< Deutéronome 26 >

1 Lorsque tu seras entré dans la terre que le Seigneur ton Dieu va le donner pour la posséder, que tu l’auras conquise et que tu auras habité en elle,
Nígbà tí ìwọ bá wọ ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ gẹ́gẹ́ bí ohun ìní tí ìwọ sì ti jogún, tí ìwọ sì ti ń gbé níbẹ̀,
2 Tu prendras les prémices de tous tes fruits, tu les mettras dans la corbeille, et tu iras au lieu que le Seigneur ton Dieu aura choisi, afin que son nom y soit invoqué,
mú díẹ̀ nínú ohun tí o pèsè láti inú erùpẹ̀ ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ń fi fún ọ, kó wọn sínú agbọ̀n. Nígbà náà kí o lọ sí ibi tí Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò yàn gẹ́gẹ́ bí ibi tí orúkọ rẹ̀ yóò máa gbé.
3 Et tu t’approcheras du prêtre qu’il y aura en ces jours-là, et tu lui diras: Je déclare hautement aujourd’hui, en présence du Seigneur ton Dieu, que je suis entré dans la terre, au sujet de laquelle il a juré à nos pères qu’il nous la donnerait.
Kí o sì sọ fun àlùfáà tí ó wà ní ibi iṣẹ́ ní àsìkò náà, pé, “Mo sọ ọ́ di mí mọ̀ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé mo ti wá sí ilẹ̀ tí Olúwa búra fún àwọn baba wa.”
4 Alors le prêtre prenant la corbeille de ta main, la déposera devant l’autel du Seigneur ton Dieu,
Àlùfáà yóò gbé agbọ̀n náà kúrò ní ọwọ́ rẹ, yóò sì gbé e kalẹ̀ níwájú pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run rẹ.
5 Et tu diras en présence du Seigneur ton Dieu: Un Syrien poursuivait mon père, qui descendit en Egypte, et là, il séjourna avec un très petit nombre d’hommes; mais il forma une nation grande, forte et nombreuse à l’infini.
Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní iwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Baba mi jẹ́ alárìnkiri ará Aramu, ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí Ejibiti pẹ̀lú ènìyàn díẹ̀, ó sì ń gbé níbẹ̀, ó sì wá di orílẹ̀-èdè olókìkí, alágbára, tí ó kún fún ọ̀pọ̀ ènìyàn.
6 Mais les Egyptiens nous affligèrent et nous persécutèrent, nous imposant des fardeaux très lourds,
Ṣùgbọ́n àwọn ará Ejibiti ṣe àìdára sí wa, wọ́n jẹ wá ní yà, wọ́n fún wa ní iṣẹ́ líle ṣe.
7 Alors nous criâmes au Seigneur le Dieu de nos pères, qui nous exauça, et regarda notre humiliation, notre labeur, et notre angoisse;
Nígbà náà ni a kégbe pe Olúwa Ọlọ́run àwọn baba wa, Olúwa sì gbọ́ ohùn wa, ó sì rí ìrora, làálàá àti ìnira wa.
8 Et il nous retira de l’Egypte par une main forte et un bras étendu, par une grande terreur, des signes et des prodiges;
Nígbà náà ni Olúwa mú wa jáde wá láti Ejibiti pẹ̀lú ọwọ́ agbára àti apá nínà, pẹ̀lú ẹ̀rù ńlá àti iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu.
9 Puis il nous a introduits en ce lieu et nous a livré cette terre, où coulent du lait et du miel.
Ó mú wa wá síbí, ó sì fún wa ní ilẹ̀ yìí, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti oyin;
10 Et c’est pour cela que maintenant j’offre les prémices des fruits de la terre, que le Seigneur m’a donnée. Et tu les laisseras en la présence du Seigneur ton Dieu, et adore le Seigneur ton Dieu.
àti pé ní báyìí, mo mú àkọ́so ilẹ̀ tí ìwọ Olúwa ti fún mi wá.” Ìwọ yóò gbé agbọ̀n náà síwájú Olúwa Ọlọ́run rẹ, kí o sì wólẹ̀ níwájú u rẹ̀.
11 Et tu feras un festin de tous les biens que le Seigneur ton Dieu t’aura donnés, à toi et à ta maison, toi et le Lévite et l’étranger qui est avec toi.
Ìwọ àti àwọn ọmọ Lefi àti àjèjì láàrín yín yóò máa yọ̀ nínú gbogbo oore tí Olúwa ti fi fún ọ àti fún àwọn ará ilé rẹ.
12 Quand tu auras accompli la dîme de tous tes fruits, à la troisième année des décimes, tu les donneras au Lévite, à l’étranger, à l’orphelin et à la veuve, afin qu’ils les mangent au dedans de tes portes, et qu’ils soient rassasiés;
Nígbà tí ìwọ bá ṣetán láti ya ìdámẹ́wàá gbogbo ohun tí o ti mú jáde ní ọdún kẹta sọ́tọ̀ sí apá kan. Ọdún ìdámẹ́wàá, ìwọ yóò fi fún ọmọ Lefi, àjèjì, aláìní baba àti opó, kí wọn kí ó lè jẹ ní àwọn ìlú rẹ, kí wọn sì yó.
13 Et tu diras en la présence du Seigneur ton Dieu: J’ai ôté de ma maison ce qui était consacré, et je l’ai donné au Lévite, à l’étranger, à l’orphelin et à la veuve, comme vous m’avez ordonné; je n’ai pas négligé vos commandements, et n’ai pas oublié votre ordre.
Nígbà náà ní kí o wí fún Olúwa Ọlọ́run rẹ pé, “Èmi ti mú ohun mímọ́ kúrò nínú ilé mi, èmi sì ti fi fún àwọn Lefi, àwọn àjèjì, àwọn aláìní baba àti àwọn opó, gẹ́gẹ́ bí ohun gbogbo tí ìwọ ti pàṣẹ. Èmi kò yípadà kúrò nínú àṣẹ rẹ bẹ́ẹ̀ ni èmi kò gbàgbé ọ̀kankan nínú wọn.
14 Je n’ai pas mangé de ces choses pendant mon deuil, je ne les ai mises à part pour aucun usage profane, et je n’en ai rien employé dans les funérailles. J’ai obéi à la voix du Seigneur mon Dieu et j’ai fait toutes choses, comme vous m’avez ordonné.
Èmi kò jẹ lára ohun mímọ́ ní ìgbà tí mo ń ṣọ̀fọ̀, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mu nínú wọn ní ìgbà tí mo wà ní àìmọ́, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò fi nínú wọn fún òkú. Èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run mi, èmi sì ti ṣe gbogbo ohun tí ó pàṣẹ fún mi.
15 Regardez de votre sanctuaire, du haut des cieux, votre demeure, et bénissez votre peuple d’Israël, et la terre que vous nous avez donnée, comme vous avez juré à nos pères, terre où coulent du lait et du miel.
Wo ilẹ̀ láti ọ̀run wá, ibùgbé mímọ́ rẹ, kí o sì bùkún fún àwọn ènìyàn Israẹli, àti fún ilẹ̀ náà tí ìwọ ti fi fún wa, bí ìwọ ti búra fún àwọn baba ńlá wa, ilẹ̀ tí ó ń sàn fún wàrà àti fún oyin.”
16 Aujourd’hui le Seigneur ton Dieu t’a ordonné d’exécuter ces commandements et ces ordonnances, de les garder et de les accomplir de tout ton cœur et de toute ton âme.
Olúwa Ọlọ́run rẹ pàṣẹ fún ọ ní òní láti máa tẹ̀lé àwọn ìlànà àti òfin, kí o sì máa ṣe wọ́n pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ àti gbogbo àyà rẹ.
17 Tu as choisi aujourd’hui le Seigneur, afin qu’il soit ton Dieu, afin que tu marches dans ses voies, et que tu gardes ses cérémonies, ses commandements et ses ordonnances, et que tu obéisses à son ordre;
Ìwọ jẹ́wọ́ Olúwa ní òní pé Olúwa ni Ọlọ́run rẹ, àti pé ìwọ yóò máa rìn ní ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, àti pé ìwọ yóò máa pa ìlànà rẹ̀, àṣẹ rẹ̀ àti òfin rẹ̀ mọ́, àti pé ìwọ yóò máa ṣe ìgbọ́ràn sí i.
18 Et le Seigneur t’a choisi aujourd’hui, afin que tu sois son peuple particulier, comme il t’a dit, et que tu gardes tous ses préceptes,
Ní òní ni Olúwa jẹ́wọ́ rẹ pé ìwọ ni ènìyàn òun, ilé ìṣúra rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí, àti pé ìwọ yóò máa pa gbogbo àṣẹ rẹ̀ mọ́.
19 Et qu’il t’élève au-dessus de toutes les nations qu’il a créées pour sa louange, son nom et sa gloire; afin que tu sois le peuple saint du Seigneur ton Dieu, comme il a dit.
Òun sì jẹ́wọ́ pé, òun yóò gbé ọ sókè ju gbogbo orílẹ̀-èdè tí òun ti dá lọ, ní ìyìn, ní òkìkí àti ní ọlá; kí ìwọ kí ó le jẹ́ ènìyàn mímọ́ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ gẹ́gẹ́ bí òun ti ṣe ìlérí.

< Deutéronome 26 >