< Amos 4 >

1 Ecoutez cette parole, vaches grasses qui êtes sur la montagne de Samarie, qui opprimez les indigènes et qui écrasez les pauvres, qui dites à vos maîtres: Apportez, et nous boirons.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ yìí, ẹ̀yin màlúù Baṣani lórí òkè Samaria, ẹ̀yin obìnrin tí ó ń ni tálákà lára, tí ó ń tẹ aláìní mọ́lẹ̀, tí ó wí fún ọkọ rẹ̀, “Gbé wá kí a sì mu!”
2 Le Seigneur Dieu a juré par sa sainteté, disant: Voici que des jours viendront sur vous, et on vous enlèvera avec des perches, et on jettera vos restes dans des chaudières bouillantes.
Olúwa Olódùmarè ti fi ìwà mímọ́ rẹ̀ búra: “Àkókò náà yóò dé nítòótọ́ nígbà tí a ó fi ìwọ̀ mú un yín lọ, ẹni tí ó kẹ́yìn pẹ̀lú ìwọ̀ ẹja.
3 Et vous sortirez par des ouvertures, l’une devant l’autre, et vous serez jetées en Armon, dit le Seigneur.
Ẹni kọ̀ọ̀kan yín yóò jáde lọ gba àárín odi yíya a ó sì lé e yín sí Harmoni,” ni Olúwa wí.
4 Venez à Béthel, et agissez avec impiété; allez à Galgala et multipliez vos prévarications; et amenez dès le matin vos victimes, et tous les trois jours apportez vos dîmes.
“Ẹ lọ sí Beteli láti dẹ́ṣẹ̀; ẹ lọ sí Gilgali kí ẹ sì dẹ́ṣẹ̀ sí i. Ẹ mú ẹbọ sísun yín láràárọ̀ wá, ìdámẹ́wàá yín ní ọdọọdún mẹ́ta.
5 Et offrez avec du levain des sacrifices de louange; et proclamez et annoncez des oblations volontaires; car c’est ainsi que vous l’avez voulu, fils d’Israël, dit le Seigneur Dieu.
Kí ẹ mú ọ̀rẹ́ ìdúpẹ́ ìyẹ̀fun ìwúkàrà ti a sun kí ẹ sì mú ọrẹ àtinúwá lọ fi wọ́n yangàn, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, nítorí èyí ni ẹ fẹ́ láti ṣe,” ni Olúwa Olódùmarè wí.
6 De là moi aussi, je vous ai donné un engourdissement de dents dans toutes vos villes, et un manque de pains dans tout votre pays, et vous n’êtes pas revenus à moi, dit le Seigneur.
“Èmi fún un yín ní mímọ́ eyín ní gbogbo ìlú yín, àti àìní oúnjẹ ní gbogbo ibùgbé yín, síbẹ̀, ẹ̀yin kò yípadà sọ́dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
7 Moi aussi, je vous ai refusé la pluie, lorsqu’il restait encore trois mois jusqu’à la moisson; et j’ai fait pleuvoir sur une cité, et sur une autre cité je n’ai pas fait pleuvoir; une partie n’a pas reçu de pluie, et une partie sur laquelle je n’ai pas fait pleuvoir a été desséchée.
“Àti pẹ̀lú mo mú òjò dúró nígbà tí ìkórè ku oṣù mẹ́ta. Mo rán òjò sí ibùgbé kan ṣùgbọ́n kò rọ̀ sí ìlú mìíràn. Oko kan ní òjò; àwọn mìíràn kò ní ó sì gbẹ.
8 Et deux et trois cités sont venues vers une seule cité afin d’y boire de l’eau, et elles n’ont pas été désaltérées; et vous n’êtes pas revenus à moi, dit le Seigneur.
Àwọn ènìyàn ń rìn láti ìlú kan sí ìlú mìíràn fún omi wọn kò rí mu tẹ́ wọn lọ́rùn, síbẹ̀ ẹ̀yin kò padà sí ọ̀dọ̀ mi,” ni Olúwa wí.
9 Je vous ai frappés d’un vent brûlant et de la nielle, et la chenille a dévoré la multitude de vos jardins et de vos vignes, et vos plants d’oliviers et vos plants de figuiers; et vous n’êtes pas revenus à moi, dit le Seigneur.
“Lọ́pọ̀ ìgbà ni mo kọlu ọgbà àti ọgbà àjàrà yín mo fi ìrẹ̀dànù àti ìmúwòdù lù wọ́n. Eṣú sì jẹ igi ọ̀pọ̀tọ́ àti igi olifi yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
10 J’ai envoyé contre vous la mort sur la voie de l’Egypte; j’ai frappé par le glaive vos jeunes hommes; j’ai étendu la captivité jusque sur vos chevaux; j’ai fait monter l’infection de vos camps à vos narines; et vous n’êtes pas revenus à moi, dit le Seigneur.
“Mo rán àjàkálẹ̀-ààrùn sí i yín bí mo ti ṣe sí Ejibiti. Mo fi idà pa àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín. Pẹ̀lú àwọn ẹṣin tí a kó ní ìgbèkùn. Mo kún imú yín fún òórùn ibùdó yín, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
11 Je vous ai détruits, comme le Seigneur a détruit Sodome et Gomorrhe; vous êtes devenus comme un tison arraché à un incendie; et vous n’êtes pas revenus à moi, dit le Seigneur.
“Mo ti bì ṣubú nínú yín, bí Ọlọ́run ti bi Sodomu àti Gomorra ṣubú ẹ̀yin sì dàbí ògúnná tí a fa yọ kúrò nínú iná, síbẹ̀ ẹ̀yin kò yípadà sí mi,” ni Olúwa wí.
12 C’est pourquoi je te traiterai ainsi, ô Israël; et après que je t’aurai traité ainsi, prépare-toi à aller à la rencontre de ton Dieu, ô Israël.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí i yín, Israẹli, àti nítorí tí èmi ó ṣe èyí sí i yín, ẹ múra láti pàdé Ọlọ́run yín, ẹ̀yin Israẹli.”
13 Parce que voici celui qui forme les montagnes et qui crée les vents, et qui annonce à l’homme sa parole, qui produit la nuée du matin, et qui marche sur les hauteurs de la terre; son nom est le Seigneur Dieu des armées.
Ẹni tí ó dá àwọn òkè tí ó dá afẹ́fẹ́ tí ó sì fi èrò rẹ̀ hàn sí ènìyàn, ẹni tí ó yípadà sí òkùnkùn tí ó sì tẹ ibi gíga ayé. Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.

< Amos 4 >