< 2 Rois 3 >

1 Or, Joram, fils d’Achab, régna sur Israël dans Samarie, la dix-huitième année de Josaphat, roi de Juda; et il régna douze ans.
Jehoramu ọmọ Ahabu sì di ọba Israẹli ní Samaria ní ọdún kejìdínlógún ti Jehoṣafati ọba Juda, ó sì jẹ ọba fún ọdún méjìlá.
2 Et il fit le mal devant le Seigneur, mais non comme son père et sa mère, car il détruisit les statues de Baal qu’avait faites son père.
Ó sì ṣe búburú níwájú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí ti ìyá àti baba rẹ̀ ti ṣe. Ó gbé òkúta ère ti Baali tí baba rẹ̀ ti ṣe kúrò.
3 Cependant il resta attaché aux péchés de Jéroboam, fils de Nabath, qui avait fait pécher Israël, et il ne s’en éloigna point.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ó fi ara mọ́ ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu ọmọ Nebati, tí ó ti fi Israẹli bú láti dẹ́ṣẹ̀; kò sì yí kúrò lọ́dọ̀ wọn.
4 Or Mésa, roi de Moab, nourrissait des troupeaux nombreux, et payait au roi d’Israël cent mille agneaux et cent mille béliers avec leurs toisons.
Nísinsin yìí Meṣa ọba Moabu ń sin àgùntàn, ó sì gbọdọ̀ fi fún ọba Israẹli pẹ̀lú ọ̀kẹ́ márùn-ún ọ̀dọ́-àgùntàn àti pẹ̀lú irun ọ̀kẹ́ márùn-ún àgbò.
5 Mais, lorsqu’Achab fut mort, il rompit le traité qu’il avait fait avec le roi d’Israël.
Ṣùgbọ́n lẹ́yìn ikú Ahabu, ọba Moabu ṣọ̀tẹ̀ lórí ọba Israẹli.
6 Le roi Joram sortit donc en ce jour-là de Samarie, et il recensa tout Israël.
Lásìkò ìgbà yìí ọba Jehoramu jáde kúrò ní Samaria ó sì yí gbogbo Israẹli ní ipò padà.
7 Et il envoya à Josaphat, roi de Juda, disant: Le roi de Moab s’est retiré de moi; venez avec moi pour combattre contre lui. Josaphat répondit: Je monterai: qui est à moi est à vous; mon peuple est votre peuple, et mes chevaux, vos chevaux.
Ó sì ránṣẹ́ yìí sí Jehoṣafati ọba Juda pé, “Ọba Moabu sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi. Ṣé ìwọ yóò lọ pẹ̀lú mi láti lọ bá Moabu jà?” Ọba Juda sì dáhùn pé, “Èmi yóò lọ pẹ̀lú rẹ. Èmi jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà, ènìyàn rẹ bí ènìyàn mi, ẹṣin mi bí ẹṣin rẹ.”
8 il ajouta: Par quel chemin monterons-nous? Et Joram répondit: Par le désert d’Idumée.
“Nípa ọ̀nà wo ni àwa yóò gbà dojúkọ wọ́n?” Ó béèrè. “Lọ́nà aginjù Edomu,” ó dáhùn.
9 Le roi d’Israël et le roi de Juda et le roi d’Edom marchèrent donc, et ils firent des circuits dans le chemin durant sept jours: et il n’y avait point d’eau pour l’armée, et pour les bêtes qui les suivaient.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli jáde lọ pẹ̀lú ọba Juda àti ọba Edomu. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n yíká fún ọjọ́ méje. Àwọn ọmọ-ogun wọn kò ní omi púpọ̀ fún ara wọn tàbí fún ẹranko tí ó wà pẹ̀lú wọn.
10 Alors le roi d’Israël dit: Hélas! hélas! hélas! le Seigneur nous a assemblés, trois rois, pour nous livrer entre les mains de Moab.
“Kí ni?” ọba Israẹli kígbe sókè. “Ṣé Olúwa pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́?”
11 Et Josaphat demanda: Y a-t-il ici un prophète du Seigneur, afin que nous implorions le Seigneur par lui? Et un des serviteurs du roi d’Israël répondit: Il y a ici Élisée, fils de Saphat, qui versait de l’eau sur les mains d’Élie.
Ṣùgbọ́n Jehoṣafati sì wí pé, “Ṣé kò sí wòlíì Olúwa níbí, tí àwa ìbá ti ọ̀dọ̀ rẹ̀ béèrè lọ́wọ́ rẹ̀?” Ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ ọba Israẹli dáhùn pé, “Eliṣa ọmọ Ṣafati wà níbí. Ó máa sábà bu omi sí ọwọ́ Elijah.”
12 Et Josaphat dit: La parole du Seigneur est en lui. Et le roi d’Israël descendit vers lui, ainsi que Josaphat, roi de Juda, et le roi d’Edom.
Jehoṣafati wí pé, “Ọ̀rọ̀ Olúwa wà pẹ̀lú rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni ọba Israẹli àti Jehoṣafati àti ọba Edomu sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ lọ.
13 Or Élisée dit au roi d’Israël: Qu’importe à moi et à vous? Allez aux prophètes de votre père et de votre mère. Et le roi d’Israël lui dit: Pourquoi le Seigneur a-t-il assemblé ces trois rois pour les livrer entre les mains de Joab?
Eliṣa wí fún ọba Israẹli pé, “Kí ni àwa ní ṣe pẹ̀lú ara wa? Lọ sọ́dọ̀ wòlíì baba rẹ àti wòlíì ti ìyá rẹ.” Ọba Israẹli dá a lóhùn, “Rárá, nítorí Olúwa ni ó pe àwa ọba mẹ́tẹ̀ẹ̀ta papọ̀ láti fi wá lé Moabu lọ́wọ́.”
14 Et Élisée lui dit: Il vit, le Seigneur des armées, en la présence duquel je suis! si je ne respectais la personne de Josaphat, roi de Juda, je n’aurais pas même fait attention à vous, et je ne vous aurais pas regardé.
Eliṣa wí pé, “Gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pé Olúwa àwọn ọmọ-ogun wà láyé, ẹni tí mo ń sìn tí èmi kò bá ní ọ̀wọ̀ fún ojú Jehoṣafati ọba Juda, èmi kò ní wò ó tàbí èmi kì bá ti rí ọ.
15 Mais maintenant amenez-moi un joueur de psaltérion. Et pendant que le joueur de psaltérion chantait, la main du Seigneur fut sur Élisée, et il dit:
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, mú wá fún mi ohun èlò orin olókùn.” Nígbà tí akọrin náà n kọrin, ọwọ́ Olúwa wá sórí Eliṣa.
16 Voici ce que dit le Seigneur: Faites du lit de ce torrent des fosses et des fosses.
Ó sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ‘Jẹ́ kí àfonífojì kún fún ọ̀gbun.’
17 Car voici ce que dit le Seigneur: Vous ne verrez pas de vent,’ni de pluie, et ce lit sera rempli d’eau, et vous boirez, vous, et vos familles et vos bêtes.
Nítorí èyí ni Olúwa wí, o kò ní í rí afẹ́fẹ́ tàbí òjò, bẹ́ẹ̀ ni àfonífojì yìí yóò kún pẹ̀lú omi, àti ìwọ àti ẹran ọ̀sìn àti pẹ̀lú àwọn ẹran yóò mu.
18 Et ceci est peu aux yeux du Seigneur: de plus, il livrera les Moabites entre vos mains.
Èyí jẹ́ ohun tí kò lágbára níwájú Olúwa, yóò sì fi Moabu lé e yín lọ́wọ́ pẹ̀lú.
19 Et vous attaquerez vivement toute cité fortifiée, toute ville importante; vous couperez par le pied tout arbre fruitier; vous boucherez toutes les sources d’eaux; et tout champ le plus fertile, vous le couvrirez de pierres.
Ìwọ yóò sì bi gbogbo ìlú olódi àti gbogbo àgbà ìlú ṣubú. Ìwọ yóò sì gé gbogbo igi dáradára ṣubú, dá gbogbo orísun omi dúró, kí o sì pa gbogbo pápá dáradára pẹ̀lú òkúta run.”
20 Il arriva donc le matin, quand on a coutume d’offrir le sacrifice, que des eaux venaient sur la voie d’Edom, et la terre fut remplie d’eaux.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ní àsìkò ẹbọ, níbẹ̀ ni omí sàn láti ọ̀kánkán Edomu! Ilé náà sì kún pẹ̀lú omi.
21 Or tous les Moabites, apprenant que les rois étaient montés pour combattre contre eux, convoquèrent tous ceux qui étaient ceints par-dessus d’un baudrier, et ils se tinrent sur les frontières.
Nísinsin yìí gbogbo ará Moabu gbọ́ pé àwọn ọba tí dé láti bá wọn jà. Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ènìyàn, ọmọdé àti àgbà tí ó lè ja ogun wọn pè wọ́n sókè wọ́n sì dúró ní etí ilẹ̀.
22 Et, se levant de grand matin, et le soleil paraissant déjà vis-à-vis des eaux, les Moabites virent à l’opposite les eaux rouges comme le sang;
Nígbà tí wọ́n dìde ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, oòrùn ti tàn sí orí omi náà sí àwọn ará Moabu ní ìkọjá ọ̀nà, omi náà sì pupa bí ẹ̀jẹ̀.
23 Et ils dirent: C’est le sang du glaive; les rois se sont battus l’un contre l’autre, et ils se sont taillés en pièces mutuellement: maintenant, va au butin, Moab.
“Ẹ̀jẹ̀ ni èyí!” wọ́n wí pé, “Àwọn ọba wọ̀nyí lè ti jà kí wọn sì pa ara wọn ní ìpakúpa. Nísinsin yìí sí àwọn ìkógun Moabu!”
24 Et ils marchèrent vers le camp d’Israël; mais Israël, se levant, battit Moab, et Moab s’enfuit devant Israël. Ils vinrent donc ceux qui avaient vaincu, et ils battirent Moab;
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ará Moabu dé sí ibùdó ti Israẹli, àwọn ará Israẹli dìde, wọ́n sì kọlù wọ́n títí tí wọ́n fi sálọ. Àwọn ará Israẹli gbógun sí ilẹ̀ náà wọ́n sì pa Moabu run.
25 Ils détruisirent les villes, et jetant chacun leur pierre, ils remplirent tout champ le plus fertile; ils bouchèrent toutes les sources d’eaux, coupèrent par le pied tous les arbres fruitiers, en sorte qu’il ne resta que les murailles faites d’argile; la ville fut investie par les frondeurs, et en grande partie, abattue.
Wọ́n sì wọ gbogbo ìlú náà olúkúlùkù ènìyàn, wọ́n ju òkúta sí gbogbo ohun dáradára orí pápá títí tí ó fi run. Wọ́n sì dá gbogbo orísun omi dúró wọ́n sì gé gbogbo orísun dáradára. Kiri-Hareseti nìkan ni wọ́n fi òkúta rẹ̀ sílẹ̀ ní ààyè rẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn ológun pẹ̀lú kànnàkànnà yíká, wọ́n sì kọlù ìlú náà.
26 Lorsque le roi de Moab eut vu cela, c’est-à-dire que les ennemis avaient prévalu, il prit avec lui sept cents hommes tirant l’épée pour qu’ils se jetassent sur le roi d’Edom; mais ils ne le purent pas.
Nígbà tí ọba Moabu rí i wí pé ogun náà le ju ti òun lọ, ó mú idà pẹ̀lú ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin ọkùnrin onídà láti jà pẹ̀lú ọba Edomu, ṣùgbọ́n wọn kò yege.
27 Et alors, saisissant son fils le premier-né qui devait régner après lui, il l’offrit en holocauste sur le mur, et il y eut une grande indignation parmi les enfants d’Israël; et aussitôt ils se retirèrent de lui, et ils retournèrent en leur terre.
Nígbà náà ó mú àkọ́bí ọmọkùnrin rẹ̀, tí kò bá jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ọba, ó sì fi rú ẹbọ sísun ní orí ògiri ìlú. Wọ́n sì bínú lórí Israẹli púpọ̀púpọ̀; wọ́n yọ́ kúrò wọ́n sì padà sí ìlú wọn.

< 2 Rois 3 >