< 2 Rois 17 >

1 En la douzième année d’Achaz, roi de Juda, Osée, fils d’Ela, régna à Samarie sur Israël pendant neuf ans.
Ní ọdún kejìlá ọba Ahasi ará Juda, Hosea ọmọ Ela jẹ ọba Israẹli ní Samaria, ó sì jẹ fún ọdún mẹ́sàn-án.
2 Et il fit le mal devant le Seigneur, mais non comme les rois d’Israël qui furent avant lui.
Ó sì ṣe búburú ní ojú Olúwa, ṣùgbọ́n kì í ṣe bí i ti ọba Israẹli ẹni tí ó ti wà ṣáájú rẹ̀.
3 Salmanasar, roi des Assyriens, monta contre lui, et Osée fut asservi à Salmanasar, roi des Assyriens, et il lui payait des tributs.
Ṣalamaneseri ọba Asiria wá sókè láti mú Hosea, ẹni tí ó ti jẹ fún Ṣalamaneseri ó sì ti san owó òde fún un.
4 Mais, le roi des Assyriens, ayant découvert qu’Osée s’efforçait de se révolter contre lui, avait envoyé des messagers à Sua, roi d’Egypte, pour ne point payer des tributs au roi des Assyriens, comme il avait coutume tous les ans, il l’assiégea, et l’envoya lié en prison.
Ṣùgbọ́n ọba Asiria rí i wí pé Hosea jẹ́ ọlọ́tẹ̀, nítorí ó ti rán oníṣẹ́ sọ́dọ̀ ọba Ejibiti, kò sì san owó òde mọ́ fún ọba Asiria, gẹ́gẹ́ bí o ti máa ń ṣe ní ọdọọdún. Nígbà náà ọba Asiria fi agbára mú ún, ó sì fi sínú túbú.
5 Il parcourut ensuite tout le pays; et montant à Samarie, il l’assiégea pendant trois ans.
Ọba Asiria gòkè wá sí gbogbo ibi ilé náà, ó sì lọ sí Samaria, ó sì dúró tí ì fún ọdún mẹ́ta.
6 Or, en la neuvième année d’Osée, le roi des Assyriens prit Samarie, et transféra Israël chez les Assyriens, et les conduisit en Hala et en Habor, près du fleuve de Gozan, dans les villes des Mèdes.
Ní ọdún kẹsànán ti Hosea, ọba Asiria mú Samaria ó sì kó Israẹli lọ sí Asiria. Ó sì fi wọ́n sílẹ̀ ní Hala, ní Gosani ní etí odò Habori àti ní ìlú àwọn ará Media.
7 Et cela arriva parce que les enfants d’Israël avaient péché contre le Seigneur leur Dieu, qui les avait retirés de l’Egypte et de la main de Pharaon, roi d’Egypte, et parce qu’ils adorèrent des dieux étrangers.
Gbogbo eléyìí ṣẹlẹ̀ nítorí àwọn ọmọ Israẹli ti dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wọn, ẹni tí ó mú wọn jáde ní Ejibiti lábẹ́ agbára Farao ọba Ejibiti. Wọ́n sin ọlọ́run mìíràn,
8 Et ils marchèrent selon les coutumes des nations que le Seigneur avait exterminées en la présence des enfants d’Israël, et selon les coutumes des rois d’Israël, parce qu’ils avaient fait de même que ces nations.
wọn si tẹ̀lé ìwà orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti gbá kúrò níwájú wọn gẹ́gẹ́ bí ìwà ti ọba Israẹli tí ó ti paláṣẹ.
9 Et les enfants d’Israël offensèrent le Seigneur leur Dieu par des actions qui n’étaient pas droites, et ils se bâtirent des hauts lieux dans toutes leurs villes, depuis la Tour des gardes jusqu’à la Cité fortifiée.
Àwọn ọmọ Israẹli ṣe ohun ìríra sí Olúwa Ọlọ́run wọn kọ́ láti ilé ìṣọ́ sí ìlú tí a dáàbò bò, wọ́n kọ́ ilé gíga fún ara wọn ní gbogbo ìlú wọn.
10 Et ils se firent des statues, et des bois sacrés sur toute colline haute, et sous tout arbre touffu;
Wọ́n sì gbé àwọn òkúta tí a yà sọ́tọ̀ sókè àti ère òrìṣà Aṣerah lórí gbogbo igi tútù.
11 Et ils brûlaient là de l’encens sur des autels, à la manière des nations que le Seigneur avait transportées loin de leur face, et ils firent des actions très mauvaises en irritant le Seigneur.
Ní gbogbo ibi gíga, wọ́n sun tùràrí gẹ́gẹ́ bí orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti lé jáde níwájú wọn. Wọ́n ṣe ohun búburú tí ó rú ìbínú Olúwa sókè.
12 Et ils adorèrent les impuretés, au sujet desquelles le Seigneur leur avait ordonné de ne pas faire cette chose.
Wọ́n sìn òrìṣà, èyí tí Olúwa ti sọ pé, “Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí.”
13 Le Seigneur protesta dans Israël et dans Juda par l’entremise de tous les prophètes et des voyants, en disant: Revenez de vos voies très mauvaises, et gardez mes préceptes et mes cérémonies, selon toute la loi que j’ai prescrite à vos pères, et comme je vous l’ai envoyé dire par l’entremise de mes serviteurs, les prophètes.
Olúwa kìlọ̀ fún Israẹli àti Juda nípa gbogbo àwọn wòlíì wọn àti aríran: “Ẹ yípadà kúrò ní ọ̀nà búburú yín. Kí ẹ ṣe òfin mi àti ìlànà mi, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo òfin tí Èmi paláṣẹ fún àwọn baba yín láti tẹ̀lé àti èyí tí mo rán sí i yín nípa ìránṣẹ́ àwọn wòlíì mi.”
14 Et ils n’écoutèrent point; mais ils rendirent leur cou inflexible, comme le cou de leurs pères, qui ne voulurent pas obéir au Seigneur leur Dieu.
Ṣùgbọ́n wọn kò ní gbọ́, wọ́n sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọlọ́rùn líle gẹ́gẹ́ bí i ti baba wọn, ẹni tí kò gbà Olúwa Ọlọ́run wọn gbọ́.
15 Et ils rejetèrent ses lois, et l’alliance qu’il fit avec leurs pères, et les déclarations par lesquelles il protesta contre eux; ils suivirent aussi les vanités, et agirent vainement; ils suivirent les nations qui étaient autour d’eux, et au sujet desquelles le Seigneur leur avait ordonné de ne pas faire comme elles-mêmes faisaient.
Wọ́n kọ̀ ìlànà rẹ̀ àti májẹ̀mú tí ó ti ṣe pẹ̀lú baba wọn àti ìkìlọ̀ tí ó ti fi fún wọn. Wọ́n tẹ̀lé òrìṣà aláìníláárí, àwọn fún rara wọn sì jẹ́ aláìníláárí. Wọ́n tẹ̀lé orílẹ̀-èdè tí ó yí wọn ká bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Olúwa ti kìlọ̀ fún wọn pé, “Má ṣe ṣe gẹ́gẹ́ bí wọn tí ń ṣe,” wọ́n sì ṣe ohun tí Olúwa ti kà léèwọ̀ fún wọn láti ṣe.
16 Et ils abandonnèrent tous les préceptes du Seigneur leur Dieu; et ils se firent deux veaux de fonte et des bois sacrés, adorèrent toute la milice du ciel, et servirent Baal;
Wọ́n kọ̀ gbogbo òfin Olúwa Ọlọ́run wọn sílẹ̀, wọ́n sì ṣe òrìṣà méjì fún ara wọn, wọ́n sì gbẹ́ ẹ ọ̀kan ní ère ẹgbọrọ màlúù, àti ọ̀kan ní ère òrìṣà Aṣerah. Wọ́n sì tẹrí wọn ba sí gbogbo ogun ọ̀run, wọ́n sì sin Baali.
17 Puis ils consacrèrent leurs fils et leurs filles par le feu; et ils se livraient à des divinations et aux augures, et ils s’abandonnèrent à faire le mal devant le Seigneur, en sorte qu’ils l’irritèrent.
Wọ́n sì fi àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin wọn rú ẹbọ nínú iná. Wọ́n sì ń fọ àfọ̀ṣẹ, wọ́n sì ń ṣe àlúpàyídà wọ́n sì ta ara wọn láti ṣe ohun búburú níwájú Olúwa, wọ́n sì mú un bínú.
18 Le Seigneur donc fut extrêmement irrité contre Israël, et il les ôta de sa présence, et il ne demeura que la tribu de Juda seulement.
Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì bínú gidigidi pẹ̀lú Israẹli ó sì mú wọn kúrò níwájú rẹ̀. Ẹ̀yà Juda nìkan ṣoṣo ni ó kù,
19 Or Juda lui-même ne garda point les commandements du Seigneur son Dieu; mais il marcha dans les erreurs qu’Israël avait commises.
àti pẹ̀lú, Juda kò pa òfin Olúwa Ọlọ́run wọn mọ́. Wọ́n tẹ̀lé ìhùwàsí àwọn Israẹli tí wọ́n ṣe.
20 Et le Seigneur rejeta toute la race d’Israël; et il les affligea, et les livra à la main des pillards, jusqu’à ce qu’il les rejetât de devant sa face;
Nítorí náà Olúwa kọ gbogbo àwọn ènìyàn Israẹli; ó sì jẹ wọ́n ní yà. Ó sì fi wọ́n lé ọwọ́ àwọn olè títí tí ó fi ta wọ́n nù kúrò níwájú rẹ̀.
21 Ce qui commença dès le temps même qu’Israël se sépara de la maison de David, et qu’ils établirent pour leur roi Jéroboam, fils de Nabath; car Jéroboam sépara Israël d’avec le Seigneur, et leur fit commettre un grand péché.
Nígbà tí ó ta Israẹli kúrò láti ìdílé Dafidi, wọ́n sì mú Jeroboamu ọmọ Nebati jẹ ọba wọn. Jeroboamu sì mú kí àwọn ọmọ Israẹli yípadà kúrò ní títẹ̀lé Olúwa, ó sí mú kí wọn dẹ́ṣẹ̀ ńlá.
22 Et les enfants d’Israël marchèrent dans tous les péchés que Jéroboam avait commis, et ils ne s’en écartèrent point,
Àwọn ọmọ Israẹli forítì í nínú gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ Jeroboamu kò sì yí padà kúrò lọ́dọ̀ wọn,
23 Jusqu’à ce que le Seigneur ôtât Israël de sa face, comme il avait dit par l’entremise de tous ses serviteurs, les prophètes; et Israël fut transféré de sa terre chez les Assyriens, jusqu’à ce jour.
títí tí Olúwa fi mú wọn kúrò níwájú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ó ti paláṣẹ láti ọ̀dọ̀ àwọn ìránṣẹ́ wòlíì. Bẹ́ẹ̀ ni a kó gbogbo ènìyàn Israẹli kúrò ní ilẹ̀ wọn lọ sí ìgbèkùn ni Asiria, títí di òní yìí.
24 Or le roi des Assyriens amena des habitants de Babylone, de Cutha, d’Ava, d’Emath et de Sépharvaïm, et les établit dans les villes de la Samarie, en la place des enfants d’Israël: et ils possédèrent la Samarie, et habitèrent dans ses villes.
Ọba Asiria mú àwọn ènìyàn láti Babeli, Kuta, Afa, Hamati àti Sefarfaimi, wọ́n sì fi wọ́n sínú ìlú Samaria láti rọ́pò àwọn ọmọ Israẹli. Wọ́n sì ń gbé ní ìlú náà.
25 Or lorsqu’ils commencèrent à y habiter, ils ne craignaient pas le Seigneur; et le Seigneur envoya contre eux les lions qui les tuaient.
Nígbà tí wọ́n gbé bẹ̀ ní àkọ́kọ́, wọn kò sì bẹ̀rù Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni ó rán kìnnìún sí àárín wọn. Wọ́n sì pa nínú wọn.
26 On l’annonça au roi des Assyriens, et on lui dit: Les nations que vous avez transférées, et que vous avez fait habiter dans les villes de la Samarie, ignorent les lois du Dieu de ce pays; et le Seigneur a envoyé contre eux les lions qui les tuent, parce qu’ils ignorent le culte du Dieu de ce pays.
Wọ́n sì sọ fún ọba Asiria pé, “Àwọn ènìyàn tí ìwọ lé kúrò tí o sì fi sínú ìlú Samaria kò mọ ohun tí ọlọ́run ìlú náà béèrè. Ó sì ti rán kìnnìún sí àárín wọn, tí ó sì ń pa wọ́n run, nítorí ènìyàn wọn kò mọ ohun tí ó béèrè.”
27 Aussi le roi des Assyriens ordonna, disant: Envoyez là l’un des prêtres que vous en avez emmenés captifs; qu’il aille et habite avec eux, et qu’il leur apprenne les lois du Dieu de ce pays.
Nígbà náà ọba Asiria pàṣẹ yìí wí pé, “Mú ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó mú láti Samaria lọ padà gbé níbẹ̀ kí ó sì kọ́ àwọn ènìyàn ní, ohun tí ọlọ́run ilẹ̀ náà béèrè.”
28 Ainsi, lorsque fut venu l’un des prêtres qui avaient été emmenés captifs de Samarie, il habita à Béthel, et il leur apprenait comment il devaient honorer le Seigneur.
Bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan lára àwọn àlùfáà tí ó ti kúrò ní Samaria wá gbé ní Beteli ó sì kọ́ wọn bí a ti ń sin Olúwa.
29 Mais chaque nation se fabriqua son dieu, et elles le mirent dans les temples des hauts lieux qu’avaient faits les Samaritains, chaque nation dans ses villes, dans lesquelles elle habitait.
Bí ó tilẹ̀ rí bẹ́ẹ̀, olúkúlùkù orílẹ̀-èdè ṣe òrìṣà tirẹ̀ ní gbogbo ìlú níbi tí wọ́n gbé wà, wọ́n sì gbé wọn nínú ilé òrìṣà àti àwọn ènìyàn Samaria ó sì ṣe wọ́n sí ibi gíga wọ̀n-ọn-nì.
30 Car les hommes de Babylone firent Sochothbénoth; mais les hommes de Chuta firent Nergel, et les hommes d’Emath firent Asima.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọkùnrin láti Babeli ṣe àgọ́ àwọn wúńdíá, àwọn ènìyàn Kuti ṣe òrìṣà Nergali, àti àwọn ènìyàn Hamati ṣe ti Aṣima;
31 Or les Hévéens firent Nébahaz et Tharthac; mais ceux qui étaient de Sépharvaïm brûlaient leurs enfants au feu en l’honneur; d’Adramélech et d’Anamélech, dieux de Sépharvaïm;
àti àwọn ará Afa ṣe Nibhasi àti Tartaki, àti àwọn ará Sefarfaimi sun àwọn ọmọ wọn níná gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sí Adrameleki àti Anameleki, àwọn òrìṣà Sefarfaimi.
32 Et néanmoins ils adoraient le Seigneur. Mais ils se firent des derniers d’entre eux des prêtres des hauts lieux, et ils les établissaient dans les temples des hauts lieux.
Wọ́n sin Olúwa, ṣùgbọ́n wọ́n sì tún yan gbogbo ẹgbẹ́ tí ènìyàn wọn láti ṣe iṣẹ́ oyè fún wọn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà ní ibi gíga.
33 Ainsi, quoiqu’ils adorassent le Seigneur, ils servaient aussi leurs dieux, selon la coutume des nations du milieu desquelles ils avaient été transférés en Samarie.
Wọ́n sin Olúwa ṣùgbọ́n wọ́n sin òrìṣà wọn ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú àṣà orílẹ̀-èdè wọn láti ibi tí wọ́n ti gbé wọn wá.
34 Jusqu’au présent jour ils suivent leur ancienne coutume: ils ne craignent point le Seigneur, et ne gardent point ses cérémonies, ses ordonnances, ni sa loi, ni le commandement qu’avait prescrit le Seigneur aux enfants de Jacob, qu’il surnomma Israël:
Láti ìgbà náà wá àwọn àlùfáà wọn ṣe bí ti àtẹ̀yìnwá. Wọn kò sin Olúwa tàbí kí wọ́n fi ara mọ́ ìlànà àti àṣẹ àti òfin tí Olúwa fi fún ìránṣẹ́ Jakọbu, tí wọ́n pe orúkọ rẹ̀ ní Israẹli.
35 Et il avait fait avec eux alliance, et leur avait commandé, disant: Ne craignez point les dieux étrangers, ne les adorez point, ne les servez point et ne leur sacrifiez point;
Nígbà tí Olúwa ṣe májẹ̀mú pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ó pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe sin òrìṣà mìíràn tàbí tẹríba fún wọn, sìn wọ́n tàbí kí ẹ rú ẹbọ sí wọn.
36 Mais ne craignez que le Seigneur votre Dieu, qui vous a retirés de l’Egypte par une grande puissance et par un bras étendu; n’adorez que lui, et ne sacrifiez qu’à lui.
Ṣùgbọ́n Olúwa, ẹni tí ó mú yín gòkè jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti pẹ̀lú agbára ńlá àti nínà apá, òun ni ẹni náà tí ó yẹ kí ẹ sìn. Òun ni ẹni tí ó yẹ kí ẹ tẹríba fún àti sí òun ni kí ẹ rú ẹbọ fún.
37 Les cérémonies aussi, et les ordonnances, et la loi et le commandement qu’il a écrits pour vous, gardez-les, afin que vous les pratiquiez tous les jours; et ne craignez pas les dieux étrangers.
Ó yẹ kí ẹ̀yin kí ó máa kíyèsi ara yín gidigidi láti pa ìlànà àti àṣẹ, àti òfin tí ó kọ fún un yín mọ́. Ẹ má ṣe sin ọlọ́run mìíràn.
38 Et l’alliance qu’il a faite avec vous, ne l’oubliez point, et n’honorez point des dieux étrangers;
Ẹ má ṣe gbàgbé májẹ̀mú tí mo ti ṣe pẹ̀lú yín mọ́ àti kí ẹ má sin ọlọ́run mìíràn.
39 Mais craignez le Seigneur votre Dieu, et il vous arrachera lui-même à la main de tous vos ennemis.
Kúkú sin Olúwa Ọlọ́run rẹ; Òun ni ẹni náà tí yóò gbà yín kúrò lọ́wọ́ gbogbo àwọn ọ̀tá a yín.”
40 Or, ils n’écoutèrent point; mais ils agissaient selon leur ancienne coutume.
Wọn kò ní gbọ́, bẹ́ẹ̀ ni, wọ́n sì ń ṣe iṣẹ́ wọ́n ti àtijọ́.
41 Ainsi ces nations ont craint, à la vérité, le Seigneur; mais néanmoins elles ont servi leurs idoles; car leurs fils et leurs petits-fils font jusqu’au présent jour comme ont fait leurs pères.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn wọn sin Olúwa, wọ́n sì ń sin òrìṣà wọn. Títí di ọjọ́ òní ọmọ wọn àti àwọn ọmọ ọmọ wọn sì ń ṣe bí àwọn baba wọn ti ń ṣe.

< 2 Rois 17 >