wí pé, ‘Báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí,’ nígbà tí ó ṣépè Olúwa kò sọ̀rọ̀.
29 Les peuples du pays ajoutaient calomnie à calomnie, et commettaient des rapines avec violence; ils affligeaient l’indigent et le pauvre, et ils opprimaient l’étranger par la calomnie sans jugement.
Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìninilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídìí. Kò sì ṣí ìdájọ́ òdodo.
30 Et j’ai cherche parmi eux un homme, qui mît une haie entre moi et eux, et qui se tînt opposé à moi pour cette terre, afin que je ne la détruisisse point; et je n’en ai pas trouvé.
“Èmi si wá ẹnìkan láàrín wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má bá à parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31 C’est pourquoi j’ai répandu mon indignation sur eux; dans le feu de ma colère je les ai consumés, j’ai ramené leur voie sur leur tête, dit le Seigneur Dieu.
Nítorí náà ni mo ṣe da ìbínú mi sí wọn lórí, mo ti fi iná ìbínú mi run wọn, mo si ti fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< Ézéchiel 22 >