< Exode 30 >

1 Tu feras aussi pour brûler un parfum, un autel de bois de sétim,
“Ìwọ yóò sì ṣe pẹpẹ igi kasia kan; máa jó tùràrí lórí rẹ̀.
2 Ayant une coudée de longueur, et une de largeur, c’est-à-dire carré, et deux coudées en hauteur. Des cornes en sortiront.
Kí igun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin rẹ̀ ṣe déédé, kí ó jẹ́ ìdajì mita ní gígùn, ìdajì mita ní fífẹ̀ àti ìgbọ̀nwọ́ méjì ni gíga rẹ̀—kí ìwo rẹ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
3 Or, tu le revêtiras d’un or très pur, tant la grille que les parois tout autour, et les cornes. Et tu y feras une couronne d’or tout autour,
Ìwọ yóò sì bo òkè rẹ̀, gbogbo ìhà rẹ̀ àti ìwo rẹ̀ pẹ̀lú u kìkì wúrà, ìwọ yóò sì ṣe wúrà gbà á yíká.
4 Et deux anneaux d’or sous la couronne, à chaque côté, pour qu’on y passe des leviers et que l’autel puisse être porté.
Ìwọ yóò sì ṣe òrùka wúrà méjì fún pẹpẹ náà níṣàlẹ̀ ìgbátí méjèèjì ní òdìkejì ìhà rẹ̀—láti gbá àwọn òpó rẹ̀ mú, láti lè máa fi gbé e.
5 Et les leviers eux-mêmes tu les feras de bois de sétim, et tu les doreras.
Ìwọ yóò sì ṣe òpó igi kasia, ìwọ yóò sì bọ́ wọ́n pẹ̀lú wúrà.
6 Et tu placeras l’autel contre le voile qui est suspendu devant l’arche de témoignage, devant le propitiatoire dont est couvert le témoignage, où je te parlerai.
Ìwọ yóò gbé pẹpẹ náà sí iwájú aṣọ ìkélé, èyí tí ó wà níwájú àpótí ẹ̀rí níwájú ìtẹ́ àánú èyí tí ó wà lórí àpótí ẹ̀rí níbi ti èmi yóò ti máa bá ọ pàdé.
7 Et Aaron y brûlera le matin un parfum, exhalant une odeur suave. Quand il apprêtera les lampes, il le brûlera;
“Aaroni yóò sì máa jó tùràrí dídùn lórí pẹpẹ náà ní àràárọ̀, nígbà tí ó tún àwọn fìtílà náà ṣe.
8 Et quand il les placera vers le soir, il brûlera un parfum perpétuel devant le Seigneur en vos générations.
Aaroni yóò sì tún jó tùràrí nígbà tí ó bá tan fìtílà ní àṣálẹ́, bẹ́ẹ̀ ní tùràrí yóò máa jó títí láé níwájú Olúwa fún àwọn ìran tó ń bọ̀.
9 Vous n’offrirez sur cet autel, ni parfum d’une autre composition, ni oblation, ni victime; et vous n’y ferez point de libations.
Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mú àjèjì tùràrí wá sórí pẹpẹ yìí tàbí ẹbọ sísun kankan tàbí ọrẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ da ẹbọ ohun mímu sórí i rẹ̀.
10 Et Aaron fera des expiations sur les cornes de l’autel une fois par an, en y répandant le sang de la victime qui a été offerte pour le péché, et il conciliera à l’autel la faveur du Seigneur dans vos générations. Ce sera une chose très sainte pour le Seigneur.
Aaroni yóò sì máa ṣe ètùtù sórí àwọn ìwo rẹ̀ lẹ́ẹ̀kan lọ́dún. Òun yóò sì máa ṣe ètùtù ọdọọdún yìí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ẹbọ ètùtù fún ìran tó ń bọ̀. Mímọ́ jùlọ ni sí Olúwa.”
11 Le Seigneur parla encore à Moïse, disant:
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
12 Quand tu auras fait le dénombrement des enfants d’Israël, ils donneront chacun un prix au Seigneur pour leurs âmes, et il n’y aura point de plaie parmi eux, lorsqu’ils auront été recensés.
“Nígbà tí ìwọ bá ka iye àwọn ọmọ Israẹli láti mọ iye wọn, ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gbọdọ̀ mú ìràpadà ọkàn rẹ̀ wá fún Olúwa ní ìgbà tí o bá ka iye wọn. Nígbà náà ni àjàkálẹ̀-ààrùn kì yóò súnmọ́ wọn, nígbà tí o bá ń ka iye wọn.
13 Or voici ce que donnera quiconque aura présenté son nom: un demi-sicle selon la mesure du temple. Le sicle a vingt oboles. La moitié d’un sicle sera offerte au Seigneur.
Olúkúlùkù ẹrù tí ó bá kọjá lọ sọ́dọ̀ àwọn tí a ti kà yóò san ìdajì ṣékélì, gẹ́gẹ́ bí ṣékélì ibi mímọ́, èyí tí ó wọn ogún gera. Ìdajì ṣékélì yìí ní ọrẹ fún Olúwa.
14 Celui qui est compris dans le dénombrement, depuis vingt ans et au-dessus donnera ce prix.
Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá sínú àwọn tí a kà láti ẹni ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni yóò fi ọrẹ fún Olúwa.
15 Le riche n’ajoutera point à la moitié d’un sicle, et le pauvre n’y diminuera rien.
Àwọn olówó kì yóò san ju ìdajì ṣékélì lọ, àwọn tálákà kò sì gbọdọ̀ dín ní ìdajì ṣékélì nígbà tí ẹ̀yin bá mú ọrẹ wá fún Olúwa láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.
16 Et l’argent reçu qui aura été apporté par les enfants d’Israël, tu le donneras pour les usages du tabernacle de témoignage, afin qu’il soit un souvenir d’eux devant le Seigneur et que le Seigneur se montre propice à leurs âmes.
Ìwọ yóò sì gba owó ètùtù náà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Israẹli, ìwọ yóò sì fi lélẹ̀ fún ìsìn àgọ́ àjọ. Yóò jẹ́ ìrántí fún àwọn ọmọ Israẹli níwájú Olúwa, láti ṣe ètùtù fún ọkàn yín.”
17 Le Seigneur parla encore à Moïse, disant:
Nígbà náà ni Olúwa wí fún Mose pé,
18 Tu feras aussi un bassin d’airain avec sa base pour se laver, et tu le placeras entre le tabernacle de témoignage et l’autel. Or, de l’eau ayant été mise,
“Ìwọ yóò sì ṣe agbada idẹ kan, àti ẹsẹ̀ rẹ̀ idẹ, fún wíwẹ̀. Ìwọ yóò sì gbé e sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ náà, ìwọ yóò sì pọn omi sínú rẹ̀.
19 Aaron et ses fils y laveront leurs mains et leurs pieds,
Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ yóò máa wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn pẹ̀lú omi tí ó wà nínú rẹ̀.
20 Quand ils devront entrer dans le tabernacle de témoignage, et quand ils devront s’approcher de l’autel pour y offrir un parfum à brûler au Seigneur,
Nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ inú àgọ́ àjọ, wọ́n yóò wẹ̀ pẹ̀lú omi nítorí kí wọ́n má ba à kú. Bákan náà, nígbà tí wọ́n bá súnmọ́ ibi pẹpẹ láti ṣe ìsìn, láti mú ẹbọ ti a fi iná sun wá fún Olúwa,
21 De peur qu’ils ne meurent. Ce sera une loi perpétuelle pour Aaron et sa postérité durant ses successions.
wọn yóò sì wẹ ọwọ́ wọn àti ẹsẹ̀ wọn, nítorí kí wọn máa ba à kú. Èyí ni yóò jẹ́ ìlànà títí láé fún Aaroni àti irú àwọn ọmọ rẹ̀ fún ìrandíran wọn.”
22 Le Seigneur parla encore à Moïse,
Olúwa sọ fún Mose pé,
23 Disant: Prends des aromates, cinq cents sicles de myrrhe, première et choisie, et la moitié moins de cinnamome, c’est-à-dire, deux cent cinquante sicles, et pareillement deux cent cinquante sicles de canne;
“Ìwọ yóò mú ààyò tùràrí olóòórùn sí ọ̀dọ̀ rẹ; ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì (kilogiramu mẹ́fà) tí òjìá ṣíṣàn, ìdajì bí ó bá yẹ àádọ́ta lé nígba ṣékélì tí kinamoni dídùn, àti kénì dídùn àádọ́ta lé nígba ṣékélì,
24 Cinq cents sicles de casse au poids du sanctuaire et une mesure de hin d’huile d’olive;
kasia ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ṣékélì gbogbo rẹ̀ ní ìlànà ṣékélì ibi mímọ́ àti hínì òróró olifi kan (lita mẹ́rin).
25 Et tu feras de l’huile sainte d’onction, essence composée selon l’art d’un parfumeur.
Ṣe ìwọ̀nyí ní òróró mímọ́ ìkunra, tí a pò gẹ́gẹ́ bí olùṣe òórùn dídùn tì í ṣe. Yóò jẹ òróró mímọ́ ìtasórí.
26 Puis tu en oindras le tabernacle de témoignage, l’arche du testament,
Ìwọ yóò sì lò ó láti ya àgọ́ sí mímọ́ àti àpótí ẹ̀rí náà,
27 La table avec ses vases, le chandelier et ses ustensiles, les autels du parfum à brûler,
tábìlì àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ọ̀pá fìtílà àti ohun èlò rẹ̀, àti pẹpẹ tùràrí,
28 Et de l’holocauste, et tous les objets qui appartiennent à leur service.
pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, àti agbada pẹ̀lú ẹsẹ̀ rẹ̀.
29 Et tu sanctifieras toutes ces choses, et elles seront très saintes: celui qui les touchera sera sanctifié.
Ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè jẹ́ mímọ́ jùlọ, àti ohunkóhun tí ó bá fi ọwọ́ kàn wọn yóò di mímọ́.
30 Tu oindras Aaron et ses fils, et tu les sanctifieras, afin qu’ils exercent les fonctions du sacerdoce pour moi.
“Ìwọ yóò sì ta òróró sí orí Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, ìwọ yóò sì sọ wọ́n di mímọ́, nítorí kí wọn lè sìn mí bí àlùfáà.
31 Et aux enfants d’Israël aussi tu diras: Cette huile d’onction me sera consacrée en vos générations.
Ìwọ yóò sì sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé, ‘Èyí ni yóò ṣe òróró mímọ́ ìtasórí mi fún ìrandíran tó ń bọ̀.
32 Aucune chair d’homme n’en sera ointe, et tu n’en feras point d’autre selon sa composition, parce qu’elle a été sanctifiée, et elle sera sainte pour vous.
Má ṣe dà á sí ara ènìyàn kí o má sì ṣe ṣe òróró kankan ni irú rẹ̀. Mímọ́ ni, ẹ̀yin sì gbọdọ̀ kà á sí mímọ́.
33 Un homme quelconque qui en composera de pareille et qui en donnera à un étranger, sera exterminé du milieu de son peuple.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá po irú rẹ̀, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó bá fi sára àlejò yàtọ̀ sí àlùfáà, a ó gé e kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.’”
34 Le Seigneur dit encore à Moïse: Prends des aromates, du si acte, de l’onyx, du galbanum odoriférant et de l’encens le plus luisant, toutes ces choses seront de même poids,
Olúwa sọ fún Mose pé, “Mú tùràrí olóòórùn dídùn sọ́dọ̀ rẹ, onika, àti galibanumu àti kìkì tùràrí dáradára, òsùwọ̀n kan fún gbogbo rẹ,
35 Et tu feras un parfum à brûler composé selon l’art d’un parfumeur, mêlé avec soin, pur et très digne de sanctification.
ṣe tùràrí olóòórùn dídùn tí a pò, iṣẹ́ àwọn olóòórùn, tí ó ní iyọ̀, ó dára, ó sì jẹ́ mímọ́.
36 Et lorsqu’en les broyant tu auras réduit toutes ces choses en une poudre très fine, tu en mettras devant le tabernacle de témoignage, dans lequel lieu je t’apparaîtrai. Ce sera pour vous un très saint parfum à brûler.
Ìwọ yóò sì lọ díẹ̀ nínú rẹ̀ kúnná, ìwọ yóò sì gbé e síwájú ẹ̀rí ní àgọ́ àjọ, níbi tí èmi yóò ti pàdé yín. Yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ fún yín.
37 Vous ne ferez point de pareille composition pour votre usage, parce que c’est une chose sainte pour le Seigneur.
Ẹ má ṣe ṣe tùràrí kankan ní irú èyí fúnra yín; ẹ kà á ní mímọ́ sí Olúwa.
38 Un homme quelconque qui en fera de semblable pour en respirer avec plaisir l’odeur, périra du milieu de ses peuples.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá ṣe irú rẹ̀ láti máa gbádùn òórùn rẹ̀, òun ni a ó gé kúrò nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.”

< Exode 30 >