< 2 Rois 23 >
1 Et ils rapportèrent au roi ce qu’elle avait dit. Et le roi envoya, et tous les anciens de Juda et de Jérusalem s’assemblèrent près de lui.
Nígbà náà ọba pe gbogbo àwọn àgbàgbà Juda àti Jerusalẹmu jọ.
2 Et le roi monta dans le temple du Seigneur, ainsi que tous les hommes de Juda et tous ceux qui habitaient dans Jérusalem avec lui, les prêtres, les prophètes et tout le peuple, depuis le petit jusqu’au grand, et il lut, tous l’écoutant, toutes les paroles du livre de l’alliance, qui avait été trouvé dans la maison du Seigneur.
Ó gòkè lọ sí ilé Olúwa pẹ̀lú àwọn ọkùnrin Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu, àwọn àlùfáà àti àwọn wòlíì—gbogbo àwọn ènìyàn láti ibi kéékèèké sí ńlá. Ó kà á sí etí ìgbọ́ ọ wọn, gbogbo ọ̀rọ̀ tí ó wà nínú ìwé májẹ̀mú, tí a ti rí nínú ilé Olúwa.
3 Et le roi se tint debout dans la tribune, et fit l’alliance devant le Seigneur, afin qu’ils marchassent à la suite du Seigneur, qu’ils observassent ses préceptes, ses lois et ses cérémonies en tout leur cœur et en toute leur âme, et qu’ils rétablissent toutes les paroles de l’alliance qui étaient écrites dans ce livre; et le peuple acquiesça à l’alliance.
Ọba sì dúró lẹ́bàá òpó, ó sì sọ májẹ̀mú di tuntun níwájú Olúwa, láti tẹ̀lé Olúwa àti láti pa òfin rẹ̀ mọ́, ìlànà àti òfin pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ̀ àti gbogbo ẹ̀mí rẹ̀, àti láti ṣe ìwádìí àwọn ọ̀rọ̀ májẹ̀mú tí a kọ sínú ìwé yìí. Nígbà náà, gbogbo àwọn ènìyàn sì ṣèlérí fúnra wọn sí májẹ̀mú náà.
4 Alors le roi ordonna à Helcias, le pontife, aux prêtres du second ordre, et aux portiers, de jeter hors du temple du Seigneur tous les vases qui avaient appartenu à Baal, au bois sacré et à toute l’armée du ciel, et il les brûla hors de Jérusalem, dans la vallée de Cédron, et il en emporta la poussière à Béthel.
Ọba sì pàṣẹ fún Hilkiah olórí àlùfáà àti àwọn, àlùfáà tí ó tẹ̀lé e ní ipò àti àwọn olùṣọ́nà láti yọ kúrò nínú ilé Olúwa gbogbo ohun èlò tí a ṣe fún Baali àti Aṣerah àti gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run. Ó sì sun wọ́n ní ìta Jerusalẹmu ní pápá àfonífojì Kidironi. Ó sì kó eérú wọn jọ sí Beteli.
5 Et il détruisit les aruspices qu’avaient établis les rois de Juda pour sacrifier sur les hauts lieux, dans les villes de Juda et autour de Jérusalem, et ceux qui brûlaient de l’encens à Baal, au Soleil, à la Lune, aux douze signes et à toute la milice du ciel.
Ó sì kúrò pẹ̀lú àwọn àlùfáà abọ̀rìṣà tí a yàn láti ọwọ́ ọba Juda láti sun tùràrí ní ibi gíga ti ìlú Juda àti àwọn tí ó yí Jerusalẹmu ká. Àwọn tí ó ń sun tùràrí sí Baali, sí oòrùn àti òṣùpá, sí àwọn àmì ìràwọ̀ àti sí gbogbo ẹgbẹ́ ogun ọ̀run.
6 Et il fit emporter le bois sacré de la maison du Seigneur hors de Jérusalem, dans la vallée de Cédron, où il le brûla et le réduisit en poussière qu’il jeta sur les sépulcres du petit peuple.
Ó mú ère òrìṣà Aṣerah láti ilé Olúwa sí àfonífojì Kidironi ní ìta Jerusalẹmu, ó sì sun wọ́n níbẹ̀. Ó lọ̀ ọ́ bí àtíkè ó sì fọ́n eruku náà sórí isà òkú àwọn ènìyàn tí ó wọ́pọ̀.
7 Il détruisit aussi les petites maisons des efféminés, lesquelles étaient dans la maison du Seigneur, et dans lesquelles les femmes tissaient comme des tentes pour le bois sacré.
Ó sì wó ibùgbé àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà lulẹ̀. Tí ó wà nínú ilé Olúwa àti ibi tí àwọn obìnrin tí ń ṣe iṣẹ́ aṣọ híhun fún òrìṣà Aṣerah.
8 Et il assembla tous les prêtres des villes de Juda, et il profana les hauts lieux où sacrifiaient les prêtres, depuis Gabaa jusqu’à Bersabée, et il détruisit les autels des portes, à l’entrée de la porte de Josué, prince de la ville, laquelle était à la gauche de la porte de la ville.
Josiah kó gbogbo àwọn àlùfáà láti àwọn ìlú Juda ó sì ba ibi mímọ́ wọ̀n-ọn-nì jẹ́ láti Geba sí Beerṣeba, níbi tí àwọn àlùfáà ti sun tùràrí. Ó wó àwọn ojúbọ lulẹ̀ ní ẹnu ìlẹ̀kùn—ní ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé ti Joṣua, baálẹ̀ ìlú ńlá tí ó wà ní apá òsì ẹnu ìlẹ̀kùn ìlú ńlá.
9 Cependant les prêtres des hauts lieux ne montaient point à l’autel du Seigneur dans Jérusalem; mais seulement ils mangeaient des azymes au milieu de leurs frères.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, àwọn àlùfáà ibi gíga kò jọ́sìn ní ibi pẹpẹ Olúwa ní Jerusalẹmu, wọ́n jẹ nínú àkàrà aláìwú pẹ̀lú àwọn àlùfáà ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn.
10 Le roi profana aussi Topheth, qui est dans la vallée du fils d’Ennom, afin que personne ne consacrât son fils ou sa fille par le feu à Moloch.
Ó sì ba ohun mímọ́ Tofeti jẹ́, tí ó wà ní àfonífojì Beni-Hinnomu, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkan tí ó lè lò ó fún ẹbọ rírú fún ọmọ rẹ̀ ọkùnrin tàbí ọmọ rẹ̀ obìnrin nínú iná sí Moleki.
11 Il enleva aussi les chevaux qu’avaient donnés les rois de Juda au Soleil, à l’entrée du temple du Seigneur, près de la salle de Nathanmélech, l’eunuque, qui était à Pharurim; mais les chariots du Soleil, il les brûla au feu.
Ó sì kúrò láti ẹnu-ọ̀nà àbáwọlé sí ilé Olúwa, àwọn ẹṣin tí àwọn ọba Juda ti yà sọ́tọ̀ sí oòrùn náà. Wọ́n wà nínú ilé ẹjọ́ lẹ́bàá yàrá oníṣẹ́ tí orúkọ rẹ̀ a máa jẹ́ Natani-Meleki. Josiah sì sun àwọn kẹ̀kẹ́ tí a yà sọ́tọ̀ fún oòrùn.
12 Les autels mêmes qui étaient sur le toit de la chambre d’Achaz, qu’avaient faits les rois de Juda, et les autels qu’avait faits Manassé dans les deux parvis du temple du Seigneur, le roi les détruisit, et il répandit les cendres dans le torrent de Cédron.
Ó wó o palẹ̀ pẹpẹ tí àwọn ọba Juda ti wọ́n gbé dúró ní orí òrùlé lẹ́bàá yàrá òkè ti Ahasi pẹ̀lú àwọn pẹpẹ tí Manase ti kọ́ nínú ilé ẹjọ́ méjèèjì sí ilé Olúwa. Ó ṣí wọn kúrò níbẹ̀, ó fọ́ wọn sí wẹ́wẹ́. Ó sì da ekuru wọn sínú àfonífojì Kidironi.
13 Le roi profana aussi les hauts lieux qui étaient à Jérusalem, du côté droit de la montagne du Scandale, que Salomon, roi d’Israël, avait bâtis à Astaroth, idole des Sidoniens, à Chamos, le scandale de Moab, et à Melchom, l’abomination des enfants d’Ammon.
Ọba pẹ̀lú ba ohun mímọ́ àwọn ibi gíga jẹ́ tí ó wà ní ìhà ìlà-oòrùn Jerusalẹmu ní ìhà gúúsù ti òkè ìbàjẹ́—èyí tí Solomoni ọba Israẹli ti kọ́ fún Aṣtoreti ọlọ́run ìríra àwọn ará Sidoni, fún Kemoṣi ọlọ́run ìríra àwọn ará Moabu àti fún Moleki, ọlọ́run ìríra àwọn ènìyàn Ammoni.
14 Et il brisa les statues et coupa les bois sacrés, et il remplit ces lieux-là d’os de morts.
Josiah fọ́ òkúta yíyà sọ́tọ̀, ó sì gé ère Aṣerah lulẹ̀. Ó sì bo ẹ̀gbẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pẹ̀lú egungun ènìyàn.
15 En outre, quant à l’autel même qui était à Béthel, et le haut lieu qu’avait bâti Jéroboam, fils de Nabath, qui fit pécher Israël, il détruisit et cet autel et ce haut lieu; il les brûla et les réduisit en poussière, et il mit aussi le feu au bois sacré.
Àní pẹpẹ tí ó wà ní Beteli ibi gíga tí Jeroboamu ọmọ Nebati dá. Tí ó ti fa Israẹli láti ṣẹ̀, àní pẹpẹ náà àti ibi gíga tí ó fọ́ túútúú. Ó jó àwọn ibi gíga, ó sì lọ̀ ọ́ sí ẹ̀tù, ó sì sun ère Aṣerah pẹ̀lú.
16 Et, se tournant, Josias vit là les sépulcres qui étaient sur la montagne, et il envoya et il prit les os de ces sépulcres, et les brûla sur l’autel, et il le profana, selon la parole du Seigneur, qu’avait dite l’homme de Dieu qui avait prédit ces choses.
Nígbà náà, Josiah wò yíká, nígbà tí ó sì rí àwọn isà òkú tí ó wà níbẹ̀ ní ẹ̀bá òkè, ó yọ egungun kúrò lára wọn, ó sì jó wọn lórí pẹpẹ láti sọ ọ́ di èérí ní ìbámu pẹ̀lú ọ̀rọ̀ Olúwa tí a ti kéde láti ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run tí ó ti àwọn nǹkan wọ̀nyí tẹ́lẹ̀.
17 Et il demanda: Quel est ce tombeau que je vois? Et les citoyens de cette ville lui dirent: C’est le sépulcre de l’homme de Dieu qui vint de Juda, et qui prédit ce que vous avez fait sur l’autel de Béthel.
Ọba sì béèrè pé, “Kí ni ọwọ̀n isà òkú yẹn tí mo rí?” Àwọn ọkùnrin ìlú ńlá wí pé, “Ó sàmì sí isà òkú ènìyàn Ọlọ́run tí ó wá láti Juda, tí ó sì kéde ìdojúkọ pẹpẹ Beteli, ohun kan wọ̀nyí tí ìwọ ti ṣe sí wọn.”
18 Et il dit: Laissez-le, que personne ne remue ses os. Et ses os demeurèrent intacts, avec les os du prophète qui était venu de Samarie.
“Fi sílẹ̀ nìkan,” Ó wí pé. “Má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni ó da àwọn egungun rẹ̀ láàmú.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n dá egungun rẹ̀ sí àti ti àwọn wòlíì tí ó wá láti Samaria.
19 De plus, tous les temples mêmes des hauts lieux qui étaient dans les villes de Samarie, qu’avaient faits les rois d’Israël pour irriter le Seigneur, Josias les détruisit; et il leur fit selon tout ce qu’il avait fait à Béthel.
Gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ní Beteli, Josiah sì kúrò, ó sì ba gbogbo ojúbọ òrìṣà ti ibi gíga jẹ́, tí àwọn ọba Israẹli ti kọ́ sí àwọn ìlú ní Samaria, tí ó ti mú Olúwa bínú.
20 Et il tua tous les prêtres des hauts lieux qui étaient là préposés aux autels, et il brûla des ossements humains sur ces autels, et il retourna à Jérusalem.
Josiah dúńbú gbogbo àwọn àlùfáà ibi gíga lórí pẹpẹ. Ó sì sun egungun ènìyàn lórí wọn. Nígbà náà, ó padà lọ sí Jerusalẹmu.
21 Et il ordonna à tout le peuple, disant: Faites une Pâque du Seigneur votre Dieu, selon ce qui est écrit dans le livre de cette alliance;
Ọba pàṣẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn pé, “Ẹ ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá sí Olúwa Ọlọ́run yín, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ ọ́ sí inú ìwé májẹ̀mú yìí.”
22 Car il n’a été fait aucune Pâque depuis les jours des juges qui jugèrent Israël, et pendant tous les jours des rois d’Israël et des rois de Juda,
Kì í ṣe láti ọjọ́ àwọn Juda tí ó tọ́ Israẹli, ní gbogbo àwọn ọjọ́ àwọn ọba Israẹli àti àwọn ọba Juda. Ṣé wọ́n ti ṣe ìrántí àjọ ìrékọjá rí.
23 Comme à la dix-huitième année du roi Josias a été faite cette Pâque du Seigneur dans Jérusalem.
Ṣùgbọ́n ní ọdún kejìdínlógún tí ọba Josiah, àjọ ìrékọjá yìí ni a ṣe ìrántí sí Olúwa ní Jerusalẹmu.
24 Mais aussi ceux qui avaient un esprit de python, les devins et les figures des idoles, les impuretés et les abominations qui avaient été dans la terre de Juda et de Jérusalem, Josias les fit disparaître pour accomplir les paroles de la loi qui sont écrites dans le livre que trouva Helcias, le prêtre, dans le temple du Seigneur.
Síwájú sí, Josiah sì lé àwọn oṣó àti àwọn ẹ̀mí ní àwọn ìdílé, àti àwọn òrìṣà àti gbogbo àwọn nǹkan ìríra tí a rí ní Juda àti ní Jerusalẹmu. Èyí ni ó ṣe kí ó le è mú ọ̀rọ̀ òfin náà ṣe ní ti òfin tí a kọ sínú ìwé tí Hilkiah àlùfáà ti rí nínú ilé Olúwa.
25 Il n’y a point eu avant Josias de roi semblable, qui soit retourné comme lui au Seigneur en tout son cœur, en toute son âme, et en toute sa force, selon toute la loi de Moïse, et après lui, il n’y en a pas eu de semblable à lui.
Kò sì sí ọba kankan níwájú tàbí lẹ́yìn Josiah tí ó dàbí rẹ̀, tí ó yí padà sí olúwa tinútinú àti gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe tọkàntọkàn pẹ̀lú gbogbo ẹ̀mí i rẹ̀, pẹ̀lú gbogbo agbára rẹ̀ ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin Mose.
26 Cependant le Seigneur ne revint point de la colère de sa grande fureur, dont fut irritée sa fureur contre Juda, à cause des sujets d’irritation qu’avait provoqués en lui Manassé.
Bí ó ti wù kí ó rí Olúwa kò yípadà kúrò nínú ìmúná ìbínú ńlá rẹ̀ tí ó jó sí Juda, nítorí gbogbo èyí tí Manase ti ṣe láti mú un bínú.
27 C’est pourquoi le Seigneur dit: Juda aussi, je l’ôterai de devant ma face, comme j’en ai ôté Israël, et je rejetterai cette ville, que j’ai choisie, Jérusalem et cette maison dont j’ai dit: Mon nom sera là.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí pé, “Èmi yóò mú Juda kúrò pẹ̀lú níwájú mi, bí mo ti mú Israẹli, èmi yóò sì kó Jerusalẹmu, ìlú ńlá tí mo yàn àti ilé Olúwa yìí, nípa èyí tí mo sọ, ‘Níbẹ̀ ni orúkọ mi yóò wà?’”
28 Mais le reste des actions de Josias, et tout ce qu’il a fait, n’est-ce pas écrit dans le Livre des actions des jours des rois de Juda?
Fún ti ìyókù iṣẹ́ nígbà ìjọba Josiah, àti gbogbo ohun tí ó ṣe, ṣé a kò kọ wọ́n sí inú ìwé ìtàn ayé àwọn ọba Juda?
29 Aux jours de Josias, Pharaon Néchao, roi d’Egypte, monta contre le roi des Assyriens, vers le fleuve d’Euphrate, et Josias, le roi, alla à sa rencontre; et il fut tué à Mageddo, lorsqu’il l’eut vu.
Nígbà tí Josiah jẹ́ ọba, Farao Neko ọba Ejibiti gòkè lọ sí odò Eufurate láti lọ ran ọba Asiria lọ́wọ́. Ọba Josiah jáde lọ láti lọ bá a pàdé lójú ogun ṣùgbọ́n Neko dojúkọ ọ́, ó sì pa á ní Megido.
30 Et ses serviteurs l’enlevèrent mort de Mageddo, le portèrent à Jérusalem et l’ensevelirent dans son sépulcre. Alors le peuple du pays prit Joachaz, fils de Josias; et ils l’oignirent, et l’établirent en la place de son père.
Ìránṣẹ́ Josiah gbé ara rẹ̀ wá nínú kẹ̀kẹ́ láti Megido sí Jerusalẹmu ó sì sin ín sínú isà òkú rẹ̀. Àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà mú Jehoahasi ọmọ Josiah. Ó fi àmì òróró yàn án, ó sì ṣe é ní ọba ní ipò baba a rẹ̀.
31 Joachaz avait vingt-trois ans lorsqu’il commença à régner, et il régna trois mois à Jérusalem: le nom de sa mère était Amital, fille de Jérémie de Lobna,
Jehoahasi sì jẹ́ ẹni ọdún mẹ́tàlélógún nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún oṣù mẹ́ta. Orúkọ ìyá rẹ̀ a máa jẹ́ Hamutali ọmọbìnrin Jeremiah; ó wá láti Libina.
32 Et il fit le mal devant le Seigneur, selon tout ce que ses pères avaient fait.
Ó ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.
33 Et Pharaon Néchao l’enchaîna à Rébla, qui est dans la terre d’Emath, afin qu’il ne régnât point à Jérusalem, et il imposa une amende au pays de cent talents d’argent et un talent d’or.
Farao Neko sì fi sí inú ìdè ní Ribla ní ilẹ̀ Hamati, kí ó má ba à lè jẹ ọba ní Jerusalẹmu. Ó sì tan Juda jẹ fun iye ìwọ̀n ẹgbẹ̀rin tálẹ́ǹtì wúrà kan.
34 Et Pharaon Néchao établit roi Eliacim, fils de Josias, en la place de Josias, son père, et il changea son nom en Joakim: or il prit Joachaz et le conduisit en Egypte, et il y mourut.
Farao Neko ṣe Eliakimu ọmọ Josiah ní ọba ní ipò baba rẹ̀ Josiah. Ó sì yí orúkọ Eliakimu padà sí Jehoiakimu. Ṣùgbọ́n ó mú Jehoahasi, ó sì gbé e lọ sí Ejibiti, níbẹ̀ ni ó sì kú.
35 Joakim donna à Pharaon l’argent et l’or, puisqu’il avait taxé le pays par tête, afin qu’ils fussent apportés ensemble selon l’ordre de Pharaon; et il exigea de chacun, selon ses moyens, tant l’argent que l’or du peuple du pays, pour donner à Pharaon Néchao.
Jehoiakimu sì san fún Farao Neko fàdákà àti wúrà tí ó béèrè. Láti ṣe bẹ́ẹ̀, ó bu owó òde fún ilẹ̀ náà láti san, ó fi agbára gba fàdákà àti wúrà láti ọwọ́ àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà ní ìbámu pẹ̀lú iye tí a pín.
36 Joakim avait vingt-cinq ans lorsqu’il commença à régner, et il régna onze ans à Jérusalem: le nom de sa mère était Zébida, fille de Phadaïa de Ruma.
Jehoiakimu jẹ́ ẹni ọdún mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n nígbà tí ó di ọba, ó sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu fún ọdún mọ́kànlá orúkọ ìyá rẹ̀ ni Sebida ọmọbìnrin Pedaiah ó wá láti Ruma.
37 Et il fit le mal devant le Seigneur, selon tout ce qu’avaient fait ses pères.
Ó sì ṣe búburú lójú Olúwa gẹ́gẹ́ bí baba a rẹ̀ ti ṣe.