< Amos 3 >

1 Ecoutez la parole que le Seigneur a dite sur vous, fils d’Israël, et sur toute la famille que j’ai retirée de la terre d’Egypte.
Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀, ẹ̀yin ènìyàn Israẹli nípa àwọn ìdílé tí mo mú jáde láti Ejibiti:
2 C’est seulement vous que j’ai connus de toutes les familles de la terre; c’est pour cela que je visiterai en vous toutes vos iniquités.
“Ìwọ nìkan ni ẹni tí mo yàn nínú gbogbo àwọn ìran ayé yìí; nígbà náà èmi ó jẹ ọ́ ní yà fún gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.”
3 Est-ce que deux hommes marcheront ensemble, si cela ne leur convient pas?
Ẹni méjì ha à le rìn pọ̀ láìjẹ́ pé wọ́n ti pinnu láti ṣe bẹ?
4 Est-ce qu’un lion rugira dans la forêt, s’il n’a pas une proie? est-ce que le petit d’un lion fera entendre sa voix de sa tanière, s’il n’a rien saisi?
Ǹjẹ́ Kìnnìún yóò ha bú ramúramù nínú igbó, bí kò bá ní ohun ọdẹ? Ọmọ kìnnìún yóò ha ké jáde nínú ìhó rẹ̀ bí kò bá rí ohun kan mú?
5 Est-ce qu’un oiseau tombera dans un lacs posé sur la terre, sans qu’un oiseleur l’ait tendu? est-ce qu’on enlèvera un lacs de dessus la terre, avant qu’il ait rien pris?
Ǹjẹ́ ẹyẹ ṣubú sínú okùn ọdẹ lórí ilẹ̀ nígbà tí a kò dẹ okùn ọdẹ fún un? Okùn ọdẹ ha lè hù jáde lórí ilẹ̀ nígbà tí kò sí ohun tí yóò mú?
6 Si une trompette sonne, le peuple ne sera-t-il pas épouvanté? Y aurait-il un mal dans une cité, que le Seigneur n’aura pas fait?
Nígbà tí ìpè bá dún ní ìlú, àwọn ènìyàn kò ha bẹ̀rù? Tí ewu bá wa lórí ìlú kò ha ṣe Olúwa ni ó fà á?
7 Car le Seigneur Dieu n’a rien fait, s’il n’a auparavant révélé son secret à ses serviteurs les prophètes.
Nítòótọ́ Olúwa Olódùmarè kò ṣe ohun kan láìfi èrò rẹ̀ hàn fun àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
8 Un lion rugira, qui ne craindra? le Seigneur Dieu a parlé, qui ne prophétisera?
Kìnnìún ti bú ramúramù ta ni kì yóò bẹ̀rù? Olúwa Olódùmarè ti sọ̀rọ̀ ta ni le ṣe àìsọ àsọtẹ́lẹ̀?
9 Faites-le entendre sur les édifices d’Azot et sur les édifices de la terre d’Egypte, et dites: Assemblez-vous sur les montagnes de Samarie, voyez des folies nombreuses au milieu d’elle, et ceux qui souffrent l’oppression dans son enceinte.
Ẹ kéde ní ààfin Aṣdodu àti ní ààfin ní ilẹ̀ Ejibiti. “Ẹ kó ara yín jọ sí orí òkè ńlá Samaria; kí ẹ sì wo ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ńlá láàrín rẹ̀ àti ìnilára láàrín àwọn ènìyàn rẹ.”
10 Et ils n’ont pas su faire le bien, dit le Seigneur, thésaurisant l’iniquité et la rapine dans leurs maisons.
“Wọn kò mọ bí wọ́n ṣe ń ṣe rere,” ni Olúwa wí, “àwọn ẹni tí ó gba àwọn ìwà ipá àti olè sí ààfin rẹ̀.”
11 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: La terre sera pressurée et cernée; et ta force te sera ôtée, et tes édifices seront pillés.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: “Àwọn ọ̀tá yóò pa ilẹ̀ náà run; yóò wó ibi gíga yín palẹ̀ a ó sì ba ààfin rẹ̀ jẹ́.”
12 Voici ce que dit le Seigneur: Comme si le pasteur arrachait de la gueule du lion deux jambes ou un bout d’oreille, ainsi seront arrachés des mains de l’ennemi les fils d’Israël qui habitent dans Samarie sur le coin d’un petit lit et sur un grabat de Damas.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Bí olùṣọ́-àgùntàn ti ń gbà itan méjì kúrò ní ẹnu kìnnìún tàbí ẹ̀là etí kan bẹ́ẹ̀ ni a ó mú àwọn ọmọ Israẹli, tí ń gbé Samaria kúrò ní igun ibùsùn wọn ní orí àga ìrọ̀gbọ̀kú wọn ní Damasku.”
13 Ecoutez, et déclarez à la maison de Jacob, dit le Seigneur Dieu des armées,
“Gbọ́ èyí kí o sì jẹ́rìí nípa ilé Jakọbu,” ni Olúwa wí, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun.
14 Disant: Au jour où je commencerai à visiter les prévarications d’Israël, et les autels de Béthel, alors seront arrachées les cornes de l’autel et elles tomberont par terre.
“Ní ọjọ́ tí mo fìyà jẹ Israẹli lórí ẹ̀ṣẹ̀ wọn, Èmi yóò pa pẹpẹ Beteli run; ìwo pẹpẹ ni a ó ké kúrò yóò sì wó lulẹ̀.
15 Et je frapperai la maison d’hiver avec la maison d’été, et les maisons d’ivoire périront, et des édifices nombreux seront détruits, dit le Seigneur.
Èmi yóò wó ilé òtútù lulẹ̀ pẹ̀lú ilé ooru; ilé tí a fi eyín erin ṣe lọ́ṣọ̀ọ́ yóò ṣègbé a ó sì pa ilé ńlá náà run,” ni Olúwa wí.

< Amos 3 >