< Exode 14 >

1 Or le Seigneur parla à Moïse, disant:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Dis aux enfants d’Israël qu’ils retournent, et qu’ils campent vis-à-vis de Phihahiroth, qui est entre Magdalum et la mer, contre Béelséphon: c’est la vue de ce lieu que vous poserez votre camp, près de la mer.
“Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli kí wọn padà sẹ́yìn, kí wọ́n sì pàgọ́ sí tòsí Pi-Hahirotu láàrín Migdoli òun Òkun, kí wọn kí ó pàgọ́ sí ẹ̀bá Òkun, ní òdìkejì Baali-Ṣefoni.
3 Car Pharaon va dire des enfants d’Israël: Ils sont resserrés dans la terre, le désert les tient enfermés.
Farao yóò ronú pé àwọn ọmọ Israẹli ń ráre káàkiri ní ìdààmú ni àti wí pé aginjù náà ti sé wọn mọ́.
4 Et j’endurcirai son cœur, et il les poursuivra; et je serai glorifié en Pharaon et en toute son armée; et les Egyptiens sauront que je suis le Seigneur. Et les enfants d’Israël firent ainsi.
Èmi yóò sé ọkàn Farao le ti yóò fi lépa wọn. Ṣùgbọ́n èmi yóò gba ògo fún ará mi láti ìpàṣẹ Farao àti ogun rẹ̀, àti pé àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa.” Àwọn Israẹli sì ṣe bẹ́ẹ̀.
5 Cependant on annonça au roi des Egyptiens que le peuple s’était enfui, et le cœur de Pharaon et de ses serviteurs fut changé à l’égard du peuple; et ils dirent: Qu’avons-nous voulu faire en laissant aller Israël, pour qu’il ne nous servît plus?
Nígbà tí wọ́n sọ fún ọba Ejibiti pé àwọn ènìyàn náà ti sálọ, ọkàn Farao àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ yí padà sí àwọn ènìyàn, wọ́n sì wí pé, “Kí ni ohun tí àwa ṣe yìí? Àwa ti jẹ́ kí àwọn ọmọ Israẹli kí ó lọ, a sì ti pàdánù ìsìnrú wọn.”
6 Il attela donc son char, et prit tout son peuple avec lui.
Ó sì di kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀, ó sì kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀,
7 Il emmena aussi, outre six cents chars d’élite, tout ce qu’il y eut de chars dans l’Egypte, et les chefs de toute l’armée.
ó mú ẹgbẹ̀ta ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ tí ó jáfáfá jùlọ àti gbogbo ọmọ-ogun oníkẹ̀kẹ́ mìíràn ní Ejibiti, olórí sì wà fún olúkúlùkù wọn.
8 Et le Seigneur endurcit le cœur de Pharaon, roi d’Egypte, et il poursuivit les enfants d’Israël; mais eux étaient sortis par une main élevée.
Olúwa sé ọkàn Farao ọba Ejibiti le, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí lépa àwọn ọmọ Israẹli ti ń jáde lọ ní àìbẹ̀rù.
9 Et comme les Egyptiens suivaient leurs traces de près, ils les trouvèrent dans leur camp près de la mer: toute la cavalerie et les chars de Pharaon et l’armée entière étaient à Phihahiroth contre Béelséphon.
Àwọn ará Ejibiti ń lépa wọn pẹ̀lú gbogbo ẹṣin kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀, wọ́n sì lé wọn bá ni ibi tí wọ́n pa àgọ́ sí lẹ́bàá òkun ní ìhà Pi-Hahirotu, ni òdìkejì Baali-Ṣefoni.
10 Et quand Pharaon se fut approché, les enfants d’Israël, levant les yeux, virent les Egyptiens derrière eux, et ils furent saisis d’une grande crainte, et ils crièrent au Seigneur,
Bí Farao ti súnmọ́ tòsí ọ̀dọ̀ wọn, àwọn ọmọ Israẹli gbé ojú wọn sókè, wọn sì rí àwọn ará Ejibiti tó súnmọ́ wọn. Ẹ̀rù ńlá sì bá àwọn ará Israẹli, wọ́n kígbe sókè sí Olúwa.
11 Et ils dirent à Moïse: Peut-être qu’il n’y avait pas de sépultures en Egypte; c’est pour cela que tu nous a amenés, afin que nous mourions dans le désert: qu’as-tu voulu faire en nous retirant de la terre d’Egypte?
Wọ́n sọ fún Mose pé, “Ṣe nítorí pé kò sí ibojì ni Ejibiti ní ìwọ ṣe mú wa wá láti kú sínú aginjù? Kí ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa ti ìwọ fi mú wa jáde láti Ejibiti wá?
12 N’est-ce pas là le langage que nous te tenions en Egypte, disant: Retire-toi de nous, afin que nous servions les Egyptiens? car il valait beaucoup mieux les servir que mourir dans le désert.
Ǹjẹ́ èyí kọ́ ni àwa sọ fún ọ ni Ejibiti, ‘Fi wá sílẹ̀, jẹ́ kí àwa máa sin ará Ejibiti’? Nítorí kò bá sàn fún wa kí a sin àwọn ará Ejibiti ju kí a kú sínú aginjù yìí lọ!”
13 Or Moïse répondit au peuple: Ne craignez point, demeurez fermes, et voyez les grandes œuvres que le Seigneur va faire aujourd’hui; car les Egyptiens que vous voyez en ce moment, vous ne les verrez plus jamais.
Nígbà náà ni Mose sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Ẹ má bẹ̀rù, ẹ dúró ṣinṣin kí ẹ sì rí ìdáǹdè tí Olúwa yóò fi fún un yín lónìí, àwọn ará Ejibiti ti ẹ̀yin rí lónìí ni ẹ kò ni tún padà rí wọn mọ́.
14 Le Seigneur combattra pour vous, et vous serez dans le silence.
Olúwa yóò jà fún un yín; kí ẹ̀yin kí ó sá à mu sùúrù.”
15 Le Seigneur dit ensuite à Moïse: Pourquoi cries-tu vers moi? Dis aux enfants d’Israël qu’ils partent.
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń ké pè mí? Sọ fún àwọn ará Israẹli kí wọn máa tẹ̀síwájú.
16 Mais toi, élève ta verge, et étends ta main sur la mer, et divise-la, afin que les enfants d’Israël marchent au milieu de la mer à sec.
Ṣùgbọ́n, gbé ọ̀pá rẹ̀ sókè, kí o sì na ọwọ́ rẹ sí orí omi Òkun, kí ó lè pín ní yà kí àwọn ọmọ Israẹli lè la òkun kọjá ni orí ìyàngbẹ ilẹ̀.
17 Pour moi, j’endurcirai le cœur des Egyptiens, afin qu’ils vous poursuivent, et je serai glorifié en Pharaon, et en toute son armée, et en ses chars et en ses cavaliers
Nígbà náà ni èmi yóò sé ọkàn àwọn ará Ejibiti le, wọn yóò sì máa lépa wọn; Èmi yóò gba ògo fún ara mi lórí Farao; lórí gbogbo ogun rẹ̀, lórí kẹ̀kẹ́ ogun àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.
18 Et les Egyptiens sauront que moi, je suis le Seigneur, quand j’aurai été glorifié en Pharaon, et en ses chars et en ses cavaliers.
Àwọn ará Ejibiti yóò mọ̀ pé Èmi ni Olúwa nígbà ti èmi bá gba ògo fún ara mi lórí Farao: lórí kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ àti lórí àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀.”
19 Alors l’ange de Dieu qui précédait le camp d’Israël, alla derrière eux; et ainsi que lui, la colonne de nuée, passant de devant en arrière,
Nígbà náà ni angẹli Ọlọ́run tó ti ń ṣáájú ogun Israẹli lọ, padà o sì rìn ni ẹ̀yìn wọn; Òpó ìkùùkuu tí ń rìn ni iwájú wọn sì padà sí í rìn ni ẹ̀yìn wọn.
20 Se tint entre le camp des Egyptiens et le camp d’Israël; or la nuée était ténébreuse, et elle éclairait la nuit; en sorte que durant tout le temps de la nuit, ils ne pouvaient s’approcher l’un de l’autre.
Ó sì wà láàrín àwọn ọmọ-ogun Ejibiti àti Israẹli. Ìkùùkuu sì ṣú òkùnkùn sí àwọn ará Ejibiti ni òru náà. Ṣùgbọ́n ó tan ìmọ́lẹ̀ sí àwọn Israẹli ni òru náà, ọ̀kan kò sì súnmọ́ èkejì ni gbogbo òru náà.
21 Lors donc que Moïse eut étendu la main sur la mer, le Seigneur la fit retirer, un vent impétueux et brûlant ayant soufflé toute la nuit, et il la mit à sec, et l’eau fut divisée.
Nígbà náà ni Mose na ọwọ́ rẹ̀ sí orí Òkun, ni gbogbo òru náà ni Olúwa fi lé òkun sẹ́yìn pẹ̀lú ìjì líle láti ìlà-oòrùn wá, ó sì sọ ọ́ di ìyàngbẹ ilẹ̀. Omi òkun sì pínyà,
22 Ainsi les enfants d’Israël entrèrent au milieu de la mer desséchée; car l’eau était comme un mur à leur droite et à leur gauche.
àwọn ọmọ Israẹli sì la ìyàngbẹ ilẹ̀ kọjá nínú òkun pẹ̀lú ògiri omi ní ọ̀tún àti òsì.
23 Et les poursuivant, les Egyptiens entrèrent après eux au milieu de la mer, ainsi que toute la cavalerie de Pharaon, ses chars et ses cavaliers.
Àwọn ará Ejibiti sì ń lépa wọn, gbogbo ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ́ tọ̀ wọ́n lọ sínú òkun.
24 Et déjà était venue la veille du matin, et voilà que le Seigneur jetant un regard sur le camp des Égyptiens à travers la colonne de feu et de nuée, tua toute leur armée,
Ní ìṣọ́ òwúrọ̀ Olúwa bojú wo ogun àwọn ará Ejibiti láàrín ọ̀wọ̀n iná àti ìkùùkuu, ó sì kó ìpayà bá àwọn ọmọ-ogun Ejibiti.
25 Et renversa les roues des chars, ils furent entraînés au profond de la mer. Les Égyptiens dirent donc: Fuyons Israël, car le Seigneur combat pour eux contre nous.
Ó sì yọ àgbá ẹsẹ̀ kẹ̀kẹ́ ogun wọn kí ó bá à le ṣòro fún wọn láti fi kẹ̀kẹ́ ogun náà rìn. Àwọn ará Ejibiti wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sá àsálà kúrò ní iwájú àwọn ará Israẹli nítorí Olúwa ń bá wa jà nítorí wọn.”
26 Et le Seigneur dit à Moïse: Étends ta main sur la mer, afin que les eaux retournent vers les Égyptiens, sur leurs chars et leurs cavaliers.
Olúwa sì wí fún Mose pé, “Na ọwọ́ rẹ sí orí òkun kí omi òkun lè ya padà sórí àwọn ará Ejibiti, kẹ̀kẹ́ ogun wọn àti sórí ẹlẹ́ṣin wọn.”
27 Et lorsque Moïse eut étendu sa main contre la mer, elle retourna au premier point du jour en son premier lieu; et les eaux vinrent à la rencontre des Égyptiens qui s’enfuyaient, et le Seigneur les enveloppa au milieu des flots.
Mose sì na ọwọ́ rẹ̀ sí orí òkun, òkun sì padà bọ́ sí ipò rẹ̀ nígbà ti ilẹ̀ mọ́. Àwọn ará Ejibiti ń sá fún omi òkun, Olúwa sì gbá wọn sínú òkun.
28 Ainsi les eaux retournèrent et couvrirent les chars et les cavaliers de toute l’armée de Pharaon, qui poursuivant Israël, étaient entrés dans la mer: et il ne resta pas même un seul d’entre eux.
Omi òkun sì ya padà, ó sì bo kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin: àní, gbogbo ọmọ-ogun Farao tiwọn wọ inú òkun tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ kò sí ọ̀kan nínú wọn tí ó yè.
29 Mais les enfants d’Israël poursuivirent leur chemin au milieu de la mer desséchée, et les eaux étaient pour eux comme un mur à droite et à gauche:
Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli la òkun kọjá lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ pẹ̀lú ògiri omi ni ọ̀tún àti òsì wọn.
30 Et le Seigneur délivra en ce jour-là Israël de la main des Egyptiens.
Ni ọjọ́ yìí ni Olúwa gba Israẹli là kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Ejibiti; Israẹli sì rí òkú àwọn ará Ejibiti ni etí òkun.
31 Et ils virent les Égyptiens morts sur le rivage de la mer, et la main puissante qu’avait étendue le Seigneur contre eux: et le peuple craignit le Seigneur, et ils crurent au Seigneur et à Moïse son serviteur.
Nígbà ti àwọn ọmọ Israẹli rí iṣẹ́ ìyanu ńlá ti Olúwa ṣe fún wọn lára àwọn ará Ejibiti, àwọn ènìyàn bẹ̀rù Olúwa, wọ́n sì gba Olúwa àti Mose ìránṣẹ́ rẹ gbọ́.

< Exode 14 >