< Ézéchiel 10 >

1 Et je vis, et voilà que dans le firmament qui était sur la tête des chérubins, parut comme une pierre de saphir, comme une espèce de ressemblance de trône au-dessus d’eux.
Mo sì wò ó, mo rí ohun kan tó dàbí òkúta safire nínú òfúrufú tó wà lókè orí kérúbù, ìrísí ohun yìí sì dàbí ìtẹ́.
2 Et le Seigneur dit à l’homme qui était vêtu de lin: Entre au milieu des roues qui sont sous les chérubins, et remplis tes mains de charbons ardents de feu qui sont entre les chérubins, et répands-les sur la cité. Et il entra en ma présence;
Olúwa sì sọ fún ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun pé, “Lọ sí àárín àwọn kẹ̀kẹ́ tó wà lábẹ́ kérúbù. Bu ẹyin iná tó kúnwọ́ rẹ láàrín kérúbù, kí o sì fọ́n sórí ìlú náà.” Ó sì lọ lójú mi.
3 Mais les chérubins se tenaient à la droite de la maison, lorsque l’homme entra, et la nuée remplit le parvis intérieur.
Àwọn kérúbù dúró sí apá gúúsù tẹmpili nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ìkùùkuu sì bo inú àgbàlá.
4 Et la gloire du Seigneur s’éleva de dessus les chérubins vers le seuil de sa maison; et la maison fut remplie de la nuée, et le parvis fut rempli de l’éclat de la gloire du Seigneur.
Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹmpili. Ìkùùkuu sì bo inú tẹmpili, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.
5 Et l’on entendait le bruit des ailes des chérubins jusqu’au parvis extérieur, comme la voix du Dieu tout-puissant lorsqu’il parle.
A sì gbọ́ ariwo ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí títí dé àgbàlá tó wà ní ìta gẹ́gẹ́ bí ìgbà tí Ọlọ́run Olódùmarè bá ń sọ̀rọ̀.
6 Et lorsque le Seigneur eut commandé à l’homme qui était vêtu de lin, en disant: Prends du feu du milieu des roues qui sont entre les chérubins, celui-ci entra et se tint près de la roue.
Nígbà tí Olúwa pàṣẹ fún ọkùnrin aláṣọ funfun yìí pé, “Mú iná láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, láàrín àwọn kérúbù,” ó sì lọ dúró ṣẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kẹ̀kẹ́ náà.
7 Et le chérubin étendit sa main, du milieu des chérubins, vers le feu qui était entre les chérubins; et il en prit, et il le mit dans les mains de celui qui était vêtu de lin; lequel l’ayant reçu, sortit.
Ọ̀kan nínú àwọn kérúbù sì nawọ́ sí ibi iná tó wà láàrín kérúbù yòókù. Ó mú lára rẹ, ó fi sínú ọwọ́ ọkùnrin aláṣọ funfun, òun náà gbà á, ó sì jáde lọ.
8 Et il parut dans les chérubins, la ressemblance d’une main d’homme sous leurs ailes.
(Ohun tó dàbí ọwọ́ ènìyàn wà lábẹ́ ìyẹ́ àwọn kérúbù yìí.)
9 Et je vis, et voilà quatre roues près des chérubins; une roue près d’un chérubin, et une autre roue près d’un autre chérubin; mais l’apparence des quatre roues était comme celle d’une pierre de chrysolithe;
Nígbà tí mo sì wò, kíyèsí i, àwọn kẹ̀kẹ́ mẹ́rin wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ àwọn kérúbù yìí, kẹ̀kẹ́ kọ̀ọ̀kan wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ kérúbù kọ̀ọ̀kan; ìrí àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ń tàn yanran bí àwọ̀ òkúta berili.
10 Et d’après leur apparence, toutes les quatre avaient la même forme; comme serait une roue au milieu d’une autre roue.
Ní ti ìrísí wọn, gbogbo wọn jọra wọn; ọ̀kọ̀ọ̀kan rí bí ìgbà tí kẹ̀kẹ́ kan wà nínú kẹ̀kẹ́ mìíràn.
11 Et lorsqu’elles marchaient, elles allaient de quatre côtés et ne se retournaient pas en marchant; mais quand la première allait d’un côté, les autres suivaient et ne se détournaient point.
Nígbà tí wọ́n ń lọ, wọ́n tẹ̀lé ọ̀kan nínú ọ̀nà mẹ́rin tí àwọn kérúbù dojúkọ; àwọn kẹ̀kẹ́ náà kò yípadà bí àwọn kérúbù ti ń lọ. Àwọn kérúbù ń lọ sí ibi tí orí dojúkọ láì yà.
12 Et tout le corps de ces quatre roues, et les cous, et les mains, et les ailes et les cercles étaient pleins d’yeux tout autour.
Gbogbo ara wọn àti ẹ̀yìn, ọwọ́ wọn àti ìyẹ́ wọn, àti àwọn kẹ̀kẹ́ kún fún ojú yíkákiri kẹ̀kẹ́, tí àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ní.
13 Et ces roues furent appelées, moi l’entendant, les roulantes.
Mo gbọ́ tí wọ́n pe àwọn kẹ̀kẹ́ yìí ni “kẹ̀kẹ́ àjà.”
14 Chacun de ces animaux avait quatre faces; la première face était la face du chérubin, la seconde face une face d’homme, le troisième animal avait une face de lion, et le quatrième une face d’aigle.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan àwọn kérúbù yìí ni ojú mẹ́rin: ojú èkínní jẹ́ ojú kérúbù, ojú kejì jẹ́ ti ènìyàn, ojú kẹta jẹ́ ti kìnnìún nígbà tí ojú kẹrin jẹ́ ti ẹyẹ idì.
15 Et les chérubins s’élevèrent, c’est ranimai même que j’avais vu près du fleuve de Chobar.
A gbé àwọn kérúbù sókè. Èyí ni àwọn ẹ̀dá alààyè tí mo rí létí odò Kebari.
16 Et lorsque les chérubins marchaient, allaient pareillement aussi les roues près d’eux; et lorsque les chérubins haussaient leurs ailes, afin de s’élever de terre, les roues n’y restaient pas, mais elles étaient près d’eux.
Bí àwọn kérúbù yìí bá ń lọ àwọn kẹ̀kẹ́ ẹgbẹ́ wọn náà yóò lọ; bẹ́ẹ̀ ni bí àwọn kérúbù bá tú ìyẹ́ wọn ká láti dìde nílẹ̀, àwọn kẹ̀kẹ́ yìí kò ní kúrò lẹ́gbẹ̀ẹ́ wọn.
17 Eux s’arrêtant, elles s’arrêtaient, et quand ils s’élevaient, elles s’élevaient, parce que l’esprit de vie était en elles.
Bí àwọn kérúbù bá dúró díẹ̀ àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dúró jẹ́ẹ́; bí àwọn kérúbù bá dìde àwọn kẹ̀kẹ́ náà yóò dìde, nítorí pé ẹ̀mí àwọn ẹ̀dá alààyè yìí wà nínú wọn.
18 Et la gloire du Seigneur sortit du seuil du temple, elle se reposa sur les chérubins.
Ògo Olúwa kúrò níbi ìloro tẹmpili, ó sì dúró sórí àwọn kérúbù.
19 Et les chérubins, haussant leurs ailes, s’élevèrent de terre devant moi; et eux sortant, les roues aussi les suivirent; et ils s’arrêtèrent à l’entrée de la porte orientale de la maison du Seigneur; et la gloire du Dieu d’Israël était sur eux,
Àwọn kérúbù gbé ìyẹ́ wọn sókè, wọ́n sì fò kúrò nílẹ̀ lójú mi, wọ́n sì lọ pẹ̀lú kẹ̀kẹ́ wọn lẹ́ẹ̀kan náà. Wọ́n dúró níbi ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà ìlà-oòrùn ilé Olúwa, ògo Ọlọ́run Israẹli sì wà lórí wọn.
20 C’est l’animal même que je vis au-dessous du Dieu d’Israël près du fleuve de Chobar; et je reconnus que c’étaient des chérubins.
Àwọn wọ̀nyí ni ẹ̀dá alààyè tí mo rí lábẹ́ Ọlọ́run Israẹli létí odò Kebari, mo sì mọ̀ pé kérúbù ni wọ́n.
21 Chacun avait quatre faces, et chacun quatre ailes; et la ressemblance d’une main d’homme sous leurs ailes.
Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ojú mẹ́rin àti ìyẹ́ mẹ́rin, lábẹ́ ìyẹ́ wọn ni ohun tó jọ ọwọ́ ènìyàn wà.
22 Et la ressemblance de leurs visages, c’étaient les visages mêmes que j’avais vus près du fleuve de Chobar, et aussi leur aspect, et l’impétuosité de chacun à marcher devant sa face.
Àfiwé ojú àti ìrísí wọn rí bákan náà pẹ̀lú àwọn tí mo rí létí odò Kebari. Olúkúlùkù wọn sì ń lọ sí ọ̀kánkán tààrà.

< Ézéchiel 10 >