< Exode 2 >

1 Après cela un homme de la famille de Lévi sortit et prit une femme de sa race;
Ó sì ṣe, ọkùnrin ará ilé Lefi kan fẹ́ ọmọbìnrin ará Lefi kan ni ìyàwó.
2 Laquelle conçut et enfanta un fils; et le voyant beau, elle le cacha pendant trois mois.
Obìnrin náà sì lóyún, ó sì bí ọmọkùnrin kan. Nígbà tí ó rí í pé ọmọ náà rẹwà, ó gbé ọmọ náà pamọ́ fún oṣù mẹ́ta.
3 Mais comme elle ne pouvait plus le cacher, elle prit une corbeille de jonc, et l’enduisit de bitume et de poix; puis elle mit dedans le petit enfant, et l’exposa parmi les joncs de la rive du fleuve,
Ṣùgbọ́n nígbà tí kò le è gbé e pamọ́ mọ́, ó fi ewé papirusi hun apẹ̀rẹ̀, ó sì fi ọ̀dà àti òjé igi sán apẹ̀rẹ̀ náà. Ó sì tẹ́ ọmọ náà sínú rẹ̀, ó sì gbe é sí inú eèsún ni etí odò Naili.
4 La sœur de l’enfant se tenant au loin, et considérant l’issue de la chose.
Arábìnrin rẹ̀ dúró ni òkèèrè láti wo ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ọmọ náà.
5 Or voilà que la fille de Pharaon descendait pour se baigner dans le fleuve, et ses jeunes filles marchaient le long du bord de l’eau. Lorsqu’elle eut vu la corbeille au milieu des joncs, elle envoya une de ses servantes, qui l’apporta.
Nígbà náà ni ọmọbìnrin Farao sọ̀kalẹ̀ wá sí etí odò Naili láti wẹ̀, àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sì ń rìn ni etí bèbè odò. Ó sì ri apẹ̀rẹ̀ náà ni àárín eèsún, ó sì rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ obìnrin kan láti lọ gbé e wá,
6 Ouvrant la corbeille, et y apercevant le petit enfant qui criait, elle eut pitié de lui, et dit: C’est un enfant des Hébreux.
ó ṣí i, ó sì rí ọmọ náà. Ọmọ náà ń sọkún, àánú ọmọ náà sì ṣe é. Ó wí pé, “Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Heberu ni èyí.”
7 Alors la sœur de l’enfant: Voulez-vous, lui dit-elle, que j’aille, et que je vous fasse venir une femme des Hébreux qui puisse nourrir ce petit enfant?
Nígbà náà ni arábìnrin rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ ọmọbìnrin Farao pé, “Ṣé kí èmi lọ wá ọ̀kan lára àwọn obìnrin Heberu wá fún ọ láti bá ọ tọ́jú ọmọ náà?”
8 Elle répondit: Va. La jeune fille alla et appela sa mère,
Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni; lọ.” Arábìnrin náà sì lọ, ó sì pe ìyá ọmọ náà wá.
9 À laquelle la fille de Pharaon ayant parlé: Prends, dit-elle, cet enfant, et nourris-le-moi; c’est moi qui te donnerai ton salaire. La femme prit et nourrit l’enfant; et quand il eut grandi elle le remit à la fille de Pharaon,
Ọmọbìnrin Farao sì wí fún un pé, “Gba ọmọ yìí kí o sì tọ́jú rẹ̀ fún mi, èmi yóò san owó iṣẹ́ ẹ̀ rẹ fún ọ.” Ọmọbìnrin náà sì gbé ọmọ náà lọ, ó sì tọ́jú rẹ̀.
10 Qui l’adopta pour son fils, et lui donna le nom de Moïse, disant: C’est de l’eau que je l’ai tiré.
Nígbà tí ọmọ náà sì dàgbà, ó mú un tọ ọmọbìnrin Farao wá, ó sì di ọmọ rẹ̀. Ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Mose, ó wí pé, “Nítorí tí mo fà á jáde nínú omi.”
11 En ces jours-là, après que Moïse fut devenu grand, il sortit vers ses frères, et il vit leur affliction, et un Egyptien frappant un des Hébreux ses frères.
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Mose ti dàgbà, ó jáde lọ sí ibi ti àwọn ènìyàn rẹ̀ wà, ó ń wò wọ́n lẹ́nu iṣẹ́ líle wọn, ó ri ará Ejibiti tí ń lu ará Heberu, ọ̀kan nínú àwọn ènìyàn rẹ̀.
12 Or lorsqu’il eut regardé çà et là, et qu’il eut vu qu’il n’y avait personne, il tua l’Egyptien et le cacha dans le sable.
Ó wo ìhín, ó wo ọ̀hún, nígbà tí kò rí ẹnìkankan, ni ó bá pa ará Ejibiti náà, ó sì bò ó mọ́ inú iyanrìn.
13 Et étant sorti le jour suivant, il aperçut deux Hébreux qui se querellaient; et il demanda à celui qui faisait l’injure: Pourquoi frappes-tu ton semblable?
Ní ọjọ́ kejì, ó jáde lọ, ó rí àwọn ará Heberu méjì tí wọ́n ń jà. Ó béèrè lọ́wọ́ èyí tí ó jẹ̀bi pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń lu Heberu arákùnrin rẹ?”
14 Celui-ci répondit: Qui t’a établi prince et juge sur nous? Est-ce que tu veux me tuer, comme hier tu as tué l’Egyptien? Moïse eut peur, et dit: Comment cette chose est-elle devenue publique?
Ọkùnrin náà sì dáhùn pé, “Ta ni ó fi ọ́ jẹ olórí àti onídàájọ́ lórí wa? Ṣé ìwọ fẹ́ pa mí bí o ti pa ará Ejibiti?” Nígbà náà ni ẹ̀rù ba Mose, ó sì wí pé, “Lóòótọ́ ni ọ̀ràn yìí ti di mí mọ̀.”
15 Cependant Pharaon apprit ce discours, et il cherchait à faire mourir Moïse, qui fuyant de sa présence, demeura dans la terre de Madian, et s’assit près d’un puits.
Nígbà ti Farao sì gbọ́ nípa èyí, ó wá ọ̀nà láti pa Mose, ṣùgbọ́n Mose sá kúrò ní àrọ́wọ́tó o Farao, ó lọ sí Midiani láti máa gbé, nígbà tí ó dé bẹ̀, ó jókòó ni ẹ̀bá a kànga kan.
16 Or le prêtre de Madian avait sept filles, qui vinrent pour puiser de l’eau; et les canaux remplis, elles désiraient abreuver les troupeaux de leur père.
Ó sì ṣe, àlùfáà Midiani kan ni àwọn ọmọbìnrin méje, wọn sì wá láti pọn omi kún ọpọ́n ìmumi fún ẹran ọ̀sìn baba wọn.
17 Les pasteurs survinrent et les chassèrent; mais Moïse se leva, et les jeunes filles défendues, il abreuva leurs brebis.
Àwọn darandaran kan wá, wọ́n sì lé wọn sẹ́yìn, ṣùgbọ́n Mose dìde láti gbà wọ́n sílẹ̀ àti láti ràn wọ́n lọ́wọ́ láti fún ẹran wọn ní omi.
18 Lorsqu’elles furent revenues vers Raguel leur père, il leur demanda: Pourquoi êtes-vous revenues plus tôt que de coutume?
Nígbà ti àwọn ọmọbìnrin náà padà dé ọ̀dọ̀ Reueli baba wọn, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tètè dé ni òní?”
19 Elles répondirent: Un Egyptien nous a délivrées de la main des pasteurs: de plus, il a même puisé de l’eau avec nous, et il a donné à boire à nos brebis.
Wọ́n dá a lóhùn pé, “Ará Ejibiti kan ni ó gbà wá sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn darandaran, ó tilẹ̀ ràn wá lọ́wọ́ láti fa omi àti láti fún agbo ẹran ní omi.”
20 Mais où est-il? reprit Raguel. Pourquoi avez-vous laissé aller cet homme? appelez-le, afin qu’il mange du pain.
Ó sọ fún àwọn ọmọbìnrin rẹ̀, “Níbo ni ó wà? Èéṣe ti ẹ fi fi ọkùnrin náà sílẹ̀? Ẹ pè é wá jẹun.”
21 Moïse jura donc qu’il habiterait avec lui, et il prit Séphora sa fille pour femme:
Mose gbà láti dúró lọ́dọ̀ ọkùnrin náà, ẹni tí o fi Sippora, ọmọbìnrin rẹ̀ fún Mose láti fi ṣe aya.
22 Laquelle lui enfanta un fils qu’il appela Gersam, disant: J’ai été voyageur dans une terre étrangère. Mais elle en enfanta un autre qu’il appela Eliézer, disant: Le Dieu de mon père, mon aide, m’a délivré de la main de Pharaon.
Ó sì bí ọmọkùnrin kan tí ó pe orúkọ rẹ̀ ní Gerṣomu, ó wí pé, “Èmi ń ṣe àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì.”
23 Mais après bien du temps, le roi d’Egypte mourut, et les enfants d’Israël, gémissant à cause de leurs travaux, vociférèrent, et leur clameur monta de leurs travaux jusqu’à Dieu.
Lẹ́yìn ìgbà pípẹ́, ọba Ejibiti kú. Àwọn ará Israẹli ń kérora ní oko ẹrú wọn, wọ́n ń ké fún ìrànlọ́wọ́ nítorí oko ẹrú tí wọ́n wà, igbe wọ́n sì dé ọ̀dọ̀ Ọlọ́run.
24 Et il entendit leur gémissement, et il se souvint de l’alliance qu’il fit avec Abraham, Isaac et Jacob.
Ọlọ́run gbọ́ igbe wọn, Ó sì rántí májẹ̀mú rẹ̀ pẹ̀lú Abrahamu, Isaaki àti pẹ̀lú Jakọbu.
25 Et le Seigneur regarda les enfants d’Israël et il les reconnut.
Nítorí náà, Ọlọ́run bojú wo àwọn ará Israẹli, Ó sì wà láti gbà wọ́n sílẹ̀.

< Exode 2 >