< Exode 16 >

1 Et ils partirent d’Elim, et toute la multitude des enfants d’Israël vint au désert de Sin, qui est entre Elim et Sinaï, le quinzième jour du second mois après qu’ils furent sortis de la terre d’Egypte.
Ìjọ àwọn ọmọ Israẹli mú ọ̀nà wọn pọ̀n kúrò ni Elimu, wọ́n dé sí ijù Sini tí ó wà láàrín Elimu àti Sinai, ni ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù kejì tí wọ́n jáde kúrò ni ilẹ̀ Ejibiti.
2 Et toute l’assemblée des enfants d’Israël murmura contre Moïse et Aaron dans le désert.
Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sì ń kùn sí Mose àti Aaroni ní ijù náà.
3 Et les enfants d’Israël leur dirent: Plût à Dieu que nous fussions morts par la main du Seigneur dans la terre d’Egypte, quand nous étions assis près des marmites de viandes, et que nous mangions du pain à satiété! Pourquoi nous avez-vous amenés dans ce désert, pour faire mourir toute cette multitude de faim?
Àwọn ọmọ Israẹli wí fún wọn pé, “Àwa ìbá ti ọwọ́ Olúwa kú ni Ejibiti! Níbi tí àwa ti jókòó ti ìkòkò ẹran ti a sì ń jẹ ohun gbogbo tí a fẹ́ ni àjẹyó, ṣùgbọ́n ẹ̀yin mú wa wá sí inú ijù yìí láti fi ebi pa wá tí a ó fi kú.”
4 Or le Seigneur dit à Moïse: Voici que moi, je ferai pleuvoir pour vous du pain du ciel; que le peuple sorte, et qu’il en amasse ce qui lui suffira pour chaque jour, afin que j’éprouve s’il marche en ma loi, ou non.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èmi yóò rọ òjò oúnjẹ láti ọ̀run wá fún yín. Àwọn ènìyàn yóò sì máa jáde lọ ni ọjọ́ kọ̀ọ̀kan láti kó ìwọ̀nba oúnjẹ ti ó tó fún oúnjẹ òòjọ́ wọn. Ní ọ̀nà yìí ni, èmi yóò fi dán wọn wò láti mọ bóyá wọn yóò máa tẹ̀lé ìlànà mi.
5 Mais qu’au sixième jour ils apprêtent ce qu’ils auront apporté, et que ce soit le double de ce qu’ils avaient coutume d’amasser chaque jour.
Ní ọjọ́ kẹfà, ki wọn kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń ko ni ojoojúmọ́ tẹ́lẹ̀.”
6 Et Moïse et Aaron dirent à tous les enfants d’Israël: Ce soir vous saurez que c’est le Seigneur qui vous a retirés de la terre d’Egypte;
Mose àti Aaroni sọ fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ní ìrọ̀lẹ́, ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Olúwa ni ó mú un yín jáde láti Ejibiti wá.
7 Et au matin vous verrez la gloire du Seigneur; car il a entendu votre murmure contre lui; mais nous, qui sommes-nous, pour que vous murmuriez contre nous?
Ní òwúrọ̀, ẹ̀yin yóò ri ògo Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn tí ẹ kùn sí i. Ta ni àwa ti ẹ̀yin yóò máa kùn sí wa?”
8 Et Moïse ajouta: Le Seigneur vous donnera ce soir de la chair à manger, et au matin du pain à satiété, parce qu’il a entendu vos murmures par lesquels vous avez murmuré contre lui; car, nous, que sommes-nous? ce n’est donc pas contre nous qu’est votre murmure, mais contre le Seigneur.
Mose tún wí pé, “Ẹ̀yin yóò mọ pé Olúwa ni, nígbà ti ó bá fún un yín ni ẹran ni ìrọ̀lẹ́ àti gbogbo oúnjẹ ti ẹ̀yin ń fẹ́ ni òwúrọ̀, nítorí kíkùn ti ẹ̀yin ń kùn sí i. Ta ni àwa? Ẹ̀yin kò kùn sí àwa, Olúwa ni ẹ̀yin kùn sí i.”
9 Moïse dit aussi à Aaron: Dis à toute l’assemblée des enfants d’Israël: Approchez-vous devant le Seigneur car il a entendu votre murmure.
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli pe, ‘Ẹ wá sí iwájú Olúwa, nítorí òun ti gbọ́ kíkùn yín.’”
10 Et lorsque Aaron parlait à toute l’assemblée des enfants d’Israël, ils regardèrent vers le désert, et voilà que la gloire du Seigneur apparut dans la nuée.
Ó sì ṣe bí Aaroni ti ń bá gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli sọ̀rọ̀, wọn si bojú wo ìhà ijù, sì kíyèsi ògo Olúwa si farahàn ni àwọsánmọ̀.
11 Or le Seigneur parla à Moïse, disant:
Olúwa sọ fún Mose pé,
12 J’ai entendu les murmures des enfants d’Israël, dis-leur: Ce soir vous mangerez de la chair, et au matin vous serez rassasiés de pain, et vous saurez que je suis le Seigneur votre Dieu.
“Èmi ti gbọ́ kíkùn àwọn ọmọ Israẹli. Sọ fun wọn, ‘Ní àṣálẹ́, ẹ̀yin yóò jẹ ẹran, àti ni òwúrọ̀ ni ẹ̀yin yóò jẹ oúnjẹ. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín.’”
13 Le soir vint donc, et les cailles montant couvrirent le camp: le matin aussi la rosée se trouva répandue autour du camp.
Ní àṣálẹ́ ọjọ́ náà ni àwọn àparò fò dé, wọ́n sì bo àgọ́ mọ́lẹ̀, ní òwúrọ̀ ìrì sì sẹ̀ yí gbogbo àgọ́ náà ká.
14 Et lorsqu’elle eut couvert la surface de la terre, il apparut dans le désert quelque chose de menu et comme pilé au mortier, ressemblant à la gelée blanche sur la terre.
Nígbà tí ìrì tí ó sẹ̀ bo ilẹ̀ ti lọ, kíyèsi i, ohun tí ó dì, tí ó sì ń yooru bí i yìnyín wà lórí ilẹ̀.
15 Ce qu’ayant vu les enfants d’Israël, ils se dirent les uns aux autres: Manhu, ce qui signifie: Qu’est-ceci? ils ignoraient, en effet, ce que c’était. Moïse leur dit: C’est le pain que le Seigneur vous a donné à manger.
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli rí i, wọ́n bi ara wọn léèrè pé, “Kí ni èyí?” Nítorí pé wọn kò mọ ohun tí i ṣe. Mose sì wí fún wọn pé, “Èyí ni oúnjẹ tí Olúwa fi fún un yín láti jẹ.
16 Voici les paroles que le Seigneur a ordonnées: Que chacun en amasse autant qu’il suffit pour manger: un gomor pour chaque tête, selon le nombre de vos âmes qui habitent dans leur tente; voilà ce que vous recueillerez.
Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ, ‘Kí olúkúlùkù máa kó èyí ti ó tó fún un láti jẹ. Ẹ mú òsùwọ̀n omeri kan fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ti ó wà nínú àgọ́ yín.’”
17 Et les enfants d’Israël firent ainsi, et ils en amassèrent, l’un plus, l’autre moins.
Àwọn ọmọ Israẹli sì ṣe bí a ti sọ fún wọn; àwọn kan kó púpọ̀, àwọn kan kó kékeré.
18 Et ils la mesurèrent à la mesure du gomor: or celui qui en avait plus amassé, n’en eut pas davantage, et celui qui en avait moins amassé, n’en trouva pas moins, car chacun en recueillit selon ce qu’il pouvait manger.
Nígbà tí wọ́n fi òsùwọ̀n omeri wọ̀n-ọ́n, ẹni tí ó kó púpọ̀ kò ní púpọ̀ jù, bẹ́ẹ̀ ni ẹni tí ó kó ìwọ̀nba kò ní kéré jù. Ẹnìkọ̀ọ̀kan kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un.
19 Moïse leur dit aussi: Que nul n’en laisse pour le malin.
Mose sì wí fún wọ́n pé, “Kí ẹnikẹ́ni ó má ṣe kó pamọ́ lára rẹ̀ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì.”
20 Tous ne l’écoutèrent pas, mais quelques-uns d’entre eux en laissèrent jusqu’au matin; or elle commença par fourmiller de vers, puis elle se corrompit; et Moïse fut irrité contre eux.
Ṣùgbọ́n, àwọn kan nínú wọn kò fetí sí Mose, wọ́n kó lára rẹ̀ pamọ́ di òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ohun ti wọ́n kó pamọ́ kún fún ìdin, ó sì ti bẹ̀rẹ̀ sí ní rùn. Nítorí náà Mose bínú sí wọn.
21 Chacun en amassait donc le matin autant qu’il pouvait suffire pour manger; et lorsque le soleil était devenu chaud, elle se fondait.
Ní òwúrọ̀, ni ojoojúmọ́ ni ẹnìkọ̀ọ̀kan ń lọ kó ìwọ̀nba ti ó tó fún un láti jẹ, bí oòrùn bá sì mú, a sì yọ́.
22 Mais, au sixième jour, ils amassèrent le double de cette nourriture, c’est-à-dire, deux gomors pour chaque personne: tous les chefs de la multitude vinrent, et l’annoncèrent à Moïse,
Ní ọjọ́ kẹfà, wọ́n kó ìlọ́po méjì èyí tiwọn ń kó tẹ́lẹ̀: òsùwọ̀n omeri méjì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan; àwọn olórí ìjọ ènìyàn sì wá, wọ́n sì sọ èyí fún Mose.
23 Qui leur dit: Voici ce qu’a dit le Seigneur: C’est demain le repos du sabbat, consacré au Seigneur; ce qui doit être fait, faites-le aujourd’hui; et ce qui doit être cuit, faites-le cuire, mais tout ce qui sera de reste, serrez-le jusqu’au matin.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ: ‘Ọ̀la jẹ́ ọjọ́ ìsinmi, ìsinmi mímọ́ fún Olúwa. Ẹ yan èyí ti ẹ̀yin ní yan, kí ẹ sì bọ èyí ti ẹ̀yin ní bọ̀. Ẹ tọ́jú èyí ti ó kù sílẹ̀, kí ẹ pa á mọ́ di òwúrọ̀.’”
24 Ils firent donc selon qu’avait ordonné Moïse, et la manne ne se corrompit point; et on n’y trouva pas de ver.
Wọ́n sì tọ́jú rẹ̀ di òwúrọ̀ bí Mose ti pàṣẹ; kò sì rùn bẹ́ẹ̀ ni kò sì ní ìdin.
25 Et Moïse dit: Mangez-la aujourd’hui, parce que c’est le sabbat du Seigneur; il ne s’en trouvera pas aujourd’hui dans la campagne.
Mose sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ ẹ́ ní òní nítorí òní jẹ́ ọjọ́ ìsinmi Olúwa. Ẹ̀yin kò ni rí i ni orí ilẹ̀ ní ọjọ́ òní.
26 Pendant six jours ramassez-en, car au septième jour, c’est le sabbat du Seigneur; c’est pourquoi on n’en trouvera pas.
Ní ọjọ́ mẹ́fà ni kí ẹ fi kó o, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ keje ọjọ́ ìsinmi, kò ní sí i fún un yín ni ọjọ́ náà.”
27 Or vint le septième jour, et quelques-uns du peuple étant sortis pour en amasser, ils n’en trouvèrent point.
Síbẹ̀síbẹ̀ àwọn ènìyàn kan jáde lọ ní ọjọ́ keje láti kó o, ṣùgbọ́n wọn kò ri nǹkan kan kó.
28 Alors le Seigneur dit à Moïse: Jusqu’à quand ne voudrez vous point garder mes commandements et ma loi?
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Yóò ti pẹ́ tó ti ẹ ó kọ̀ láti pa àṣẹ mi àti ìlànà mi mọ́?
29 Voyez que le Seigneur vous a donné le sabbat, et à cause de cela au sixième jour il vous a accordé le double de nourriture: que chacun demeure chez soi, et que nul ne sorte de son lieu au septième jour.
Wò ó? Olúwa ti fún un yín ni ọjọ́ ìsinmi, nítorí náà, ni ọjọ́ kẹfà, ó fún un yín ni oúnjẹ ọjọ́ méjì; kí ẹnìkọ̀ọ̀kan dúró ni ibi tí ó gbé wà; kí ẹ má ṣe kúrò ni ibi tí ẹ wà ni ọjọ́ keje.”
30 Ainsi le peuple sabbatisa au septième jour.
Nítorí náà, àwọn ènìyàn sinmi ní ọjọ́ keje.
31 Et la maison d’Israël appela cette nourriture du nom de Man; elle était blanche comme une graine de coriandre, et son goût, celui de la fleur de farine mêlée avec du miel.
Àwọn ènìyàn Israẹli sì pe oúnjẹ náà ní manna. Ó funfun bí irúgbìn korianderi, ó sì dùn bí àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ ti a fi oyin ṣe.
32 Or Moïse dit: Voici les paroles qu’a ordonnées le Seigneur: Emplis-en un gomor, et qu’il soit gardé dans les générations qui doivent venir dans la suite, afin qu’elles connaissent le pain dont je vous ai nourris dans le désert, quand vous avez été retirés de la terre d’Egypte.
Mose wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pàṣẹ, ‘Ẹ mú òsùwọ̀n omeri manna kí ẹ sì pa á mọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀, kí wọn kí ó lè rí oúnjẹ ti èmi fi fún un yín jẹ ní ijù, nígbà tí mo mú un yín jáde ni ilẹ̀ Ejibiti.’”
33 Et Moïse dit à Aaron: Prends un vase et mets-y de la Manne, autant que peut en contenir un gomor; et place-le devant le Seigneur, afin de le conserver en vos générations,
Nígbà náà ni Mose sọ fún Aaroni pe, “Mú ìkòkò kan, kí o sì kó manna tí ó kún òsùwọ̀n omeri kan sí inú rẹ̀, kí o sì gbé e kalẹ̀ ni iwájú Olúwa láti tọ́jú rẹ̀ pamọ́ de àwọn ìran ti ń bọ̀.”
34 Comme a ordonné le Seigneur à Moïse. Et Aaron le plaça dans le tabernacle pour être réservé.
Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, Aaroni gbé manna sí iwájú ẹ̀rí láti pa á mọ́.
35 Or, les enfants d’Israël mangèrent la Manne pendant quarante ans, jusqu’à ce qu’ils vinrent en une terre habitable; c’est de cet aliment qu’ils furent nourris, jusqu’à ce qu’ils touchèrent aux confins de la terre de Chanaan.
Àwọn ará Israẹli jẹ manna fún ogójì ọdún títí wọ́n fi dé ilẹ̀ Kenaani ni ibi ti èso ti wà fún wọn láti jẹ, wọ́n jẹ manna títí tí wọ́n fi dé ilẹ̀ agbègbè Kenaani.
36 Or, le gomor est la dixième partie de l’éphi.
(Òsùwọ̀n omeri kan sì jẹ́ ìdákan nínú ìdámẹ́wàá efa.)

< Exode 16 >