< Amos 8 >

1 Voici ce que m’a montré le Seigneur Dieu; or voici un crochet pour abattre des fruits.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 Et il dit: Que vois-tu, Amos? Et je dis: Un crochet pour abattre des fruits. Et le Seigneur me dit: Elle est venue, la fin pour mon peuple d’Israël; je ne le traverserai plus à l’avenir.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 Et les gonds du temple retentiront en ce jour-là, dit le Seigneur Dieu; beaucoup mourront; en tout lieu régnera le silence.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 Ecoutez ceci, vous qui écrasez le pauvre, et qui faites défaillir les indigents de la terre,
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 Disant: Quand sera passé le mois, alors nous vendrons nos marchandises; et quand sera passé le Sabbat, alors nous ouvrirons nos greniers de blé, afin que nous diminuions la mesure, et que nous augmentions le sicle, et que nous substituions des balances trompeuses,
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 Afin d’avoir en notre possession, pour de l’argent, des indigents et des pauvres, pour des chaussures, et que nous vendions le rebut du blé.
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Le Seigneur a juré contre l’orgueil de Jacob: Si j’oublierai jamais aucune de leurs œuvres.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 Est-ce que sur cela la terre ne sera pas ébranlée, et que tous ses habitants ne seront pas dans le deuil? et que tous entièrement ne monteront pas comme le fleuve, et qu’ils ne seront pas chassés, et qu’ils ne s’écouleront pas comme le fleuve d’Egypte?
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 Et il arrivera en ce jour-là, dit le Seigneur Dieu, que le soleil se couchera à midi, et je ferai que la terre se couvrira de ténèbres en un jour de lumière.
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 Et je convertirai vos fêtes en deuil, et tous vos cantiques en lamentations; et je mettrai sur tous vos reins un cilice, et sur toutes vos têtes la calvitie; et je plongerai Israël dans le deuil, comme à la mort d’un fils unique, et ses derniers moments seront comme un jour amer.
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 Voilà que des jours viennent, dit le Seigneur, et j’enverrai la faim sur la terre, non la faim du pain, ni la soif de l’eau, mais d’entendre la parole du Seigneur.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Et ils seront dans le trouble depuis une mer jusqu’à l’autre, et depuis l’aquilon jusqu’à l’orient; ils iront de tous côtés, cherchant la parole du Seigneur, et ils ne la trouveront pas.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 En ce jour-là, les vierges dans leur beauté et les jeunes hommes défaudront par la soif.
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Ceux qui jurent par le péché de Samarie et disent: Il vit, ton Dieu, Dan! et elle vit, la voie de Bersabée! tomberont et ne se relèveront plus.
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

< Amos 8 >