< Ézéchiel 11 >

1 Et un esprit m’éleva, et me conduisit à la porte orientale de la maison du Seigneur, qui regarde le soleil levant; et voilà à l’entrée de la porte vingt-cinq hommes, et je vis au milieu d’eux Jézonias, fils d’Azur, et Pheltias, fils de Banaïas, princes du peuple.
Ẹ̀mí sì gbé mi sókè, ó mú mi lọ sí ẹnu-ọ̀nà ilé Olúwa èyí tó dojúkọ ìlà-oòrùn. Ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà yìí ni àwọn ọkùnrin mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n wá, mo rí Jaaṣaniah ọmọ Assuri àti Pelatiah ọmọ Benaiah, tí wọ́n jẹ́ ìjòyè àwọn ènìyàn.
2 Et il me dit: Fils d’un homme, voici les hommes qui pensent l’iniquité, et qui forment un conseil pervers en cette ville,
Olúwa sì sọ fún mi pé, “Ọmọ ènìyàn, àwọn ọkùnrin yìí ló ń pète ibi, wọ́n sì ń gbé ìmọ̀ràn búburú kalẹ̀ nínú ìlú.
3 Disant: N’est-ce pas depuis longtemps que sont bâties des maisons? celle-ci est la chaudière, et nous nous sommes la chair.
Wọ́n ní, ‘Kò ha tí ì tó àsìkò láti kọ́lé? Ìlú yìí ni ìkòkò ìdáná, àwa sì ni ẹran’.
4 C’est pourquoi prophétise sur eux, prophétise, fils d’un homme.
Nítorí náà sọtẹ́lẹ̀ nípa wọn; ọmọ ènìyàn, sọtẹ́lẹ̀.”
5 Et l’esprit du Seigneur s’empara de moi, et me dit: Parle: Voici ce que dit le Seigneur: Ainsi vous avez parlé, maison d’Israël, et les pensées de votre cœur, je les connais.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé mi, ó sì wí pé, “Sọ̀rọ̀!” Báyìí ni Olúwa wí, ohun tí ẹ ń sọ nìyìí, ilé Israẹli, mo mọ ohun tó wà lọ́kàn yín.
6 Vous avez fait mourir un très grand nombre dans cette ville, et vous avez rempli ses rues de tués.
Ẹ̀yin ti sọ òkú yín di púpọ̀ nínú ìlú yìí, òkú sì ti kún gbogbo ìgboro rẹ̀.
7 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Vos tués, que vous avez mis au milieu de la ville, ceux-là sont la chair, et celle-ci la chaudière; mais je vous tirerai du milieu de cette ville.
“Torí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, àwọn òkú tí ẹ fọn sílẹ̀ sí àárín yín ni ẹran, ìlú yìí sì ni ìkòkò ìdáná ṣùgbọ́n èmi yóò le yín jáde níbẹ̀.
8 Vous avez craint le glaive, et j’amènerai le glaive sur vous, dit le Seigneur Dieu.
Ẹ bẹ̀rù idà, èmi yóò sì mú idà wá sórí yín, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
9 Et je vous chasserai du milieu d’elle, et je vous livrerai à la main des ennemis, et j’exercerai sur vous des jugements.
Èmi yóò lé yín jáde kúrò ní ìlú yìí, èmi yóò sì fà yín lé àjèjì lọ́wọ́, èmi yóò sì mú ìdájọ́ ṣẹ lé yín lórí.
10 Vous tomberez sous le glaive; c’est sur les confins d’Israël que je vous jugerai, et vous saurez que je suis le Seigneur.
Nípa idà ni ẹ̀yin yóò ṣubú, èmi yóò sì ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
11 Cette ville ne sera point pour vous une chaudière, et vous, vous ne serez point comme des chairs au milieu d’elle; c’est dans les confins d’Israël que je vous jugerai.
Ìlú yìí kò ní i jẹ́ ìkòkò ìdáná, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin náà kò sì ní jẹ́ ẹran nínú rẹ̀, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ yín ní àwọn ààlà ìlú Israẹli.
12 Et vous saurez que je suis le Seigneur, parce que vous n’avez pas marché dans mes préceptes, et que vous n’avez pas accompli mes ordonnances, mais que vous avez agi suivant les coutumes des nations qui sont autour de vous.
Ẹ̀yin yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nítorí pé ẹ̀yin kò tẹ̀lé àṣẹ mi ẹ̀yin kò sì pa òfin mi mọ́, ṣùgbọ́n ẹ̀yin ti hùwà gẹ́gẹ́ bí àwọn aláìgbàgbọ́ orílẹ̀-èdè tó yí yín ká.”
13 Et il arriva, lorsque je prophétisais, que Pheltias, fils de Banaïas, mourut; et je tombai sur ma face, criant à haute voix, et je dis: Hélas, hélas, hélas! Seigneur Dieu, c’est vous qui consumez les restes d’Israël?
Bí mo ṣe ń sọtẹ́lẹ̀ lọ́wọ́, Pelatiah ọmọ Benaiah kú. Mo sì dojúbolẹ̀, mo sì kígbe sókè pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Ṣé ìwọ yóò ha pa ìyókù Israẹli run pátápátá ni?”
14 Et la parole du Seigneur me fut adressée, disant:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tún tọ̀ mí wá wí pé,
15 Fils d’un homme, tes frères, tes frères, les hommes, tes proches, et toute la maison d’Israël, tous ceux à qui les habitants de Jérusalem ont dit: Retirez-vous loin du Seigneur, c’est à nous que la terre a été donnée en possession.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn arákùnrin rẹ, àní àwọn ará rẹ, àwọn ọkùnrin nínú ìbátan rẹ, àti gbogbo ilé Israẹli pátápátá, ni àwọn ará Jerusalẹmu ti wí fún pé, ‘Ẹ jìnnà sí Olúwa, àwa ni a fi ilẹ̀ yìí fún yín ní ìní.’
16 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Parce que je les ai envoyés loin parmi îles nations, et que je les ai dispersés dans les pays, je leur serai en petite sanctification dans la terre où ils sont venus.
“Nítorí náà, sọ fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, bó tilẹ̀ jẹ́ pé mo ti fọ́n wọn káàkiri orílẹ̀-èdè, síbẹ̀ fún ìgbà díẹ̀, èmi yóò jẹ́ ibi mímọ́ fún wọn níbi tí wọ́n lọ.’
17 À cause de cela dis: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Je vous rassemblerai du milieu des peuples, et je vous réunirai des terres dans lesquelles vous avez été dispersés, et je vous donnerai le sol d’Israël.
“Nítorí náà, wí pé, ‘Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí, Èmi yóò kó wọn jọ kúrò láàrín àwọn orílẹ̀-èdè tí mo fọ́n wọn ká sí, Èmi yóò sì fún wọn ní ilẹ̀ Israẹli padà.’
18 Et ils y entreront, et ils ôteront d’elle tous ses scandales et toutes ses abominations.
“Wọn yóò padà síbẹ̀, wọn yóò sì mú gbogbo àwòrán ìríra rẹ̀ àti ìbọ̀rìṣà rẹ̀ kúrò.
19 Et je leur donnerai un même cœur, et je mettrai un esprit nouveau dans leurs entrailles; et j’ôterai le cœur de pierre de leur chair, et je leur donnerai un cœur de chair,
Èmi yóò fún wọn ní ọ̀kankan; èmi yóò sì fi ẹ̀mí tuntun sínú wọn, Èmi yóò mú ọkàn òkúta kúrò lára wọn, èmi yóò sì fún wọn ní ọkàn tó rọ̀ bí ara ẹran.
20 Afin qu’ils marchent dans mes préceptes, et qu’ils gardent mes ordonnances, et qu’ils les exécutent; et qu’ils soient mon peuple, et que moi je sois leur Dieu.
Kí wọn le tẹ̀lé àṣẹ mi, kí wọn sì le pa òfin mi mọ́. Wọ́n yóò jẹ́ ènìyàn mi, Èmi náà yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn.
21 Mais ceux dont le cœur marche après leurs pierres d’achoppement et leurs abominations, je mettrai leur voie sur leur tête, dit le Seigneur Dieu.
Ṣùgbọ́n fún àwọn tí wọ́n ń fi gbogbo ọkàn wọn sin àwọn àwòrán ìríra àti àwọn òrìṣà, Èmi yóò mú ẹ̀san ohun tí wọ́n ṣe wá sí orí wọn bẹ́ẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.”
22 Et les chérubins élevèrent leurs ailes, et les roues s’élevèrent avec eux; et la gloire du Dieu d’Israël était sur eux.
Àwọn kérúbù sì gbé ìyẹ́ wọn sókè pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lókè orí wọn.
23 Et la gloire du Seigneur monta du milieu de la cité, et s’arrêta sur la montagne qui est à l’orient de la ville.
Ògo Olúwa sì gòkè lọ kúrò láàrín ìlú, ó sì dúró lórí òkè tó wà ní ìlà-oòrùn ìlú náà.
24 Et un esprit m’éleva, et me conduisit en Chaldée vers la transmigration, dans la vision, par l’esprit de Dieu; et la vision que j’avais vue me fut enlevée.
Lẹ́yìn náà, Ẹ̀mí gbé mi sókè, ó sì mú mi wá sí Kaldea lójú ìran, nípa ti Ẹ̀mí Ọlọ́run sí ọ̀dọ̀ àwọn ti ìgbèkùn. Bẹ́ẹ̀ ni ìran tí mo rí lọ kúrò ní ọ̀dọ̀ mi,
25 Et je dis à la transmigration toutes les choses que le Seigneur m’avait montrées.
mo sì sọ gbogbo ohun tí Olúwa fihàn mí fún àwọn tó wà ní ìgbèkùn.

< Ézéchiel 11 >