< 2 Samuel 21 >

1 Il y eut aussi une famine, dans les jours de David, pendant trois ans continuels: et David consulta l’oracle du Seigneur. Et le Seigneur dit: C’est à cause de Saül et de sa maison de sang, parce qu’il a tué les Gabaonites.
Ìyàn kan sì mú lọ́jọ́ Dafidi ní ọdún mẹ́ta, láti ọdún dé ọdún; Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa sì wí pé, “Nítorí ti Saulu ni, àti nítorí ilé rẹ̀ tí ó kún fún ẹ̀jẹ̀, nítorí pé ó pa àwọn ará Gibeoni.”
2 Les Gabaonites donc appelés, le roi leur dit (or, les Gabaonites n’étaient point des enfants d’Israël, mais les restes des Amorrhéens; car les enfants d’Israël leur avaient fait serment, et Saül voulut les frapper par zèle, comme pour les enfants d’Israël et de Juda);
Ọba sì pe àwọn ará Gibeoni, ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; àwọn ará Gibeoni kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Israẹli, ṣùgbọ́n wọ́n jẹ́ àwọn tí ó kù nínú àwọn ọmọ Amori; àwọn ọmọ Israẹli sì ti búra fún wọn, Saulu sì ń wá ọ̀nà àti pa wọ́n ní ìtara rẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli àti Juda.
3 David donc dit aux Gabaonites: Que ferai-je pour vous, et quelle sera la réparation envers vous, afin que vous bénissiez l’héritage du Seigneur?
Dafidi sì bi àwọn ará Gibeoni léèrè pé, “Kí ni èmi ó ṣe fún un yín? Àti kín ni èmi ó fi ṣe ètùtù, kí ẹ̀yin lè súre fún ilẹ̀ ìní Olúwa?”
4 Et les Gabaonites lui répondirent: Ce n’est pas pour nous une question d’argent et d’or, mais une question contre Saül et contre sa maison; et nous ne voulons pas qu’aucun homme d’Israël soit tué. Le roi leur dit: Que voulez-vous donc que je fasse pour vous?
Àwọn ará Gibeoni sì wí fún un pé, “Kì í ṣe ọ̀rọ̀ fàdákà tàbí wúrà láàrín wa àti Saulu tàbí ìdílé rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni a kò sì fẹ́ kí ẹ pa ẹnìkan ní Israẹli.” Dafidi sì wí pé, “Èyí tí ẹ̀yin bá wí ni èmi ó ṣe?”
5 Ils dirent au roi: Nous devons tellement exterminer l’homme qui nous a brisés et opprimés injustement, qu’il ne reste pas même un seul de sa race dans tous les confins d’Israël.
Wọ́n sì wí fún ọba pé, “Ọkùnrin tí ó run wá, tí ó sì rò láti pa wá rẹ́ ki a má kù níbikíbi nínú gbogbo agbègbè Israẹli.
6 Que sept hommes de ses fils nous soient donnés, afin que nous les crucifiions au Seigneur à Gabaa de Saül, autrefois l’élu du Seigneur. Et le roi dit: Oui, je vous les donnerai.
Mú ọkùnrin méje nínú àwọn ọmọ rẹ̀ fún wá, àwa ó sì so wọ́n rọ̀ fún Olúwa ní Gibeah ti Saulu ẹni tí Olúwa ti yàn.” Ọba sì wí pé, “Èmi ó fi wọ́n fún yín.”
7 Et le roi épargna Miphiboseth, fils de Jonathas, fils de Saül, à cause du serment du Seigneur qui avait été fait entre David et Jonathas, fils de Saül.
Ṣùgbọ́n ọba dá Mefiboṣeti sí, ọmọ Jonatani, ọmọ Saulu, nítorí ìbúra Olúwa tí ó wà láàrín Dafidi àti Jonatani ọmọ Saulu.
8 C’est pourquoi le roi prit les deux fils de Respha, fille d’Aïa, qu’elle avait enfantés à Saül, Armoni et Miphiboseth, et les cinq fils de Michol, fille de Saül, qu’elle avait engendrés à Hadriel, fils de Berzellaï, lequel était de Molath;
Ọba sì mú àwọn ọmọkùnrin méjèèjì tí Rispa ọmọbìnrin Aiah bí fún Saulu, àní Ammoni àti Mefiboṣeti àwọn ọmọkùnrin márààrún ti Merabu, ọmọbìnrin Saulu, àwọn tí ó bí fún Adrieli ọmọ Barsillai ará Mehola.
9 Et il les livra aux mains des Gabaonites, qui les crucifièrent sur la montagne, devant le Seigneur; et ces sept hommes tombèrent morts ensemble dans les premiers jours de la moisson, la moisson de l’orge commençant.
Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Gibeah lọ́wọ́, wọ́n sì so wọ́n rọ̀ lórí òkè níwájú Olúwa: àwọn méjèèjì sì ṣubú lẹ́ẹ̀kan, a sì pa wọ́n ní ìgbà ìkórè, ní ìbẹ̀rẹ̀, ìkórè ọkà barle.
10 Or, Respha, fille d’Aïa, prenant son cilice, l’étendit sous elle sur le rocher, depuis le commencement de la moisson jusqu’à ce que l’eau du ciel tombât sur eux; et elle ne laissa pas les oiseaux les déchirer pendant le jour, ni les bêtes sauvages pendant la nuit.
Rispa ọmọbìnrin Aiah sì mú aṣọ ọ̀fọ̀ kan, ó sì tẹ́ fún ará rẹ̀ lórí àpáta ní ìbẹ̀rẹ̀ ìkórè, títí omi fi dà sí wọn lára láti ọ̀run wá, kò sì jẹ́ kí àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run bà lé wọn lọ́sàn, tàbí àwọn ẹranko igbó lóru.
11 Et l’on annonça à David ce que Respha, fille d’Aïa, femme du second rang de Saül, avait fait.
A sì ro èyí, tí Rispa ọmọbìnrin Aiah obìnrin Saulu ṣe, fún Dafidi.
12 Et David s’en alla, et prit les os de Saül et de Jonathas, son fils, chez les hommes de Jabès-Galaad, qui les avaient enlevés furtivement de la place de Bethsan, où les Philistins les avaient suspendus, lorsqu’on eut tué Saül à Gelboé;
Dafidi sì lọ ó sì kó egungun Saulu, àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin Jabesi Gileadi, àwọn tí ó jí wọn kúrò ní ìta Beti-Ṣani, níbi tí àwọn Filistini gbé so wọ́n rọ̀, nígbà tí àwọn Filistini pa Saulu ní Gilboa.
13 Et il apporta de là les os de Saül et les os de Jonathas, son fils; et, recueillant les os de ceux qui avaient été attachés à une croix,
Ó sì mú egungun Saulu àti egungun Jonatani ọmọ rẹ̀ láti ibẹ̀ náà wá; wọ́n sì kó egungun àwọn tí a ti so rọ̀ jọ.
14 On les ensevelit avec les os de Saül et de Jonathas, son fils, dans la terre de Benjamin, sur un côté, dans le sépulcre de Cis, son père; et on fit tout ce que le roi avait ordonné; et Dieu redevint propice à la terre après cela.
Wọ́n sì sin egungun Saulu àti ti Jonatani ọmọ rẹ̀ ní ilé Benjamini, ní Ṣela, nínú ibojì Kiṣi baba rẹ̀, wọ́n sì ṣe gbogbo èyí tí ọba paláṣẹ, lẹ́yìn èyí ni Ọlọ́run si gba ẹ̀bẹ̀ nítorí ilẹ̀ náà.
15 Or il se fit de nouveau une guerre des Philistins contre Israël, et David descendit et ses serviteurs avec lui, et ils combattirent contre les Philistins. Or, David défaillant,
Ogun sì tún wà láàrín àwọn Filistini àti Israẹli; Dafidi sì sọ̀kalẹ̀, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, ó sì bá àwọn Filistini jà, ó sì rẹ Dafidi.
16 Jesbibénob, qui était de la race d’Arapha, dont le fer de la hache pesait trois cents onces, et qui était ceint d’un glaive neuf, s’efforça de frapper David.
Iṣbi-Benobu sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn Rafa, ẹni tí ọ̀kọ̀ rẹ̀ wọn ọ̀ọ́dúnrún ṣékélì idẹ, ó sì sán idà tuntun, ó sì gbèrò láti pa Dafidi.
17 Mais Abisaï, fils de Sarvia, le défendit, et ayant frappé le Philistin, le tua. Alors les serviteurs de David jurèrent, disant: Maintenant vous ne sortirez plus avec nous à la guerre, afin que vous n’éteigniez pas la lampe d’Israël.
Ṣùgbọ́n Abiṣai ọmọ Seruiah ràn án lọ́wọ́, ó sì kọlu Filistini náà, ó sì pa á. Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì búra fún un pé, “Ìwọ kì yóò sì tún bá wa jáde lọ sí ibi ìjà mọ́ kí ìwọ má ṣe pa iná Israẹli.”
18 Et la seconde guerre fut à Gob, contre les Philistins; alors Sobochaï de Husati tua Saph, de la descendance d’Arapha, de la race des géants.
Lẹ́yìn èyí, ìjà kan sì tún wà láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini ní Gobu, nígbà náà ni Sibekai ará Huṣati pa Safu, ẹni tí í ṣe ọ̀kan nínú àwọn Rafa.
19 La troisième guerre fut aussi à Gob, contre les Philistins, en laquelle Adéodatus, fils de Saltus, tisseur en diverses couleurs, Bethléhémite, tua Goliath, le Géthéen, dont la hampe de la lance était comme un ensouple de tisserands.
Ìjà kan sì tún wà ní Gobu láàrín àwọn Israẹli àti àwọn Filistini, Elhanani ọmọ Jairi ará Bẹtilẹhẹmu sì pa arákùnrin Goliati ará Gitti, ẹni tí ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ dàbí ìdábùú apásá ìhunṣọ.
20 Une quatrième guerre fut à Geth, en laquelle était un homme très grand, qui avait six doigts en ses mains et en ses pieds, c’est-à-dire vingt-quatre et il tirait son origine d’Arapha.
Ìjà kan sì tún wà ní Gati, ọkùnrin kan sì wà tí ó ga púpọ̀, ó sì ní ìka mẹ́fà ní ọwọ́ kan, àti ọmọ ẹsẹ̀ mẹ́fà ní ẹsẹ̀ kan, àpapọ̀ rẹ̀ sì jẹ́ mẹ́rìnlélógún; a sì bí òun náà ní Rafa.
21 Et il blasphéma Israël; mais Jonathan, fils de Samaa, le frère de David, le tua.
Nígbà tí òun sì pe Israẹli ní ìjà. Jonatani ọmọ Ṣimea arákùnrin Dafidi sì pa á.
22 Ces quatre hommes étaient nés d’Arapha, à Geth, et ils tombèrent sous la main de David et de ses serviteurs.
Àwọn mẹ́rẹ̀ẹ̀rin wọ̀nyí ni ìran Rafa ní Gati, wọ́n sì ti ọwọ́ Dafidi ṣubú àti ọwọ́ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.

< 2 Samuel 21 >