< Ézéchiel 13 >

1 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
2 Adresse tes prédictions aux prophètes d’Israël qui prophétisent, et tu diras à ceux qui prophétisent d’après leur cœur: Ecoutez la parole du Seigneur.
“Ọmọ ènìyàn sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí àwọn wòlíì Israẹli tó ń sọtẹ́lẹ̀, kí o sì sọ fún àwọn tí ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa!
3 Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Malheur aux prophètes insensés qui suivent leur esprit, et ne voient rien.
Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Ègbé ni fún àwọn aṣiwèrè wòlíì tó ń tẹ̀lé ẹ̀mí ara wọn tí wọn kò sì rí nǹkan kan!
4 Tes prophètes, Israël, étaient comme des renards dans les déserts.;
Israẹli àwọn wòlíì rẹ dàbí kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ nínú pápá.
5 Vous n’êtes pas montés à la rencontre de l’ennemi, vous n’avez pas opposé un mur pour la maison d’Israël, afin de tenir ferme dans le combat au jour du Seigneur.
Ẹ̀yin kò gòkè láti mọ odi tí ó ya ní ilé Israẹli kí wọ́n ba lè dúró gbọin ní ojú ogun ní ọjọ́ Olúwa.
6 Ils voient des choses vaines, et ils prophétisent le mensonge, disant: Le Seigneur dit, lorsque le Seigneur ne les a pas envoyés; et ils persistent à maintenir leur discours.
Ìran àti àfọ̀ṣẹ wọn jẹ́ èké. Wọ́n wí pé, “Olúwa wí,” nígbà tí Olúwa kò rán wọn, síbẹ̀ wọ́n fẹ́ kí Olúwa mú ọ̀rọ̀ wọn ṣẹ.
7 Est-ce que vous n’avez pas vu une vision vaine, et annoncé une prédiction mensongère? et vous dites: Le Seigneur dit, lorsque moi je n’ai pas parlé.
Ẹ̀yin kò ha ti rí ìran asán, ẹ̀yin kò ha ti fọ àfọ̀ṣẹ èké, nígbà tí ẹ̀yin sọ pé, “Olúwa wí,” bẹ́ẹ̀ sì ni Èmi kò sọ̀rọ̀?
8 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Parce que vous avez dit des choses vaines, et que vous avez vu le mensonge; c’est pourquoi, voici que moi je suis contre vous, dit le Seigneur Dieu.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nítorí ọ̀rọ̀ asán àti ìran èké yín, mo lòdì sí yín: ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Et ma main sera sur les prophètes qui voient des choses vaines, et qui prédisent le mensonge; ils ne seront pas dans le conseil de mon peuple, et ils ne seront point écrits dans le livre de la maison d’Israël, et ils n’entreront pas dans la terre d’Israël, et vous saurez que je suis le Seigneur Dieu;
Ọwọ́ mi yóò sì wà lórí àwọn wòlíì tó ń ríran asán, tó sì ń sọ àfọ̀ṣẹ èké. Wọn kò ní sí nínú ìjọ àwọn ènìyàn mi, a ó sì yọ orúkọ wọn kúrò nínú àkọsílẹ̀ ilé Israẹli, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì ní wọ ilẹ̀ Israẹli mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa Olódùmarè.
10 Parce qu’ils ont trompé mon peuple, disant: Paix, et il n’y a point de paix; et lui bâtissait une muraille; mais eux l’enduisaient de boue, sans paille.
“‘Wọ́n ti mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà, wọ́n ní, “Àlàáfíà,” nígbà tí kò sí àlàáfíà, nítorí pé bí àwọn ènìyàn bá mọ odi fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, wọn a fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, wọn ó sì fi ẹfun kùn ún,
11 Dis à ceux qui enduisent sans mélange, que la muraille tombera; car viendra une pluie inondante, et je lancerai des pierres énormes qui tomberont d’en haut, et un vent de tempête qui la renversera.
nítorí náà, sọ fún àwọn tí ń fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ àti àwọn tó fi ẹfun kùn ún pé, odi náà yóò wó, ìkún omi òjò yóò dé, Èmi yóò sì rán òkúta yìnyín sọ̀kalẹ̀, ìjì líle yóò ya á lulẹ̀.
12 Si toutefois la muraille tombe, ne vous dira-t-on pas: Où est l’enduit dont vous l’avez enduite?
Nígbà tí odi náà bá sì wó, ǹjẹ́ àwọn ènìyàn wọn kò níbi yín pé, “Rírẹ́ tí ẹ rẹ́ ẹ dà, ibo sì ni ẹfun tí ẹ fi kùn ún wà?”
13 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Je ferai éclater un vent de tempêtes dans mon indignation, et une pluie inondante se répandra dans ma fureur, et dans ma colère des pierres énormes consumeront tout.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Nínú ìbínú gbígbóná mi, èmi yóò tu afẹ́fẹ́ líle lé e lórí nínú ìrunú mi, àti nínú ìbínú mi, òjò yóò sì rọ̀ púpọ̀ nínú ìbínú mi, àti yìnyín ńlá nínú ìrunú mi láti pa wọ́n run.
14 Et je détruirai la muraille que vous avez enduite sans mélange; et je l’égalerai à la terre, et ses fondements seront mis à nu; et elle tombera; et celui qui l’avait enduite sera consumé au milieu d’elle; et vous saurez que moi je suis le Seigneur.
Èmi yóò wó ògiri tí ẹ fi amọ̀ àìpò rẹ́, èyí tí ẹ fi ẹfun kùn lulẹ̀ dé bi pé ìpìlẹ̀ rẹ yóò hàn jáde. Nígbà ti odi náà wó palẹ̀, a ó sì run yín sínú rẹ̀, ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
15 Et j’assouvirai mon indignation contre la muraille, et contre ceux qui l’enduisent sans mélange, et je vous dirai: La muraille n’est plus, et ceux qui l’ont enduite ne sont plus.
Báyìí ni Èmi yóò ṣe lo ìbínú mi lórí odi yìí àti àwọn to fi amọ̀ àìpò rẹ́ ẹ, tí wọ́n sì fi ẹfun kùn ún. Èmi yóò sì sọ fún yín pé, “Kò sí odi mọ́, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tó rẹ́ ẹ náà kò sí mọ́.
16 Ils ne sont plus, les prophètes d’Israël qui prophétisent à Jérusalem, et qui voient pour elle une vision de paix; et il n’y a point de paix, dit le Seigneur Dieu.
Àwọn wòlíì Israẹli tí ń sọtẹ́lẹ̀ sí Jerusalẹmu, tí wọn ríran àlàáfíà sí i nígbà ti kò sì àlàáfíà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí.”’
17 Et toi, fils d’un homme, tourne ta face contre les filles de ton peuple qui prophétisent d’après leur cœur, et fais des prédictions contre elles,
“Nísinsin yìí, ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn ọmọbìnrin ènìyàn rẹ tí wọ́n ń sọtẹ́lẹ̀ láti inú èrò ọkàn wọn, sọtẹ́lẹ̀ sí wọn
18 Et dis: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Malheur à celles qui cousent des coussinets pour tous les coudes, et qui font des oreillers sous la tête des personnes de tout âge, afin de s’emparer des âmes; et lorsqu’elles s’emparaient des âmes de mon peuple, elles les vivifiaient.
wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Ègbé ni fún ẹ̀yin obìnrin tí ẹ ń rán ìfúnpá òògùn sí ìgbọ̀nwọ́ àwọn ènìyàn, tí ẹ ń ṣe ìbòjú oríṣìíríṣìí fún orí oníkálùkù ènìyàn láti ṣọdẹ ọkàn wọn. Ẹ̀yin yóò wa dẹkùn fún ọkàn àwọn ènìyàn mi bí? Ẹ̀yin yóò sì gba ọkàn ti ó tọ̀ yín wá là bí?
19 Elles me déshonoraient auprès de mon peuple pour un peu d’orge et un morceau de pain, afin de tuer les âmes qui n’étaient pas mortes, et de vivifier les âmes qui ne vivaient pas, mentant à mon peuple, qui croit aux mensonges.
Nítorí ẹ̀kúnwọ́ ọkà barle àti òkèlè oúnjẹ. Ẹ ti pa àwọn tí kò yẹ kí ẹ pa, ẹ sì fi àwọn tí kò yẹ kó wà láààyè sílẹ̀ nípa irọ́ tí ẹ ń pa fún àwọn ènìyàn mi, èyí tí àwọn náà ń fetí sí.
20 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Voici que moi je suis contre vos coussinets avec lesquels vous prenez des âmes au vol, je les déchirerai de dessus vos bras, et je laisserai aller les âmes que vous avez prises, ces âmes pour qu’elles s’envolent.
“‘Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Mo lòdì sí ìfúnpá òògùn tí ẹ fi ń ṣọdẹ ọkàn ènìyàn káàkiri bí ẹyẹ, Èmi yóò ya á kúrò lápá yín, Èmi yóò sì dá ọkàn àwọn ènìyàn tí ẹ ń ṣọdẹ sílẹ̀.
21 Et je déchirerai vos oreillers; et je délivrerai mon peuple de votre main, et ils ne seront plus en vos mains comme une proie; et vous saurez que je suis le Seigneur,
Èmi yóò ya àwọn ìbòjú yín, láti gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín, wọn kò sì ní jẹ́ ìjẹ fún yín mọ́. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
22 Parce que vous avez affligé en mentant le cœur du juste, que moi je n’ai pas contristé; et parce que vous avez fortifié les mains de l’impie, afin qu’il ne revînt point de sa voie mauvaise, et qu’il ne trouvât point la vie;
Nítorí pé ẹ̀yin ti ba ọkàn àwọn olódodo jẹ́ pẹ̀lú irọ́ yín, nígbà tí Èmi kò mú ìbànújẹ́ bá wọn, àti nítorí ẹ̀yin ti mú ọkàn àwọn ènìyàn búburú le, kí wọ́n má ba à kúrò nínú ọ̀nà ibi wọn dé bi tí wọn yóò fi gba ẹ̀mí wọn là,
23 À cause de cela, vous ne verrez plus de choses vaines, et vous ne ferez plus de prédictions, et j’arracherai mon peuple de votre main, et vous saurez que je suis le Seigneur.
nítorí èyí, ẹ̀yin kò ní í ríran èké, ẹ̀yin kò sì ní fọ àfọ̀ṣẹ mọ́. Èmi yóò gba àwọn ènìyàn mi lọ́wọ́ yín. Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”

< Ézéchiel 13 >