< 2 Rois 4 >

1 Or une certaine femme d’entre les femmes des prophètes criait à Élisée, disant: Ton serviteur, mon mari, est mort; et toi, tu sais que ton serviteur fut craignant le Seigneur: et voilà qu’un créancier vient, afin de prendre mes deux fils pour le servir.
Ìyàwó ọkùnrin kan láti ara ẹgbẹ́ wòlíì sọkún tọ Eliṣa wá, “Ìránṣẹ́ rẹ ọkọ mi ti kú, ó sì mọ̀ wí pé ó bu ọlá fún Olúwa. Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, onígbèsè rẹ̀ ti ń bọ̀ láti wá kó ọmọ ọkùnrin mi gẹ́gẹ́ bí ẹrú rẹ̀.”
2 Élisée lui dit: Que veux-tu que je fasse pour toi? Dis-moi, qu’as-tu dans ta maison? Et elle répondit: Je n’ai, moi ta servante, dans ma maison qu’un peu d’huile dont je m’oins.
Eliṣa dá a lóhùn pé, “Báwo ni èmi ṣe lè ràn ọ́ lọ́wọ́? Sọ fún mi; kí ni ìwọ ní ní ilé rẹ?” Ó wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ kò ní ohunkóhun níbẹ̀ rárá, àyàfi òróró kékeré.”
3 Il lui dit: Va, emprunte de tes voisines un grand nombre de vases vides,
Eliṣa wí pé, “Lọ yíká kí o sì béèrè lọ́wọ́ gbogbo àwọn aládùúgbò fún ìkòkò òfìfo. Má ṣe béèrè fún kékeré.
4 Puis rentre, et ferme ta porte, lorsque tu seras dedans, toi et tes fils; verse de cette huile dans tous ces vases; et quand ils seront pleins, tu les emporteras.
Nígbà náà, lọ sí inú ilé kí o sì pa lẹ́kun dé ní ẹ̀gbẹ́ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin, dà òróró sínú gbogbo ìkòkò, gẹ́gẹ́ bí gbogbo rẹ̀ ti kún, kó o sí apá kan.”
5 C’est pourquoi cette femme s’en alla et ferma la porte sur elle et sur ses fils; ceux-ci lui présentaient les vases, et elle y versait l’huile.
Ó sì fi sílẹ̀ lẹ́yìn náà ó ti ìlẹ̀kùn ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀. Wọ́n gbé ìkòkò wá fún un ó sì ń dà á.
6 Et lorsque les vases furent pleins, elle dit à son fils: Apporte-moi encore un vase. Et il lui répondit: Je n’en ai point. Et l’huile s’arrêta.
Nígbà tí gbogbo ìkòkò náà kún, ó sọ fún ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ gbé òmíràn fún mi wá.” Ṣùgbọ́n wọ́n dáhùn pé, “Kò sí ìkòkò tí ó kù mọ́.” Nígbà náà ni òróró kò dà mọ́.
7 Or cette femme vint et raconta tout à l’homme de Dieu. Et lui: Va, dit-il, vends l’huile, et rends à ton créancier ce qui lui est dû; mais toi et tes fils, vivez avec le reste.
Ó sì lọ ó sì lọ sọ fún àwọn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì wí pé, “Lọ, ta òróró náà kí o sì san gbèsè rẹ. Ìwọ àti ọmọ rẹ kí ẹ máa sinmi lórí èyí tí ó kù.”
8 Or un certain jour arriva, et Élisée passait par Sunam: or il y avait là une femme considérable, laquelle le retint pour qu’il mangeât du pain; et comme il passait souvent par là, il allait loger chez elle pour manger du pain.
Ní ọjọ́ kan Eliṣa lọ sí Ṣunemu. Obìnrin ọlọ́rọ̀ kan sì wà níbẹ̀, ẹni tí ó rọ̀ ọ́ kí ó dúró jẹun. Bẹ́ẹ̀ ni nígbàkígbà tí ó bá ń kọjá lọ, ó máa ń dúró níbẹ̀ láti jẹun.
9 Cette femme dit à son mari: Je m’aperçois que c’est un saint, cet homme de Dieu qui passe par chez nous fréquemment.
Ó sọ fún ọkọ rẹ̀, “Mo mọ̀ pé ọkùnrin tí ó máa ń sábà wá sí ọ̀dọ̀ wa jẹ́ ọkùnrin mímọ́ Ọlọ́run.
10 Faisons-lui donc une petite chambre, et mettons-y un lit, une table, un siège et un chandelier, afin que, lorsqu’il viendra chez nous, il demeure là.
Jẹ́ kí a ṣe yàrá kékeré kan sórí ilé kí a sì gbé ibùsùn àti tábìlì oúnjẹ, àga kan àti fìtílà fún un. Nígbà náà ó lè dúró níbẹ̀ ní ìgbàkúgbà tí ó bá wá sọ́dọ̀ wa.”
11 Un certain jour arriva donc, et Élisée venant, alla loger en cette chambre et s’y reposa.
Ní ọjọ́ kan nígbà tí Eliṣa wá, ó lọ sí orí òkè ní yàrá rẹ̀ ó sì dùbúlẹ̀ síbẹ̀.
12 Et il dit à Giézi, son serviteur: Appelle cette Sunamite, Lorsque Giézi l’eut appelée, et qu’elle se tenait devant lui,
Ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi pé, “Pe ará Ṣunemu.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é wá, ó sì dúró níwájú rẹ̀.
13 Il dit à son serviteur: Dis-lui: Voilà que tu nous as servis soigneusement; que veux-tu que je fasse pour toi? As-tu quelque affaire, et veux-tu que je parle au roi ou au prince de la milice? Elle lui répondit: J’habite au milieu de mon peuple.
Eliṣa wí fún un pé, “Wí fún un, ‘Ìwọ ti lọ ṣe gbogbo àníyàn iṣẹ́ ìyìnrere fún wa. Nísinsin yìí kí ni a lè ṣe fún ọ?’” “Ṣé a lè jẹ́ agbẹnusọ fún ọ ní ọ̀dọ̀ ọba tàbí olórí ogun?”
14 Il dit encore: Que veut-elle donc que je fasse pour elle? Et Giézi répondit: Ne cherchez pas; car elle n’a point de fils, et son mari est vieux.
“Kí ni a lè ṣe fún obìnrin yìí?” Eliṣa béèrè. Gehasi wí pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, kò ní ọmọ, ọkọ rẹ̀ náà sì tún di arúgbó.”
15 C’est pourquoi il ordonna de l’appeler; et lorsqu’elle eut été appelée, et qu’elle se tenait devant la porte,
Nígbà náà Eliṣa wí pé, “Pè é,” bẹ́ẹ̀ ni ó sì pè é, ó sì dúró ní àbáwọlé ẹnu-ọ̀nà.
16 Il lui dit: Dans ce temps et à cette même heure, si tu vis encore, tu auras en ton sein un fils. Mais elle répondit: Non, je te prie, mon seigneur, homme de Dieu, non, ne mens pas à ta servante.
Eliṣa sọ wí pé, “Ìwòyí ọdún tí ń bọ̀, ìwọ yóò fi ọwọ́ rẹ gbé ọmọ.” “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa mi!” n kò fi ara mọ́ ọn. “Jọ̀wọ́, ìwọ ènìyàn Ọlọ́run, ma ṣe ṣi ìránṣẹ́ rẹ lọ́nà!”
17 Et cette femme conçut, et elle enfanta un fils dans le temps et à la même heure qu’Élisée avait dit.
Ṣùgbọ́n obìnrin náà lóyún ní ọdún kejì ní àkókò náà, ó bí ọmọ ọkùnrin kan, gẹ́gẹ́ bí Eliṣa ti sọ fún un.
18 Or l’enfant grandit; et comme il arriva un certain jour qu’il était sorti vers son père, vers les moissonneurs,
Ọmọ náà dàgbà, ní ọjọ́ kan, ó jáde lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀, ó wà pẹ̀lú àwọn olùkórè.
19 Il dit à son père: J’ai mal à la tête, j’ai mal à la tête. Celui-ci dit à son serviteur: Prends cet enfant, et conduis-le à sa mère.
“Orí mi! Orí mi!” Ó wí fún baba rẹ̀. Baba rẹ̀ sọ fún ìránṣẹ́, “Gbé e lọ sọ́dọ̀ ìyá rẹ̀.”
20 Lorsque le serviteur l’eut pris et l’eut conduit à sa mère, celle-ci le mit sur ses genoux jusqu’à midi, et il mourut.
Lẹ́yìn ìgbà tí ìránṣẹ́ náà ti gbé e sókè tí ó sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ, ọmọ ọkùnrin náà jókòó sórí ẹsẹ̀ rẹ̀ títí ó fi di ọ̀sán gangan, nígbà náà ó sì kú.
21 Or elle monta et le plaça sur le lit de l’homme de Dieu, et elle ferma la porte; et, étant sortie,
Ó lọ sí òkè ó sì tẹ́ ọmọ náà lórí ibùsùn ènìyàn Ọlọ́run, ó sì tìlẹ̀kùn, ó jáde lọ.
22 Elle appela son mari, et dit: Envoie avec moi, je te conjure, un de tes serviteurs et une ânesse, pour que je coure jusqu’à l’homme de Dieu, et je reviendrai.
Ó pe ọkọ rẹ̀ ó sì wí pé, “Jọ̀wọ́ rán ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ rẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kan kí èmi kí ó lè lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run kíákíá kí n sì padà.”
23 Son mari lui demanda: Pour quel motif vas-tu vers lui? Aujourd’hui ce ne sont point des calendes ni un sabbat. Elle répondit: J’irai.
“Kí ni ó dé tí o fi fẹ́ lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ lónìí?” Ó béèrè. “Kì í ṣe oṣù tuntun tàbí ọjọ́ ìsinmi.” Ó wí pé, “Gbogbo rẹ̀ ti dára.”
24 Et elle sella l’ânesse, et ordonna à son serviteur: Conduis, et hâte-toi, ne me retarde point en allant, et fais ce que je t’ordonne.
Ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ní gàárì ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Máa nìṣó; má ṣe dẹ́sẹ̀ dúró dè mí àyàfi tí mo bá sọ fún ọ.”
25 Elle partit donc, et vint vers l’homme de Dieu sur la montagne du Carmel; et lorsque l’homme de Dieu l’eut vue en face de lui, il dit à Giézi son serviteur: Voilà cette Sunamite.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì jáde wá, ó sì wá sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè Karmeli. Nígbà tí ó sì rí i láti òkèrè, ènìyàn Ọlọ́run sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Gehasi, “Wò ó! Ará Ṣunemu nì!
26 Va donc à sa rencontre, et dis-lui: Tout va-t-il bien pour vous, pour votre mari et pour votre fils? Elle répondit: Bien.
Sáré lọ pàdé rẹ̀ kí o sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀, ‘Ṣé o wà dáradára? Ṣé ọkọ rẹ wà dáradára? Ṣé ọmọ rẹ wà dáradára?’” Ó wí pé, “Gbogbo nǹkan wà dáradára.”
27 Et, lorsqu’elle fut venue vers l’homme de Dieu sur la montagne, elle saisit ses pieds, et Giézi s’approcha pour l’écarter. Mais l’homme de Dieu dit: Laissez-la: car son âme est dans l’amertume, et le Seigneur me l’a caché et ne me l’a point fait connaître.
Nígbà tí ó dé ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run ní orí òkè, ó gbá a ní ẹsẹ̀ mú. Gehasi wá láti wá lé e dànù, ṣùgbọ́n ènìyàn Ọlọ́run wí pé, “Fi í sílẹ̀! Ó wà nínú ìpọ́njú kíkorò, ṣùgbọ́n Olúwa fi pamọ́ fún mi kò sì sọ ìdí rẹ̀ fún mi.”
28 Cette femme lui dit: Ai-je demandé un fils à mon seigneur? Ne t’ai-je pas dit: Ne me trompe point?
“Ṣé mo béèrè ọmọ lọ́wọ́ rẹ, olúwa mi?” Obìnrin náà wí pé, “Ṣé mi ò sọ fún ọ pé kí o, ‘Má ṣe fa ìrètí mi sókè’?”
29 Élisée dit à Giézi: Ceins tes reins, et prends mon bâton en ta main, et va. Si un homme te rencontre, ne le salue point; et si quelqu’un te salue, ne lui réponds point, et mets mon bâton sur la face de l’enfant.
Eliṣa wí fún Gehasi pé, “Ká agbádá rẹ sínú ọ̀já àmùrè, mú ọ̀pá mi sí ọwọ́ rẹ kí o sì sáré. Tí o bá pàdé ẹnikẹ́ni má ṣe kí i, tí ẹnikẹ́ni bá kí ọ, má ṣe dá a lóhùn, fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ ọkùnrin náà.”
30 Or la mère de l’enfant dit: Le Seigneur vit et ton âme vit! Je ne te quitterai point. Il se leva donc et la suivit.
Ṣùgbọ́n ìyá ọmọ náà wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ó ti wà láààyè, èmi kò ní í fi ọ́ sílẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ó sì dìde ó sì tẹ̀lé e.
31 Or Giézi était allé devant eux, et il avait mis le bâton d’Élisée sur la face de l’enfant; mais il n’y avait en lui ni parole ni sentiment. Aussi il retourna à la rencontre de son maître, et il le lui annonça, disant: L’enfant ne s’est pas levé.
Gehasi sì ń lọ síbẹ̀ ó sì fi ọ̀pá náà lé ojú ọmọ náà, ṣùgbọ́n kò sí ohùn tàbí ìdáhùn. Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi padà lọ láti lọ bá Eliṣa láti sọ fún un pé, “Ọmọ ọkùnrin náà kò tí ì dìde.”
32 Élisée entra donc dans la maison, et voilà que l’enfant mort gisait sur son lit.
Nígbà tí Eliṣa dé inú ilé, níbẹ̀ ni òkú ọmọ ọkùnrin náà dùbúlẹ̀ lórí ibùsùn.
33 Et étant entré, il ferma la porte sur lui et sur l’enfant, et adressa des prières au Seigneur.
Ó sì wọ ilé, ó sì ti ìlẹ̀kùn mọ́ àwọn méjèèjì ó sì gbàdúrà sí Olúwa.
34 Puis il monta sur le lit et se coucha sur l’enfant; et il mit sa bouche sur sa bouche, ses yeux sur ses yeux, et ses mains sur ses mains; et il se courba sur lui, et la chair de l’enfant fut échauffée.
Nígbà náà ó dé orí ibùsùn, ó sùn sórí ọmọ ọkùnrin náà, ẹnu sí ẹnu, ojú sí ojú, ọwọ́ sí ọwọ́. Gẹ́gẹ́ bí ó ti nà ara rẹ̀ lórí rẹ̀, ara ọmọ náà sì gbóná.
35 Or étant revenu du lit, il se promena dans la maison une fois ici et une fois là, et il monta et se coucha sur l’enfant; et l’enfant bâilla sept fois et il ouvrit les yeux.
Eliṣa yípadà lọ, ó sì rìn padà ó sì jáde wá sínú ilé nígbà náà ó sì padà sí orí ibùsùn ó sì tún nà lé e ní ẹ̀ẹ̀kan sí i. Ọmọ ọkùnrin náà sì sín ní ìgbà méje ó sì ṣí ojú rẹ̀.
36 Cependant Élisée appela Giézi, et lui dit: Appelle cette Sunamite. Elle ayant été appelée, entra auprès d’Élisée, et Élisée dit: Emmène ton fils.
Eliṣa sì pe Gehasi ó sì wí pé, “Pe ará Ṣunemu.” Ó sì ṣe bẹ́ẹ̀. Nígbà tí ó dé, ó wí pé, “Gba ọmọ rẹ.”
37 Cette femme vint, et se jeta à ses pieds, et se prosterna jusqu’à terre; et elle prit son fils et sortit.
Ó sì wọlé, ó sì kúnlẹ̀ síwájú ẹsẹ̀ rẹ̀ ó sì tẹ̀ orí sílẹ̀. Nígbà náà ó sì mú ọmọ rẹ̀ ó sì jáde lọ.
38 Et Élisée retourna à Galgala. Or la famine était sur la terre, et les fils des prophètes habitaient auprès de lui; il dit donc à l’un de ses serviteurs: Prends la grande marmite, et fait cuire un mets pour les fils des prophètes.
Eliṣa padà sí Gilgali ìyàn sì wà ní ilẹ̀ náà. Nígbà tí àwọn ọmọ wòlíì ṣe ìpàdé pẹ̀lú rẹ̀, ó sì wí fún ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Gbé ìkòkò ńlá ka iná kí o sì se ọbẹ̀ aláta díẹ̀ fún àwọn ọkùnrin yìí.”
39 Et l’un d’eux sortit dans la campagne pour cueillir des herbes des champs; et il trouva comme une vigne sauvage, et il en cueillit des coloquintes sauvages, et il remplit son manteau; et, étant revenu, il les coupa par morceaux dans la marmite pour le mets; car il ne savait ce que c’était.
Ọ̀kan lára wọn jáde lọ sí orí pápá láti kó ewébẹ̀ jọ àti láti wá àjàrà igbó. Ó sì kó díẹ̀ nínú ẹ̀fọ́ gbọ̀rọ̀ rẹ̀ jọ, ó sì ka a kún aṣọ agbádá rẹ̀. Nígbà tí ó padà dé, ó sì gé wọn sínú ìkòkò ọbẹ̀, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé kò sí ẹni tí ó mọ ohun tí wọ́n ń jẹ.
40 Il les versa ensuite de la marmite pour les serviteurs d’Élisée; mais lorsqu’ils eurent goûté de ce mets, ils crièrent, disant: La mort est dans la marmite, homme de Dieu. Et ils ne purent manger.
Wọ́n da ọbẹ̀ náà jáde fun àwọn ọkùnrin náà, ṣùgbọ́n bí wọ́n ti bẹ̀rẹ̀ sí ní jẹ oúnjẹ náà, wọ́n sọkún jáde, “Ìwọ ènìyàn Ọlọ́run ikú ń bẹ nínú ìkòkò yìí!” Wọn kò sì le jẹ ẹ́.
41 Mais Élisée: Apportez, dit-il, de la farine. Et lorsqu’ils en eurent apporté, il la mit dans la marmite, et dit: Versez-en pour la troupe, afin qu’ils en mangent. Et il n’y eut plus aucune amertume dans la marmite.
Eliṣa sì wí pé, “Mú ìyẹ̀fun díẹ̀ wá,” Ó sì fi sínú ìkòkò ó sì wí pé, “Kí ó sì fi fún àwọn ènìyàn láti jẹ.” Kò sì sí ohun tí ó léwu nínú ìkòkò náà.
42 Or un certain homme vint de Baalsalisa, portant à l’homme de Dieu des pains des prémices, vingt pains d’orge et du blé nouveau dans sa besace. Élisée dit à son serviteur: Donne au peuple, afin qu’il mange.
Ọkùnrin kan wá láti Baali-Ṣaliṣa, ó sì mú àkàrà àkọ́so èso, ogún ìṣù àkàrà barle, tí wọ́n dín láti ara àkọ́so èso àgbàdo, àti pẹ̀lú síírí ọkà tuntun nínú àpò rẹ̀ wá fún ènìyàn Ọlọ́run náà. Òun sì wí pé, “Fún àwọn ènìyàn láti jẹ.”
43 Et son serviteur lui répondit: Qu’est-ce que cela pour que je le serve à cent hommes? Élisée dit de nouveau: Donne au peuple, afin qu’il mange; car voici ce que dit le Seigneur: Ils mangeront, et il en restera.
“Báwo ni èmi yóò ṣe gbé èyí ka iwájú àwọn ọgọ́rùn-ún ènìyàn?” ìránṣẹ́ rẹ̀ béèrè. Ṣùgbọ́n Eliṣa dá a lóhùn pé, “Gbé e fún àwọn ènìyàn láti jẹ, nítorí èyí ni ohun tí Olúwa sọ: ‘Wọn yóò jẹ yóò sì tún ṣẹ́kù.’”
44 Il mit donc les pains devant eux, et ils mangèrent, et il en resta, selon la parole du Seigneur.
Nígbà náà ó gbé e ka iwájú wọn, wọ́n sì jẹ ẹ́, wọ́n sì ní èyí tó ṣẹ́kù, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.

< 2 Rois 4 >